587 lines
25 KiB
Plaintext
587 lines
25 KiB
Plaintext
\id MIC - Biblica® Open Yoruba Contemporary Bible (Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
|
||
\rem Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.®
|
||
\h Mika
|
||
\toc1 Ìwé Wòlíì Mika
|
||
\toc2 Mika
|
||
\toc3 Mik
|
||
\mt1 Ìwé Wòlíì Mika
|
||
\c 1
|
||
\p
|
||
\v 1 Ọ̀rọ̀ \nd Olúwa\nd* tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
|
||
\b
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,
|
||
\q2 fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,
|
||
\q1 kí \nd Olúwa\nd* Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,
|
||
\q2 \x - \xo 1.2: \xt 1Ọb 22.28.\x*Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
|
||
\s1 Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu
|
||
\q1
|
||
\v 3 Wò ó! \nd Olúwa\nd* ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;
|
||
\q2 yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,
|
||
\q2 àwọn àfonífojì yóò sì pínyà,
|
||
\q1 bí idà níwájú iná,
|
||
\q2 bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,
|
||
\q2 àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.
|
||
\q1 Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?
|
||
\q2 Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?
|
||
\q1 Kí ni àwọn ibi gíga Juda?
|
||
\q2 Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 “Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,
|
||
\q2 bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.
|
||
\q1 Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.
|
||
\q2 Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́
|
||
\q2 gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun,
|
||
\q2 Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.
|
||
\q1 Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
|
||
\s1 Ẹkún òun ọfọ̀
|
||
\q1
|
||
\v 8 Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,
|
||
\q2 èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:
|
||
\q1 èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò.
|
||
\q2 Èmi yóò ké bí akátá,
|
||
\q2 èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;
|
||
\q2 ó sì ti wá sí Juda.
|
||
\q1 Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,
|
||
\q2 àní sí Jerusalẹmu.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ẹ má ṣe sọ ní Gati
|
||
\q2 ẹ má ṣe sọkún rárá.
|
||
\q1 Ní ilẹ̀ Beti-Ofra
|
||
\q2 mo yí ara mi nínú eruku.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,
|
||
\q2 ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.
|
||
\q1 Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani
|
||
\q2 kì yóò sì jáde wá.
|
||
\q1 Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;
|
||
\q2 a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd* wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìwọ olùgbé Lakiṣi,
|
||
\q2 dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.
|
||
\q1 Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀
|
||
\q2 sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,
|
||
\q2 nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀
|
||
\q2 fún Moreṣeti Gati.
|
||
\q1 Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.
|
||
\q2 Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli
|
||
\q2 yóò sì wá sí Adullamu.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀
|
||
\q2 nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,
|
||
\q1 sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,
|
||
\q2 nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.
|
||
\c 2
|
||
\s1 Èrò ènìyàn àti ti Ọlọ́run
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé
|
||
\q2 tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn!
|
||
\q1 Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde
|
||
\q2 nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n,
|
||
\q2 àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n.
|
||
\q1 Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára
|
||
\q2 àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
|
||
\p
|
||
\v 3 Nítorí náà, \nd Olúwa\nd* wí pé:
|
||
\q1 “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí,
|
||
\q2 nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là.
|
||
\q1 Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́,
|
||
\q2 nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín;
|
||
\q2 wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé:
|
||
\q1 ‘Ní kíkó a ti kó wọn tán;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi;
|
||
\q1 Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi!
|
||
\q2 Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’ ”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
|
||
\s1 Àwọn wòlíì èké
|
||
\q1
|
||
\v 6 “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí.
|
||
\q2 “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí;
|
||
\q2 kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu:
|
||
\q2 “Ǹjẹ́ ẹ̀mí \nd Olúwa\nd* ha ń bínú bí?
|
||
\q2 Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?”
|
||
\b
|
||
\q1 “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere
|
||
\q2 fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
|
||
\q1
|
||
\v 8 Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde
|
||
\q2 bí ọ̀tá sí mi.
|
||
\q1 Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀
|
||
\q2 kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu,
|
||
\q2 bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi
|
||
\q2 kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn,
|
||
\q1 ẹ̀yin sì ti gba ògo mi,
|
||
\q2 kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ!
|
||
\q2 Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín,
|
||
\q1 nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́
|
||
\q2 yóò pa yín run,
|
||
\q2 àní ìparun kíkorò.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé,
|
||
\q2 ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’
|
||
\q2 òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
|
||
\s1 Ìlérí ìgbàlà
|
||
\q1
|
||
\v 12 “Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu;
|
||
\q2 Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ.
|
||
\q1 Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran,
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn,
|
||
\q2 ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn;
|
||
\q2 wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ.
|
||
\q1 Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ni yóò sì ṣe olórí wọn.”
|
||
\c 3
|
||
\s1 Bíbá àwọn olórí àti àwọn wòlíì wí
|
||
\p
|
||
\v 1 Nígbà náà, ni mo wí pé,
|
||
\q1 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu,
|
||
\q2 ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli.
|
||
\q1 Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
|
||
\q2
|
||
\v 2 Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi;
|
||
\q1 ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn
|
||
\q2 àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
|
||
\q1
|
||
\v 3 àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi,
|
||
\q2 wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn.
|
||
\q2 Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́;
|
||
\q1 wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò,
|
||
\q2 bí ẹran inú agbada?”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn.
|
||
\q1 Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn,
|
||
\q2 nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.
|
||
\p
|
||
\v 5 Báyìí ni \nd Olúwa\nd* wí,
|
||
\q1 “Ní ti àwọn Wòlíì
|
||
\q2 tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà,
|
||
\q1 tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ,
|
||
\q2 wọn yóò kéde àlàáfíà;
|
||
\q1 ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu,
|
||
\q2 wọn yóò múra ogun sí i.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nítorí náà òru yóò wá sórí yín,
|
||
\q2 tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan,
|
||
\q1 òkùnkùn yóò sì kùn fún yín,
|
||
\q2 tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀.
|
||
\q1 Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì
|
||
\q2 ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ojú yóò sì ti àwọn wòlíì
|
||
\q2 àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú.
|
||
\q1 Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn,
|
||
\q2 nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ṣùgbọ́n ní tèmi,
|
||
\q2 èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un,
|
||
\q2 àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu,
|
||
\q2 àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli,
|
||
\q1 tí ó kórìíra òdodo
|
||
\q2 tí ó sì yí òtítọ́ padà;
|
||
\q1
|
||
\v 10 tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀,
|
||
\q2 àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀,
|
||
\q2 àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà
|
||
\q2 àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó.
|
||
\q1 Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*, wọ́n sì wí pé,
|
||
\q2 “Nítòótọ́, \nd Olúwa\nd* wà pẹ̀lú wa!
|
||
\q2 Ibi kan kì yóò bá wa.”
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nítorí náà, nítorí tiyín,
|
||
\q2 ni a ó ṣe ro Sioni bí oko,
|
||
\q1 Jerusalẹmu yóò sì di ebè
|
||
\q2 àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.
|
||
\c 4
|
||
\s1 Òkè \nd Olúwa\nd*
|
||
\p
|
||
\v 1 \x - \xo 4.1-3: \xt Isa 2.2-4.\x*Ní ọjọ́ ìkẹyìn
|
||
\q1 a ó fi òkè ilé \nd Olúwa\nd* lélẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá,
|
||
\q2 a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ,
|
||
\q2 àwọn ènìyàn yóò sì máa wọ̀ sínú rẹ̀.
|
||
\p
|
||
\v 2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò wá,
|
||
\q1 wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu.
|
||
\q1 Òun yóò sì kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀,
|
||
\q2 kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.”
|
||
\q1 Òfin yóò jáde láti Sioni wá,
|
||
\q2 àti ọ̀rọ̀ \nd Olúwa\nd* láti Jerusalẹmu.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn,
|
||
\q2 yóò sì parí aáwọ̀ fún orílẹ̀-èdè alágbára jíjìn réré.
|
||
\q1 Wọn yóò sì fi idà wọn rọ ohun èlò ìtulẹ̀
|
||
\q2 àti ọ̀kọ̀ wọn di dòjé
|
||
\q1 orílẹ̀-èdè kì yóò gbé idà sókè sí orílẹ̀-èdè mọ́,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 4.4: \xt Sk 3.10.\x*Ṣùgbọ́n olúkúlùkù yóò jókòó lábẹ́ àjàrà rẹ̀
|
||
\q2 àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀,
|
||
\q1 ẹnìkan kì yóò sì dẹ́rùbà wọ́n,
|
||
\q2 nítorí \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun ti sọ̀rọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Gbogbo àwọn ènìyàn ń rìn,
|
||
\q2 olúkúlùkù ni orúkọ ọlọ́run tirẹ̀,
|
||
\q1 ṣùgbọ́n àwa yóò máa rìn ní orúkọ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q2 Ọlọ́run wa láé àti láéláé.
|
||
\s1 Èrò \nd Olúwa\nd*
|
||
\p
|
||
\v 6 “Ní ọjọ́ náà,” ni \nd Olúwa\nd* wí,
|
||
\q1 “Èmi yóò kó àwọn arọ jọ;
|
||
\q2 èmi yóò sì ṣà àwọn tí a lé kúrò ní ìlú jọ,
|
||
\q2 àti àwọn ẹni tí èmi ti pọ́n lójú.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Èmi yóò dá àwọn arọ sí fún èyí tókù,
|
||
\q2 èmi yóò sì sọ àwọn tí a lé kúrò ní ìlú di orílẹ̀-èdè alágbára.
|
||
\q1 \nd Olúwa\nd* yóò sì jẹ ọba lórí wọn ní òkè ńlá Sioni
|
||
\q2 láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ní ti ìwọ, ilé ìṣọ́ agbo àgùntàn,
|
||
\q2 odi alágbára ọmọbìnrin Sioni,
|
||
\q1 a ó mú ìjọba ìṣáájú padà bọ̀ sípò fún un yín;
|
||
\q2 ìjọba yóò sì wà sí ọ̀dọ̀ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Kí ni ìwọ ha ń kígbe sókè sí nísinsin yìí?
|
||
\q2 Ǹjẹ́ ìwọ kò ní ọba bí?
|
||
\q1 Àwọn ìgbìmọ̀ rẹ ṣègbé bí?
|
||
\q2 Nítorí ìrora ti dì ọ́ mú bí obìnrin tí ń rọbí.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Máa yí síyìn-ín sọ́hùn-ún nínú ìrora,
|
||
\q2 ìwọ obìnrin Sioni,
|
||
\q1 bí ẹni tí ń rọbí,
|
||
\q2 nítorí nísinsin yìí ìwọ yóò jáde lọ kúrò ní ìlú,
|
||
\q1 ìwọ yóò sì máa gbé inú igbó.
|
||
\q2 Ìwọ yóò lọ sí Babeli;
|
||
\q1 níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì ti rí ìgbàlà.
|
||
\q2 Níbẹ̀ ni \nd Olúwa\nd* yóò ti rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ọ̀pọ̀lọpọ̀ Orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ sí ọ.
|
||
\q2 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ ọ́ di àìmọ́,
|
||
\q2 ẹ jẹ́ kí ojú wa kí ó wo Sioni!”
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ṣùgbọ́n wọn kò mọ
|
||
\q2 èrò inú \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q1 bẹ́ẹ̀ ni òye ìmọ̀ rẹ̀ kò yé wọn,
|
||
\q2 nítorí ó ti kó wọn jọ bí i ìtí sínú ìpakà.
|
||
\q1
|
||
\v 13 “Dìde, kí ó sì máa pa ọkà ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
|
||
\q2 nítorí èmi yóò sọ ìwo rẹ̀ di irin,
|
||
\q1 èmi yóò sì sọ pátákò rẹ̀ di idẹ
|
||
\q2 ìwọ yóò run ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pátápátá.”
|
||
\q1 Èmi yóò sì ya èrè wọn sọ́tọ̀ fún \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 àti ọrọ̀ wọn sí Olúwa gbogbo ayé.
|
||
\c 5
|
||
\s1 Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Olùgbàlà láti Bẹtilẹhẹmu
|
||
\q1
|
||
\v 1 Nísinsin yìí, kó àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ jọ,
|
||
\q2 ìwọ ìlú ti o ni ọmọ-ogun,
|
||
\q1 nítorí ó ti fi gbógun dó tì wá.
|
||
\q2 Wọn yóò fi ọ̀pá lu àwọn alákòóso Israẹli ní ẹ̀rẹ̀kẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 “Ṣùgbọ́n ìwọ, Bẹtilẹhẹmu Efrata,
|
||
\q2 bí ìwọ ti jẹ́ kékeré láàrín àwọn ẹ̀yà Juda,
|
||
\q1 nínú rẹ ni ẹni tí yóò jẹ́ olórí ní Israẹli
|
||
\q2 yóò ti jáde tọ̀ mí wá,
|
||
\q1 ìjáde lọ rẹ̀ sì jẹ́ láti ìgbà àtijọ́,
|
||
\q2 láti ìgbà láéláé.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí náà Israẹli yóò di kíkọ̀sílẹ̀ pátápátá
|
||
\q2 títí di àkókò tí ẹni tí ń rọbí yóò fi bí,
|
||
\q1 àti àwọn ìyókù arákùnrin rẹ̀ yóò fi padà
|
||
\q2 láti darapọ̀ mọ́ àwọn Israẹli.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Òun yóò sì dúró,
|
||
\q2 yóò sì máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn àwọn agbo ẹran rẹ̀ ní agbára \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ní ọláńlá orúkọ \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run rẹ̀.
|
||
\q1 Wọn yóò sì wà láìléwu,
|
||
\q2 nítorí nísinsin yìí ni títóbi rẹ
|
||
\q2 yóò sì dé òpin ayé.
|
||
\s1 Ìgbàlà àti ìparun
|
||
\q1
|
||
\v 5 Òun yóò sì jẹ́ àlàáfíà wọn.
|
||
\q2 Nígbà tí àwọn Asiria bá gbógun sí ilẹ̀ wa
|
||
\q2 tí wọ́n sì ń yan lórí odi alágbára wa,
|
||
\q1 nígbà náà ni a ó gbé olùṣọ́-àgùntàn méje dìde sí i,
|
||
\q2 àti olórí ènìyàn mẹ́jọ.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Wọn yóò sì fi idà pa ilẹ̀ Asiria run,
|
||
\q2 àti ilẹ̀ Nimrodu pẹ̀lú idà tí a fà.
|
||
\q1 Òun yóò sì gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Asiria
|
||
\q2 nígbà tí wọn bá gbógun ti ilẹ̀ wa
|
||
\q2 tí wọ́n sì tún yan wọ ẹnu-bodè wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìyókù Jakọbu yóò sì wà
|
||
\q2 láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn
|
||
\q1 bí ìrì láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd* wa,
|
||
\q2 bí ọ̀wààrà òjò lórí koríko,
|
||
\q1 tí kò gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn
|
||
\q2 tàbí kò dúró de àwọn ọmọ ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ìyókù Jakọbu yóò sì wà láàrín àwọn aláìkọlà
|
||
\q2 ní àárín àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn,
|
||
\q1 bí i kìnnìún láàrín àwọn ẹranko inú igbó,
|
||
\q2 bí i ọmọ kìnnìún láàrín agbo àgùntàn,
|
||
\q1 èyí tí ó máa ń fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,
|
||
\q2 tí ó sì máa ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀,
|
||
\q2 tí kò sì ṣí ẹnìkan tí ó lè gbà á là.
|
||
\q1
|
||
\v 9 A ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀,
|
||
\q2 gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sì ni a ó parun.
|
||
\p
|
||
\v 10 “Ní ọjọ́ náà,” ni \nd Olúwa\nd* wí,
|
||
\q1 “Èmi yóò pa àwọn ẹṣin rẹ̀ run kúrò láàrín rẹ
|
||
\q2 èmi yóò sì pa àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ run.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Èmi yóò sì pa ilẹ̀ ìlú ńlá rẹ̀ run,
|
||
\q2 èmi ó sì fa gbogbo ibi gíga rẹ̀ ya.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Èmi yóò gé ìwà àjẹ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀,
|
||
\q2 ìwọ kì yóò sì ní aláfọ̀ṣẹ mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Èmi yóò pa àwọn ère fínfín rẹ̀ run,
|
||
\q2 àti ọwọ̀n rẹ̀ kúrò láàrín rẹ̀;
|
||
\q1 ìwọ kì yóò sì le è foríbalẹ̀
|
||
\q2 fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Èmi yóò fa ère Aṣerah tu kúrò láàrín rẹ̀,
|
||
\q2 èmi yóò sì pa ìlú ńlá rẹ̀ run.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Èmi yóò gbẹ̀san ní ìbínú àti ìrunú
|
||
\q2 lórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò ti tẹríba fún mi.”
|
||
\c 6
|
||
\s1 Ọlọ́run pe Israẹli níjà
|
||
\p
|
||
\v 1 Ẹ fi etí sí ohun tí \nd Olúwa\nd* wí:
|
||
\q1 “Dìde dúró, bẹ ẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ rẹ níwájú òkè ńlá;
|
||
\q2 sì jẹ́ kí àwọn òkè kéékèèké gbọ́ ohun tí ó fẹ́ wí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 “Gbọ́, ìwọ òkè ńlá, ẹ̀sùn \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 gbọ́, ìwọ ìpìlẹ̀ ilé ayérayé.
|
||
\q1 Nítorí \nd Olúwa\nd* ń bá àwọn ènìyàn rẹ̀ wíjọ́;
|
||
\q2 òun yóò sì bá Israẹli rojọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 “Ẹ̀yin ènìyàn mi, kí ni mo ṣe fún yín?
|
||
\q2 Àti nínú kí ni mo ti dá yin lágara? Dá mi lóhùn.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,
|
||
\q2 mo sì rà yín padà láti ilẹ̀ ẹrú wá.
|
||
\q1 Mo rán Mose láti darí yín,
|
||
\q2 bákan náà mo rán Aaroni àti Miriamu síwájú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ ènìyàn mi,
|
||
\q2 rántí ohun tí Balaki ọba Moabu gbèrò
|
||
\q2 àti ohun tí Balaamu ọmọ Beori dáhùn.
|
||
\q1 Rántí ìrìnàjò rẹ̀ láti Ṣittimu dé Gilgali,
|
||
\q2 kí ìwọ ba le mọ òdodo \nd Olúwa\nd*.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Kí ni èmi yóò ha mú wá síwájú \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 tí èmi ó fi tẹ ara mi ba níwájú Ọlọ́run gíga?
|
||
\q1 Kí èmi ha wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun,
|
||
\q2 pẹ̀lú ọmọ màlúù ọlọ́dún kan?
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ǹjẹ́ \nd Olúwa\nd* yóò ní inú dídùn sí ẹgbẹgbàarùn-ún àgbò,
|
||
\q2 tàbí sí ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìṣàn òróró?
|
||
\q1 Èmi yóò ha fi àkọ́bí mi sílẹ̀ fún ìré-òfin-kọjá mi,
|
||
\q2 èso inú ara mi fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkàn mi?
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ó ti fihàn ọ́, ìwọ ènìyàn, ohun tí ó dára,
|
||
\q2 àti ohun tí \nd Olúwa\nd* ń béèrè lọ́wọ́ rẹ?
|
||
\q1 Bí kò ṣe láti ṣe òtítọ́, kí o sì fẹ́ràn àánú,
|
||
\q2 àti kí o rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
|
||
\s1 Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli àti ìjìyà wọn
|
||
\q1
|
||
\v 9 Gbọ́! Ohùn \nd Olúwa\nd* kígbe sí ìlú ńlá náà,
|
||
\q2 láti jẹ ọlọ́gbọ́n ni láti bẹ̀rù orúkọ rẹ.
|
||
\q2 “Ẹ kíyèsi ọ̀pá rẹ̀ gbọ́ ọ̀pá àti Ẹni náà tí ó yàn án.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ǹjẹ́ ìṣúra ìwà búburú ha wà
|
||
\q2 ní ilé ènìyàn búburú síbẹ̀,
|
||
\q2 àti òsùwọ̀n àìkún tí ó jẹ́ ohun ìbínú?
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ǹjẹ́ èmi ha lè kà wọ́n sí mímọ́
|
||
\q2 pẹ̀lú òsùwọ̀n búburú,
|
||
\q2 pẹ̀lú àpò òsùwọ̀n ẹ̀tàn?
|
||
\q1
|
||
\v 12 Àwọn ọlọ́rọ̀ inú rẹ̀ kún fún ìwà ipá;
|
||
\q2 àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ ti ọ̀rọ̀ èké
|
||
\q2 àti ahọ́n wọn ń sọ ẹ̀tàn?
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ ṣàìsàn ní lílù ọ́,
|
||
\q2 láti sọ ọ́ dahoro nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ìwọ yóò jẹun ṣùgbọ́n kì yóò yó;
|
||
\q2 ìyàn yóò wà láàrín rẹ.
|
||
\q1 Ìwọ yóò kó pamọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò lò láìléwu,
|
||
\q2 nítorí ohun tí ìwọ kò pamọ́ ni èmi yóò fi fún idà.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ìwọ yóò gbìn ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò kórè
|
||
\q2 ìwọ yóò tẹ olifi,
|
||
\q1 ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò fi òróró rẹ̀ kún ara rẹ;
|
||
\q2 ìwọ yóò tẹ èso àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò mu wáìnì.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nítorí tí ìwọ ti pa òfin Omri mọ́,
|
||
\q2 àti gbogbo iṣẹ́ ilé Ahabu,
|
||
\q2 tí ó sì ti tẹ̀lé ìmọ̀ràn wọn,
|
||
\q1 nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ fún ìparun
|
||
\q2 àti àwọn ènìyàn rẹ fún ìfiṣe ẹlẹ́yà;
|
||
\q2 ìwọ yóò sì ru ẹ̀gàn àwọn ènìyàn mi.”
|
||
\c 7
|
||
\s1 Ìrora Israẹli
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ègbé ni fún mi!
|
||
\q1 Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ,
|
||
\q2 ìpèsè ọgbà àjàrà;
|
||
\q1 kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ,
|
||
\q2 kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà,
|
||
\q2 kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́;
|
||
\q1 gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀,
|
||
\q2 olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú;
|
||
\q2 àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn,
|
||
\q1 àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀
|
||
\q2 alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́,
|
||
\q2 gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún,
|
||
\q2 ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ.
|
||
\q1 Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé,
|
||
\q2 àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò.
|
||
\q2 Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́;
|
||
\q2 ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan.
|
||
\q1 Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni
|
||
\q2 tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 6 \x - \xo 7.6: \xt Mt 10.21,35,36; Mk 13.12; Lk 12.53.\x*Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀,
|
||
\q2 ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀,
|
||
\q1 aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀,
|
||
\q2 ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi;
|
||
\q2 Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.
|
||
\s1 Israẹli yóò dìde
|
||
\q1
|
||
\v 8 Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi.
|
||
\q2 Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde.
|
||
\q1 Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i,
|
||
\q2 èmi yóò faradà ìbínú \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q1 títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò,
|
||
\q2 tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi.
|
||
\q1 Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀;
|
||
\q2 èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i
|
||
\q2 ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé,
|
||
\q1 “Níbo ni \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run rẹ wà?”
|
||
\q2 Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀;
|
||
\q1 nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀
|
||
\q2 bí ẹrẹ̀ òpópó.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé,
|
||
\q2 ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ
|
||
\q2 láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti
|
||
\q1 àní láti Ejibiti dé Eufurate
|
||
\q2 láti Òkun dé Òkun
|
||
\q2 àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀,
|
||
\q2 nítorí èso ìwà wọn.
|
||
\s1 Àdúrà àti ìyìn
|
||
\q1
|
||
\v 14 Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ,
|
||
\q2 èyí tí ó ń dágbé nínú igbó
|
||
\q1 ní àárín Karmeli.
|
||
\q2 Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi
|
||
\q2 bí ọjọ́ ìgbàanì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 “Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá,
|
||
\q2 ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n,
|
||
\q2 nínú gbogbo agbára wọn.
|
||
\q1 Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn,
|
||
\q2 etí wọn yóò sì di.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò,
|
||
\q2 wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló.
|
||
\q1 Wọn yóò bẹ̀rù \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa,
|
||
\q2 wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀,
|
||
\q2 ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì,
|
||
\q2 tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀?
|
||
\q1 Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé
|
||
\q2 nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa;
|
||
\q2 òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀,
|
||
\q2 yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
|
||
\q1
|
||
\v 20 \x - \xo 7.20: \xt Lk 1.55.\x*Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu
|
||
\q2 ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu,
|
||
\q1 bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa
|
||
\q2 láti ọjọ́ ìgbàanì.
|