3439 lines
122 KiB
Plaintext
3439 lines
122 KiB
Plaintext
\id PRO - Biblica® Open Yoruba Contemporary Bible (Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
|
||
\rem Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.®
|
||
\h Òwe
|
||
\toc1 Ìwé Òwe
|
||
\toc2 Òwe
|
||
\toc3 Òw
|
||
\mt1 Ìwé Òwe
|
||
\c 1
|
||
\s1 Èròǹgbà àti kókó-ọ̀rọ̀
|
||
\p
|
||
\v 1 Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́,
|
||
\q2 láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo,
|
||
\q2 àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;
|
||
\q1
|
||
\v 4 láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀,
|
||
\q2 ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀,
|
||
\q2 sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe,
|
||
\q2 àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.
|
||
\s1 Ọ̀rọ̀ ìyànjú láti ṣàfẹ́rí ọgbọ́n
|
||
\q1
|
||
\v 8 Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ,
|
||
\q2 má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ
|
||
\q2 àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́,
|
||
\q2 má ṣe gbà fún wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa;
|
||
\q2 jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan,
|
||
\q2 jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;
|
||
\q1
|
||
\v 12 jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú,
|
||
\q2 àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò;
|
||
\q1
|
||
\v 13 a ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí
|
||
\q2 a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa,
|
||
\q1
|
||
\v 14 da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa,
|
||
\q2 a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà,”
|
||
\q1
|
||
\v 15 ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ,
|
||
\q2 má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀,
|
||
\q2 wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀,
|
||
\q2 ní ojú ẹyẹ!
|
||
\q1
|
||
\v 18 Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn.
|
||
\q2 Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́;
|
||
\q2 yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.
|
||
\s1 Ìkìlọ̀ láti má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 20 \x - \xo 1.20,21: \xt Òw 8.1-3.\x*Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó
|
||
\q2 ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;
|
||
\q1
|
||
\v 21 láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde
|
||
\q2 ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 “Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó?
|
||
\q2 Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó?
|
||
\q2 Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?
|
||
\q1
|
||
\v 23 Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni,
|
||
\q2 ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín
|
||
\q2 kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè
|
||
\q2 kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,
|
||
\q1
|
||
\v 25 níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi,
|
||
\q2 tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,
|
||
\q1
|
||
\v 26 Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín;
|
||
\q2 èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle,
|
||
\q2 nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà,
|
||
\q2 nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 “Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn;
|
||
\q2 wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀
|
||
\q2 tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi
|
||
\q2 tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,
|
||
\q1
|
||
\v 31 wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn
|
||
\q2 wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún.
|
||
\q1
|
||
\v 32 Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n
|
||
\q2 ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;
|
||
\q1
|
||
\v 33 ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu
|
||
\q2 yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”
|
||
\c 2
|
||
\s2 Èrè ìwà rere tí ọgbọ́n ń mú wá
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi,
|
||
\q2 tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
|
||
\q1
|
||
\v 2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n
|
||
\q2 tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
|
||
\q1
|
||
\v 3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn,
|
||
\q2 tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
|
||
\q1
|
||
\v 4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà
|
||
\q2 tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nítorí \nd Olúwa\nd* ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n,
|
||
\q2 láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo,
|
||
\q2 Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́
|
||
\q2 Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́,
|
||
\q2 àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ
|
||
\q2 ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́
|
||
\q2 òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú,
|
||
\q2 lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
|
||
\q1
|
||
\v 13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin
|
||
\q2 láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
|
||
\q1
|
||
\v 14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú,
|
||
\q2 tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
|
||
\q1
|
||
\v 15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́
|
||
\q2 tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin,
|
||
\q2 àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
|
||
\q1
|
||
\v 17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀
|
||
\q2 tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú
|
||
\q2 ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere
|
||
\q2 kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà
|
||
\q2 àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà
|
||
\q2 a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.
|
||
\c 3
|
||
\s2 Àwọn àǹfààní ọgbọ́n mìíràn
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi.
|
||
\q2 Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà,
|
||
\q2 ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé
|
||
\q2 so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ,
|
||
\q2 kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 3.4: \xt Ro 12.17.\x*Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere
|
||
\q2 ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd* pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ
|
||
\q2 má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ
|
||
\q2 òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 \x - \xo 3.7: \xt Ro 12.16.\x*Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ
|
||
\q2 bẹ̀rù \nd Olúwa\nd* kí o sì kórìíra ibi.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ
|
||
\q2 àti okun fún àwọn egungun rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ,
|
||
\q1
|
||
\v 10 nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya
|
||
\q2 àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 \x - \xo 3.11,12: \xt Hb 12.5,6.\x*Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
|
||
\q1
|
||
\v 12 nítorí \nd Olúwa\nd* a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí
|
||
\q2 bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀,
|
||
\q2 ẹni tí ó tún ní òye sí i,
|
||
\q1
|
||
\v 14 nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ
|
||
\q2 ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ;
|
||
\q2 kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀;
|
||
\q2 ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura,
|
||
\q2 òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á;
|
||
\q2 àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Nípa ọgbọ́n, \nd Olúwa\nd* fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;
|
||
\q1
|
||
\v 20 nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà,
|
||
\q2 àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́,
|
||
\q2 má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ,
|
||
\q2 àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu,
|
||
\q2 ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù,
|
||
\q2 nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì,
|
||
\q2 tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Nítorí \nd Olúwa\nd* yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ,
|
||
\q2 kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ,
|
||
\q2 nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé,
|
||
\q2 “Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,”
|
||
\q2 nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ,
|
||
\q2 ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí,
|
||
\q2 nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 31 Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan
|
||
\q2 tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 32 Nítorí \nd Olúwa\nd* kórìíra ènìyàn aláyídáyidà
|
||
\q2 ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 33 Ègún \nd Olúwa\nd* ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.
|
||
\q1
|
||
\v 34 \x - \xo 3.34: \xt (Gk): Jk 4.6; 1Pt 5.5.\x*Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 35 Ọlọ́gbọ́n jogún iyì,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.
|
||
\c 4
|
||
\s2 Ọgbọ́n ni o ga jùlọ
|
||
\q1
|
||
\v 1 Tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ mi, sí ẹ̀kọ́ baba; fetísílẹ̀ kí o sì ní òye sí i.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Mo fún ọ ní ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro,
|
||
\q2 nítorí náà, má ṣe kọ ẹ̀kọ́ mi sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nígbà tí mo jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin ní ilé baba à mí,
|
||
\q2 mo jẹ́ èwe, tí mo sì jẹ́ ọ̀kan ṣoṣo lọ́wọ́ ìyá mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ó kọ́ mi ó sì wí pé,
|
||
\q2 “Jẹ́ kí àyà rẹ kí ó gba ọ̀rọ̀ mi dúró,
|
||
\q1 pa òfin mi mọ́, kí ìwọ kí ó sì yè.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Gba ọgbọ́n, gba òye,
|
||
\q2 má ṣe gbàgbé ọ̀rọ̀ mi tàbí kí o yẹsẹ̀ kúrò nínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀, yóò sì dáàbò bò ọ́,
|
||
\q2 fẹ́ràn rẹ̀, yóò sì bojútó ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ọgbọ́n ni ó ga jù; nítorí náà gba ọgbọ́n.
|
||
\q2 Bí ó tilẹ̀ ná gbogbo ohun tí o ní, gba òye.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Gbé e ga, yóò sì gbé ọ ga
|
||
\q2 dìrọ̀ mọ́ ọn, yóò sì bu iyì fún ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Yóò fi òdòdó ọ̀ṣọ́ ẹwà sí orí rẹ
|
||
\q2 yóò sì fi adé ẹlẹ́wà fún ọ.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Tẹ́tí, ọmọ mi, gba ohun tí mo sọ,
|
||
\q2 ọjọ́ ayé è rẹ yóò sì gùn.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Mo tọ́ ọ ṣọ́nà ní ọ̀nà ti ọgbọ́n
|
||
\q2 mo sì mú ọ lọ ní ọ̀nà ti tààrà.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nígbà tí o rìn, ìgbésẹ̀ rẹ kò ní ní ìdíwọ́
|
||
\q2 nígbà tí o bá sáré, ìwọ kì yóò kọsẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Di ẹ̀kọ́ mú, má ṣe jẹ́ kí ó lọ;
|
||
\q2 tọ́jú u rẹ̀ dáradára nítorí òun ni ìyè rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Má ṣe gbé ẹsẹ̀ rẹ sí ojú ọnà àwọn ènìyàn búburú
|
||
\q2 tàbí kí o rìn ní ọ̀nà àwọn ẹni ibi.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Yẹra fún un, má ṣe rìn níbẹ̀;
|
||
\q2 yàgò fún un kí o sì bá ọ̀nà tìrẹ lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nítorí wọn kò le sùn àyàfi tí wọ́n bá ṣe ibi,
|
||
\q2 wọn kò ní tòògbé àyàfi tí wọ́n bá gbé ẹlòmíràn ṣubú.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Wọ́n ń jẹ oúnjẹ ìwà búburú
|
||
\q2 wọ́n sì ń mu wáìnì ìwà ìkà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ipa ọ̀nà olódodo dàbí àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn
|
||
\q2 tí ń tànmọ́lẹ̀ sí i títí ọjọ́ fi kanrí
|
||
\q1
|
||
\v 19 ṣùgbọ́n ọ̀nà ènìyàn búburú dàbí òkùnkùn biribiri;
|
||
\q2 wọn kò mọ ohun tí ó ń mú wọn kọsẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ọmọ mi, tẹ́tí sí ohun tí mo sọ;
|
||
\q2 fetísílẹ̀ dáradára sí ọ̀rọ̀ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Má ṣe jẹ́ kí wọ́n rá mọ́ ọ lójú
|
||
\q2 pa wọ́n mọ́ sínú ọkàn rẹ,
|
||
\q1
|
||
\v 22 nítorí ìyè ni wọ́n jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó rí wọn
|
||
\q2 àti ìlera fún gbogbo ara ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ju gbogbo nǹkan tókù lọ, pa ọkàn rẹ mọ́,
|
||
\q2 nítorí òun ni orísun ìyè.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Mú àrékérekè kúrò ní ẹnu rẹ;
|
||
\q2 sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ jìnnà réré sí ẹnu rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Jẹ́ kí ojú rẹ máa wo iwájú,
|
||
\q2 jẹ́ kí ìwo ojú rẹ máa wo ọ̀kánkán iwájú rẹ sá á.
|
||
\q1
|
||
\v 26 \x - \xo 4.26: \xt (Gk): Hb 12.13.\x*Kíyèsi ìrìn ẹsẹ̀ rẹ
|
||
\q2 sì rìn ní àwọn ọ̀nà tí ó dára nìkan.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì;
|
||
\q2 pa ẹsẹ̀ rẹ mọ́ kúrò nínú ibi.
|
||
\c 5
|
||
\s2 Ìkìlọ̀ láti yàgò fún àgbèrè
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọmọ mi, fiyèsí ọgbọ́n mi,
|
||
\q2 kí o sì dẹtí rẹ sí òye mi,
|
||
\q1
|
||
\v 2 kí ìwọ sì lè ní ìṣọ́ra
|
||
\q2 kí ètè rẹ sì le pa ìmọ̀ mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí ètè àwọn àjèjì obìnrin a máa sun bi oyin,
|
||
\q2 ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì kúnná ju òróró lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín, ó korò ju òróǹró lọ,
|
||
\q2 ó mú bí idà olójú méjì.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà ikú
|
||
\q2 ìgbésẹ̀ rẹ̀ lọ tààrà sí ibojì òkú.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Kí ìwọ má ba à já ipa ọ̀nà ìyè;
|
||
\q2 ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla, ṣùgbọ́n kò tilẹ̀ mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nítorí náà, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ dẹtí sí mi,
|
||
\q2 kí ẹ̀yin kí ó má ṣe yàgò kúrò nínú ọ̀rọ̀ tí mo sọ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Rìn ní ọ̀nà tí ó jìnnà sí ti rẹ̀,
|
||
\q2 má ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 9 àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò gbé gbogbo ọlá rẹ lé ẹlòmíràn lọ́wọ́
|
||
\q2 àti ọjọ́ ayé rẹ fún ìkà ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Kí a má ba à fi ọrọ̀ rẹ fún àjèjì ènìyàn,
|
||
\q2 kí làálàá rẹ sì sọ ilé ẹlòmíràn di ọlọ́rọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ní ìgbẹ̀yìn ayé rẹ ìwọ yóò kérora,
|
||
\q2 nígbà tí agbára rẹ àti ara rẹ bá ti joro tán.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ìwọ yóò wí pé, “Mo ti kórìíra ẹ̀kọ́ tó!
|
||
\q2 Ọkàn mi ṣe wá kórìíra ìbáwí!
|
||
\q1
|
||
\v 13 N kò gbọ́rọ̀ sí àwọn olùkọ́ mi lẹ́nu,
|
||
\q2 tàbí kí n fetí sí àwọn tí ń kọ́ mi lẹ́kọ̀ọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Mo ti bẹ̀rẹ̀ ìparun pátápátá
|
||
\q2 ní àárín gbogbo àwùjọ ènìyàn.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Mu omi láti inú kànga tìrẹ,
|
||
\q2 omi tí ń sàn láti inú kànga rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ó ha yẹ kí omi ìsun rẹ kún àkúnya sí ojú ọ̀nà
|
||
\q2 àti odò tí ń sàn lọ sí àárín ọjà?
|
||
\q1
|
||
\v 17 Jẹ́ kí wọn jẹ́ tìrẹ nìkan,
|
||
\q2 má ṣe ṣe àjọpín wọn pẹ̀lú àjèjì láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Jẹ́ kí orísun rẹ kí ó ní ìbùkún;
|
||
\q2 kí ìwọ ó sì máa yọ nínú aya ìgbà èwe rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Abo àgbọ̀nrín tó dára, ìgalà tí ó wu ni jọjọ,
|
||
\q2 jẹ́ kí ọmú rẹ̀ kí ó máa fi ayọ̀ fún ọ nígbà gbogbo,
|
||
\q2 kí o sì máa yọ̀ nínú ìfẹ́ rẹ̀ nígbàkígbà.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ọmọ mi, èéṣe tí ìwọ ó fi máa yọ̀ nínú ìfẹ́ obìnrin panṣágà,
|
||
\q2 tí ìwọ ó sì fi dì mọ́ ìyàwó ẹlòmíràn?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Nítorí ọ̀nà ènìyàn kò fi ara sin rárá fún \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 Ó sì ń gbé gbogbo ọ̀nà rẹ̀ yẹ̀ wò.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ìwà búburú ènìyàn búburú ni yóò mú kó bọ́ sínú okùn;
|
||
\q2 okùn ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀ yóò sì dìímú.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Yóò kú ní àìgba ẹ̀kọ́
|
||
\q2 ìwà òmùgọ̀ ara rẹ̀ yóò sì mú kí ó máa ṣìnà kiri.
|
||
\c 6
|
||
\s2 Ìkìlọ̀ láti ṣọ́ra fún ìwà òmùgọ̀
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ,
|
||
\q2 bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,
|
||
\q1
|
||
\v 2 bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ,
|
||
\q2 tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ
|
||
\q2 níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ:
|
||
\q1 lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀;
|
||
\q2 bẹ aládùúgbò rẹ dáradára.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́,
|
||
\q2 tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ,
|
||
\q2 bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ;
|
||
\q2 kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!
|
||
\q1
|
||
\v 7 Kò ní olùdarí,
|
||
\q2 kò sí alábojútó tàbí ọba,
|
||
\q1
|
||
\v 8 síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò
|
||
\q2 yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ?
|
||
\q2 Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?
|
||
\q1
|
||
\v 10 Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,
|
||
\q2 ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà
|
||
\q2 àti àìní bí adigunjalè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú,
|
||
\q2 tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,
|
||
\q1
|
||
\v 13 tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò,
|
||
\q2 ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀
|
||
\q2 ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,
|
||
\q1
|
||
\v 14 tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀
|
||
\q2 ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn;
|
||
\q2 yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
|
||
\b
|
||
\li1
|
||
\v 16 Àwọn ohun mẹ́fà wà tí \nd Olúwa\nd* kórìíra,
|
||
\li2 ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i,
|
||
\li3
|
||
\v 17 Ojú ìgbéraga,
|
||
\li3 ahọ́n tó ń parọ́
|
||
\li3 ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,
|
||
\li3
|
||
\v 18 ọkàn tí ń pète ohun búburú,
|
||
\li3 ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,
|
||
\li3
|
||
\v 19 ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu
|
||
\li3 àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.
|
||
\s1 Ìkìlọ̀ nítorí àgbèrè
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́
|
||
\q2 má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé
|
||
\q2 so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ;
|
||
\q2 nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ;
|
||
\q2 nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà,
|
||
\q2 ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀,
|
||
\q2 àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí
|
||
\q2 ni ọ̀nà sí ìyè.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú,
|
||
\q2 kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ
|
||
\q2 tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan
|
||
\q2 kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná?
|
||
\q2 Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?
|
||
\q1
|
||
\v 29 Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya;
|
||
\q2 kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè
|
||
\q2 nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje
|
||
\q2 bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.
|
||
\q1
|
||
\v 32 Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú;
|
||
\q2 ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni.
|
||
\q1
|
||
\v 33 Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀,
|
||
\q2 ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 34 Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè,
|
||
\q2 kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.
|
||
\q1
|
||
\v 35 Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn;
|
||
\q2 yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.
|
||
\c 7
|
||
\s2 Ìkìlọ̀ nítorí àwọn aṣẹ́wó
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́,
|
||
\q2 sì fi àwọn òfin mi pamọ́ sínú ọkàn rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yè
|
||
\q2 tọ́jú ẹ̀kọ́ mi bí ẹyinlójú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹun
|
||
\q2 kọ wọ́n sí inú wàláà àyà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,”
|
||
\q2 sì pe òye ní ìbátan rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè,
|
||
\q2 kúrò lọ́wọ́ àjèjì obìnrin àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ní ojú fèrèsé ilé è mi
|
||
\q2 mo wo ìta láti ojú fèrèsé.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Mo rí i láàrín àwọn aláìmọ̀kan
|
||
\q2 mo sì kíyèsi láàrín àwọn ọ̀dọ́kùnrin,
|
||
\q2 ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbèrè obìnrin náà,
|
||
\q2 ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀,
|
||
\q2 bí òkùnkùn ṣe ń bo ni lára.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀,
|
||
\q2 ó múra bí panṣágà pẹ̀lú ètè búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 11 (Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí,
|
||
\q2 ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;
|
||
\q1
|
||
\v 12 bí ó ti ń já níhìn-ín ní ó ń já lọ́hùn ún
|
||
\q2 gbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ó dìímú, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu
|
||
\q1 pẹ̀lú ojú díndín ó wí pé,
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 “Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé;
|
||
\q2 lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Nítorí náà ni n o ṣe jáde wá pàdé è rẹ;
|
||
\q2 mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!
|
||
\q1
|
||
\v 16 Mo ti tẹ́ ibùsùn mi
|
||
\q2 pẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Ejibiti.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Mo ti fi nǹkan olóòórùn dídùn sí ibùsùn mi
|
||
\q2 bí i òjìá, aloe àti kinamoni.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀;
|
||
\q2 jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé;
|
||
\q2 ó ti lọ sí ìrìnàjò jíjìn.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ó mú owó púpọ̀ lọ́wọ́
|
||
\q2 kò sì ní darí dé kí ó tó di ọ̀sán.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ dídùn ó sì í lọ́nà;
|
||
\q2 ó tàn án jẹ pẹ̀lú ẹnu dídùn.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Òun sì tọ̀ ọ́ lọ lẹsẹ̀ kan náà,
|
||
\q2 bí i màlúù tí ń lọ sí ibi pípa,
|
||
\q2 tàbí bí àgbọ̀nrín tí ń lọ sí ibi okùn ìso.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Títí tí ọ̀kọ̀ fi gún un ní ẹ̀dọ̀,
|
||
\q2 bí ẹyẹ ṣe ń fẹ́ wọ inú okùn,
|
||
\q2 láìmọ̀ pé yóò gba ẹ̀mí òun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Nítorí náà báyìí ẹ̀yin ọmọ mi, tẹ́tí sí mi
|
||
\q2 fọkàn sí nǹkan tí mo sọ.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yà sí ọ̀nà rẹ̀,
|
||
\q2 tàbí kí ó rìn lọ sí ipa ọ̀nà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó ti fà lulẹ̀.
|
||
\q2 Ogunlọ́gọ̀ àwọn alágbára ni ó ti pa.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ilé e rẹ̀ ni ọ̀nà tààrà sí isà òkú,
|
||
\q2 tí ó lọ tààrà sí àgbàlá ikú.
|
||
\c 8
|
||
\s2 Ọgbọ́n n fi ìpè síta
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 8.1-3: \xt Òw 1.20,21.\x*Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta?
|
||
\q2 Òye kò ha ń gbé ohùn rẹ sókè?
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà,
|
||
\q2 ní ìkóríta, ní ó dúró;
|
||
\q1
|
||
\v 3 ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú,
|
||
\q2 ní ẹnu ibodè ni ó ń kígbe sókè:
|
||
\q1
|
||
\v 4 “Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè;
|
||
\q2 mo gbé ohun mi sókè sí gbogbo ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n;
|
||
\q2 ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹ gba òye.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye;
|
||
\q2 Èmí ṣí ètè mi láti sọ ohun tí ó tọ́,
|
||
\q1
|
||
\v 7 ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́,
|
||
\q2 nítorí ètè mi kórìíra ibi.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́,
|
||
\q2 kò sí èyí tí ó jẹ́ ẹ̀tàn tàbí àyídáyidà níbẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà;
|
||
\q2 wọ́n jẹ́ aláìlẹ́gàn fún gbogbo ẹni tí ó ní ìmọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà,
|
||
\q2 ìmọ̀ dípò o wúrà àṣàyàn,
|
||
\q1
|
||
\v 11 nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ,
|
||
\q2 kò sí ohun tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ tí a sì le fiwé e.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 “Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye;
|
||
\q2 mo ní ìmọ̀ àti ọgbọ́n-inú.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* ni ìkórìíra ibi
|
||
\q2 mo kórìíra ìgbéraga àti agídí,
|
||
\q2 ìwà ibi àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi
|
||
\q2 mo ní òye àti agbára.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso
|
||
\q2 tí àwọn aláṣẹ sì ń ṣe òfin tí ó dára.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso,
|
||
\q2 àti gbogbo ọlọ́lá tí ń ṣàkóso ilẹ̀ ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi,
|
||
\q2 àwọn tí ó sì wá mi rí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà,
|
||
\q2 ọrọ̀ tí í tọ́jọ́ àti ìgbéga rere.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ;
|
||
\q2 ohun tí mò ń mú wá ju àṣàyàn fàdákà lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo,
|
||
\q2 ní ojú ọ̀nà òtítọ́,
|
||
\q1
|
||
\v 21 mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi
|
||
\q2 mo sì ń mú kí ilé ìṣúra wọn kún.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 “Èmi ni \nd Olúwa\nd* kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀.
|
||
\q2 Ṣáájú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àtijọ́;
|
||
\q1
|
||
\v 23 a ti yàn mí láti ayérayé,
|
||
\q2 láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ayé tó bẹ̀rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi,
|
||
\q2 nígbà tí kò tí ì sí ìsun tí ó ní omi nínú;
|
||
\q1
|
||
\v 25 kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn,
|
||
\q2 ṣáájú àwọn òkè ni a ti bí mi,
|
||
\q1
|
||
\v 26 kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀
|
||
\q2 tàbí èyíkéyìí nínú eruku ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn,
|
||
\q2 nígbà tí ó fi òsùwọ̀n àyíká sórí ibú omi,
|
||
\q1
|
||
\v 28 nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè
|
||
\q2 tí ó sì fi orísun ibú omi sí ipò rẹ̀ láì le è yẹsẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 29 nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun
|
||
\q2 kí omi má ba à kọjá ààlà àṣẹ rẹ̀,
|
||
\q2 àti nígbà tí ó pààlà ìpìlẹ̀ ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀
|
||
\q2 mo kún fún inú dídùn lójoojúmọ́,
|
||
\q2 mo ń yọ̀ nígbà gbogbo níwájú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá
|
||
\q2 mo sì ní inú dídùn sí àwọn ọmọ ènìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 32 “Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi,
|
||
\q2 ìbùkún ni fún àwọn tí ó pa ọ̀nà mi mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 33 Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n;
|
||
\q2 má ṣe pa á tì sápá kan.
|
||
\q1
|
||
\v 34 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi,
|
||
\q2 tí ń ṣọ́nà ní ẹnu-ọ̀nà mi lójoojúmọ́,
|
||
\q2 tí ń dúró ní ẹnu-ọ̀nà mi.
|
||
\q1
|
||
\v 35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè
|
||
\q2 ó sì rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 36 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára
|
||
\q2 gbogbo ẹni tí ó kórìíra mi fẹ́ ikú.”
|
||
\c 9
|
||
\s2 Ìpè ti ọgbọ́n àti àìgbọ́n
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọgbọ́n ti kọ́ ilé rẹ̀,
|
||
\q2 ó ti gbẹ́ òpó o rẹ̀ méjèèjì,
|
||
\q1
|
||
\v 2 ó ti fi ilé pọn tí, ó ti fọ̀nà rokà.
|
||
\q2 Ó sì ti ṣètò o tábìlì oúnjẹ rẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 3 ó ti rán àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ jáde, ó sì ń pè,
|
||
\q2 láti ibi tí ó ga jù láàrín ìlú.
|
||
\q1
|
||
\v 4 “Jẹ́ kí gbogbo àwọn aláìgbọ́n wọ ibí wá!”
|
||
\q2 Ó ń wí fún àwọn tí kò lọ́gbọ́n pé,
|
||
\q1
|
||
\v 5 “Wá, ẹ wá jẹ́ oúnjẹ mi
|
||
\q2 sì mu wáìnì tí mo ti pò.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Fi ìwà àìmọ̀kan rẹ sílẹ̀ ìwọ yóò sì yè;
|
||
\q2 rìn ní ọ̀nà òye.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹlẹ́gàn wí, kọ lẹ́tà sí àbùkù
|
||
\q2 ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹni búburú wí kọ lẹ́tà sí èébú.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Má ṣe bá ẹlẹ́gàn wí, àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò kórìíra rẹ.
|
||
\q2 Bá ọlọ́gbọ́n wí yóò sì fẹ́ràn rẹ;
|
||
\q1
|
||
\v 9 kọ́ ọlọ́gbọ́n ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì gbọ́n sí i
|
||
\q2 kọ́ olódodo ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì fi kún ìmọ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 “Ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n,
|
||
\q2 ìmọ̀ nípa Ẹni Mímọ́ ni òye.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Nítorí nípasẹ̀ mi ọjọ́ rẹ yóò gùn
|
||
\q2 ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún yóò sì kún ọjọ́ ayé rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Bí ìwọ bá gbọ́n, ọgbọ́n rẹ yóò fún ọ ní èrè:
|
||
\q2 bí ìwọ bá jẹ́ ẹlẹ́gàn, ìwọ nìkan ni yóò jìyà.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Òmùgọ̀ obìnrin jẹ́ aláriwo;
|
||
\q2 ó jẹ́ aláìlẹ́kọ̀ọ́ àti aláìní ìmọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ó jókòó ní ẹnu-ọ̀nà ilé rẹ̀
|
||
\q2 lórí ìjókòó níbi tí ó ga jù láàrín ìlú,
|
||
\q1
|
||
\v 15 ó ń pe àwọn tí ó ń kọjá lọ,
|
||
\q2 tí wọn ń lọ tààrà ní ọ̀nà wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 16 “Jẹ́ kí gbogbo ẹni tí ó jẹ́ aláìlóye súnmọ́ bí!”
|
||
\q2 Ni ó wí fún ẹni tí òye kù díẹ̀ ká à tó fún.
|
||
\q1
|
||
\v 17 “Omi tí a jí mu dùn
|
||
\q2 oúnjẹ tí a jẹ ní ìkọ̀kọ̀ a máa ládùn!”
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ṣùgbọ́n wọn ò funra pé àwọn òkú wà níbẹ̀,
|
||
\q2 pé àwọn àlejò rẹ̀ wà ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ isà òkú.
|
||
\c 10
|
||
\ms1 Àwọn òwe Solomoni
|
||
\p
|
||
\v 1 Àwọn òwe Solomoni.
|
||
\q1 Ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú baba rẹ̀ dùn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aṣiwèrè ọmọ ń ba inú ìyá rẹ̀ jẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 \nd Olúwa\nd* kì í jẹ́ kí ebi máa pa olódodo,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó ba ète àwọn ènìyàn búburú jẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di tálákà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọwọ́ tí ó múra ṣíṣẹ́ a máa sọ ni di ọlọ́rọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ ọlọ́gbọ́n ọmọ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó sùn ní àsìkò ìkórè jẹ́ adójútini ọmọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìbùkún ní ó máa ń kún orí olódodo,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwà ipá máa ń kún ẹnu ènìyàn búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìrántí olódodo yóò jẹ́ ìbùkún,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n orúkọ ènìyàn búburú yóò jẹrà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ètè wérewère yóò parun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ẹni tí ó ń rìn déédé, ń rìn láìléwu,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àṣírí ẹni tí ń rin ọ̀nà pálapàla yóò tú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ẹni tí ń ṣẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn,
|
||
\q2 aláìgbọ́n tí ń ṣàròyé kiri yóò parun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwà ipá ni ó gba gbogbo ẹnu ènìyàn búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìfẹ́ a máa bo gbogbo àṣìṣe mọ́lẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n kùmọ̀ wà fún ẹ̀yìn àwọn aláìlóye.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n a máa ṣokùnfà ìparun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ọrọ̀ àwọn olódodo ni ìlú olódi wọn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n òsì ni ìparun aláìní.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Èrè olódodo ń mú ìyè wá fún wọn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èrè ènìyàn búburú ń mú ìjìyà wá fún wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ ìbáwí mú àwọn mìíràn ṣìnà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́
|
||
\q2 ẹni tí ó sì ń ba ni jẹ́ jẹ́ aláìgbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ètè olódodo jẹ́ ààyò fàdákà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú kò níye lórí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ètè olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ìbùkún \nd Olúwa\nd* ń mú ọrọ̀ wá,
|
||
\q2 kì í sì í fi ìdààmú sí i.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a;
|
||
\q2 olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n a gé ọjọ́ ayé ènìyàn búburú kúrú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ìrètí olódodo ni ayọ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú jásí òfo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Ọ̀nà \nd Olúwa\nd* jẹ́ ààbò fún olódodo,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìparun ni ó jẹ́ fún àwọn tí ń ṣe ibi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 A kì yóò fa olódodo tu láéláé,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kì yóò dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 31 Ẹnu olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ètè àyípadà ni a ó gé kúrò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 32 Ètè olódodo mọ ohun ìtẹ́wọ́gbà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ètè ènìyàn búburú kò mọ̀ ju èké lọ.
|
||
\b
|
||
\c 11
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd* kórìíra òsùwọ̀n èké,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n òsùwọ̀n òtítọ́ jẹ́ inú dídùn un rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nígbà tí ìgbéraga bá dé, nígbà náà ni ìdójútì dé,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrẹ̀lẹ̀ ni ọgbọ́n ń wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Òtítọ́ inú ẹni dídúró ṣinṣin ń ṣe amọ̀nà rẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aláìṣòótọ́ yóò parun nípasẹ̀ àìṣòótọ́ wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ọ̀rọ̀ kò níláárí ní ọjọ́ ìbínú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Òdodo aláìlẹ́gàn ṣe ọ̀nà tààrà fún wọn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwà búburú ènìyàn búburú yóò fà á lulẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Òdodo ẹni ìdúró ṣinṣin gbà wọ́n là,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìdẹ̀kùn ètè búburú mú aláìṣòótọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nígbà tí ènìyàn búburú bá kú, ìrètí rẹ̀ a parun;
|
||
\q2 gbogbo ohun tó ń fojú ṣọ́nà fún nípa agbára rẹ̀ já ṣófo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 A gba olódodo kúrò lọ́wọ́ ibi dípò o rẹ̀,
|
||
\q2 ibi wá sórí ènìyàn búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Aláìmọ Ọlọ́run fi ẹnu rẹ̀ ba aládùúgbò rẹ̀ jẹ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ìmọ̀ olódodo sá àsálà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nígbà tí olódodo ń gbèrú, ìlú a yọ̀;
|
||
\q2 nígbà tí ènìyàn búburú parun, ariwo ayọ̀ gba ìlú kan.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Nípasẹ̀ ìbùkún, olódodo a gbé ìlú ga:
|
||
\q2 ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ẹnu ènìyàn búburú, a pa ìlú run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ẹni tí kò gbọ́n fojú kékeré wo aládùúgbò rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó ní òye pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Olófòófó tú àṣírí ìkọ̀kọ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tó ṣe é gbẹ́kẹ̀lé a pa àṣírí mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Nítorí àìní ìtọ́sọ́nà orílẹ̀-èdè ṣubú
|
||
\q2 ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn ìṣẹ́gun dájú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ fún àlejò yóò rí ìyọnu,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kọ̀ láti ṣe onígbọ̀wọ́ yóò wà láìléwu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Obìnrin oníwà rere gba ìyìn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n alágbára aláìbìkítà ènìyàn gba ọrọ̀ nìkan.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ènìyàn rere ń ṣe ara rẹ̀ lóore
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ènìyàn ìkà ń mú ìyọnu wá sórí ara rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ènìyàn búburú gba èrè ìtànjẹ
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tó fúnrúgbìn òdodo yóò gba èrè tó dájú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Olódodo tòótọ́ rí ìyè
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa ibi lé e sí ibi ikú ara rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 \nd Olúwa\nd* kórìíra àwọn ènìyàn ọlọ́kàn búburú
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn tí ọ̀nà wọn kò lábùkù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Mọ èyí dájú pé, ènìyàn búburú kì yóò lọ láìjìyà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn olódodo yóò lọ láìjìyà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Bí òrùka wúrà ní imú ẹlẹ́dẹ̀
|
||
\q2 ni arẹwà obìnrin tí kò lọ́gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ìfẹ́ inú olódodo yóò yọrí sí ohun rere
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú yóò yọrí sí ìbínú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ènìyàn kan ń fún ni lọ́fẹ̀ẹ́, síbẹ̀ ó ń ní sí i;
|
||
\q2 òmíràn ń háwọ́ ju bí ó ti yẹ ṣùgbọ́n ó di aláìní.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ẹni tí ń ṣoore yóò máa gbèrú sí i;
|
||
\q2 ẹni tí ó tu ẹlòmíràn lára yóò ní ìtura.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Àwọn ènìyàn a ṣẹ́ èpè lé ènìyàn tí ń kó oúnjẹ pamọ́
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìbùkún a máa wá sórí ẹni tí ó ṣetán láti tà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ẹni tí ń lépa ohun rere yóò rí ohun rere
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ibi yóò dé bá ẹni tí ń lépa ibi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ yóò ṣubú;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olódodo yóò gbilẹ̀ bí i koríko tútù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Ẹni tí ó ń mú ìdààmú dé bá ìdílé rẹ̀ yóò jogún afẹ́fẹ́ lásán
|
||
\q2 aláìgbọ́n yóò sì máa ṣe ìránṣẹ́ fún ọlọ́gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Èso òdodo ni igi ìyè
|
||
\q2 ẹni tí ó sì jèrè ọkàn jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 31 \x - \xo 11.31: \xt (Gk): 1Pt 4.18.\x*Bí àwọn olódodo bá gba ìpín wọn lórí ilẹ̀ ayé
|
||
\q2 mélòó mélòó ni ènìyàn búburú àti àwọn tó dẹ́ṣẹ̀!
|
||
\b
|
||
\c 12
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹnikẹ́ni tí ó fẹ́ ẹ̀kọ́ fẹ́ ìmọ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kórìíra ìbáwí jẹ́ aláìgbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ènìyàn rere gba ojúrere lọ́dọ̀ \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ènìyàn ètè búburú ni yóò dá lẹ́bi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 A kò lè fi ẹsẹ̀ ènìyàn múlẹ̀ nípa ìwà búburú
|
||
\q2 ṣùgbọ́n a kò le è fa olódodo tu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Aya oníwà rere ni adé ọkọ rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aya adójútini dàbí inú egungun rẹ̀ jẹrà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Èrò àwọn olódodo tọ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìgbìmọ̀ ènìyàn búburú jẹ́ ẹ̀tàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọ̀rọ̀ ènìyàn búburú lúgọ de ẹ̀jẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ àwọn olódodo gbà wọ́n là.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 A ṣí àwọn ènìyàn búburú ní ìdí, wọn kò sì sí mọ́;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ilé olódodo dúró ṣinṣin.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 A ń yín ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀n ọgbọ́n rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ọlọ́pọlọ wúruwùru ni a kẹ́gàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ó sàn kí a má jẹ́ ènìyàn pàtàkì kí a sì ní ìránṣẹ́
|
||
\q2 ju kí a díbọ́n pé a jẹ́ ẹni pàtàkì láìní oúnjẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Olódodo ènìyàn ń ṣe aájò ohun tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ nílò,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìyọ́nú àwọn ènìyàn búburú, ìkà ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ẹni tí ó bá dá oko yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa òjìji lásán làsàn kò gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ènìyàn búburú ń fẹ́ ìkógun àwọn ènìyàn ìkà
|
||
\q2 ṣùgbọ́n gbòǹgbò olódodo ń gbilẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 A mú ènìyàn búburú nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olódodo bọ́ kúrò lọ́wọ́ ìdààmú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Láti inú èso rẹ̀, ènìyàn kún fún onírúurú ohun rere
|
||
\q2 bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ti ń pín in lérè dájúdájú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ọ̀nà aláìgbọ́n dára lójú ara rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa gba ìmọ̀ràn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Aláìgbọ́n ènìyàn fi ìbínú un rẹ̀ hàn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olóye ènìyàn fojú fo ìyànjẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ẹni tí ó jẹ́ ajẹ́rìí òtítọ́ jẹ́rìí ohun tí ojú rẹ̀ rí
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ajẹ́rìí èké máa ń parọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ọ̀rọ̀ tí a kò rò jinlẹ̀ máa ń gún ni bí ọ̀kọ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ahọ́n ọlọ́gbọ́n ń mú ìwòsàn wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ètè tí ń ṣọ òtítọ́ yóò wà láéláé
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ahọ́n tí ń parọ́ kì í tọ́jọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ẹ̀tàn wà nínú ọkàn àwọn tí ń pète búburú
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ayọ̀ wà fún àwọn tí ń mú kí àlàáfíà gbilẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ibi kì í ṣubú lu olódodo rárá
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ènìyàn búburú gba ìpín ìyọnu tiwọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 \nd Olúwa\nd* kórìíra ètè tí ń parọ́
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn olóòtítọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ènìyàn olóye fi ìmọ̀ rẹ̀ pamọ́ sínú ara rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú ń gbé ìwà òmùgọ̀ jáde.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ọwọ́ àìṣọ̀lẹ yóò jẹ ọba
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀lẹ ṣíṣe a máa yọrí sí ẹrú ṣíṣe.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ìbànújẹ́ ní ọkàn ènìyàn ní dorí rẹ̀ kodò
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ rere a máa mú kó yọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Olódodo ènìyàn máa ń ṣọ́ra láti dọ́rẹ̀ẹ́
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ń mú wọn ṣìnà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ọ̀lẹ ènìyàn kò sun ẹran tí ó pa lóko ọdẹ
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí kì í ṣe ọ̀lẹ máa ń díwọ̀n ohun ìní rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ní ọ̀nà àwọn olódodo ni ìyè wà
|
||
\q2 ní ọ̀nà náà ni àìkú wà.
|
||
\b
|
||
\c 13
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọlọ́gbọ́n ọmọ gba ẹ̀kọ́ baba rẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹlẹ́gàn kò gbọ́ ìbáwí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ènìyàn ń gbádùn ohun rere,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n, ìfẹ́ ọkàn aláìṣòótọ́ ní ìwà ipá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹnikẹ́ni tí ó ṣọ́ ẹnu rẹ̀ pa ẹnu ara rẹ̀ mọ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ gbàù gbàù yóò parun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ọkàn ọ̀lẹ ń fẹ́, ṣùgbọ́n kò rí nǹkan kan,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọkàn àwọn ti kì í ṣe ọ̀lẹ rí ìtẹ́lọ́rùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Olódodo kórìíra ohun tí í ṣe irọ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ènìyàn búburú hu ìwà ìríra àti ìtìjú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Òdodo ń ṣamọ̀nà ènìyàn olóòtítọ́ inú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwà búburú ṣí ẹlẹ́ṣẹ̀ ní ipò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ènìyàn kan díbọ́n bí ẹni tí ó ní ọrọ̀ síbẹ̀ kò ní nǹkan kan
|
||
\q2 ẹlòmíràn díbọ́n bí i tálákà, síbẹ̀ ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ọrọ̀ ènìyàn le è ra ẹ̀mí rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n tálákà kì í gbọ́ ìdẹ́rùbà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìmọ́lẹ̀ olódodo tàn roro,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n fìtílà ènìyàn búburú ni a pa kú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìgbéraga máa ń dá ìjà sílẹ̀ ni
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọgbọ́n wà nínú àwọn tí ń gba ìmọ̀ràn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Owó tí a fi ọ̀nà èrú kójọ yóò ṣí lọ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ń kó owó jọ díẹ̀díẹ̀ yóò pọ̀ sí i.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ìrètí tí ń falẹ̀ máa ń mú kí ọkàn ṣàárẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìrètí tí a rí gbà jẹ́ igi ìyè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ẹni tí ó kẹ́gàn ẹ̀kọ́ yóò jìyà rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa àṣẹ mọ́ gba èrè rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ìkọ́ni ọlọ́gbọ́n jẹ́ orísun ìyè,
|
||
\q2 tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìdẹ̀kùn ikú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Òye pípé ń mú ni rí ojúrere,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀nà aláìṣòótọ́ kì í tọ́jọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Gbogbo olóye ènìyàn máa ń hùwà pẹ̀lú ìmọ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aláìgbọ́n a fi ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ hàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ìránṣẹ́ búburú bọ́ sínú ìdààmú
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aṣojú olóòtítọ́ mú ìwòsàn wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ẹni tí ó kọ ìbáwí yóò di tálákà yóò sì rí ìtìjú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí ni yóò rí ọlá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ìfẹ́ tí a mú ṣẹ dùn mọ́ ọkàn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìríra ni fún aṣiwèrè láti kúrò nínú ibi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ẹni tí ó ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ń bá aláìgbọ́n kẹ́gbẹ́ ń pa ara rẹ̀ lára.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Òsì a máa ta ẹlẹ́ṣẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọrọ̀ ni èrè fún olódodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ènìyàn rere a máa fi ogún sílẹ̀ fún àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n, a kó ọrọ̀ àwọn tó dẹ́ṣẹ̀ pamọ́ fún àwọn olódodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ilẹ̀ ẹ tálákà le è mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìre oko wá
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àìṣòdodo gbá gbogbo rẹ̀ lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ẹni tí ó fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kórìíra ọmọ rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó fẹ́ràn ọmọ rẹ̀ yóò máa bá a wí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Olódodo jẹ́wọ́ títí ó fi tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ikùn ènìyàn búburú.
|
||
\b
|
||
\c 14
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọlọ́gbọ́n obìnrin kọ́ ilé e rẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aṣiwèrè obìnrin fi ọwọ́ ara rẹ̀ fà á lulẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹni tí ń rìn déédé bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ kò tọ́ kẹ́gàn \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọ̀rọ̀ aṣiwèrè a máa ṣokùnfà pàṣán fún ẹ̀yìn rẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ètè ọlọ́gbọ́n a máa dáàbò bò ó.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Níbi tí kò sí ẹran, ibùjẹ ẹran a máa mọ́ tónítóní,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n, nípa agbára akọ màlúù ni ọ̀pọ̀ ìkórè ti ń wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹlẹ́rìí tí ń ṣọ òtítọ́ kì í tan ni
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí èké a máa tú irọ́ jáde.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ẹlẹ́gàn ń wá ọgbọ́n kò sì rí rárá,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìmọ̀ máa ń wà fún olóye.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Má ṣe súnmọ́ aláìgbọ́n ènìyàn,
|
||
\q2 nítorí ìwọ kì yóò rí ìmọ̀ ní ètè rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ọgbọ́n olóye ni láti ronú jinlẹ̀ nípa ọ̀nà wọn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ aṣiwèrè ni ìtànjẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Aláìgbọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ nígbà tí ó yẹ kí ó ṣe àtúnṣe ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n láàrín àwọn olódodo ni a ti rí ojúrere.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ọkàn kọ̀ọ̀kan ló mọ ẹ̀dùn ọkàn tirẹ̀
|
||
\q2 kò sì ṣí ẹnìkan tó le è bá ọkàn mìíràn pín ayọ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 A ó pa ilé ènìyàn búburú run,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àgọ́ olódodo yóò máa gbèrú sí i.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ọ̀nà kan wà tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín, a máa jásí ikú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Kódà nígbà tí a ń rẹ́rìn-ín, ọkàn le è máa kérora;
|
||
\q2 ayọ̀ sì le è yọrí sí ìbànújẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 A ó san án lẹ́kùnrẹ́rẹ́ fún aláìgbàgbọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀,
|
||
\q2 ènìyàn rere yóò sì gba èrè fún tirẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Òpè ènìyàn gba ohun gbogbo gbọ́
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olóye ènìyàn ronú lórí àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ọlọ́gbọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run ó sì kórìíra ibi
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aláìgbọ́n jẹ́ alágídí àti aláìṣọ́ra.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ẹni tí ó máa ń tètè bínú máa ń hùwà aṣiwèrè,
|
||
\q2 a sì kórìíra eléte ènìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Òpè jogún ìwà òmùgọ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n a dé ọlọ́gbọ́n ní adé ìmọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ènìyàn ìkà yóò tẹríba níwájú àwọn ènìyàn rere
|
||
\q2 àti ènìyàn búburú níbi ìlẹ̀kùn àwọn olódodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Kódà àwọn aládùúgbò tálákà kò fẹ́ràn rẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n, ọlọ́rọ̀ ní ọ̀rẹ́ púpọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ẹni tí ó kẹ́gàn aládùúgbò o rẹ̀ ti dẹ́ṣẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ẹni tí ó ṣàánú àwọn aláìní.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ǹjẹ́ àwọn tí ń pète ibi kì í ṣìnà bí?
|
||
\q2 Ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbèrò ohun rere ń rí ìfẹ́ àti òtítọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Gbogbo iṣẹ́ àṣekára ló máa ń mú èrè wá,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹjọ́ rírò lásán máa ń ta ni lósì ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ọrọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn ni adé orí wọn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwà aláìgbọ́n ń mú ìwà òmùgọ̀ wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ẹlẹ́rìí tí ó ṣọ òtítọ́ gba ẹ̀mí là
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí èké jẹ́ ẹlẹ́tàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Nínú ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* ni ìgbẹ́kẹ̀lé tí ó lágbára,
|
||
\q2 yóò sì tún jẹ́ ibi ààbò fún àwọn ọmọ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* jẹ́ orísun ìyè,
|
||
\q2 tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìkẹ́kùn ikú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ènìyàn púpọ̀ ní ìlú jẹ́ ògo ọba,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n láìsí ìjòyè, ọba á parun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Onísùúrù ènìyàn ní òye tí ó pọ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n onínú-fùfù ènìyàn máa ń fi ìwà aṣiwèrè hàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Ọkàn tí ó lálàáfíà fi ìyè mú kí ọjọ́ ayé gùn fún ara,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìlara mú kí egungun jẹrà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 31 Ẹni tí ó fi ìyà jẹ aláìní ń fi ìkórìíra hàn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó ṣoore fún aláìní bu ọlá fún Ọlọ́run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 32 Nígbà tí ìyọnu bá dé, a fa àwọn búburú lulẹ̀,
|
||
\q2 kódà nínú ikú àwọn olódodo ni ààbò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 33 Ọgbọ́n wà nínú ọkàn olóye
|
||
\q2 kódà láàrín àwọn aláìlóye, ó jẹ́ kí wọn mọ òun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 34 Òdodo a máa gbé orílẹ̀-èdè lékè,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìtìjú ni ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́ fún àwùjọ káwùjọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 35 Ọba a máa ní inú dídùn sí ìránṣẹ́ tí ó gbọ́n
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ wá sórí ìránṣẹ́ adójútini.
|
||
\b
|
||
\c 15
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìdáhùn pẹ̀lẹ́ yí ìbínú padà
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ líle máa ń ru ìbínú sókè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ahọ́n ọlọ́gbọ́n a máa gbé ìmọ̀ jáde
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń tú ọ̀rọ̀ ọ òmùgọ̀ jáde.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ojú \nd Olúwa\nd* wà níbi gbogbo,
|
||
\q2 Ó ń wo àwọn ẹni búburú àti àwọn ẹni rere.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ahọ́n tí ń mú ìtura wá jẹ́ igi ìyè
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ahọ́n ẹ̀tàn ń pa ẹ̀mí run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Aláìgbọ́n ọmọ kọ ìbáwí baba rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ilé olódodo kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìṣúra,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èrè àwọn ènìyàn búburú ń mú ìyọnu wá fún wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ètè olódodo ń tan ìmọ̀ kalẹ̀;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n kò rí bẹ́ẹ̀ fún ọkàn aláìgbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 \nd Olúwa\nd* kórìíra ìrúbọ àwọn ènìyàn búburú
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àdúrà olódodo tẹ́ ẹ lọ́rùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 \nd Olúwa\nd* kórìíra ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó fẹ́ràn àwọn tí ń lépa òdodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ẹni tí ó kúrò lójú ọ̀nà yóò rí ìbáwí gan an,
|
||
\q2 ẹni tí ó kórìíra ìbáwí yóò kú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ikú àti ìparun ṣí sílẹ̀ níwájú \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 mélòó mélòó ní nínú ọkàn àwọn ènìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ẹlẹ́gàn kò fẹ́ ẹni tí ń ba wí:
|
||
\q2 kò ní gbàmọ̀ràn lọ́dọ̀ ọlọ́gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Inú dídùn máa ń mú kí ojú túká
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìbànújẹ́ ọkàn máa ń pa ẹ̀mí run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ọkàn olóye ń wá ìmọ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń fẹ́ ìwà òmùgọ̀ bí ẹní jẹun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Gbogbo ọjọ́ àwọn olùpọ́njú jẹ́ ibi,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n onínúdídùn ń jẹ àlàáfíà ní ìgbà gbogbo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ó sàn kí ó má pọ̀, kí ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* sì wà
|
||
\q2 ju ọrọ̀ púpọ̀ pẹ̀lú ìyọnu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Oúnjẹ ewébẹ̀ níbi tí ìfẹ́ wà
|
||
\q2 sàn ju àbọ́pa màlúù tòun ti ìríra.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ènìyàn onínú ríru dá ìjà sílẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n onísùúrù paná ìjà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ọ̀nà ọ̀lẹ ni ẹ̀gún dí,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀nà olódodo já geerege ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ọlọ́gbọ́n ọmọ mú inú baba rẹ̀ dùn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aṣiwèrè ènìyàn kẹ́gàn ìyá rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Inú ènìyàn aláìlóye a máa dùn sí ìwà òmùgọ̀;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa rin ọ̀nà tààrà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ìgbèrò a máa dasán níbi tí kò sí ìmọ̀ràn;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n a máa yege níbi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn wà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Inú ènìyàn a máa dùn nígbà tí ó bá fèsì tó yẹ
|
||
\q2 ọ̀rọ̀ tí ó bá sì wá lásìkò tó yẹ dára púpọ̀!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ọ̀nà ìyè ń lọ sókè fún ọlọ́gbọ́n
|
||
\q2 láti sọ kí ó má bá à sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 \nd Olúwa\nd* fa ilé onígbèéraga ya lulẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó pa ààlà opó onírẹ̀lẹ̀ mọ́ láìyẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 \nd Olúwa\nd* kórìíra èrò ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n mímọ́ ni ọ̀rọ̀ ẹni pípé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ọ̀kánjúwà ènìyàn mú ìyọnu bá ilé rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóò yè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ọkàn olódodo ń wọn ìdáhùn wò
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹnu ènìyàn búburú ń tú ibi jáde.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 \nd Olúwa\nd* jìnnà sí ènìyàn búburú
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó ń gbọ́ àdúrà olódodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Ojú tó túká máa ń mú ayọ̀ wá fún ọkàn,
|
||
\q2 ìròyìn ayọ̀ sì ń mú ìlera wá sínú egungun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 31 Ẹni tí ó fetí sí ìbáwí tí ń fún ni ní ìyè,
|
||
\q2 yóò wà ní àpéjọpọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 32 Ẹni tí ó kọ̀ ìbáwí kẹ́gàn ara rẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí yóò ní ìmọ̀ sí i.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 33 Ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* kọ́ ènìyàn ní ọgbọ́n,
|
||
\q2 ìrẹ̀lẹ̀ sì ni ó máa ń ṣáájú ọlá.
|
||
\b
|
||
\c 16
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd* ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n \nd Olúwa\nd* ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé \nd Olúwa\nd* lọ́wọ́,
|
||
\q2 èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 \nd Olúwa\nd* ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́
|
||
\q2 kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 \nd Olúwa\nd* kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀
|
||
\q2 mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀
|
||
\q2 nípasẹ̀ ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* ènìyàn sá fún ibi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ \nd Olúwa\nd* lọ́rùn,
|
||
\q2 yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo
|
||
\q2 ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n \nd Olúwa\nd* ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i
|
||
\q2 ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Òdínwọ̀n àti òsùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́
|
||
\q2 nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́,
|
||
\q2 wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè;
|
||
\q2 ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ
|
||
\q2 àti láti yan òye dípò o fàdákà!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi,
|
||
\q2 ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun,
|
||
\q2 agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrín àwọn olùpọ́njú
|
||
\q2 jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ìre,
|
||
\q2 ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye
|
||
\q2 ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Òye jẹ́ orísun ìyè fún àwọn tí ó ní i,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ọkàn ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀
|
||
\q2 ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ dàgbà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin
|
||
\q2 ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ọkàn alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún ara rẹ̀;
|
||
\q2 nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ènìyàn búburú ń pète
|
||
\q2 ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Aláyídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀
|
||
\q2 olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn ní yà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀
|
||
\q2 ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte;
|
||
\q2 ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 31 Adé ògo ni ewú orí jẹ́,
|
||
\q2 ìgbé ayé òdodo ní í mú ni dé bẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 32 Ó sàn láti jẹ́ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ,
|
||
\q2 ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun ṣẹ́gun ìlú lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 33 A ṣẹ́ kèké si ìṣẹ́po aṣọ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\c 17
|
||
\q1
|
||
\v 1 Òkèlè gbígbẹ tòun tàlàáfíà àti ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ sàn
|
||
\q2 ju ilé tí ó kún fọ́fọ́ fún ẹran àti ìjà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ọlọ́gbọ́n ìránṣẹ́ yóò ṣàkóso adójútini ọmọ,
|
||
\q2 yóò sì pín ogún gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Iná ni a fi fọ́ fàdákà àti wúrà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n \nd Olúwa\nd* ló ń dán ọkàn wò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ènìyàn búburú ń tẹ́tí sí ètè tí ń sọ ibi;
|
||
\q2 òpùrọ́ a máa fetí sí ahọ́n búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sín olùpọ́njú jẹ, ó gan Ẹlẹ́dàá rẹ̀,
|
||
\q2 ẹnikẹ́ni tí ń yọ̀ sí ìyọnu kò ní lọ láìjìyà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọmọ ọmọ ni adé orí arúgbó,
|
||
\q2 ògo àwọn ọmọ sì ni òbí jẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ọ̀rọ̀ dídùn kò yẹ aṣiwèrè,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ètè èké kò yẹ ọmọ-aládé!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Òkúta iyebíye jẹ́ ẹ̀bùn ní ojú ẹni tí ó ni í,
|
||
\q2 ibikíbi tí ó yí sí, á ṣe rere.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ẹni tí ó fojú fo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀ ẹ́ mú kí ìfẹ́ gbòòrò sí i.
|
||
\q2 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ń tẹnumọ́ ọ̀rọ̀ yóò pín ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ méjì ní yà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ọ̀rọ̀ ìbáwí dun olóye ènìyàn
|
||
\q2 ju ọgọ́rùn-ún pàṣán lọ lẹ́yìn òmùgọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Orí kunkun ni ènìyàn ìkà máa ń ṣe,
|
||
\q2 ìjòyè aláìláàánú ni a ó rán sí i.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ó sàn kí ènìyàn pàdé beari tí a ti kó lọ́mọ
|
||
\q2 jù aláìgbọ́n nínú ìwà òmùgọ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Bí ènìyàn kan bá fi ibi san ìre,
|
||
\q2 ibi kì yóò kúrò nílé rẹ̀ láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Bíbẹ̀rẹ̀ ìjà dàbí ẹni tí ó dá ojú fún adágún omi;
|
||
\q2 nítorí náà mẹ́nu kúrò nínú ọ̀rọ̀ kí ó tó di ìjà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Gbígbé ẹ̀bi fún aláre àti dídá ẹni jàre lẹ́bi,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* kórìíra méjèèjì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Kí ni ìwúlò owó lọ́wọ́ aṣiwèrè,
|
||
\q2 níwọ̀n bí kò ti ní èròǹgbà láti rí ọgbọ́n?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ọ̀rẹ́ a máa fẹ́ni nígbà gbogbo,
|
||
\q2 arákùnrin sì wà fún ìgbà ìpọ́njú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ènìyàn aláìgbọ́n ṣe ìbúra,
|
||
\q2 ó sì ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ẹni tí ó fẹ́ràn ìjà fẹ́ràn ẹ̀ṣẹ̀;
|
||
\q2 ẹni tí ó kọ́ ibodè gígàn ń wá ìparun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ènìyàn aláyídáyidà ọkàn kì í gbèrú,
|
||
\q2 ẹni tí ó ní ahọ́n ẹ̀tàn bọ́ sínú ìyọnu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Láti bí aláìgbọ́n lọ́mọ a máa fa ìbànújẹ́ ọkàn,
|
||
\q2 kò sí ayọ̀ fún baba ọmọ tí kò gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ọkàn tí ó túká jẹ́ oògùn gidi,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọkàn tí ó bàjẹ́ a máa mú kí egungun gbẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ènìyàn búburú a gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀
|
||
\q2 láti yí ìdájọ́ po.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Olóye ènìyàn gbójú wo ọgbọ́n níwájú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ojú aláìgbọ́n ń wò káàkiri ilẹ̀ ayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Aṣiwèrè ọmọ mú ìbànújẹ́ bá baba rẹ̀
|
||
\q2 àti ìkorò fún ẹni tí ó bí i lọ́mọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Kò dára láti fìyà jẹ ènìyàn tí kò ṣẹ̀,
|
||
\q2 tàbí láti na ìjòyè lórí òtítọ́ inú wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ènìyàn tó ní ìmọ̀ máa ń ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ,
|
||
\q2 ènìyàn olóye sì máa ń ní sùúrù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Kódà aláìgbọ́n máa ń dàbí ọlọ́gbọ́n bí ó bá dákẹ́,
|
||
\q2 àti bí olóye bí ó bá fètèmétè.
|
||
\b
|
||
\c 18
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ènìyàn tí kò ba ni rẹ́ a máa lépa ìmọ̀ ara rẹ̀;
|
||
\q2 ó kọjú ìjà sí gbogbo ìdájọ́ òdodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Aláìgbọ́n kò rí inú dídùn sí òye
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí sísọ èrò tirẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nígbà ti ènìyàn búburú dé ni ẹ̀gàn dé,
|
||
\q2 nígbà ti ẹ̀gàn dé ni ìtìjú dé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ọ̀rọ̀ ẹnu ènìyàn jẹ́ omi jíjìn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n orísun ọgbọ́n jẹ́ odò tí ń sàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Kò dára kí ènìyàn ṣe ojúsàájú fún ènìyàn búburú
|
||
\q2 tàbí kí a fi ìdájọ́ òdodo du aláìṣẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ètè aláìgbọ́n dá ìjà sílẹ̀
|
||
\q2 ẹnu rẹ̀ sì ń ṣokùnfà ẹgba.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ẹnu aláìgbọ́n ni ó ba tirẹ̀ jẹ́,
|
||
\q2 ètè rẹ̀ sì jẹ́ ìdẹ̀kùn fún ọkàn rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ọ̀rọ̀ olófòófó dàbí oúnjẹ àdídùn;
|
||
\q2 wọ́n a sì wọ ìsàlẹ̀ inú lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ẹni tí kò ṣe déédé nínú iṣẹ́ rẹ̀
|
||
\q2 arákùnrin ló jẹ́ fún apanirun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Orúkọ \nd Olúwa\nd*, ilé ìṣọ́ agbára ni;
|
||
\q2 olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì rí ìgbàlà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ọ̀rọ̀ olówó ni ìlú olódi wọn;
|
||
\q2 wọ́n rò ó bí i wí pé odi tí kò ṣe é gùn ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ṣáájú ìṣubú ọkàn ènìyàn a kọ́kọ́ máa gbéraga,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìrẹ̀lẹ̀ ni ó máa ń ṣáájú ọlá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ẹni tí ó ń fèsì kí ó tó gbọ́,
|
||
\q2 èyí ni ìwà òmùgọ̀ àti ìtìjú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ọkàn ènìyàn a máa gbé e ró nígbà àìsàn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ta ni ó le forí ti ọkàn tí ó rẹ̀wẹ̀sì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ọkàn olóye ní i gba ìmọ̀;
|
||
\q2 etí ọlọ́gbọ́n ní í ṣe àwárí rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ẹ̀bùn máa ń ṣí ọ̀nà fún ẹni tí ń fún ni lẹ́bùn
|
||
\q2 a sì mú un wọlé sí ọ̀dọ̀ àwọn olókìkí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ẹni tí ó kọ́kọ́ rọjọ́ máa ń dàbí i pé ó jàre,
|
||
\q2 títí ẹlòmíràn yóò fi bọ́ síwájú kí ó sì tú àṣírí gbogbo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ìbò dídì máa ń parí ìjà
|
||
\q2 a sì mú kí àwọn alátakò méjì jìnnà sí ara wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Arákùnrin tí a ṣẹ̀ sí ṣòro yípadà ju ìlú olódi lọ,
|
||
\q2 ìjà wọ sì dàbí ọ̀pá ìdábùú ààfin.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ikùn ènìyàn a yó;
|
||
\q2 láti inú ìkórè ẹnu rẹ̀ ni ó ti jẹ yó.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ikú àti ìyè ń bẹ nípa ahọ́n wọn,
|
||
\q2 àwọn tí ó sì fẹ́ràn rẹ̀ yóò jẹ ẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ẹni tí ó rí aya fẹ́, rí ohun rere,
|
||
\q2 o sì gba ojúrere lọ́dọ̀ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Tálákà ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ a dáhùn pẹ̀lú ìkanra.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ènìyàn tí ó ní ọ̀rẹ́ púpọ̀ le è parun,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ kan wà tí ó súnmọ́ ni tímọ́tímọ́ ju arákùnrin.
|
||
\b
|
||
\c 19
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ó sàn kí ènìyàn jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ kò lábùkù
|
||
\q2 ju aláìgbọ́n tí ètè rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Kò dára láti ní ìtara láìní ìmọ̀,
|
||
\q2 tàbí kí ènìyàn kánjú kí ó sì ṣìnà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ìwà òmùgọ̀ ènìyàn fúnra rẹ̀ a pa ẹ̀mí rẹ̀ run;
|
||
\q2 síbẹ̀ ọkàn rẹ̀ yóò máa bínú sí \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ọrọ̀ máa ń fa ọ̀rẹ́ púpọ̀;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ tálákà tún kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ajẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà,
|
||
\q2 ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde kò ní lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọ̀pọ̀ ń wá ojúrere olórí;
|
||
\q2 gbogbo ènìyàn sì ni ọ̀rẹ́ ẹni tí ó lawọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Gbogbo ará ilé e tálákà ni ó pa á tì,
|
||
\q2 mélòó mélòó ni ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tí ń sá fún un!
|
||
\q2 Bí ó tilẹ̀ ń lé wọn kiri pẹ̀lú ẹ̀bẹ̀,
|
||
\q2 kò tilẹ̀ le rí wọn rárá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹni tí ó gba ọgbọ́n fẹ́ràn ọkàn ara rẹ̀;
|
||
\q2 ẹni tí ó bá káràmáṣìkí òye yóò gbèrú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ajẹ́rìí èké kì yóò lọ láìjìyà
|
||
\q2 ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde yóò parun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Kò yẹ aláìgbọ́n láti máa gbé nínú ọláńlá,
|
||
\q2 mélòó mélòó bí ó ti burú tó fún ẹrú láti jẹ ọba lórí ọmọ-aládé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ọgbọ́n ènìyàn a máa fún un ní sùúrù;
|
||
\q2 fún ògo rẹ̀ ni láti fojú fo àṣìṣe dá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ìbínú ọba dàbí kíké e kìnnìún,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ojúrere rẹ̀ dàbí ìrì lára koríko.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Aṣiwèrè ọmọ jẹ́ ìparun baba rẹ̀,
|
||
\q2 aya tí ó máa ń jà sì dàbí ọ̀ṣọ̀ọ̀rọ̀ òjò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 A máa ń jogún ilé àti ọrọ̀ lọ́dọ̀ òbí,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aya olóye láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd* ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ọ̀lẹ ṣíṣe máa ń fa oorun sísùn fọnfọn,
|
||
\q2 ebi yóò sì máa pa ènìyàn tí ó lọ́ra.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́ ẹ̀kọ́ pa ẹnu rẹ̀ mọ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá kẹ́gàn ọ̀nà rẹ̀ yóò kú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ẹni tí ó ṣàánú tálákà, \nd Olúwa\nd* ní ó yá,
|
||
\q2 yóò sì pín in lérè ohun tí ó ti ṣe.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Bá ọmọ rẹ wí nítorí nínú ìyẹn ni ìrètí wà;
|
||
\q2 àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ lọ́wọ́ nínú ìparun un rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ènìyàn onínú-fùfù gbọdọ̀ gba èrè ìwà rẹ̀;
|
||
\q2 bí ìwọ bá gbà á là, ìwọ yóò tún ní láti ṣe é lẹ́ẹ̀kan sí i.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Fetí sí ìmọ̀ràn kí o sì gba ẹ̀kọ́,
|
||
\q2 ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín ìwọ yóò di ọlọ́gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ète inú ọkàn ènìyàn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìfẹ́ \nd Olúwa\nd* ní ó máa ń borí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ohun tí ènìyàn ń fẹ́ ni ìfẹ́ tí kì í yẹ̀;
|
||
\q2 ó sàn láti jẹ́ tálákà ju òpùrọ́ lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* ń mú ìyè wá;
|
||
\q2 nígbà náà ọkàn ń balẹ̀, láìsí ewu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ọ̀lẹ ki ọwọ́ rẹ̀ bọ inú àwo oúnjẹ;
|
||
\q2 kò tilẹ̀ ní mú u padà wá sí ẹnu rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Na ẹlẹ́gàn, òpè yóò sì kọ́gbọ́n;
|
||
\q2 bá olóye ènìyàn wí, yóò sì ní ìmọ̀ sí i.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ẹni tí ó ṣìkà sí baba rẹ̀, tí ó sì lé ìyá rẹ̀ jáde
|
||
\q1 òun ni ọmọ tí ń ṣe ìtìjú, tí ó sì mú ẹ̀gàn wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ọmọ mi, dẹ́kun láti tẹ́tí sí ẹ̀kọ́,
|
||
\q2 tí í mú ni ṣìnà kúrò nínú ọ̀rọ̀-ìmọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ẹlẹ́rìí búburú fi ìdájọ́ ṣẹ̀sín,
|
||
\q2 ẹnu ènìyàn búburú sì ń gbé ibi mì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 A ti pèsè ìjìyà sílẹ̀ fún ẹlẹ́gàn;
|
||
\q2 àti pàṣán fún ẹ̀yìn àwọn aṣiwèrè.
|
||
\b
|
||
\c 20
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọtí líle;
|
||
\q2 ẹnikẹ́ni tí ó bá fi tànjẹ kò gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìbẹ̀rù ọba dàbí kíké e kìnnìún;
|
||
\q2 ẹnikẹ́ni tí ó bá mú un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹ,
|
||
\q2 nítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ète ọkàn ènìyàn dàbí omi jíjìn;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ènìyàn olóye á wá wọn jáde.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń sọ pe àwọn ní ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòtítọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkù
|
||
\q2 ìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́
|
||
\q2 yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ta ni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́,
|
||
\q2 mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìwọ̀n èké àti òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* kórìíra méjèèjì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀
|
||
\q2 nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ni ó dá méjèèjì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di tálákà.
|
||
\q2 Ma ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 “Kò dára, kò dára!” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wí;
|
||
\q2 nígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán,
|
||
\q2 yóò máa yangàn bí òun tí ṣe rí rà sí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Wúrà wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò;
|
||
\q2 mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà èrú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyàn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n, a yọrí sí ibi ẹnu tí ó kún fún erùpẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀ràn
|
||
\q2 bí o bá ń jagun, gba ìtọ́sọ́nà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Olófòófó a máa tú àṣírí
|
||
\q2 nítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ púpọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀,
|
||
\q2 ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ogún tí a kójọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀
|
||
\q2 kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Má ṣe wí pé, “N ó sẹ̀san àṣìṣe rẹ yìí fún ọ.”
|
||
\q2 Dúró de \nd Olúwa\nd* yóò sì gbà ọ́ là.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 \nd Olúwa\nd* kórìíra òdínwọ̀n èké.
|
||
\q2 Òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 \nd Olúwa\nd* ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyàn.
|
||
\q2 Báwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ìdẹ̀kùn ni fún ènìyàn láti ṣe ìlérí kíákíá
|
||
\q2 nígbà tí ó bá sì yá kí ó máa ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ọlọ́gbọ́n ọba tú ènìyàn búburú ká;
|
||
\q2 Ó sì fi òòlọ ìpakà lọ̀ wọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Àtùpà \nd Olúwa\nd* ń ṣe àwárí ẹ̀mí ènìyàn
|
||
\q2 a máa ṣàwárí ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ìfẹ́ àti òdodo pa ọba mọ́,
|
||
\q2 nípa ìfẹ́, ìtẹ́ rẹ̀ wà láìléwu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Ògo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ni agbára wọn,
|
||
\q2 ewú orí ni iyì arúgbó.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Ìgbájú ìgbámú àti ìfarapa máa ń mú ibi lọ,
|
||
\q2 pàṣán sì máa ń ṣe àfọ̀mọ́ ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
|
||
\b
|
||
\c 21
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n, \nd Olúwa\nd* ló ń díwọ̀n ọkàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà
|
||
\q2 ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí \nd Olúwa\nd* ju ẹbọ lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga,
|
||
\q2 ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ètè àwọn olóye jásí èrè
|
||
\q2 bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́
|
||
\q2 jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ,
|
||
\q2 nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé
|
||
\q2 ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi
|
||
\q2 aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn,
|
||
\q2 òpè a máa kọ́gbọ́n,
|
||
\q2 nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú
|
||
\q2 ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.
|
||
\s1 Ìṣúra ẹni tí o gbọ́n
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú,
|
||
\q2 òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò:
|
||
\q2 àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá,
|
||
\q2 dẹ́kun ìbínú líle.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́:
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye,
|
||
\q2 yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di tálákà:
|
||
\q2 ẹni tí ó fẹ́ ọtí wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó ìràpadà fún olódodo,
|
||
\q2 àti olùrékọjá fún ẹni dídúró ṣinṣin.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ó sàn láti jókòó ní aginjù ju pẹ̀lú
|
||
\q2 oníjà obìnrin àti òṣónú lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ìṣúra iyebíye àti òróró wà ní ibùgbé ọlọ́gbọ́n;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn n bà á jẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ẹni tí ó bá tẹ̀lé òdodo àti àánú yóò rí ìyè,
|
||
\q2 òdodo, àti ọlá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára,
|
||
\q2 ó sì bi ibi gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́,
|
||
\q2 ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Agbéraga àti alágídí ènìyàn ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀,
|
||
\q2 àti nínú ìbínú púpọ̀púpọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé;
|
||
\q2 nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ó ń fi ìlara ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́:
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni:
|
||
\q2 mélòó mélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà ibi?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé:
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le:
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni ìdúró ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye,
|
||
\q2 tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 31 A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun:
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 22
|
||
\s2 Orúkọ rere sàn ju ọrọ̀ lọ
|
||
\q1
|
||
\v 1 Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ,
|
||
\q2 àti ojúrere dára ju fàdákà àti wúrà lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀:
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ni ẹlẹ́dàá gbogbo wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀,
|
||
\q2 ó ṣé ara rẹ̀ mọ́:
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn òpè tẹ̀síwájú, a sì jẹ wọ́n ní yà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà:
|
||
\q2 ẹni tí ó bá pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóò jìnnà sí wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀:
|
||
\q2 nígbà tí ó bá dàgbà, kì yóò kúrò nínú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú,
|
||
\q2 ajigbèsè sì ṣe ìránṣẹ́ fún ẹni tí a jẹ ní gbèsè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 \x - \xo 22.8: \xt (Gk): 1Kọ 9.7.\x*Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán:
|
||
\q2 ọ̀pá ìbínú rẹ̀ yóò kùnà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún;
|
||
\q2 nítorí tí ó fi nínú oúnjẹ rẹ̀ fún olùpọ́njú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde;
|
||
\q2 nítòótọ́ ìjà àti ẹ̀gàn yóò dẹ́kun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà,
|
||
\q2 tí ó sì ń sọ̀rọ̀ iyì jáde, ọba yóò ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ojú \nd Olúwa\nd* pa ìmọ̀ mọ́,
|
||
\q2 ó sì yí ọ̀rọ̀ olùrékọjá pò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde!
|
||
\q2 Yóò pa mí ní ìgboro!”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni;
|
||
\q2 ẹni tí a ń bínú sí láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd* wá ni yóò ṣubú sínú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n pàṣán ìtọ́ni ni yóò lé e jìnnà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀,
|
||
\q2 tí ó sì ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ,
|
||
\q1 yóò di aláìní bí ó ti wù kó rí.
|
||
\q2 Gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
|
||
\ms1 Ọ̀rọ̀ Ọlọ́gbọ́n
|
||
\q1
|
||
\v 17 Dẹtí rẹ sílẹ̀,
|
||
\q2 kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n,
|
||
\q2 kí o sì fi àyà rẹ sí ẹ̀kọ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ;
|
||
\q2 nígbà tí a sì pèsè wọn tán ní ètè rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 èmi fihàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára
|
||
\q2 sí ọ ní ti ìmọ̀ràn àti ní ti ẹ̀kọ́,
|
||
\q1
|
||
\v 21 kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́;
|
||
\q2 kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́
|
||
\q2 fún àwọn tí ó rán ọ?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà:
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè,
|
||
\q1
|
||
\v 23 nítorí \nd Olúwa\nd* yóò gbèjà wọn,
|
||
\q2 yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́;
|
||
\q2 má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́,
|
||
\q2 tàbí nínú àwọn tí ó dúró fún gbèsè.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san,
|
||
\q2 nítorí kín ni yóò ṣe gba ẹni rẹ kúrò lábẹ́ rẹ?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì,
|
||
\q2 tí àwọn baba rẹ ti pa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀?
|
||
\q2 Òun yóò dúró níwájú àwọn ọba;
|
||
\q2 òun kì yóò dúró níwájú àwọn ènìyàn lásán.
|
||
\c 23
|
||
\s2 Ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ohun àdídùn
|
||
\q1
|
||
\v 1 Nígbà tí ìwọ bá jókòó láti bá ìjòyè jẹun,
|
||
\q2 kíyèsi ohun tí ó wà níwájú rẹ gidigidi.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìwọ a sì fi ọ̀bẹ lé ara rẹ ní ọ̀fun,
|
||
\q2 bí ìwọ bá jẹ́ òkúndùn ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Má ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀:
|
||
\q2 nítorí pé oúnjẹ ẹ̀tàn ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Má ṣe ṣe làálàá láti lọ́rọ̀:
|
||
\q2 ṣíwọ́ kúrò nínú ọgbọ́n ara rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ ó ha fi ojú rẹ lépa ohun tí kò sí?
|
||
\q2 Nítorí tí ọ̀rọ̀ hu ìyẹ́ apá fún ara rẹ̀,
|
||
\q2 ó sì ń fò bí idì ní ojú ọ̀run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Má ṣe jẹ oúnjẹ ẹni tí ó háwọ́,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nítorí pé bí ẹni tí ń ṣírò ní ọkàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí:
|
||
\q2 “Máa jẹ, kí o sì máa mu,” ni ó ń wí fún ọ;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ kò pẹ̀lú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Òkèlè tí ìwọ jẹ ni ìwọ ó pọ̀ jáde,
|
||
\q2 ìwọ a sì sọ ọ̀rọ̀ dídùn rẹ̀ nù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Má ṣe sọ̀rọ̀ ní etí aṣiwèrè;
|
||
\q2 nítorí tí yóò gan ọgbọ́n ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Má ṣe ṣí ààlà àtijọ́ kúrò;
|
||
\q2 má sì ṣe bọ́ sínú oko aláìní baba.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára;
|
||
\q2 yóò gba ìjà wọn jà sí ọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Fi àyà sí ẹ̀kọ́,
|
||
\q2 àti etí rẹ sí ọ̀rọ̀-ìmọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Má ṣe fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kúrò lára ọmọdé,
|
||
\q2 nítorí pé bí ìwọ bá fi pàṣán nà án, òun kì yóò kú.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Bí ìwọ fi pàṣán nà án,
|
||
\q2 ìwọ ó sì gbà ọkàn rẹ̀ là kúrò ní ọ̀run àpáàdì.
|
||
\s2 Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n fún ọmọ rere
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ọmọ mi, bí ọkàn rẹ bá gbọ́n,
|
||
\q2 ọkàn mi yóò yọ̀, àní èmi pẹ̀lú.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ní ọjọ́ gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Nítorí pé ìgbẹ̀yìn ń bẹ nítòótọ́;
|
||
\q2 ìrètí rẹ̀ kì yóò sì gé kúrò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Gbọ́, ìwọ ọmọ mi, kí o sì gbọ́n,
|
||
\q2 kí o sì máa tọ́ àyà rẹ sí ọ̀nà títọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Má ṣe wà nínú àwọn ọ̀mùtí;
|
||
\q2 àti àwọn wọ̀bìà alájẹkì ọ̀jẹun;
|
||
\q1
|
||
\v 21 nítorí pé ọ̀mùtí àti ọ̀jẹun ni yóò di tálákà;
|
||
\q2 ìmúni-tòògbé ní sì ń fi àkísà wọ ọkùnrin láṣọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Fetí sí ti baba rẹ tí ó bí ọ,
|
||
\q2 má sì ṣe gan ìyá rẹ, nígbà tí o bá gbó.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ra òtítọ́, kí o má sì ṣe tà á;
|
||
\q2 ra ọgbọ́n pẹ̀lú àti ẹ̀kọ́ àti òye.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Baba olódodo ni yóò yọ̀ gidigidi:
|
||
\q2 ẹni tí ó sì bí ọmọ ọlọ́gbọ́n,
|
||
\q2 yóò ní ayọ̀ nínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Jẹ́ kí baba rẹ àti ìyá rẹ ó yọ̀,
|
||
\q2 sì jẹ́ kí inú ẹni tí ó bí ọ dùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ọmọ mi, fi àyà rẹ fún mi,
|
||
\q2 kí o sì jẹ́ kí ojú rẹ ní inú dídùn sí ọ̀nà mi.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Nítorí pé panṣágà obìnrin ọ̀gbun jíjìn ni;
|
||
\q2 àti àjèjì obìnrin kànga híhá ni.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Òun á sì ba ní bùba bí olè,
|
||
\q2 a sì sọ àwọn olùrékọjá di púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Ta ni ó ni òsì? Ta ni ó ni ìbànújẹ́?
|
||
\q2 Ta ni ó ni ìjà? Ta ni ó ni asọ̀? Ta ni ó ni ọgbẹ́ láìnídìí?
|
||
\q1
|
||
\v 30 Àwọn tí ó dúró pẹ́ níbi ọtí wáìnì;
|
||
\q2 àwọn tí ń lọ láti dán ọtí wáìnì àdàlú wò.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Ìwọ má ṣe wò ọtí wáìnì nígbà tí ó pọ́n,
|
||
\q2 nígbà tí ó bá ń fi àwọ̀ rẹ̀ hàn nínú ago,
|
||
\q2 tí a gbé e mì, tí ó ń dùn.
|
||
\q1
|
||
\v 32 Níkẹyìn òun á bu ni ṣán bí ejò,
|
||
\q2 a sì bunijẹ bí i paramọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 33 Ojú rẹ yóò wò àwọn àjèjì obìnrin,
|
||
\q2 àyà rẹ yóò sì sọ̀rọ̀ àyídáyidà.
|
||
\q1
|
||
\v 34 Nítòótọ́, ìwọ ó dàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ ní àárín Òkun,
|
||
\q2 tàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ lókè-ọkọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 35 Ìwọ ó sì wí pé, “Wọ́n lù mí; kò dùn mí;
|
||
\q2 wọ́n lù mí, èmi kò sì mọ̀:
|
||
\q1 nígbà wo ni èmi ó jí?
|
||
\q2 Èmi ó tún máa wá òmíràn láti mu.”
|
||
\b
|
||
\c 24
|
||
\q1
|
||
\v 1 Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
|
||
\q1
|
||
\v 2 nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú,
|
||
\q2 ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́
|
||
\q2 nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
|
||
\q1
|
||
\v 4 nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún
|
||
\q2 pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀,
|
||
\q2 ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà:
|
||
\q2 nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè
|
||
\q2 àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹni tí ń pète ibi
|
||
\q2 ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀,
|
||
\q2 àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú
|
||
\q2 báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
|
||
\q1
|
||
\v 11 Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là;
|
||
\q2 fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,”
|
||
\q2 ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n?
|
||
\q2 Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára,
|
||
\q2 oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ
|
||
\q2 bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ
|
||
\q2 ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú
|
||
\q2 láti gba ibùjókòó olódodo,
|
||
\q2 má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
|
||
\q1
|
||
\v 16 nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú;
|
||
\q1 nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Àìṣe bẹ́ẹ̀ \nd Olúwa\nd* yóò rí i yóò sì bínú
|
||
\q2 yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi
|
||
\q2 tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
|
||
\q1
|
||
\v 20 nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú
|
||
\q2 a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Bẹ̀rù \nd Olúwa\nd* àti ọba, ọmọ mi,
|
||
\q2 má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn,
|
||
\q2 ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
|
||
\ms1 Àwọn ọrọ̀ ọlọ́gbọ́n mìíràn
|
||
\p
|
||
\v 23 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n:
|
||
\q2 láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,”
|
||
\q2 àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi,
|
||
\q2 ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ìdáhùn òtítọ́
|
||
\q2 dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ
|
||
\q2 sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára;
|
||
\q2 lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí,
|
||
\q2 tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi;
|
||
\q2 Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ,
|
||
\q2 mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
|
||
\q1
|
||
\v 31 ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo,
|
||
\q2 koríko ti gba gbogbo oko náà.
|
||
\q1
|
||
\v 32 Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi
|
||
\q2 mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
|
||
\q1
|
||
\v 33 oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,
|
||
\q2 ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
|
||
\q1
|
||
\v 34 òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè
|
||
\q2 àti àìní bí olè.
|
||
\c 25
|
||
\ms1 Àwọn òwe mìíràn ti Solomoni
|
||
\p
|
||
\v 1 Wọ̀nyí ni àwọn òwe mìíràn tí Solomoni pa, tí àwọn ọkùnrin Hesekiah ọba Juda dà kọ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ògo Ọlọ́run ní láti fi ọ̀rọ̀ kan pamọ́;
|
||
\q2 láti rí ìdí ọ̀rọ̀ kan ni ògo àwọn ọba.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Bí ọ̀run ṣe ga tó tí ayé sì jì
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ó ṣòro láti mọ èrò ọkàn ọba.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Mú ìdàrọ́ kúrò lára fàdákà
|
||
\q2 ohun èlò yóò sì jáde fún alágbẹ̀dẹ fàdákà.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Mú ènìyàn búburú kúrò níwájú ọba
|
||
\q2 a ó sì fìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ nípasẹ̀ òdodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Má ṣe gbé ara rẹ ga níwájú ọba,
|
||
\q2 má sì ṣe jìjàdù ààyè láàrín àwọn ènìyàn pàtàkì,
|
||
\q1
|
||
\v 7 ó sàn kí ó wí fún ọ pé, “Gòkè wá síyìn-ín,”
|
||
\q2 ju wí pé kí ó dójútì ọ́ níwájú ènìyàn pàtàkì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ohun tí o ti fi ojú ara rẹ rí
|
||
\q2 má ṣe kánjú gbé e lọ sílé ẹjọ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe ní ìgbẹ̀yìn
|
||
\q2 bí aládùúgbò rẹ bá dójútì ọ́?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Bí o bá ń ṣe àwíjàre rẹ níwájú aládùúgbò rẹ,
|
||
\q2 má ṣe tú àṣírí tí ẹlòmíràn ní lọ́dọ̀ rẹ,
|
||
\q1
|
||
\v 10 àìṣe bẹ́ẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ le dójútì ọ́
|
||
\q2 orúkọ búburú tí ìwọ bá sì gba kì yóò tán láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ọ̀rọ̀ tí a sọ ní àkókò tí ó yẹ
|
||
\q2 ó dàbí èso wúrà nínú àpẹẹrẹ fàdákà.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Bí i yẹtí wúrà tàbí ohun ọ̀ṣọ́ ti wúrà dáradára
|
||
\q2 ni ìbáwí ọlọ́gbọ́n fún etí tí ó bá fetísílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Bí títutù òjò yìnyín ní àsìkò ìkórè
|
||
\q2 ni ìránṣẹ́ tí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí àwọn tí ó rán an
|
||
\q2 ó ń tu ọ̀gá rẹ̀ nínú.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Bí ojú ṣíṣú àti afẹ́fẹ́ láìsí òjò
|
||
\q2 ni ènìyàn tí ń yangàn nípa ẹ̀bùn tí kò fún ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Nípa sùúrù a lè yí ọba lọ́kàn padà
|
||
\q2 ahọ́n tí ń sọ̀rọ̀ rírọ̀ sí egungun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Bí ìwọ bá rí oyin, jẹ ẹ́ ní ìwọ̀nba
|
||
\q2 bí o bá jẹ ẹ́ jù, ìwọ yóò sì bì í.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Má ṣe máa lọ sí ilé aládùúgbò rẹ nígbà gbogbo
|
||
\q2 tàbí kí ó máa lọ síbẹ̀ lálọ jù, yóò sì kórìíra rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Bí ọ̀pá, idà tàbí ọ̀kọ̀ tí ó mú
|
||
\q2 ni ènìyàn tí ó jẹ́rìí èké lòdì sí aládùúgbò rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Bí eyín tí ó bàjẹ́ tàbí ẹsẹ̀ tí ó rọ
|
||
\q2 ni ìgbẹ́kẹ̀lé lórí aláìṣòótọ́ ní àsìkò ìdààmú.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Bí ẹni tí ó bọ́ra kalẹ̀ ní ọjọ́ tí òtútù mú,
|
||
\q2 tàbí, bí ọtí kíkan tí a dà sí ojú ọgbẹ́,
|
||
\q2 ní ẹni tí ń kọ orin fún ẹni tí ọkàn rẹ̀ bàjẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 \x - \xo 25.21,22: \xt Ro 12.20.\x*Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ, fún un ní oúnjẹ jẹ;
|
||
\q2 bí òǹgbẹ bá ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mú.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Nípa ṣíṣe báyìí, ìwọ yóò wa ẹ̀yín iná lé e lórí
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* yóò sì san ọ ní ẹ̀san rẹ̀ fún ọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Bí afẹ́fẹ́ gúúsù ti í mú òjò wá,
|
||
\q2 bí ahọ́n tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀yìn ṣe ń mú ojú ìbínú wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ó sàn láti gbé ní ibi igun kan lórí òrùlé
|
||
\q2 ju láti bá aya oníjà gbé ilé pọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Bí omi tútù sí ọkàn tí ń ṣe àárẹ̀
|
||
\q2 ni ìròyìn ayọ̀ láti ọ̀nà jíjìn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Bí ìsun tí ó di àbàtà tàbí kànga tí omi rẹ̀ bàjẹ́
|
||
\q2 ni olódodo tí ó fi ààyè gba ènìyàn búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Kò dára láti jẹ oyin àjẹjù,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kò pọ́n ni lé láti máa wá ọlá fún ara ẹni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Bí ìlú tí odi rẹ̀ ti wó lulẹ̀
|
||
\q2 ni ènìyàn tí kò le kó ara rẹ̀ ní ìjánu.
|
||
\c 26
|
||
\q1
|
||
\v 1 Bí òjò-dídì tàbí òjò ní ìgbà ìkórè
|
||
\q2 ọlá kò yẹ aláìgbọ́n ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Bí ológoṣẹ́ tí ń ṣí kiri tàbí alápáǹdẹ̀dẹ̀ tí ń rábàbà
|
||
\q2 èpè kò le è mọ́ ẹni tí kò ṣiṣẹ́ èpè
|
||
\q2 èpè kì í jani bí a kò bá ṣiṣẹ́ èpè.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹgba fún ẹṣin, ìjánu fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́
|
||
\q2 àti pàṣán fún ẹ̀yìn aṣiwèrè.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Má ṣe dá aláìgbọ́n lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà òmùgọ̀ rẹ̀
|
||
\q2 àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ pẹ̀lú yóò dàbí i rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Dá aláìgbọ́n lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà òmùgọ̀ rẹ̀
|
||
\q2 àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò dàbí ọlọ́gbọ́n lójú ara rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Bí ìgbà tí ènìyàn gé ẹsẹ̀ ara rẹ̀ tàbí mú ìwà ipá
|
||
\q2 ni kí a ránṣẹ́ nípasẹ̀ aṣiwèrè.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Bí ẹsẹ̀ arọ tí ó ń mi dirodiro
|
||
\q2 ni òwe lẹ́nu aṣiwèrè.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Bí ìgbà tí a so òkúta mọ́ okùn títa
|
||
\q2 ni fífún aláìgbọ́n ní ọlá.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Bí ẹ̀gún èṣùṣú lọ́wọ́ ọ̀mùtí
|
||
\q2 ni òwe lẹ́nu aláìgbọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Bí tafàtafà ti ń ṣe ni léṣe lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan
|
||
\q2 ni ẹni tí ó gba aṣiwèrè ṣíṣẹ́ tàbí ẹni tí ń kọjá lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 \x - \xo 26.11: \xt 2Pt 2.22.\x*Bí ajá ti í padà sí èébì rẹ̀
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni aṣiwèrè tún ń hu ìwà òmùgọ̀ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ǹjẹ́ o rí ènìyàn tí ó jẹ́ ọlọ́gbọ́n ní ojú ara rẹ̀?
|
||
\q2 Ìrètí ń bẹ fún aláìgbọ́n ènìyàn jù ú lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún wà lójú ọ̀nà
|
||
\q2 kìnnìún búburú ń ké ní ojú ọ̀nà.”
|
||
\q1
|
||
\v 14 Bí ìlẹ̀kùn ti ń yí lórí ìsolẹ̀kùn rẹ̀,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ ń yí lórí ibùsùn rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ọ̀lẹ ki ọwọ́ rẹ̀ bọ inú àwo oúnjẹ,
|
||
\q2 ó lẹ dé bi pé kò le è mú u padà wá sí ẹnu rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ọ̀lẹ gbọ́n ní ojú ara rẹ̀,
|
||
\q2 ju ènìyàn méje tí wọ́n le è fún un ní ìdáhùn ọlọ́gbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Bí ènìyàn tí ó di ajá ní etí mú
|
||
\q2 ni ẹni tí ń kọjá lọ tí ó dá sí ọ̀rọ̀ ìjà tí kì í ṣe tirẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Bí i asínwín ti ń ju
|
||
\q2 ọfà àti ọfà tí ń ṣe kú pa ni
|
||
\q1
|
||
\v 19 ni ènìyàn tí ń tan aládùúgbò rẹ̀ jẹ
|
||
\q2 tí ó sì wí pé, “Àwàdà lásán ni mo ń ṣe.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Láìsí igi, iná yóò kú
|
||
\q2 láìsí ọ̀rọ̀ ẹ̀yìn, ìjà máa ń parí.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Bí èédú ti rí sí ẹyin iná, igi fún iná,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn oníjà fún ìjà dídá sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ọ̀rọ̀ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀yìn dàbí àṣàyàn òkèlè
|
||
\q2 wọ́n a sì wọ ìsàlẹ̀ inú lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ètè jíjóni, àti àyà búburú,
|
||
\q2 dà bí ìdàrọ́ fàdákà tí a fi bo ìkòkò.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ènìyàn tí ó kórìíra máa ń fi ètè rẹ̀ bo àṣírí ara rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ ni ìtànjẹ wà.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Bí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tilẹ̀ fanimọ́ra, má ṣe gbà á gbọ́
|
||
\q2 nítorí ìríra méje ni ó kún inú ọkàn rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ìkórìíra rẹ le è fi ara sin nípa ẹ̀tàn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àṣírí ìwà búburú rẹ̀ yóò tú ní gbangba.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Bí ènìyàn kan bá gbẹ́ kòtò, yóò ṣubú sínú rẹ̀.
|
||
\q2 Bí ẹnìkan bá ju òkúta, yóò padà sọ́dọ̀ òun tìkára rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ahọ́n ẹ̀tàn máa ń kórìíra àwọn tí ó ṣe ní ìkà,
|
||
\q2 ẹnu ìtànjẹ sì máa ń pa ni run.
|
||
\b
|
||
\c 27
|
||
\q1
|
||
\v 1 Má ṣe yangàn nítorí ọ̀la
|
||
\q2 nítorí o kò mọ ohun tí ọjọ́ kan le è mú wáyé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Jẹ́ kí ẹlòmíràn yìn ọ́ dípò ẹnu ara rẹ,
|
||
\q2 àní àlejò, kí ó má sì ṣe ètè ìwọ fúnra rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Òkúta wúwo, erùpẹ̀ sì wúwo
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìbínú aṣiwèrè wúwo ju méjèèjì lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìbínú ni ìkà, ìrunú sì burú púpọ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ta ni ó le è dúró níwájú owú?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìbániwí gbangba sàn
|
||
\q2 ju ìfẹ́ ìkọ̀kọ̀ lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Òtítọ́ ni ọgbẹ́ ọ̀rẹ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìfẹnukonu ọ̀tá ni ẹ̀tàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Kódà oyin kò dùn lẹ́nu ẹni tí ó ti yó
|
||
\q2 ṣùgbọ́n òróǹró gan an dùn lẹ́nu ẹni tí ebi ń pa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Bí ẹyẹ tí ó ṣáko lọ kúrò níbi ìtẹ́ rẹ̀
|
||
\q2 ni ènìyàn tí ó ṣáko lọ kúrò ní ilé rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìpara olóòórùn dídùn àti tùràrí ń mú ayọ̀ wá sínú ọkàn
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni inú dídùn láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ ń wá láti inú ìmọ̀ràn tí ó ṣàkóso.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Má ṣe kọ ọ̀rẹ́ rẹ àti ọ̀rẹ́ baba rẹ sílẹ̀,
|
||
\q2 má sì ṣe lọ sílé arákùnrin rẹ nígbà tí ìdààmú dé bá ọ
|
||
\q2 ó sàn kí o jẹ́ aládùúgbò tí ó súnmọ́ ni ju arákùnrin tí ó jìnnà sí ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Gbọ́n, ọmọ mi, kí o sì mú ayọ̀ wá sínú ọkàn mi
|
||
\q2 nígbà náà ni mo le dá gbogbo ẹni tí ó bá kẹ́gàn mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ọlọ́gbọ́n rí ewu, ó sì fi ara pamọ́
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aláìgbọ́n rí, kàkà kí ó dúró ó tẹ̀síwájú, ó sì jìyà rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àjèjì
|
||
\q2 fi ṣe ẹ̀rí ìdúró bí o bá ṣe onídùúró fún obìnrin oníṣekúṣe.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Bí ènìyàn kan ń kígbe súre fún aládùúgbò rẹ ní òwúrọ̀
|
||
\q2 a ó kà á sí bí èpè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Àyà tí ó máa ń jà dàbí
|
||
\q2 ọ̀wààrà òjò ní ọjọ́ tí òjò ń rọ̀;
|
||
\q1
|
||
\v 16 dídá a lẹ́kun dàbí ìgbà tí ènìyàn ń dá afẹ́fẹ́ lẹ́kun
|
||
\q2 tàbí bí ẹni tí ó gbá òróró.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Bí irin tí ń pọ́n irin mú
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn kan ń pọ́n ẹlòmíràn mú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ẹni tí ó tọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ yóò jẹ èso rẹ̀
|
||
\q2 ẹni tí ó sì fojú tó ọ̀gá rẹ̀ yóò gba ọlá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Bí omi tí ń ṣe àfihàn ojú, nígbà tí a bá wò ó
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ènìyàn ń ṣe àfihàn ènìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Kò tẹ́ ikú àti ìparun lọ́rùn rí
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni ojú ènìyàn kò rí ìtẹ́lọ́rùn rí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Iná fún fàdákà iná ìléru fún wúrà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n a ń dán ènìyàn wò nípa ìyìn tí ó ń gbà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Bí a tilẹ̀ gún aláìgbọ́n nínú odó,
|
||
\q2 fi ọmọ odó gún un bí èlùbọ́
|
||
\q2 ìwọ kì yóò le è yọ ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ kúrò ní inú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Rí i dájú pé o mọ ipò tí àwọn agbo àgùntàn rẹ wà
|
||
\q2 bojútó àwọn agbo màlúù rẹ dáradára;
|
||
\q1
|
||
\v 24 nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títí
|
||
\q2 adé kì í sì í wà lórí títí láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Nígbà tí a bá kó koríko, ewéko tuntun yóò sì hù jáde, a ó sì kó koríko àwọn orí òkè wọlé
|
||
\q1
|
||
\v 26 àwọn àgùntàn yóò pèsè aṣọ fún ọ,
|
||
\q2 àti ewúrẹ́ yóò pèsè owó oko.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ìwọ yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà ewúrẹ́
|
||
\q2 láti bọ́ ọ àti ìdílé rẹ
|
||
\q2 àti láti tọ́jú àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ.
|
||
\b
|
||
\c 28
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ènìyàn búburú ń sá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹnìkan kò lé e
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olódodo láyà bí i kìnnìún.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nígbà tí orílẹ̀-èdè bá ní orí kunkun, àwọn ọba rẹ̀ a máa pọ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olóye àti onímọ̀ a máa pa òfin mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọba tí ó ni àwọn tálákà lára
|
||
\q2 dàbí àgbàrá òjò tí ó ń gbá gbogbo ọ̀gbìn lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àwọn tí ó kọ òfin sílẹ̀ a máa gbóríyìn fún ènìyàn búburú
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn tí ó pa òfin mọ́ kọjú ìjà sí ènìyàn búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Òye ìdájọ́ òdodo kò yé àwọn ẹni ibi
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó yé àwọn tí ń wá \nd Olúwa\nd* dáradára.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ó sàn láti jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ jẹ́ aláìlábùkù
|
||
\q2 ju ọlọ́rọ̀ tí ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ẹni tí ó pa òfin mọ́ jẹ́ olóye ọmọ
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ẹ́ jẹgúdújẹrá kẹ́gbẹ́ dójútì baba rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹni tí ó mú ọrọ̀ rẹ̀ di púpọ̀ nípa èrè àjẹjù
|
||
\q2 ń kó jọ fún ẹlòmíràn, tí yóò ní àánú àwọn tálákà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Bí ẹnikẹ́ni bá kọ etí ikún sí òfin,
|
||
\q2 kódà àdúrà rẹ̀ jẹ́ ìríra.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ẹni tí ó mú olódodo rìn ọ̀nà búburú
|
||
\q2 yóò bọ́ sínú pàkúté ara rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n aláìlẹ́gàn yóò gba ogún rere.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ọlọ́rọ̀ ènìyàn le è gbọ́n lójú ara rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n tálákà tí ó ní òye rí ìdí, rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nígbà tí olódodo ń lékè ariwo ayọ̀ ta;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú gorí òye, àwọn ènìyàn a na pápá bora.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kì yóò ṣe rere,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jẹ́wọ́ tí ó sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀ máa ń rí àánú gbà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run nígbà gbogbo
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le bọ́ sínú wàhálà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Bí kìnnìún tí ń ké tàbí Beari tí ń halẹ̀
|
||
\q2 ni ènìyàn búburú tí ń jẹ ọba lórí àwọn aláìlágbára.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ọmọ-aládé tí ó ṣe aláìmòye púpọ̀ ní ń ṣe ìwà ìkà púpọ̀ pẹ̀lú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èyí tí ó kórìíra ojúkòkòrò yóò mú ọjọ́ rẹ̀ pẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ẹni tí ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ìpànìyàn
|
||
\q2 yóò máa joró rẹ̀ títí ikú
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ràn án lọ́wọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ẹni tí ń rìn déédéé ní yóò là,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà ni yóò ṣubú lójijì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ẹni tí ó bá ro ilẹ̀ rẹ̀ yóò ní oúnjẹ lọ́pọ̀lọ́pọ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ń lé ohun asán yóò kún fún òsì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Olóòtítọ́ ènìyàn yóò rí ìbùkún gbà gan an
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ojú ń kán láti di ọlọ́rọ̀ kì yóò lọ láìjìyà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ojúsàájú ṣíṣe kò dára,
|
||
\q2 síbẹ̀ ènìyàn kan ń ṣẹ̀ nítorí òkèlè oúnjẹ kan.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ahun ń sáré àti là
|
||
\q2 kò sì funra pé òsì dúró de òun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ẹni tí ó bá ènìyàn kan wí yóò rí ojúrere ni nígbẹ̀yìn
|
||
\q2 ju ẹni tí ó ní ètè ẹ̀tàn lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ẹni tí ó ja baba tàbí ìyá rẹ̀ lólè
|
||
\q2 tí ó sì wí pé, “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀,”
|
||
\q2 irú kan ni òun àti ẹni tí ń pa ni run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ọ̀kánjúwà ènìyàn a máa dá ìjà sílẹ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd* yóò gbilẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀ jẹ́ aláìgbọ́n
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ń rìn nínú ọgbọ́n wà láìléwu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ẹni tí ó ń fi fún tálákà kì yóò ṣe aláìní ohunkóhun,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni tí ó di ojú rẹ̀ sí wọn gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ègún.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Nígbà tí ènìyàn búburú bá dórí ìjọba, àwọn ènìyàn a na pápá bora;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú bá ṣègbé,
|
||
\q2 àwọn olódodo ń gbilẹ̀ sí i.
|
||
\b
|
||
\c 29
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹni tí ó sì ń ṣorí kunkun lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbáwí
|
||
\q2 yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nígbà tí olódodo bá ń gbilẹ̀, àwọn ènìyàn a yọ̀
|
||
\q2 nígbà tí ènìyàn búburú ń ṣàkóso, àwọn ènìyàn ń kórìíra.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ènìyàn tí ó fẹ́ràn ọgbọ́n mú kí baba rẹ̀ láyọ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹni ti ń bá panṣágà kẹ́gbẹ́ ba ọrọ̀ ọ rẹ̀ jẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nípa ìdájọ́ òdodo ni ọba fi í mú ìlú tòrò nini,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èyí tí ń ṣe ojúkòkòrò àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fà á lulẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tan aládùúgbò rẹ̀
|
||
\q2 ó ń dẹ àwọ̀n de ẹsẹ̀ ẹ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ẹ̀ṣẹ̀ ènìyàn ibi ni ó jẹ́ ìdẹ̀kùn rẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olódodo le è kọrin kí ó sì máa yọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Olódodo ń máa ro ọ̀rọ̀ tálákà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kò sú sí i láti rò ó.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Àwọn ẹlẹ́yà a máa ru ìlú sókè,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn máa ń mú ìbínú kúrò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn bá lọ sí ilé ẹjọ́ pẹ̀lú aláìgbọ́n
|
||
\q2 aláìgbọ́n a máa bínú a sì máa jà, kò sì ní sí àlàáfíà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Àwọn tí ó ń tàjẹ̀ sílẹ̀ kò rí ẹni dídúró ṣinṣin
|
||
\q2 wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa olódodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Aláìgbọ́n ènìyàn fi gbogbo ẹnu rẹ̀ bínú
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa kó ìbínú rẹ̀ ní ìjánu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Bí olórí bá fetí sí irọ́,
|
||
\q2 gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ a di ènìyàn búburú lójú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Tálákà ènìyàn àti aninilára jọ ní àbùdá yìí,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* jẹ́ kí ojú àwọn méjèèjì máa ríran.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Bí ọba kan bá ń ṣe ìdájọ́ tálákà pẹ̀lú òtítọ́
|
||
\q2 ìtẹ́ ìjọba rẹ yóò fìdímúlẹ̀ nígbà gbogbo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ọ̀pá ìbániwí ń fún ni ní ọgbọ́n
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọmọ tí a fi sílẹ̀ fúnra rẹ̀ a dójútì ìyá rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nígbà tí ènìyàn búburú ń gbilẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀ṣẹ̀ ń gbilẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n olódodo yóò rí ìṣubú wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Bá ọmọ rẹ wí, yóò sì fún ọ ní àlàáfíà
|
||
\q2 yóò sì mú inú dídùn wá sí inú ọkàn rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Níbi tí kò ti sí ìfihàn, àwọn ènìyàn a gbé ìgbé ayé àìbìkítà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìbùkún ní fún àwọn tí ń pa òfin mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 A kò le fi ọ̀rọ̀ lásán kìlọ̀ fún ìránṣẹ́
|
||
\q2 bí ó tilẹ̀ yé e, kò ní kọbi ara sí i.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ǹjẹ́ ó rí ènìyàn tí ń kánjú sọ̀rọ̀?
|
||
\q2 Ìrètí wà fún aláìgbọ́n jù ú lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Bí ènìyàn kan bá kẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ lákẹ̀ẹ́jù láti kékeré
|
||
\q2 yóò mú ìbànújẹ́ wá ní ìgbẹ̀yìn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Oníbìínú ènìyàn a ru ìjà sókè,
|
||
\q2 onínú-fùfù ènìyàn a sì máa dá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ìgbéraga ènìyàn a máa sọ ọ́ di ẹni ilẹ̀
|
||
\q2 ṣùgbọ́n onírẹ̀lẹ̀ ènìyàn a máa gba iyì kún iyì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ẹni tí ó ń kó ẹgbẹ́, olè kórìíra ọkàn ara rẹ̀,
|
||
\q2 ó ń gbọ́ èpè olóhun kò sì le è fọhùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ìbẹ̀rù ènìyàn kan yóò sì di ìdẹ̀kùn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd* wà láìléwu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ń wá ojúrere alákòóso,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd* ni ènìyàn tí ń gba ìdájọ́ òdodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Olódodo kórìíra àwọn aláìṣòótọ́:
|
||
\q2 ènìyàn búburú kórìíra olódodo.
|
||
\c 30
|
||
\ms1 Àwọn ọ̀rọ̀ tí Aguri sọ.
|
||
\p
|
||
\v 1 Àwọn ọ̀rọ̀ Aguri ọmọ Jake, ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí ọkùnrin yìí sọ fún Itieli.
|
||
\q1 Sí Itieli àti sí Ukali.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 “Èmi ni aláìmòye ju nínú àwọn ènìyàn;
|
||
\q2 n kò ní òye ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Èmi kò tilẹ̀ kọ́ ọgbọ́n
|
||
\q2 tàbí ní ìmọ̀ ẹni mímọ́ nì.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ta ni ó ti gòkè lọ sí ọ̀run tí ó sì padà sọ̀kalẹ̀?
|
||
\q2 Ta ni ó ti kó afẹ́fẹ́ jọ sí ihò àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀?
|
||
\q1 Ta ni ó ti ta kókó omi sétí aṣọ?
|
||
\q2 Ta ni ó fi gbogbo ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀?
|
||
\q1 Kí ni orúkọ rẹ̀, àti orúkọ ọmọ rẹ̀?
|
||
\q2 Sọ fún mi bí o bá mọ̀.
|
||
\b
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 “Gbogbo ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ aláìlábùkù;
|
||
\q2 òun ni ààbò fún gbogbo ẹni fi í ṣe ibi ìpamọ́ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Má ṣe fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀,
|
||
\q2 àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò bá ọ wí yóò sì sọ ọ́ di òpùrọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 “Ohun méjì ni mo ń béèrè lọ́wọ́ rẹ, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 má ṣe fi wọ́n dù mí kí ń tó kú.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Mú èké ṣíṣe àti irọ́ jìnnà sí mi;
|
||
\q2 má ṣe fún mi ní òsì tàbí ọrọ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n fún mi ní oúnjẹ òòjọ́ mi nìkan.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Àìṣe bẹ́ẹ̀, mo lè ní àníjù kí n sì gbàgbé rẹ
|
||
\q2 kí ń sì wí pé, ‘Ta ni \nd Olúwa\nd*?’
|
||
\q1 Tàbí kí ń di òtòṣì kí ń sì jalè
|
||
\q2 kí ń sì ṣe àìbọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 “Má ṣe ba ìránṣẹ́ lórúkọ jẹ́ lọ́dọ̀ ọ̀gá rẹ̀,
|
||
\q2 kí ó má ba fi ọ́ bú, kí ìwọ má ba jẹ̀bi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 “Àwọn kan wá ṣépè fún àwọn baba wọn
|
||
\q2 tí wọn kò sì súre fún àwọn ìyá wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Àwọn tí ó mọ́ ní ojú ara wọn
|
||
\q2 síbẹ̀ tí wọn kò sì mọ́ kúrò nínú èérí wọn;
|
||
\q1
|
||
\v 13 àwọn ẹni tí ojú wọn gbéga nígbà gbogbo,
|
||
\q2 tí ìwolẹ̀ wọn sì kún fún ìgbéraga.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Àwọn ẹni tí eyín wọn jẹ́ idà
|
||
\q2 àwọn tí èrìgì wọn kún fún ọ̀bẹ
|
||
\q1 láti jẹ àwọn tálákà run kúrò ní ilẹ̀ ayé
|
||
\q2 àwọn aláìní kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 “Eṣúṣú ni ọmọbìnrin méjì.
|
||
\q2 ‘Mú wá! Mú wá!’ ní wọn ń ké.
|
||
\b
|
||
\li1 “Àwọn nǹkan mẹ́ta kan wà tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn láéláé,
|
||
\li2 mẹ́rin tí kò jẹ́ wí láéláé pé, ‘Ó tó!’:
|
||
\li3
|
||
\v 16 Ibojì, inú tí ó yàgàn,
|
||
\li3 ilẹ̀ tí omi kì í tẹ́lọ́rùn láéláé,
|
||
\li3 àti iná, tí kì í wí láéláé pé, ‘Ó tó!’
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 “Ojú tí ń fi baba ṣẹ̀fẹ̀,
|
||
\q2 tí ó kẹ́gàn ìgbọ́ràn sí ìyá,
|
||
\q1 ẹyẹ ìwò ẹ̀bá odò ni yóò yọ ọ́,
|
||
\q2 igún yóò mú un jẹ.
|
||
\b
|
||
\li1
|
||
\v 18 “Àwọn nǹkan mẹ́ta wà tí ó jẹ́ ìyàlẹ́nu fún mi,
|
||
\li2 mẹ́rin tí kò yé mi,
|
||
\li3
|
||
\v 19 ipa ẹyẹ idì ní òfúrufú
|
||
\li3 ipa ejò lórí àpáta
|
||
\li3 ipa ọkọ̀ ojú omi lójú agbami Òkun
|
||
\li3 àti ipa ọ̀nà ọkùnrin tí ó mú wúńdíá lọ́wọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 “Èyí ni ọ̀nà alágbèrè obìnrin
|
||
\q2 ó jẹun ó sì nu ẹnu rẹ̀
|
||
\q2 ó sì wí pé, ‘N kò ṣe ohunkóhun tí kò tọ́.’
|
||
\b
|
||
\li1
|
||
\v 21 “Lábẹ́ nǹkan mẹ́ta ni ilé ayé ti ń wárìrì
|
||
\li2 lábẹ́ ohun mẹ́rin ni kò ti lè mí fín ín.
|
||
\li3
|
||
\v 22 Ìránṣẹ́ tí ó di ọba
|
||
\li3 aláìgbọ́n tí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,
|
||
\li3
|
||
\v 23 obìnrin tí gbogbo ènìyàn kórìíra tí ó sì wá lọ́kọ
|
||
\li3 ìránṣẹ́bìnrin tí ó gbọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
|
||
\b
|
||
\li1
|
||
\v 24 “Àwọn ohun mẹ́rin ló kéré láyé
|
||
\li2 síbẹ̀ wọ́n gbọ́n gidigidi.
|
||
\li1
|
||
\v 25 Àwọn èèrà jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá,
|
||
\li3 síbẹ̀ wọ́n kó oúnjẹ wọn pamọ́ ní àsìkò òjò.
|
||
\li2
|
||
\v 26 Ehoro jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá;
|
||
\li3 síbẹ̀ wọ́n ń ṣe ihò wọn sí ibi pálapàla àpáta;
|
||
\li2
|
||
\v 27 àwọn eṣú kò ní ọba,
|
||
\li3 síbẹ̀ gbogbo wọ́n ń jáde lọ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́
|
||
\li2
|
||
\v 28 Ọmọnílé fi ọwọ́ rẹ̀ dì mú,
|
||
\li3 síbẹ̀ a ń rí i ní ààfin ọba.
|
||
\b
|
||
\li1
|
||
\v 29 “Àwọn ohun mẹ́ta ní ń bẹ tí ń rìn rere,
|
||
\li2 ohun mẹ́rin ni ó dára púpọ̀ ní ìrìn rírìn:
|
||
\li3
|
||
\v 30 Kìnnìún, alágbára láàrín ẹranko tí kì í sá fún ohunkóhun
|
||
\li3
|
||
\v 31 Ẹsin tí a dì lẹ́gbẹ̀ẹ́;
|
||
\li3 àti òbúkọ,
|
||
\li3 àti ọba láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 32 “Bí ìwọ bá ti hùwà aṣiwèrè nípa gbígbé ara rẹ ga,
|
||
\q2 tàbí tí o bá ti gbèrò ibi,
|
||
\q2 da ọwọ́ rẹ bo ẹnu rẹ!
|
||
\q1
|
||
\v 33 Nítorí bí fífún omi ọmú tí í mú wàrà wá,
|
||
\q2 tí fífún imú sì ń mú ẹ̀jẹ̀ jáde,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni rírú ìbínú sókè í mú ìjà wá.”
|
||
\c 31
|
||
\ms1 Àwọn ọ̀rọ̀ ọba Lemueli
|
||
\p
|
||
\v 1 Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba, ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ,
|
||
\q1
|
||
\v 2 “Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi!
|
||
\q2 Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,
|
||
\q2 okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 “Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli,
|
||
\q2 kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì,
|
||
\q2 kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle,
|
||
\q1
|
||
\v 5 kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí,
|
||
\q2 kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé
|
||
\q2 wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn
|
||
\q2 kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 “Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnra wọn
|
||
\q2 fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè
|
||
\q2 jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”
|
||
\ms1 Ìkádìí: Aya oníwà rere
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ta ni ó le rí aya oníwà rere?
|
||
\q2 Ó níye lórí ju iyùn lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀
|
||
\q2 kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi
|
||
\q2 ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀
|
||
\q2 Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò;
|
||
\q2 ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn;
|
||
\q2 ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀
|
||
\q2 àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á;
|
||
\q2 nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára
|
||
\q2 apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ó rí i pé òwò òun pé
|
||
\q2 fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú
|
||
\q2 ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú.
|
||
\q1
|
||
\v 20 O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà
|
||
\q2 ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀
|
||
\q2 nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;
|
||
\q2 ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 23 A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú
|
||
\q2 níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n
|
||
\q2 ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ
|
||
\q2 ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.
|
||
\q1
|
||
\v 26 A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n
|
||
\q2 ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀
|
||
\q2 kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún
|
||
\q2 ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un.
|
||
\q1
|
||
\v 29 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ.”
|
||
\q1
|
||
\v 30 Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán
|
||
\q2 nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd* yẹ kí ó gba oríyìn.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i
|
||
\q2 kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.
|