Biblica_yoOBYO17/33MICyoOBYO17.SFM

587 lines
25 KiB
Plaintext
Raw Permalink Blame History

This file contains ambiguous Unicode characters

This file contains Unicode characters that might be confused with other characters. If you think that this is intentional, you can safely ignore this warning. Use the Escape button to reveal them.

\id MIC - Biblica® Open Yoruba Contemporary Bible (Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
\rem Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.®
\h Mika
\toc1 Ìwé Wòlíì Mika
\toc2 Mika
\toc3 Mik
\mt1 Ìwé Wòlíì Mika
\c 1
\p
\v 1 Ọ̀rọ̀ \nd Olúwa\nd* tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
\b
\b
\q1
\v 2 Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,
\q2 fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,
\q1 kí \nd Olúwa\nd* Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,
\q2 \x - \xo 1.2: \xt 1Ọb 22.28.\x*Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
\s1 Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu
\q1
\v 3 Wò ó! \nd Olúwa\nd* ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;
\q2 yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
\q1
\v 4 Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,
\q2 àwọn àfonífojì yóò sì pínyà,
\q1 bí idà níwájú iná,
\q2 bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
\q1
\v 5 Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,
\q2 àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.
\q1 Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?
\q2 Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?
\q1 Kí ni àwọn ibi gíga Juda?
\q2 Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
\b
\q1
\v 6 “Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,
\q2 bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.
\q1 Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.
\q2 Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
\q1
\v 7 Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́
\q2 gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun,
\q2 Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.
\q1 Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,
\q2 gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
\s1 Ẹkún òun ọfọ̀
\q1
\v 8 Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,
\q2 èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:
\q1 èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò.
\q2 Èmi yóò ké bí akátá,
\q2 èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
\q1
\v 9 Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;
\q2 ó sì ti wá sí Juda.
\q1 Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,
\q2 àní sí Jerusalẹmu.
\q1
\v 10 Ẹ má ṣe sọ ní Gati
\q2 ẹ má ṣe sọkún rárá.
\q1 Ní ilẹ̀ Beti-Ofra
\q2 mo yí ara mi nínú eruku.
\q1
\v 11 Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,
\q2 ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.
\q1 Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani
\q2 kì yóò sì jáde wá.
\q1 Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;
\q2 a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
\q1
\v 12 Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,
\q2 ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd* wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
\q1
\v 13 Ìwọ olùgbé Lakiṣi,
\q2 dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.
\q1 Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀
\q2 sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,
\q2 nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
\q1
\v 14 Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀
\q2 fún Moreṣeti Gati.
\q1 Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
\q1
\v 15 Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.
\q2 Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli
\q2 yóò sì wá sí Adullamu.
\q1
\v 16 Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀
\q2 nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,
\q1 sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,
\q2 nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.
\c 2
\s1 Èrò ènìyàn àti ti Ọlọ́run
\q1
\v 1 Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé
\q2 tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn!
\q1 Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde
\q2 nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
\q1
\v 2 Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n,
\q2 àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n.
\q1 Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára
\q2 àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
\p
\v 3 Nítorí náà, \nd Olúwa\nd* wí pé:
\q1 “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí,
\q2 nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là.
\q1 Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́,
\q2 nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
\q1
\v 4 Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín;
\q2 wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé:
\q1 Ní kíkó a ti kó wọn tán;
\q2 \nd Olúwa\nd* ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi;
\q1 Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi!
\q2 Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’ ”
\b
\q1
\v 5 Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ \nd Olúwa\nd*,
\q2 tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
\s1 Àwọn wòlíì èké
\q1
\v 6 “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí.
\q2 “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí;
\q2 kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
\q1
\v 7 Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu:
\q2 “Ǹjẹ́ ẹ̀mí \nd Olúwa\nd* ha ń bínú bí?
\q2 Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?”
\b
\q1 “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere
\q2 fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
\q1
\v 8 Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde
\q2 bí ọ̀tá sí mi.
\q1 Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀
\q2 kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu,
\q2 bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
\q1
\v 9 Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi
\q2 kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn,
\q1 ẹ̀yin sì ti gba ògo mi,
\q2 kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
\q1
\v 10 Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ!
\q2 Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín,
\q1 nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́
\q2 yóò pa yín run,
\q2 àní ìparun kíkorò.
\q1
\v 11 Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé,
\q2 Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,
\q2 òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
\s1 Ìlérí ìgbàlà
\q1
\v 12 “Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu;
\q2 Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ.
\q1 Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran,
\q2 gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn,
\q2 ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
\q1
\v 13 Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn;
\q2 wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ.
\q1 Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn,
\q2 \nd Olúwa\nd* ni yóò sì ṣe olórí wọn.”
\c 3
\s1 Bíbá àwọn olórí àti àwọn wòlíì wí
\p
\v 1 Nígbà náà, ni mo wí pé,
\q1 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu,
\q2 ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli.
\q1 Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
\q2
\v 2 Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi;
\q1 ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn
\q2 àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
\q1
\v 3 àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi,
\q2 wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn.
\q2 Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́;
\q1 wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò,
\q2 bí ẹran inú agbada?”
\b
\q1
\v 4 Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí \nd Olúwa\nd*,
\q2 ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn.
\q1 Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn,
\q2 nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.
\p
\v 5 Báyìí ni \nd Olúwa\nd* wí,
\q1 “Ní ti àwọn Wòlíì
\q2 tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà,
\q1 tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ,
\q2 wọn yóò kéde àlàáfíà;
\q1 ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu,
\q2 wọn yóò múra ogun sí i.
\q1
\v 6 Nítorí náà òru yóò wá sórí yín,
\q2 tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan,
\q1 òkùnkùn yóò sì kùn fún yín,
\q2 tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀.
\q1 Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì
\q2 ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
\q1
\v 7 Ojú yóò sì ti àwọn wòlíì
\q2 àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú.
\q1 Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn,
\q2 nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
\q1
\v 8 Ṣùgbọ́n ní tèmi,
\q2 èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí \nd Olúwa\nd*,
\q2 láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un,
\q2 àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.
\b
\q1
\v 9 Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu,
\q2 àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli,
\q1 tí ó kórìíra òdodo
\q2 tí ó sì yí òtítọ́ padà;
\q1
\v 10 tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀,
\q2 àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
\q1
\v 11 Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀,
\q2 àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà
\q2 àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó.
\q1 Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*, wọ́n sì wí pé,
\q2 “Nítòótọ́, \nd Olúwa\nd* wà pẹ̀lú wa!
\q2 Ibi kan kì yóò bá wa.”
\q1
\v 12 Nítorí náà, nítorí tiyín,
\q2 ni a ó ṣe ro Sioni bí oko,
\q1 Jerusalẹmu yóò sì di ebè
\q2 àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.
\c 4
\s1 Òkè \nd Olúwa\nd*
\p
\v 1 \x - \xo 4.1-3: \xt Isa 2.2-4.\x*Ní ọjọ́ ìkẹyìn
\q1 a ó fi òkè ilé \nd Olúwa\nd* lélẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá,
\q2 a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ,
\q2 àwọn ènìyàn yóò sì máa wọ̀ sínú rẹ̀.
\p
\v 2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò wá,
\q1 wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá \nd Olúwa\nd*,
\q2 àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu.
\q1 Òun yóò sì kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀,
\q2 kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.”
\q1 Òfin yóò jáde láti Sioni wá,
\q2 àti ọ̀rọ̀ \nd Olúwa\nd* láti Jerusalẹmu.
\q1
\v 3 Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn,
\q2 yóò sì parí aáwọ̀ fún orílẹ̀-èdè alágbára jíjìn réré.
\q1 Wọn yóò sì fi idà wọn rọ ohun èlò ìtulẹ̀
\q2 àti ọ̀kọ̀ wọn di dòjé
\q1 orílẹ̀-èdè kì yóò gbé idà sókè sí orílẹ̀-èdè mọ́,
\q2 bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
\q1
\v 4 \x - \xo 4.4: \xt Sk 3.10.\x*Ṣùgbọ́n olúkúlùkù yóò jókòó lábẹ́ àjàrà rẹ̀
\q2 àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀,
\q1 ẹnìkan kì yóò sì dẹ́rùbà wọ́n,
\q2 nítorí \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun ti sọ̀rọ̀.
\q1
\v 5 Gbogbo àwọn ènìyàn ń rìn,
\q2 olúkúlùkù ni orúkọ ọlọ́run tirẹ̀,
\q1 ṣùgbọ́n àwa yóò máa rìn ní orúkọ \nd Olúwa\nd*.
\q2 Ọlọ́run wa láé àti láéláé.
\s1 Èrò \nd Olúwa\nd*
\p
\v 6 “Ní ọjọ́ náà,” ni \nd Olúwa\nd* wí,
\q1 “Èmi yóò kó àwọn arọ jọ;
\q2 èmi yóò sì ṣà àwọn tí a lé kúrò ní ìlú jọ,
\q2 àti àwọn ẹni tí èmi ti pọ́n lójú.
\q1
\v 7 Èmi yóò dá àwọn arọ sí fún èyí tókù,
\q2 èmi yóò sì sọ àwọn tí a lé kúrò ní ìlú di orílẹ̀-èdè alágbára.
\q1 \nd Olúwa\nd* yóò sì jẹ ọba lórí wọn ní òkè ńlá Sioni
\q2 láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
\q1
\v 8 Ní ti ìwọ, ilé ìṣọ́ agbo àgùntàn,
\q2 odi alágbára ọmọbìnrin Sioni,
\q1 a ó mú ìjọba ìṣáájú padà bọ̀ sípò fún un yín;
\q2 ìjọba yóò sì wà sí ọ̀dọ̀ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”
\b
\q1
\v 9 Kí ni ìwọ ha ń kígbe sókè sí nísinsin yìí?
\q2 Ǹjẹ́ ìwọ kò ní ọba bí?
\q1 Àwọn ìgbìmọ̀ rẹ ṣègbé bí?
\q2 Nítorí ìrora ti dì ọ́ mú bí obìnrin tí ń rọbí.
\q1
\v 10 Máa yí síyìn-ín sọ́hùn-ún nínú ìrora,
\q2 ìwọ obìnrin Sioni,
\q1 bí ẹni tí ń rọbí,
\q2 nítorí nísinsin yìí ìwọ yóò jáde lọ kúrò ní ìlú,
\q1 ìwọ yóò sì máa gbé inú igbó.
\q2 Ìwọ yóò lọ sí Babeli;
\q1 níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì ti rí ìgbàlà.
\q2 Níbẹ̀ ni \nd Olúwa\nd* yóò ti rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ.
\b
\q1
\v 11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ọ̀pọ̀lọpọ̀ Orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ sí ọ.
\q2 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ ọ́ di àìmọ́,
\q2 ẹ jẹ́ kí ojú wa kí ó wo Sioni!”
\q1
\v 12 Ṣùgbọ́n wọn kò mọ
\q2 èrò inú \nd Olúwa\nd*;
\q1 bẹ́ẹ̀ ni òye ìmọ̀ rẹ̀ kò yé wọn,
\q2 nítorí ó ti kó wọn jọ bí i ìtí sínú ìpakà.
\q1
\v 13 “Dìde, kí ó sì máa pa ọkà ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
\q2 nítorí èmi yóò sọ ìwo rẹ̀ di irin,
\q1 èmi yóò sì sọ pátákò rẹ̀ di idẹ
\q2 ìwọ yóò run ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pátápátá.”
\q1 Èmi yóò sì ya èrè wọn sọ́tọ̀ fún \nd Olúwa\nd*
\q2 àti ọrọ̀ wọn sí Olúwa gbogbo ayé.
\c 5
\s1 Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Olùgbàlà láti Bẹtilẹhẹmu
\q1
\v 1 Nísinsin yìí, kó àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ jọ,
\q2 ìwọ ìlú ti o ni ọmọ-ogun,
\q1 nítorí ó ti fi gbógun dó tì wá.
\q2 Wọn yóò fi ọ̀pá lu àwọn alákòóso Israẹli ní ẹ̀rẹ̀kẹ́.
\b
\q1
\v 2 “Ṣùgbọ́n ìwọ, Bẹtilẹhẹmu Efrata,
\q2 bí ìwọ ti jẹ́ kékeré láàrín àwọn ẹ̀yà Juda,
\q1 nínú rẹ ni ẹni tí yóò jẹ́ olórí ní Israẹli
\q2 yóò ti jáde tọ̀ mí wá,
\q1 ìjáde lọ rẹ̀ sì jẹ́ láti ìgbà àtijọ́,
\q2 láti ìgbà láéláé.”
\b
\q1
\v 3 Nítorí náà Israẹli yóò di kíkọ̀sílẹ̀ pátápátá
\q2 títí di àkókò tí ẹni tí ń rọbí yóò fi bí,
\q1 àti àwọn ìyókù arákùnrin rẹ̀ yóò fi padà
\q2 láti darapọ̀ mọ́ àwọn Israẹli.
\b
\q1
\v 4 Òun yóò sì dúró,
\q2 yóò sì máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn àwọn agbo ẹran rẹ̀ ní agbára \nd Olúwa\nd*,
\q2 ní ọláńlá orúkọ \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run rẹ̀.
\q1 Wọn yóò sì wà láìléwu,
\q2 nítorí nísinsin yìí ni títóbi rẹ
\q2 yóò sì dé òpin ayé.
\s1 Ìgbàlà àti ìparun
\q1
\v 5 Òun yóò sì jẹ́ àlàáfíà wọn.
\q2 Nígbà tí àwọn Asiria bá gbógun sí ilẹ̀ wa
\q2 tí wọ́n sì ń yan lórí odi alágbára wa,
\q1 nígbà náà ni a ó gbé olùṣọ́-àgùntàn méje dìde sí i,
\q2 àti olórí ènìyàn mẹ́jọ.
\q1
\v 6 Wọn yóò sì fi idà pa ilẹ̀ Asiria run,
\q2 àti ilẹ̀ Nimrodu pẹ̀lú idà tí a fà.
\q1 Òun yóò sì gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Asiria
\q2 nígbà tí wọn bá gbógun ti ilẹ̀ wa
\q2 tí wọ́n sì tún yan wọ ẹnu-bodè wa.
\b
\q1
\v 7 Ìyókù Jakọbu yóò sì wà
\q2 láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn
\q1 bí ìrì láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd* wa,
\q2 bí ọ̀wààrà òjò lórí koríko,
\q1 tí kò gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn
\q2 tàbí kò dúró de àwọn ọmọ ènìyàn.
\q1
\v 8 Ìyókù Jakọbu yóò sì wà láàrín àwọn aláìkọlà
\q2 ní àárín àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn,
\q1 bí i kìnnìún láàrín àwọn ẹranko inú igbó,
\q2 bí i ọmọ kìnnìún láàrín agbo àgùntàn,
\q1 èyí tí ó máa ń fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,
\q2 tí ó sì máa ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀,
\q2 tí kò sì ṣí ẹnìkan tí ó lè gbà á là.
\q1
\v 9 A ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀,
\q2 gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sì ni a ó parun.
\p
\v 10 “Ní ọjọ́ náà,” ni \nd Olúwa\nd* wí,
\q1 “Èmi yóò pa àwọn ẹṣin rẹ̀ run kúrò láàrín rẹ
\q2 èmi yóò sì pa àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ run.
\q1
\v 11 Èmi yóò sì pa ilẹ̀ ìlú ńlá rẹ̀ run,
\q2 èmi ó sì fa gbogbo ibi gíga rẹ̀ ya.
\q1
\v 12 Èmi yóò gé ìwà àjẹ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀,
\q2 ìwọ kì yóò sì ní aláfọ̀ṣẹ mọ́.
\q1
\v 13 Èmi yóò pa àwọn ère fínfín rẹ̀ run,
\q2 àti ọwọ̀n rẹ̀ kúrò láàrín rẹ̀;
\q1 ìwọ kì yóò sì le è foríbalẹ̀
\q2 fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ mọ́.
\q1
\v 14 Èmi yóò fa ère Aṣerah tu kúrò láàrín rẹ̀,
\q2 èmi yóò sì pa ìlú ńlá rẹ̀ run.
\q1
\v 15 Èmi yóò gbẹ̀san ní ìbínú àti ìrunú
\q2 lórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò ti tẹríba fún mi.”
\c 6
\s1 Ọlọ́run pe Israẹli níjà
\p
\v 1 Ẹ fi etí sí ohun tí \nd Olúwa\nd* wí:
\q1 “Dìde dúró, bẹ ẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ rẹ níwájú òkè ńlá;
\q2 sì jẹ́ kí àwọn òkè kéékèèké gbọ́ ohun tí ó fẹ́ wí.
\b
\q1
\v 2 “Gbọ́, ìwọ òkè ńlá, ẹ̀sùn \nd Olúwa\nd*;
\q2 gbọ́, ìwọ ìpìlẹ̀ ilé ayérayé.
\q1 Nítorí \nd Olúwa\nd* ń bá àwọn ènìyàn rẹ̀ wíjọ́;
\q2 òun yóò sì bá Israẹli rojọ́.
\b
\q1
\v 3 “Ẹ̀yin ènìyàn mi, kí ni mo ṣe fún yín?
\q2 Àti nínú kí ni mo ti dá yin lágara? Dá mi lóhùn.
\q1
\v 4 Nítorí èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,
\q2 mo sì rà yín padà láti ilẹ̀ ẹrú wá.
\q1 Mo rán Mose láti darí yín,
\q2 bákan náà mo rán Aaroni àti Miriamu síwájú rẹ̀.
\q1
\v 5 Ìwọ ènìyàn mi,
\q2 rántí ohun tí Balaki ọba Moabu gbèrò
\q2 àti ohun tí Balaamu ọmọ Beori dáhùn.
\q1 Rántí ìrìnàjò rẹ̀ láti Ṣittimu dé Gilgali,
\q2 kí ìwọ ba le mọ òdodo \nd Olúwa\nd*.”
\b
\q1
\v 6 Kí ni èmi yóò ha mú wá síwájú \nd Olúwa\nd*
\q2 tí èmi ó fi tẹ ara mi ba níwájú Ọlọ́run gíga?
\q1 Kí èmi ha wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun,
\q2 pẹ̀lú ọmọ màlúù ọlọ́dún kan?
\q1
\v 7 Ǹjẹ́ \nd Olúwa\nd* yóò ní inú dídùn sí ẹgbẹgbàarùn-ún àgbò,
\q2 tàbí sí ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìṣàn òróró?
\q1 Èmi yóò ha fi àkọ́bí mi sílẹ̀ fún ìré-òfin-kọjá mi,
\q2 èso inú ara mi fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkàn mi?
\q1
\v 8 Ó ti fihàn ọ́, ìwọ ènìyàn, ohun tí ó dára,
\q2 àti ohun tí \nd Olúwa\nd* ń béèrè lọ́wọ́ rẹ?
\q1 Bí kò ṣe láti ṣe òtítọ́, kí o sì fẹ́ràn àánú,
\q2 àti kí o rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
\s1 Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli àti ìjìyà wọn
\q1
\v 9 Gbọ́! Ohùn \nd Olúwa\nd* kígbe sí ìlú ńlá náà,
\q2 láti jẹ ọlọ́gbọ́n ni láti bẹ̀rù orúkọ rẹ.
\q2 “Ẹ kíyèsi ọ̀pá rẹ̀ gbọ́ ọ̀pá àti Ẹni náà tí ó yàn án.
\q1
\v 10 Ǹjẹ́ ìṣúra ìwà búburú ha wà
\q2 ní ilé ènìyàn búburú síbẹ̀,
\q2 àti òsùwọ̀n àìkún tí ó jẹ́ ohun ìbínú?
\q1
\v 11 Ǹjẹ́ èmi ha lè kà wọ́n sí mímọ́
\q2 pẹ̀lú òsùwọ̀n búburú,
\q2 pẹ̀lú àpò òsùwọ̀n ẹ̀tàn?
\q1
\v 12 Àwọn ọlọ́rọ̀ inú rẹ̀ kún fún ìwà ipá;
\q2 àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ ti ọ̀rọ̀ èké
\q2 àti ahọ́n wọn ń sọ ẹ̀tàn?
\q1
\v 13 Nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ ṣàìsàn ní lílù ọ́,
\q2 láti sọ ọ́ dahoro nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
\q1
\v 14 Ìwọ yóò jẹun ṣùgbọ́n kì yóò yó;
\q2 ìyàn yóò wà láàrín rẹ.
\q1 Ìwọ yóò kó pamọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò lò láìléwu,
\q2 nítorí ohun tí ìwọ kò pamọ́ ni èmi yóò fi fún idà.
\q1
\v 15 Ìwọ yóò gbìn ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò kórè
\q2 ìwọ yóò tẹ olifi,
\q1 ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò fi òróró rẹ̀ kún ara rẹ;
\q2 ìwọ yóò tẹ èso àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò mu wáìnì.
\q1
\v 16 Nítorí tí ìwọ ti pa òfin Omri mọ́,
\q2 àti gbogbo iṣẹ́ ilé Ahabu,
\q2 tí ó sì ti tẹ̀lé ìmọ̀ràn wọn,
\q1 nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ fún ìparun
\q2 àti àwọn ènìyàn rẹ fún ìfiṣe ẹlẹ́yà;
\q2 ìwọ yóò sì ru ẹ̀gàn àwọn ènìyàn mi.”
\c 7
\s1 Ìrora Israẹli
\q1
\v 1 Ègbé ni fún mi!
\q1 Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ,
\q2 ìpèsè ọgbà àjàrà;
\q1 kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ,
\q2 kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
\q1
\v 2 Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà,
\q2 kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́;
\q1 gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀,
\q2 olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
\q1
\v 3 Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú;
\q2 àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn,
\q1 àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀
\q2 alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́,
\q2 gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
\q1
\v 4 Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún,
\q2 ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ.
\q1 Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé,
\q2 àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò.
\q2 Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
\q1
\v 5 Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́;
\q2 ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan.
\q1 Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni
\q2 tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
\q1
\v 6 \x - \xo 7.6: \xt Mt 10.21,35,36; Mk 13.12; Lk 12.53.\x*Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀,
\q2 ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀,
\q1 aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀,
\q2 ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.
\b
\q1
\v 7 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí \nd Olúwa\nd*,
\q2 èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi;
\q2 Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.
\s1 Israẹli yóò dìde
\q1
\v 8 Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi.
\q2 Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde.
\q1 Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn
\q2 \nd Olúwa\nd* yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
\q1
\v 9 Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i,
\q2 èmi yóò faradà ìbínú \nd Olúwa\nd*,
\q1 títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò,
\q2 tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi.
\q1 Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀;
\q2 èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
\q1
\v 10 Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i
\q2 ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé,
\q1 “Níbo ni \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run rẹ wà?”
\q2 Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀;
\q1 nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀
\q2 bí ẹrẹ̀ òpópó.
\b
\q1
\v 11 Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé,
\q2 ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
\q1
\v 12 Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ
\q2 láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti
\q1 àní láti Ejibiti dé Eufurate
\q2 láti Òkun dé Òkun
\q2 àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
\q1
\v 13 Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀,
\q2 nítorí èso ìwà wọn.
\s1 Àdúrà àti ìyìn
\q1
\v 14 Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ,
\q2 èyí tí ó ń dágbé nínú igbó
\q1 ní àárín Karmeli.
\q2 Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi
\q2 bí ọjọ́ ìgbàanì.
\b
\q1
\v 15 “Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá,
\q2 ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”
\b
\q1
\v 16 Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n,
\q2 nínú gbogbo agbára wọn.
\q1 Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn,
\q2 etí wọn yóò sì di.
\q1
\v 17 Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò,
\q2 wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló.
\q1 Wọn yóò bẹ̀rù \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa,
\q2 wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
\q1
\v 18 Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀,
\q2 ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì,
\q2 tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀?
\q1 Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé
\q2 nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
\q1
\v 19 Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa;
\q2 òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀,
\q2 yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
\q1
\v 20 \x - \xo 7.20: \xt Lk 1.55.\x*Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu
\q2 ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu,
\q1 bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa
\q2 láti ọjọ́ ìgbàanì.