272 lines
11 KiB
Plaintext
272 lines
11 KiB
Plaintext
\id NAM - Biblica® Open Yoruba Contemporary Bible (Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
|
||
\rem Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.®
|
||
\h Nahumu
|
||
\toc1 Ìwé Wòlíì Nahumu
|
||
\toc2 Nahumu
|
||
\toc3 Nh
|
||
\mt1 Ìwé Wòlíì Nahumu
|
||
\c 1
|
||
\p
|
||
\v 1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.
|
||
\b
|
||
\s1 Ìbínú \nd Olúwa\nd* sí Ninefe
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú.
|
||
\q1 \nd Olúwa\nd* ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀.
|
||
\q2 Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 \x - \xo 1.3: \xt Isa 10.5-34; Sf 2.12-15.\x*\nd Olúwa\nd* lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà.
|
||
\q1 Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì,
|
||
\q2 ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ó bá òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ;
|
||
\q2 Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ.
|
||
\q1 Baṣani àti Karmeli sì rọ.
|
||
\q2 Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀,
|
||
\q2 àwọn òkè kéékèèké sì di yíyọ́,
|
||
\q1 ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀,
|
||
\q2 àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀?
|
||
\q2 Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀?
|
||
\q1 Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná;
|
||
\q2 àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Rere ni \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú.
|
||
\q1 Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,
|
||
\q2
|
||
\v 8 ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá
|
||
\q1 ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin;
|
||
\q2 òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí \nd Olúwa\nd*?
|
||
\q2 Òun yóò fi òpin sí i,
|
||
\q2 ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú
|
||
\q2 wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn
|
||
\q2 a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá
|
||
\q2 tí ó ń gbèrò ibi sí \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.
|
||
\p
|
||
\v 12 Báyìí ni \nd Olúwa\nd* wí:
|
||
\q1 “Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀,
|
||
\q1 nígbà tí òun ó bá kọjá.
|
||
\q2 Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójúmọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ
|
||
\q2 èmi yóò já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 \nd Olúwa\nd* ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe:
|
||
\q2 “Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́,
|
||
\q1 Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run
|
||
\q2 tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ.
|
||
\q1 Èmi yóò wa ibojì rẹ,
|
||
\q2 nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 \x - \xo 1.15: \xt Isa 40.9; 52.7; Ap 10.36; Ro 10.15.\x*Wò ó, lórí àwọn òkè,
|
||
\q2 àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá,
|
||
\q2 ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà.
|
||
\q1 Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́,
|
||
\q2 kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ.
|
||
\q1 Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́;
|
||
\q2 wọn yóò sì parun pátápátá.
|
||
\c 2
|
||
\s1 Ìṣubú Ninefe
|
||
\q1
|
||
\v 1 Àwọn apanirun ti dìde sí ọ, ìwọ Ninefe.
|
||
\q2 Pa ilé ìṣọ́ mọ́,
|
||
\q2 ṣọ́ ọ̀nà náà,
|
||
\q2 di àmùrè,
|
||
\q2 ẹ̀gbẹ́ rẹ kí ó le múra gírí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd* yóò mú ọláńlá Jakọbu padà sípò
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ọláńlá Israẹli
|
||
\q1 bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn apanirun ti pa ibẹ̀ run,
|
||
\q2 tí wọ́n sì ba ẹ̀ka àjàrà wọn jẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Asà àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì di pupa;
|
||
\q2 àwọn ológun wọn sì wọ aṣọ òdòdó.
|
||
\q1 Idẹ tí ó wà lórí kẹ̀kẹ́ ogun ń kọ mọ̀nàmọ́ná
|
||
\q2 ní ọjọ́ tí a bá pèsè wọn sílẹ̀ tán;
|
||
\q2 igi firi ni a ó sì mì tìtì.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun yóò ya bo àwọn pópónà,
|
||
\q2 wọn yóò sì máa sáré síwá àti sẹ́yìn ní àárín ìgboro.
|
||
\q1 Wọn sì dàbí ètùfù iná;
|
||
\q2 tí ó sì kọ bí i mọ̀nàmọ́ná.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ninefe yóò ṣe àṣàrò àwọn ọlọ́lá rẹ̀;
|
||
\q2 síbẹ̀ wọ́n ń kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà wọn;
|
||
\q1 wọn sáré lọ sí ibi odi rẹ̀,
|
||
\q2 a ó sì pèsè ààbò rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 A ó ṣí ìlẹ̀kùn àwọn odò wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀,
|
||
\q2 a ó sì mú ààfin náà di wíwó palẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 A pa á láṣẹ pé ìlú náà, èyí tí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀
|
||
\q2 ni a ó sì kó ní ìgbèkùn lọ.
|
||
\q1 A ó sì mú un gòkè wá
|
||
\q2 àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ yóò kérora bí ti ẹyẹ àdàbà,
|
||
\q2 wọn a sì máa lu àyà wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ninefe dàbí adágún omi,
|
||
\q2 tí omi rẹ̀ sì ń gbẹ́ ẹ lọ.
|
||
\q1 “Dúró! Dúró!” ni wọ́n ó máa kígbe,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹnìkankan kì yóò wo ẹ̀yìn.
|
||
\q1
|
||
\v 9 “Ẹ kó ìkógun fàdákà!
|
||
\q2 Ẹ kó ìkógun wúrà!
|
||
\q1 Ìṣúra wọn ti kò lópin náà,
|
||
\q2 àti ọrọ̀ kúrò nínú gbogbo ohun èlò ti a fẹ́!”
|
||
\q1
|
||
\v 10 Òun ti ṣòfò, ó si di asán, ó sì di ahoro:
|
||
\q2 ọkàn pami, eékún ń lu ara wọn,
|
||
\q2 ìrora púpọ̀ sì wà nínú gbogbo ẹgbẹ́
|
||
\q2 àti ojú gbogbo wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Níbo ni ihò àwọn kìnnìún wà
|
||
\q2 àti ibi ìjẹun àwọn ọmọ kìnnìún,
|
||
\q1 níbi tí kìnnìún, àní abo kìnnìún tí ń rìn,
|
||
\q2 àti ọmọ kìnnìún, láìsí ohun ìbẹ̀rù.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Kìnnìún tipa ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀,
|
||
\q2 ó sì fún un ẹran ọdẹ ní ọrùn pa fún àwọn abo kìnnìún rẹ̀,
|
||
\q1 ó sì fi ohun pípa kún ibùgbé rẹ̀
|
||
\q2 àti ihò rẹ̀ fún ohun ọdẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 “Kíyèsi i èmi dojúkọ ọ́,”
|
||
\q2 ni \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun wí.
|
||
\q1 “Èmi yóò sì fi kẹ̀kẹ́ rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jóná nínú èéfín,
|
||
\q2 idà yóò sì jẹ ọmọ kìnnìún rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì run.
|
||
\q2 Èmi yóò sì ké ohun ọdẹ rẹ kúrò lórí ilẹ̀ ayé.
|
||
\q1 Ohùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ
|
||
\q2 ni a kì yóò sì tún gbọ́ mọ́.”
|
||
\c 3
|
||
\s1 A fi Ninefe bú
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ègbé ni fún ìlú ẹ̀jẹ̀ nì,
|
||
\q2 gbogbo rẹ̀ kún fún èké,
|
||
\q1 ó kún fún olè,
|
||
\q2 ìjẹ kò kúrò!
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ariwo pàṣán àti ariwo
|
||
\q2 kíkùn kẹ̀kẹ́ ogun
|
||
\q1 àti jíjó ẹṣin
|
||
\q2 àti gbígbọn kẹ̀kẹ́ ogun jìgìjìgì!
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ológun orí ẹṣin ń fi ìgbónára
|
||
\q2 ju idà wọn mọ̀nàmọ́ná
|
||
\q2 ọ̀kọ̀ rẹ̀ ti ń dán yanran sí òkè!
|
||
\q1 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ si ní àwọn ẹni tí a pa,
|
||
\q2 àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òkú;
|
||
\q1 òkú kò sì ni òpin;
|
||
\q2 àwọn ènìyàn sì ń kọsẹ̀ lára àwọn òkú.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ panṣágà
|
||
\q2 àgbèrè tí ó rójú rere gbà,
|
||
\q1 ìyá àjẹ́ tí ó ṣọ́ àwọn Orílẹ̀-èdè di ẹrú
|
||
\q2 nípa àgbèrè rẹ̀
|
||
\q2 àti àwọn ìdílé nípa ìṣe àjẹ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 “Èmi dojúkọ ọ́,” ni \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun wí.
|
||
\q2 “Èmi ó si ká aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ ní ojú rẹ.
|
||
\q1 Èmi yóò sì fi ìhòhò rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè
|
||
\q2 àti ìtìjú rẹ̀ han àwọn ilẹ̀ ọba.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmi yóò da ẹ̀gbin tí ó ni ìríra sí ọ ní ara,
|
||
\q2 èmi yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́,
|
||
\q2 èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹlẹ́yà.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Gbogbo àwọn tí ó ba sì wò ọ́ yóò sì káàánú fún ọ, wọn yóò sì wí pé,
|
||
\q2 ‘Ninefe ṣòfò, ta ni yóò kẹ́dùn rẹ?’
|
||
\q2 Níbo ni èmi o ti wá olùtùnú fún ọ?”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Tebesi lọ,
|
||
\q2 èyí tí ó wà ní ibi odò Naili,
|
||
\q2 tí omi sì yí káàkiri?
|
||
\q1 Odò náà sì jẹ́ ààbò rẹ̀,
|
||
\q2 omi si jẹ́ odi rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Etiopia àti Ejibiti ni agbára rẹ, kò sí ní òpin;
|
||
\q2 Puti àti Libia ni àwọn olùgbèjà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Síbẹ̀síbẹ̀ a kó o ní ìgbèkùn
|
||
\q2 o sì lọ sí oko ẹrú.
|
||
\q1 Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ̀ ni a ó fọ́ mọ́lẹ̀
|
||
\q2 ní orí ìta gbogbo ìgboro.
|
||
\q1 Wọ́n sì di ìbò nítorí àwọn ọlọ́lá rẹ̀ ọkùnrin,
|
||
\q2 gbogbo àwọn ọlọ́lá rẹ ni a sì fi ẹ̀wọ̀n dè.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìwọ pẹ̀lú yóò sì mu àmupara;
|
||
\q2 a ó sì fi ọ́ pamọ́
|
||
\q2 ìwọ pẹ̀lú yóò máa ṣe àfẹ́rí ààbò nítorí ti ọ̀tá náà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Gbogbo ilé ìṣọ́ agbára rẹ yóò dàbí igi ọ̀pọ̀tọ́
|
||
\q2 pẹ̀lú àkọ́pọ́n èso wọn;
|
||
\q1 nígbà tí wọ́n bá ń gbọ̀n wọ́n,
|
||
\q2 ọ̀pọ̀tọ́ yóò sì bọ́ sí ẹnu àwọn ọ̀jẹun.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Kíyèsi gbogbo àwọn jagunjagun!
|
||
\q2 Obìnrin ni gbogbo wọn.
|
||
\q1 Ojú ibodè rẹ ní a ó ṣí sílẹ̀ gbagada,
|
||
\q2 fún àwọn ọ̀tá rẹ;
|
||
\q2 iná yóò jó ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn ibodè rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Pọn omi nítorí ìhámọ́,
|
||
\q2 mú ilé ìṣọ́ rẹ lágbára sí i
|
||
\q1 wọ inú amọ̀
|
||
\q2 kí o sì tẹ erùpẹ̀,
|
||
\q2 kí ó sì tún ibi tí a ti ń sun bíríkì-amọ̀ ṣe kí ó le.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Níbẹ̀ ni iná yóò ti jó ọ́ run;
|
||
\q2 idà yóò sì ké ọ kúrò,
|
||
\q2 yóò sì jẹ ọ́ bí i kòkòrò,
|
||
\q1 yóò sì sọ ara rẹ̀ di púpọ̀ bí i tata,
|
||
\q2 àní, di púpọ̀ bí eṣú!
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ìwọ ti sọ àwọn oníṣòwò rẹ di púpọ̀
|
||
\q2 títí wọn yóò fi pọ̀ ju ìràwọ̀ ojú ọ̀run lọ,
|
||
\q1 ṣùgbọ́n bi eṣú ni wọn yóò sọ ilẹ̀ náà di ahoro, wọn yóò sì fò lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Àwọn aládé rẹ̀ dàbí eṣú,
|
||
\q2 àwọn ọ̀gágun rẹ dàbí ẹlẹ́ǹgà ńlá,
|
||
\q2 èyí tí ń dó sínú ọgbà ni ọjọ́ òtútù,
|
||
\q1 ṣùgbọ́n nígbà tí oòrùn jáde, wọ́n sálọ,
|
||
\q2 ẹnìkan kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé wà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ìwọ ọba Asiria,
|
||
\q2 àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ ń tòògbé;
|
||
\q1 àwọn ọlọ́lá rẹ dùbúlẹ̀ láti sinmi.
|
||
\q2 Àwọn ènìyàn rẹ fọ́nká lórí àwọn òkè ńlá,
|
||
\q2 tí ẹnikẹ́ni kò sì kó wọn jọ.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Kò sì sí ohun tí ó lè wo ọgbẹ́ ẹ̀ rẹ sàn;
|
||
\q2 ọgbẹ́ rẹ kún fún ìrora,
|
||
\q1 Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ ìròyìn rẹ
|
||
\q2 yóò pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí,
|
||
\q1 nítorí ta ni kò ní pín nínú
|
||
\q2 ìwà búburú rẹ ti kò ti lópin.
|