591 lines
21 KiB
Plaintext
591 lines
21 KiB
Plaintext
\id SNG - Biblica® Open Yoruba Contemporary Bible (Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
|
|
\rem Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.®
|
|
\h Orin Solomoni
|
|
\toc1 Ìwé Orin Solomoni
|
|
\toc2 Orin Solomoni
|
|
\toc3 Os
|
|
\mt1 Ìwé Orin Solomoni
|
|
\c 1
|
|
\p
|
|
\v 1 Orin, àwọn orin tí í ṣe orin Solomoni.
|
|
\b
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 2 Fi ìfẹnukonu ìfẹ́ kò mí ní ẹnu,
|
|
\q2 nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ọtí wáìnì lọ.
|
|
\q1
|
|
\v 3 Òórùn ìkunra rẹ fanimọ́ra.
|
|
\q2 Orúkọ rẹ rí bí ìkunra tí a tú jáde
|
|
\q2 abájọ tí àwọn wúńdíá fi fẹ́ ọ.
|
|
\q1
|
|
\v 4 Fà mí lọ pẹ̀lú rẹ, kí a lọ kíákíá
|
|
\q2 ọba ti mú mi wá sínú yàrá rẹ̀.
|
|
\sp Ọ̀rẹ́
|
|
\q1 Àwa yọ̀ inú wa sì dùn sí ọ;
|
|
\q2 a gbé ìfẹ́ rẹ ga ju ọtí wáìnì lọ.
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1 Wọ́n fẹ́ ọ nítòótọ́!
|
|
\b
|
|
\q1
|
|
\v 5 Èmi dúdú mo sì ní ẹwà.
|
|
\q2 Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu
|
|
\q2 dúdú bí àgọ́ ìlú Kedari,
|
|
\q2 bí aṣọ títa ti Solomoni.
|
|
\q1
|
|
\v 6 Má ṣe wò mí nítorí wí pé mo dúdú,
|
|
\q2 nítorí oòrùn mú mi dúdú,
|
|
\q1 ọmọkùnrin ìyá mi bínú sí mi
|
|
\q2 ó sì fi mí ṣe olùtọ́jú ọgbà àjàrà;
|
|
\q2 ọgbà àjàrà tèmi ni èmi kò tọ́jú.
|
|
\q1
|
|
\v 7 Wí fún mi, ìwọ ẹni tí ọkàn mí fẹ́,
|
|
\q2 níbo ni ìwọ ń da agbo ẹran lọ.
|
|
\q1 Níbi tí ìwọ mú agbo ẹran rẹ sinmi ní ọ̀sán,
|
|
\q2 kí ni ìdí tí èmi yóò fi jẹ́ obìnrin asán
|
|
\q1 ní ẹ̀bá agbo ẹran àwọn ọ̀rẹ́ rẹ.
|
|
\sp Ọ̀rẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 8 Bí ìwọ kò bá mọ̀,
|
|
\q2 ìwọ arẹwà jùlọ nínú àwọn obìnrin.
|
|
\q1 Bá ọ̀nà tí agbo ẹran rìn lọ,
|
|
\q2 kí o sì bọ́ àwọn ọmọ ewúrẹ́ rẹ.
|
|
\q1 Ní ẹ̀bá àgọ́ àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 9 Olùfẹ́ mi,
|
|
\q2 mo fi ọ́ wé ẹṣin mi nínú kẹ̀kẹ́ Farao.
|
|
\q1
|
|
\v 10 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ dára ní ohun ọ̀ṣọ́,
|
|
\q2 ọrùn rẹ sì yẹ ọ̀ṣọ́ ìlẹ̀kẹ̀.
|
|
\q1
|
|
\v 11 A ó fi wúrà ṣe òrùka etí fún ọ,
|
|
\q2 a ó fi fàdákà ṣe ìlẹ̀kẹ̀.
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 12 Nígbà tí ọba wà ní orí ìjókòó rẹ̀,
|
|
\q2 òróró ìkunra mi tú òórùn jáde.
|
|
\q1
|
|
\v 13 Ìdì òjìá ni olùfẹ́ mi jẹ sí mi,
|
|
\q2 òun ó sinmi lé àárín ọmú mi.
|
|
\q1
|
|
\v 14 Bí ìdì ìtànná Henina ni olùfẹ́ mi rí sí mi
|
|
\q2 láti inú ọgbà àjàrà ti En-Gedi.
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 15 Báwo ni o ti lẹ́wà tó, olólùfẹ́ mi!
|
|
\q2 Háà, báwo ni o ṣe lẹ́wà tó!
|
|
\q2 Ìwọ ní ojú ẹyẹlé.
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 16 Báwo ni o ṣe dára tó, olùfẹ́ mi!
|
|
\q2 Háà, báwo ni o ṣe wu ni!
|
|
\q2 Ibùsùn wa ní ìtura.
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 17 Ìtànṣán ilé wa jẹ́ ti igi kedari
|
|
\q2 ẹkẹ́ ilé wa jẹ́ ti igi firi.
|
|
\c 2
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 1 Èmi ni ìtànná Ṣaroni
|
|
\q2 bí ìtànná lílì àwọn àfonífojì.
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 2 Bí ìtànná lílì ní àárín ẹ̀gún
|
|
\q2 ni olólùfẹ́ mi ní àárín àwọn wúńdíá.
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 3 Bí igi ápù láàrín àwọn igi inú igbó,
|
|
\q2 ni olólùfẹ́ mí láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin.
|
|
\q1 Mo fi ayọ̀ jókòó ní abẹ́ òjìji rẹ̀,
|
|
\q2 èso rẹ̀ sì dùn mọ́ mi ní ẹnu.
|
|
\q1
|
|
\v 4 Ó mú mi lọ sí ibi gbọ̀ngàn àsè,
|
|
\q2 ìfẹ́ sì ni ọ̀págun rẹ̀ lórí mi.
|
|
\q1
|
|
\v 5 Fi agbára adùn àkàrà dá mi dúró.
|
|
\q2 Fi èso ápù tù mi lára
|
|
\q2 nítorí àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mí.
|
|
\q1
|
|
\v 6 Ọwọ́ òsì rẹ ń bẹ lábẹ́ orí mi
|
|
\q2 ọwọ́ ọ̀tún rẹ sì ń gbà mí mọ́ra.
|
|
\q1
|
|
\v 7 Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu,
|
|
\q2 mo fi abo egbin àti ọmọ àgbọ̀nrín fi yín bú
|
|
\q1 kí ẹ má ṣe ru ìfẹ́ olùfẹ́ mi sókè
|
|
\q2 kí ẹ má sì ṣe jí i títí yóò fi wù ú.
|
|
\b
|
|
\q1
|
|
\v 8 Gbọ́ ohùn olùfẹ́ mi!
|
|
\q2 Wò ó! Ibí yìí ni ó ń bọ̀.
|
|
\q1 Òun ń fò lórí àwọn òkè ńlá,
|
|
\q2 òun bẹ́ lórí àwọn òkè kéékèèké.
|
|
\q1
|
|
\v 9 Olùfẹ́ mi dàbí abo egbin tàbí ọmọ àgbọ̀nrín.
|
|
\q2 Wò ó! Níbẹ̀ ni ó wà lẹ́yìn ògiri wa
|
|
\q1 Ó yọjú ní ojú fèrèsé
|
|
\q2 Ó ń fi ara rẹ̀ hàn lójú fèrèsé ọlọ́nà.
|
|
\q1
|
|
\v 10 Olùfẹ́ mi fọhùn ó sì sọ fún mi pé,
|
|
\q2 “Dìde, Olólùfẹ́ mi,
|
|
\q2 arẹwà mi, kí o sì wà pẹ̀lú mi.
|
|
\q1
|
|
\v 11 Wò ó! Ìgbà òtútù ti kọjá;
|
|
\q2 òjò ti rọ̀ dawọ́, ó sì ti lọ.
|
|
\q1
|
|
\v 12 Àwọn òdòdó fi ara hàn lórí ilẹ̀
|
|
\q2 àsìkò ìkọrin àwọn ẹyẹ dé
|
|
\q2 a sì gbọ́ ohùn àdàbà ní ilẹ̀ wa.
|
|
\q1
|
|
\v 13 Igi ọ̀pọ̀tọ́ mú èso tuntun jáde,
|
|
\q2 àwọn àjàrà nípa ìtànná wọ́n fún ni ní òórùn dídùn.
|
|
\q1 Dìde, wá, Olólùfẹ́ mi,
|
|
\q2 Arẹwà mi nìkan ṣoṣo, wá pẹ̀lú mi.”
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 14 Àdàbà mi wà nínú pàlàpálá òkúta,
|
|
\q2 ní ibi ìkọ̀kọ̀ ní orí òkè gíga,
|
|
\q1 fi ojú rẹ hàn mí,
|
|
\q2 jẹ́ kí èmi gbọ́ ohùn rẹ;
|
|
\q1 nítorí tí ohùn rẹ dùn,
|
|
\q2 tí ojú rẹ sì ní ẹwà.
|
|
\q1
|
|
\v 15 Bá wa mú àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀,
|
|
\q2 àní àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ kéékèèké
|
|
\q1 tí ń ba ọgbà àjàrà jẹ́,
|
|
\q2 àwọn ọgbà àjàrà wa tó ní ìtànná.
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 16 Olùfẹ́ mi ni tèmi èmi sì ni tirẹ̀;
|
|
\q2 Ó ń jẹ láàrín àwọn koríko lílì.
|
|
\q1
|
|
\v 17 Títí ìgbà ìtura ọjọ́
|
|
\q2 títí òjìji yóò fi fò lọ,
|
|
\q1 yípadà, olùfẹ́ mi,
|
|
\q2 kí o sì dàbí abo egbin
|
|
\q1 tàbí ọmọ àgbọ̀nrín
|
|
\q2 lórí òkè Beteri.
|
|
\b
|
|
\c 3
|
|
\q1
|
|
\v 1 Ní orí ibùsùn mi ní òru
|
|
\q2 mo wá ẹni tí ọkàn mí fẹ́;
|
|
\q2 mo wá a, ṣùgbọ́n èmi kò rí i.
|
|
\q1
|
|
\v 2 Èmi yóò dìde nísinsin yìí, èmi yóò sì rìn lọ káàkiri ìlú,
|
|
\q2 ní àwọn òpópónà àti ní àwọn gbangba òde;
|
|
\q1 èmi yóò wá ẹni tí ọkàn mi fẹ́.
|
|
\q2 Bẹ́ẹ̀ ni mo wá a ṣùgbọ́n èmi kò rí i.
|
|
\q1
|
|
\v 3 Àwọn ọdẹ tí ń ṣọ́ ìlú rí mi
|
|
\q2 bí wọ́n ṣe ń rìn yíká ìlú.
|
|
\q2 “Ǹjẹ́ ìwọ ti rí ẹni tí ọkàn mi fẹ́?”
|
|
\q1
|
|
\v 4 Gẹ́rẹ́ tí mo fi wọ́n sílẹ̀
|
|
\q2 ni mo rí ẹni tí ọkàn mi fẹ́.
|
|
\q1 Mo dìímú, èmi kò sì jẹ́ kí ó lọ
|
|
\q2 títí tí mo fi mú u wá sílé ìyá mi,
|
|
\q2 sínú yàrá ẹni tí ó lóyún mi.
|
|
\q1
|
|
\v 5 Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu,
|
|
\q2 mo fi àwọn abo egbin àti abo àgbọ̀nrín igbó fi yín bú
|
|
\q1 kí ẹ má ṣe rú olùfẹ́ mi sókè
|
|
\q2 kí ẹ má sì ṣe jí i títí yóò fi wù ú.
|
|
\b
|
|
\q1
|
|
\v 6 Ta ni ẹni tí ń ti ijù jáde wá
|
|
\q2 bí ọ̀wọ̀n èéfín
|
|
\q1 tí a ti fi òjìá àti tùràrí kùn lára
|
|
\q2 pẹ̀lú gbogbo ìpara olóòórùn oníṣòwò?
|
|
\q1
|
|
\v 7 Wò ó! Àkéte rẹ̀ tí í ṣe ti Solomoni,
|
|
\q2 àwọn akọni ọgọ́ta ni ó wà yí i ká,
|
|
\q2 àwọn akọni Israẹli,
|
|
\q1
|
|
\v 8 gbogbo wọn ni ó mú idà lọ́wọ́,
|
|
\q2 gbogbo wọn ní ìmọ̀ nínú ogun,
|
|
\q1 idà oníkálùkù wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀,
|
|
\q2 wọ́n múra sílẹ̀ fún ìdágìrì òru
|
|
\q1
|
|
\v 9 Solomoni ọba ṣe àkéte fún ara rẹ̀;
|
|
\q2 o fi igi Lebanoni ṣe é.
|
|
\q1
|
|
\v 10 Ó fi fàdákà ṣe òpó rẹ̀,
|
|
\q2 o fi wúrà ṣe ibi ẹ̀yìn rẹ̀.
|
|
\q1 Ó fi elése àlùkò ṣe ibùjókòó rẹ̀,
|
|
\q2 inú rẹ̀ ni ó ko àwọn ọ̀rọ̀ ìfẹ́ wọ̀nyí sí.
|
|
\q2 “Pẹ̀lú ìfẹ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”
|
|
\q1
|
|
\v 11 Ẹ jáde wá, ẹ̀yin ọmọbìnrin Sioni,
|
|
\q2 kí ẹ sì wo ọba Solomoni tí ó dé adé,
|
|
\q2 adé tí ìyá rẹ̀ fi dé e
|
|
\q1 ní ọjọ́ ìgbéyàwó rẹ̀,
|
|
\q2 ní ọjọ́ ayọ̀ ọkàn rẹ̀.
|
|
\c 4
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 1 Báwo ni ìwọ ti lẹ́wà tó olólùfẹ́ mi!
|
|
\q2 Háà, ìwọ jẹ́ arẹwà!
|
|
\q2 Ìwọ ní ojú àdàbà lábẹ́ ìbòjú rẹ
|
|
\q1 irun rẹ bò ọ́ lójú bí ọ̀wọ́ ewúrẹ́.
|
|
\q2 Tí ó sọ̀kalẹ̀ lórí òkè Gileadi.
|
|
\q1
|
|
\v 2 Eyín rẹ̀ funfun bí i irun àgbò
|
|
\q2 tí ó gòkè wá láti ibi ìwẹ̀;
|
|
\q1 olúkúlùkù wọn bí èjìrẹ́;
|
|
\q2 kò sí ọ̀kan nínú wọn tí ó da dúró.
|
|
\q1
|
|
\v 3 Ètè rẹ dàbí òwú òdòdó;
|
|
\q2 ẹnu rẹ̀ dùn.
|
|
\q1 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ dàbí ẹ̀là pomegiranate
|
|
\q2 lábẹ́ ìbòjú rẹ.
|
|
\q1
|
|
\v 4 Ọrùn rẹ dàbí ilé ìṣọ́ Dafidi,
|
|
\q2 tí a kọ́ pẹ̀lú ìhámọ́ra;
|
|
\q1 lórí rẹ̀ ni a fi ẹgbẹ̀rún (1,000) àpáta kọ́,
|
|
\q2 gbogbo wọn jẹ́ àṣà àwọn alágbára.
|
|
\q1
|
|
\v 5 Ọmú rẹ̀ méjèèjì dàbí abo egbin méjì
|
|
\q2 tí wọ́n jẹ́ ìbejì
|
|
\q2 tí ń jẹ láàrín ìtànná ewéko lílì.
|
|
\q1
|
|
\v 6 Títí ọjọ́ yóò fi rọ̀
|
|
\q2 tí òjìji yóò fi fò lọ,
|
|
\q1 èmi yóò lọ sí orí òkè ńlá òjìá
|
|
\q2 àti sí òkè kékeré tùràrí.
|
|
\q1
|
|
\v 7 Gbogbo ara rẹ jẹ́ kìkì ẹwà, olólùfẹ́ mi;
|
|
\q2 kò sì ṣí àbàwọ́n lára rẹ.
|
|
\b
|
|
\q1
|
|
\v 8 Kí a lọ kúrò ní Lebanoni, ìyàwó mi,
|
|
\q2 ki a lọ kúrò ní Lebanoni.
|
|
\q1 Àwa wò láti orí òkè Amana,
|
|
\q2 láti orí òkè ti Seniri, àti téńté Hermoni,
|
|
\q1 láti ibi ihò àwọn kìnnìún,
|
|
\q2 láti orí òkè ńlá àwọn ẹkùn.
|
|
\q1
|
|
\v 9 Ìwọ ti gba ọkàn mi, arábìnrin mi, ìyàwó mi;
|
|
\q2 ìwọ ti gba ọkàn mi
|
|
\q1 pẹ̀lú ìwò ẹ̀ẹ̀kan ojú rẹ,
|
|
\q2 pẹ̀lú ọ̀kan nínú ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn rẹ.
|
|
\q1
|
|
\v 10 Ìfẹ́ rẹ ti dùn tó, arábìnrin mi, ìyàwó mi!
|
|
\q2 Ìfẹ́ rẹ tu ni lára ju ọtí wáìnì lọ,
|
|
\q2 òórùn ìkunra rẹ sì ju òórùn gbogbo tùràrí lọ!
|
|
\q1
|
|
\v 11 Ètè rẹ ń kan dídùn bí afárá oyin, ìyàwó mi;
|
|
\q2 wàrà àti oyin wà lábẹ́ ahọ́n rẹ.
|
|
\q2 Òórùn aṣọ rẹ sì dàbí òórùn Lebanoni.
|
|
\q1
|
|
\v 12 Arábìnrin mi ni ọgbà tí a sọ, arábìnrin mi, ìyàwó mi;
|
|
\q2 ìsun tí a sé mọ́, orísun tí a fi èdìdì dì.
|
|
\q1
|
|
\v 13 Ohun ọ̀gbìn rẹ àgbàlá pomegiranate ni
|
|
\q2 ti òun ti àṣàyàn èso; kipiresi àti nadi,
|
|
\q2
|
|
\v 14 nadi àti Safironi,
|
|
\q2 kalamusi àti kinamoni,
|
|
\q2 àti gbogbo igi olóòórùn dídùn,
|
|
\q2 òjìá àti aloe
|
|
\q2 pẹ̀lú irú wọn.
|
|
\q1
|
|
\v 15 Ìwọ ni ọgbà orísun, kànga omi ìyè,
|
|
\q2 ìṣàn omi láti Lebanoni wá.
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 16 Jí ìwọ afẹ́fẹ́ àríwá
|
|
\q2 kí o sì wá, afẹ́fẹ́ gúúsù!
|
|
\q1 Fẹ́ lórí ọgbà mi,
|
|
\q2 kí àwọn òórùn dídùn inú rẹ lè rùn jáde.
|
|
\q1 Jẹ́ kí olùfẹ́ mi wá sínú ọgbà a rẹ̀
|
|
\q2 kí ó sì jẹ àṣàyàn èso rẹ̀.
|
|
\c 5
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 1 Mo ti dé inú ọgbà mi, arábìnrin mi, ìyàwó mi;
|
|
\q2 mo ti kó òjìá pẹ̀lú òórùn dídùn mi jọ.
|
|
\q1 Mo ti jẹ afárá mi pẹ̀lú oyin mi;
|
|
\q2 mo ti mu ọtí wáìnì mi pẹ̀lú wàrà mi.
|
|
\sp Ọ̀rẹ́
|
|
\q1 Ẹ jẹ, ẹ̀yin ọ̀rẹ́, ẹ mu,
|
|
\q2 àní ẹ mu àmuyó, ẹ̀yin olùfẹ́.
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 2 Mo ti sùn ṣùgbọ́n ọkàn mi jí.
|
|
\q2 Gbọ́! Olólùfẹ́ mi ń kan ìlẹ̀kùn.
|
|
\q1 “Ṣí i fún mi, arábìnrin mi, olùfẹ́ mi,
|
|
\q2 àdàbà mi, aláìlábàwọ́n mi,
|
|
\q1 orí mi kún fún omi ìrì,
|
|
\q2 irun mi kún fún òtútù òru.”
|
|
\q1
|
|
\v 3 Mo ti bọ́ aṣọ ìgúnwà mi
|
|
\q2 ṣé èmi gbọdọ̀ tún gbé e wọ̀?
|
|
\q1 Mo ti wẹ ẹsẹ̀ mi
|
|
\q2 ṣé èmi gbọdọ̀ tún tì í bọ eruku?
|
|
\q1
|
|
\v 4 Olùfẹ́ mi na ọwọ́ rẹ̀ láti inú ihò ìlẹ̀kùn
|
|
\q2 inú mi sì yọ́ sí i.
|
|
\q1
|
|
\v 5 Èmi dìde láti ṣílẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
|
|
\q2 òjìá bẹ̀rẹ̀ sí í kán ní ọwọ́ mi,
|
|
\q1 òjìá olóòórùn ń ti ara ìka mi ń sàn
|
|
\q2 sí orí ìdìmú ìlẹ̀kùn.
|
|
\q1
|
|
\v 6 Èmi ṣí ìlẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
|
|
\q2 ṣùgbọ́n olùfẹ́ mi ti kúrò, ó ti lọ
|
|
\q2 ọkàn mi gbọgbẹ́ fún lílọ rẹ̀.
|
|
\q1 Mo wá a kiri ṣùgbọ́n, n kò rí i.
|
|
\q2 Mo pè é ṣùgbọ́n, kò dáhùn.
|
|
\q1
|
|
\v 7 Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlú rí mi
|
|
\q2 bí wọ́n ti ṣe ń rìn yí ìlú ká.
|
|
\q1 Wọ́n nà mí, wọ́n sá mi lọ́gbẹ́;
|
|
\q2 wọ́n gba ìborùn mi lọ́wọ́ mi.
|
|
\q2 Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ odi!
|
|
\q1
|
|
\v 8 Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, mo bẹ̀ yín
|
|
\q2 bí ẹ̀yin bá rí olùfẹ́ mi,
|
|
\q1 kí ni ẹ̀yin yóò wí fún un?
|
|
\q2 Ẹ wí fún un pé àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mi.
|
|
\sp Ọ̀rẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 9 Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ,
|
|
\q2 ìwọ arẹwà jùlọ láàrín àwọn obìnrin?
|
|
\q1 Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ
|
|
\q2 tí ìwọ fi ń fi wá bú bẹ́ẹ̀?
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 10 Olùfẹ́ mi ní ìtànṣán ó sì pọ́n
|
|
\q2 ó ní ọlá ju ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) lọ.
|
|
\q1
|
|
\v 11 Orí rẹ̀ rí bí i wúrà tí ó dára jùlọ
|
|
\q2 ìdì irun rẹ̀ rí bí i imọ̀ ọ̀pẹ
|
|
\q2 ó sì dúdú bí i ẹyẹ ìwò.
|
|
\q1
|
|
\v 12 Ojú rẹ̀ rí bí i ti àdàbà
|
|
\q2 ní ẹ̀bá odò tí ń sàn,
|
|
\q1 tí a fi wàrà wẹ̀,
|
|
\q2 tí ó jì, tí ó sì dákẹ́ rọ́rọ́.
|
|
\q1
|
|
\v 13 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ rí bí ibùsùn tùràrí
|
|
\q2 tí ó sun òórùn tùràrí dídùn
|
|
\q1 Ètè rẹ̀ rí bí i ìtànná lílì
|
|
\q2 ó ń kán òjìá olóòórùn dídùn.
|
|
\q1
|
|
\v 14 Apá rẹ̀ rí bí i ọ̀pá wúrà,
|
|
\q2 tí a to ohun ọ̀ṣọ́ sí yíká.
|
|
\q1 Ara rẹ̀ rí bí i eyín erin dídán
|
|
\q2 tí a fi safire ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
|
|
\q1
|
|
\v 15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ rí bí i òpó mabu
|
|
\q2 tí a gbé ka ihò ìtẹ̀bọ̀ wúrà dáradára.
|
|
\q1 Ìrísí rẹ̀ rí bí igi kedari Lebanoni,
|
|
\q2 tí dídára rẹ̀ kò ní ẹgbẹ́.
|
|
\q1
|
|
\v 16 Ẹnu rẹ̀ jẹ́ adùn fún ara rẹ̀
|
|
\q2 ó wu ni pátápátá.
|
|
\q1 Háà! Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
|
|
\q2 Èyí ni olùfẹ́ mi, èyí sì ni ọ̀rẹ́ mi.
|
|
\c 6
|
|
\sp Ọ̀rẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 1 Níbo ni olùfẹ́ rẹ lọ,
|
|
\q2 ìwọ arẹwà jùlọ láàrín àwọn obìnrin?
|
|
\q1 Níbo ni olùfẹ́ rẹ yà sí,
|
|
\q2 kí a lè bá ọ wá a?
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 2 Olùfẹ́ mi ti sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ọgbà rẹ̀,
|
|
\q2 sí ibi ibùsùn tùràrí,
|
|
\q1 láti máa jẹ nínú ọgbà
|
|
\q2 láti kó ìtànná lílì jọ.
|
|
\q1
|
|
\v 3 Èmi ni ti olùfẹ́ mi, olùfẹ́ mi sì ni tèmi,
|
|
\q2 Ó ń jẹ láàrín ìtànná lílì.
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 4 Ìwọ lẹ́wà olùfẹ́ mi, bí i Tirsa,
|
|
\q2 ìwọ lẹ́wà bí i Jerusalẹmu,
|
|
\q2 ìwọ ògo bí ogun pẹ̀lú ọ̀págun.
|
|
\q1
|
|
\v 5 Yí ojú rẹ kúrò lára mi;
|
|
\q2 nítorí ojú rẹ borí mi.
|
|
\q1 Irun rẹ rí bí i ọ̀wọ́ ewúrẹ́
|
|
\q2 tí ó sọ̀kalẹ̀ wá láti Gileadi.
|
|
\q1
|
|
\v 6 Eyín rẹ rí bí ọ̀wọ́ àgùntàn,
|
|
\q2 tí ó gòkè láti ibi ìwẹ̀ rẹ̀ wá,
|
|
\q1 gbogbo wọn bí ìbejì,
|
|
\q2 kò sì ṣí ọ̀kankan tí ó yàgàn nínú wọn.
|
|
\q1
|
|
\v 7 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ lẹ́bàá ìbòjú rẹ,
|
|
\q2 rí bí ẹ̀là èso pomegiranate.
|
|
\q1
|
|
\v 8 Ọgọ́ta ayaba ní ń bẹ níbẹ̀,
|
|
\q2 àti ọgọ́rin àlè,
|
|
\q2 àti àwọn wúńdíá láìníye.
|
|
\q1
|
|
\v 9 Àdàbà mi, aláìlábàwọ́n mi, ọ̀kan ni,
|
|
\q2 ọ̀kan ṣoṣo ọmọbìnrin ìyá rẹ̀,
|
|
\q2 ààyò ẹyọ kan ṣoṣo ẹni tí ó bí i.
|
|
\q1 Àwọn obìnrin rí i wọ́n pè é ní alábùkún fún
|
|
\q2 àwọn ayaba àti àwọn àlè gbé oríyìn fún un.
|
|
\sp Ọ̀rẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 10 Ta ni èyí tí ó tàn jáde bí i ìràwọ̀ òwúrọ̀,
|
|
\q2 tí ó dára bí òṣùpá, tí ó mọ́lẹ̀ bí oòrùn,
|
|
\q2 tí ó ní ẹ̀rù bí i jagunjagun pẹ̀lú ọ̀págun?
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 11 Èmi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibi ọgbà èso igi
|
|
\q2 láti wo àwọn ẹ̀ka igi tuntun ní àfonífojì,
|
|
\q1 láti rí i bí àjàrà rúwé,
|
|
\q2 tàbí bí pomegiranate ti rudi.
|
|
\q1
|
|
\v 12 Kí èmi tó mọ̀,
|
|
\q2 àárẹ̀ ọkàn mú mi, mo sì fẹ́ kí ń wà láàrín àwọn ènìyàn mi.
|
|
\sp Ọ̀rẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 13 Padà wá, padà wá, ìwọ ọmọ Ṣulamati;
|
|
\q2 padà wá, padà wá, kí àwa kí ó lè yọ́ ọ wò.
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1 Èéṣe tí ẹ̀yin fẹ́ yọ́ Ṣulamati wò,
|
|
\q2 bí ẹni pé orin ijó Mahanaimu?
|
|
\b
|
|
\c 7
|
|
\q1
|
|
\v 1 Báwo ni ẹsẹ̀ rẹ ti ní ẹwà tó nínú bàtà.
|
|
\q2 Ìwọ ọmọbìnrin ọba!
|
|
\q1 Oríkèé itan rẹ rí bí ohun ọ̀ṣọ́
|
|
\q2 iṣẹ́ ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà
|
|
\q1
|
|
\v 2 Ìdodo rẹ rí bí àwo
|
|
\q2 tí kì í ṣe aláìní ọtí,
|
|
\q1 ìbàdí rẹ bí òkìtì alikama
|
|
\q2 tí a fi lílì yíká.
|
|
\q1
|
|
\v 3 Ọmú rẹ rí bí abo egbin méjì
|
|
\q2 tí wọ́n jẹ́ ìbejì àgbọ̀nrín.
|
|
\q1
|
|
\v 4 Ọrùn rẹ rí bí ilé ìṣọ́ eyín erin.
|
|
\q1 Ojú rẹ rí bí adágún ní Heṣboni
|
|
\q2 ní ẹ̀bá ẹnu ibodè Bati-Rabbimu.
|
|
\q1 Imú rẹ rí bí ilé ìṣọ́ Lebanoni
|
|
\q2 tí ó kọ ojú sí Damasku.
|
|
\q1
|
|
\v 5 Bí òkè Karmeli ṣe ṣe adé yí àwọn òkè ká,
|
|
\q2 bẹ́ẹ̀ ni irun orí rẹ ṣe adé yí orí rẹ ká
|
|
\q2 a fi àìdi irun rẹ mú ọba ní ìgbèkùn.
|
|
\q1
|
|
\v 6 Báwo ni ẹwà rẹ ti pọ̀ tó
|
|
\q2 báwo ni o sì ti dára tó ìwọ olùfẹ́ mi nínú ìfẹ́?
|
|
\q1
|
|
\v 7 Ìdúró rẹ rí bí igi ọ̀pẹ,
|
|
\q2 àti ọmú rẹ bí ìdì èso àjàrà.
|
|
\q1
|
|
\v 8 Mo ní, “Èmi yóò gun igi ọ̀pẹ lọ,
|
|
\q2 èmi yóò di ẹ̀ka rẹ̀ mú.”
|
|
\q1 Kí ọmú rẹ rí bí ìdì èso àjàrà,
|
|
\q2 àti èémí imú rẹ bí i ápù.
|
|
\q2
|
|
\v 9 Àti ìfẹnukonu rẹ rí bí ọtí wáìnì tí ó dára jùlọ.
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1 Tí ó kúnná tí ó sì dùn,
|
|
\q2 tí ń mú kí ètè àwọn tí ó sùn kí ó sọ̀rọ̀.
|
|
\q1
|
|
\v 10 Ti olùfẹ́ mi ni èmi í ṣe,
|
|
\q2 èmi sì ni ẹni tí ó wù ú.
|
|
\q1
|
|
\v 11 Wá, olùfẹ́ mi, jẹ́ kí a lọ sí ibi pápá,
|
|
\q2 jẹ́ kí a lo àṣálẹ́ ní àwọn ìletò.
|
|
\q1
|
|
\v 12 Jẹ́ kí a lọ sínú ọgbà àjàrà ní kùtùkùtù
|
|
\q2 láti wo bí àjàrà rúwé
|
|
\q1 bí ìtànná àjàrà bá là.
|
|
\q2 Àti bí pomegiranate bá ti rudi,
|
|
\q2 níbẹ̀ ni èmi yóò ti fi ìfẹ́ mi fún ọ.
|
|
\q1
|
|
\v 13 Àwọn èso mándrákì mú òórùn wọn jáde
|
|
\q2 ní ẹnu-ọ̀nà wa ni onírúurú àṣàyàn èso,
|
|
\q1 èso tuntun àti ọjọ́ pípẹ́
|
|
\q2 tí mo ti kó pamọ́ fún ọ, olùfẹ́ mi.
|
|
\b
|
|
\c 8
|
|
\q1
|
|
\v 1 Ìwọ ìbá rí bí arákùnrin mi si mi,
|
|
\q2 èyí tí ó mú ọmú ìyá mi dàgbà!
|
|
\q1 Èmi ìbá rí ọ ní òde,
|
|
\q2 èmi ìbá fi ẹnu kò ọ́ ní ẹnu,
|
|
\q2 wọn kì bá fi mí ṣe ẹlẹ́yà.
|
|
\q1
|
|
\v 2 Èmi ìbá fi ọ̀nà hàn ọ́
|
|
\q2 èmi ìbá mú ọ wá sínú ilé ìyá mi,
|
|
\q2 ìwọ ìbá kọ́ mi.
|
|
\q1 Èmi ìbá fi ọtí wáìnì olóòórùn dídùn fún ọ mu,
|
|
\q2 àti oje èso pomegiranate mi.
|
|
\q1
|
|
\v 3 Ọwọ́ òsì rẹ ìbá wà ní abẹ́ orí mi,
|
|
\q2 ọwọ́ ọ̀tún rẹ ìbá sì gbà mí mọ́ra.
|
|
\q1
|
|
\v 4 Ọmọbìnrin Jerusalẹmu, èmi pè yín ní ìjà.
|
|
\q2 Ẹ má ṣe rú olùfẹ́ mi sókè.
|
|
\q2 Ẹ má ṣe jí i títí tí yóò fi wù ú.
|
|
\sp Ọ̀rẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 5 Ta ni ẹni tí ń gòkè bọ̀ wá láti aginjù,
|
|
\q2 tí ó fi ara ti olùfẹ́ rẹ̀.
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1 Ní abẹ́ igi ápù ni mo ti jí ọ dìde; níbẹ̀ ni ìyá rẹ ti lóyún rẹ
|
|
\q2 níbẹ̀ ni ẹni tí ń rọbí bí ọ sí.
|
|
\q1
|
|
\v 6 Gbé mi sí àyà rẹ bí èdìdì
|
|
\q2 bí èdìdì lé apá rẹ;
|
|
\q1 nítorí ìfẹ́ lágbára bí ikú,
|
|
\q2 ìjowú sì le bí isà òkú
|
|
\q1 jíjò rẹ̀ rí bí jíjò iná,
|
|
\q2 gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́-iná \nd Olúwa\nd*.
|
|
\q1
|
|
\v 7 Omi púpọ̀ kò le paná ìfẹ́;
|
|
\q2 bẹ́ẹ̀ ni gbígbá omi kò le gbá a lọ.
|
|
\q1 Bí ènìyàn bá fún ìfẹ́,
|
|
\q2 ní gbogbo ọrọ̀ ilé rẹ̀,
|
|
\q2 a ó kẹ́gàn rẹ̀ pátápátá.
|
|
\sp Ọ̀rẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 8 Àwa ní arábìnrin kékeré kan,
|
|
\q2 òun kò sì ní ọmú,
|
|
\q1 kí ni àwa yóò fún arábìnrin wa,
|
|
\q2 ní ọjọ́ tí a ó bá fẹ́ ẹ?
|
|
\q1
|
|
\v 9 Bí òun bá jẹ́ ògiri,
|
|
\q2 àwa yóò kọ́ ilé odi fàdákà lé e lórí.
|
|
\q1 Bí òun bá jẹ́ ìlẹ̀kùn,
|
|
\q2 àwa yóò fi pákó kedari dí i.
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 10 Èmi jẹ́ ògiri,
|
|
\q2 ọmú mi sì rí bí ilé ìṣọ́
|
|
\q1 bẹ́ẹ̀ ni mo ṣe rí ní ojú rẹ̀
|
|
\q2 bí ẹni tí ń mú àlàáfíà wá.
|
|
\q1
|
|
\v 11 Solomoni ní ọgbà àjàrà kan ní Baali-Hamoni
|
|
\q2 ó gbé ọgbà àjàrà rẹ̀ fún àwọn alágbàtọ́jú
|
|
\q1 olúkúlùkù ni ó ń mú èso rẹ̀ wá
|
|
\q2 ẹgbẹ̀rún (1,000) fàdákà.
|
|
\q1
|
|
\v 12 Ṣùgbọ́n ọgbà àjàrà mi jẹ́ tèmi, ó wà fún mi;
|
|
\q2 ẹgbẹ̀rún ṣékélì jẹ́ tìrẹ, ìwọ Solomoni,
|
|
\q2 igba sì jẹ́ ti àwọn alágbàtọ́jú èso.
|
|
\sp Olùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 13 Ìwọ tí ń gbé inú ọgbà,
|
|
\q2 àwọn ọ̀rẹ́ rẹ dẹtí sí ohùn rẹ,
|
|
\q2 jẹ́ kí èmi náà gbọ́ ohùn rẹ!
|
|
\sp Olólùfẹ́
|
|
\q1
|
|
\v 14 Yára wá, Olùfẹ́ mi,
|
|
\q2 kí ìwọ kí ó sì rí bí abo egbin,
|
|
\q1 tàbí gẹ́gẹ́ bí ọmọ àgbọ̀nrín,
|
|
\q2 lórí òkè òórùn dídùn.
|