9535 lines
348 KiB
Plaintext
9535 lines
348 KiB
Plaintext
\id PSA - Biblica® Open Yoruba Contemporary Bible (Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)
|
||
\rem Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.®
|
||
\h Saamu
|
||
\toc1 Ìwé Saamu
|
||
\toc2 Saamu
|
||
\toc3 Sm
|
||
\mt1 Ìwé Saamu
|
||
\c 1
|
||
\ms ÌWÉ KÌN-ÍN-NÍ
|
||
\mr Saamu 1–41
|
||
\cl Saamu 1
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 1.1-3: \xt Jr 17.7-8.\x*Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà,
|
||
\q2 tí kò rìn ní ìmọ̀ àwọn ènìyàn búburú,
|
||
\q1 ti kò dúró ní ọ̀nà àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,
|
||
\q2 tàbí tí kò sì jókòó ní ibùjókòó àwọn ẹlẹ́gàn.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ṣùgbọ́n ayọ̀ inú rẹ̀ wà nínú òfin \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 àti nínú òfin rẹ̀ ni ó ń ṣe àṣàrò ní ọ̀sán àti òru.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ó dàbí igi tí a gbìn sí etí odò tí ń sàn,
|
||
\q2 tí ń so èso rẹ̀ jáde ní àkókò rẹ̀
|
||
\q1 tí ewé rẹ̀ kì yóò rẹ̀.
|
||
\q2 Ohunkóhun tí ó dáwọ́lé, ni yóò máa yọrí sí rere.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Kò le rí bẹ́ẹ̀ fún àwọn ènìyàn búburú!
|
||
\q2 Wọn yóò dàbí ìyàngbò ọkà
|
||
\q2 tí afẹ́fẹ́ ń fẹ́ dànù.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí náà àwọn ènìyàn búburú kì yóò le è dìde dúró ní ìdájọ́,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ kì yóò le è dúró ní àwùjọ àwọn olódodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nítorí \nd Olúwa\nd* ń ṣọ́ ọ̀nà àwọn olódodo,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ni yóò ṣègbé.
|
||
\c 2
|
||
\cl Saamu 2
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 2.1-2: \xt Ap 4.25-26.\x*Èéṣe tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń dìtẹ̀,
|
||
\q2 àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkíṣí asán?
|
||
\q1
|
||
\v 2 Àwọn ọba ayé péjọpọ̀
|
||
\q2 àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀
|
||
\q2 sí \nd Olúwa\nd* àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Wọ́n sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já,
|
||
\q2 kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín;
|
||
\q2 Olúwa fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nígbà náà ni yóò bá wọn wí ní ìbínú rẹ̀
|
||
\q2 yóò sì dẹ́rùbà wọ́n ní ìrunú rẹ̀, ó wí pé,
|
||
\q1
|
||
\v 6 “Èmi ti fi ọba mi sí ipò
|
||
\q2 lórí Sioni, òkè mímọ́ mi.”
|
||
\p
|
||
\v 7 \x - \xo 2.7: \xt Mt 3.17; Ap 13.33; Hb 1.5; 5.5; 2Pt 1.17.\x*Èmi yóò sì kéde ìpinnu \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q1 Ó sọ fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi;
|
||
\q2 lónìí, èmi ti di baba rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 \x - \xo 2.8-9: \xt If 2.26; 12.5; 19.15.\x*Béèrè lọ́wọ́ mi,
|
||
\q2 Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè di ìní rẹ,
|
||
\q2 òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn
|
||
\q2 ìwọ yóò sì rún wọn wómúwómú bí ìkòkò amọ̀.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n;
|
||
\q2 ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ẹ sin \nd Olúwa\nd* pẹ̀lú ìbẹ̀rù
|
||
\q2 ẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Fi ẹnu ko ọmọ náà ní ẹnu, kí ó má ba à bínú,
|
||
\q2 kí ó má ba à pa yín run ní ọ̀nà yín,
|
||
\q1 nítorí ìbínú rẹ̀ lè ru sókè ní ẹ̀ẹ̀kan.
|
||
\q2 Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó fi í ṣe ibi ìsádi wọn.
|
||
\c 3
|
||
\cl Saamu 3
|
||
\d Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí!
|
||
\q2 Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé
|
||
\q2 “Ọlọ́run kò nígbà á là.” \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.
|
||
\q1
|
||
\v 4 \nd Olúwa\nd* ni mo kígbe sókè sí,
|
||
\q2 ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn;
|
||
\q2 mo sì tún padà jí, nítorí \nd Olúwa\nd* ni ó ń gbé mi ró.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn
|
||
\q2 tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Dìde, \nd Olúwa\nd*!
|
||
\q2 Gbà mí, Ọlọ́run mi!
|
||
\q1 Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n;
|
||
\q2 kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd* ni ìgbàlà ti wá.
|
||
\q2 Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. \qs Sela.\qs*
|
||
\c 4
|
||
\cl Saamu 4
|
||
\d Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Dá mi lóhùn nígbà tí mo bá pè ọ́,
|
||
\q2 ìwọ Ọlọ́run òdodo mi.
|
||
\q1 Fún mi ní ìdáǹdè nínú ìpọ́njú mi;
|
||
\q2 ṣàánú fún mi, kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, ẹ̀yin ọmọ ènìyàn, tí ẹ ó ṣe sọ ògo mi di ìtìjú?
|
||
\q2 Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, tí ẹ̀yin yóò ṣe fẹ́ràn ìtànjẹ àti tí ẹ̀yin yóò fi máa wá ọlọ́run èké?
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ṣùgbọ́n kí ẹ mọ̀ pé, \nd Olúwa\nd* ti ya ẹni olódodo sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* yóò gbọ́ nígbà tí mo bá pè é.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 4.4: \xt Ef 4.26.\x*Ẹ bínú ẹ má ṣe ṣẹ̀,
|
||
\q2 nígbà tí ẹ bá wà lórí ibùsùn yín,
|
||
\q2 ẹ bá ọkàn yín sọ̀rọ̀, kí ó sì dákẹ́ jẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹ rú ẹbọ òdodo
|
||
\q2 kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ló ń béèrè pé, “Ta ni yóò ṣe rere fún wa?”
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, jẹ́ kí ojú rẹ mọ́lẹ̀ sí wa lára,
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìwọ ti fi ayọ̀ púpọ̀ kún ọkàn mi
|
||
\q2 ju ìgbà tí hóró irúgbìn àti wáìnì tuntun wọ́n pọ̀ fún mi lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Èmi yóò dùbúlẹ̀, èmi ó sì sùn ní àlàáfíà,
|
||
\q2 nítorí ìwọ nìkan, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ni o mú mi gbé láìléwu.
|
||
\c 5
|
||
\cl Saamu 5
|
||
\d Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin fífọn. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 kíyèsi àròyé mi.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Fi etí sílẹ̀ sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́,
|
||
\q2 ọba mi àti Ọlọ́run mi,
|
||
\q2 nítorí ìwọ ni mo gba àdúrà sí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ní òwúrọ̀, \nd Olúwa\nd*, ìwọ yóò gbọ́ ohùn mi;
|
||
\q2 ní òwúrọ̀, èmi yóò gbé ẹ̀bẹ̀ mi sí iwájú rẹ̀
|
||
\q2 èmi yóò sì dúró ní ìrètí.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọ́run tí ó ní inú dídùn sí búburú;
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi kò le è bá ọ gbé.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Àwọn agbéraga kò le è dúró
|
||
\q2 níwájú rẹ̀.
|
||
\q1 Ìwọ kórìíra gbogbo àwọn aṣebi;
|
||
\q2
|
||
\v 6 ìwọ yóò pa àwọn tí ń ṣe èké run.
|
||
\q1 Apani àti ẹni ẹ̀tàn ènìyàn
|
||
\q2 ni \nd Olúwa\nd* yóò kórìíra.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ṣùgbọ́n èmi, nípa títóbi àánú rẹ̀,
|
||
\q2 èmi yóò wá sínú ilé rẹ̀;
|
||
\q1 ní tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni èmi yóò tẹríba
|
||
\q2 sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Tọ́ mi, \nd Olúwa\nd*, nínú òdodo rẹ,
|
||
\q2 nítorí àwọn ọ̀tá mi,
|
||
\q2 mú ọ̀nà rẹ tọ́ níwájú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 9 \x - \xo 5.9: \xt Ro 3.13.\x*Kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ẹnu wọn tí a lè gbàgbọ́;
|
||
\q2 ọkàn wọn kún fún ìparun.
|
||
\q1 Ọ̀nà ọ̀fun wọn ni isà òkú tí ó ṣí sílẹ̀;
|
||
\q2 pẹ̀lú ahọ́n wọn ni wọ́n ń sọ ẹ̀tàn.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Dá wọn lẹ́bi Ọlọ́run!
|
||
\q2 Jẹ́ kí rìkíṣí wọn jẹ́ ìṣubú wọn.
|
||
\q1 Lé wọn jáde nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
|
||
\q2 nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ṣùgbọ́n, jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó sádi ọ́ kí ó yọ̀;
|
||
\q2 jẹ kí wọn máa kọrin fún ayọ̀ títí.
|
||
\q1 Tan ààbò rẹ sórí wọn,
|
||
\q2 àti àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ yóò máa yọ̀ nínú rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Dájúdájú, \nd Olúwa\nd*, ìwọ bùkún olódodo;
|
||
\q2 ìwọ fi ojúrere rẹ yí wọn ká bí asà.
|
||
\c 6
|
||
\cl Saamu 6
|
||
\d Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin olókùn. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ
|
||
\q2 kí ìwọ má ṣe nà mí nínú gbígbóná ìrunú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ṣàánú fún mi, \nd Olúwa\nd*, nítorí èmi ń kú lọ;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, wò mí sán, nítorí egungun mi wà nínú ìnira.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọkàn mi wà nínú ìrora.
|
||
\q2 Yóò ti pẹ́ tó, \nd Olúwa\nd*, yóò ti pẹ́ tó?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Yípadà, \nd Olúwa\nd*, kí o sì gbà mí;
|
||
\q2 gbà mí là nípa ìfẹ́ rẹ tí kì í ṣákì í.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹnikẹ́ni kò ni rántí rẹ nígbà tí ó bá kú.
|
||
\q2 Ta ni yóò yìn ọ́ láti inú isà òkú?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Agara ìkérora mi dá mi tán.
|
||
\b
|
||
\q1 Gbogbo òru ni mo wẹ ibùsùn mi pẹ̀lú ẹkún,
|
||
\q2 mo sì fi omi rin ibùsùn mi pẹ̀lú omijé.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ojú mi di aláìlera pẹ̀lú ìbànújẹ́;
|
||
\q2 wọ́n kùnà nítorí gbogbo ọ̀tá mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 \x - \xo 6.8: \xt Mt 7.23; Lk 13.27.\x*Kúrò lọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣe iṣẹ́ ibi,
|
||
\q2 nítorí \nd Olúwa\nd* ti gbọ́ igbe mi.
|
||
\q1
|
||
\v 9 \nd Olúwa\nd* ti gbọ́ ẹkún mi fún àánú;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ti gba àdúrà mi.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Gbogbo àwọn ọ̀tá mi lójú yóò tì, wọn yóò sì dààmú;
|
||
\q2 wọn yóò sì yípadà nínú ìtìjú àìròtẹ́lẹ̀.
|
||
\c 7
|
||
\cl Saamu 7
|
||
\d Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí \nd Olúwa\nd* nípa Kuṣi, ará Benjamini.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ;
|
||
\q2 gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,
|
||
\q1
|
||
\v 2 kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún,
|
||
\q2 wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí
|
||
\q2 tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi,
|
||
\q2 tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí,
|
||
\q1
|
||
\v 5 nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi;
|
||
\q2 jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀
|
||
\q2 kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Dìde, \nd Olúwa\nd*, nínú ìbínú rẹ;
|
||
\q2 dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi.
|
||
\q2 Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká.
|
||
\q2 Jọba lórí wọn láti òkè wá.
|
||
\q2
|
||
\v 8 Jẹ́ kí \nd Olúwa\nd* ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.
|
||
\q1 Ṣe ìdájọ́ mi, \nd Olúwa\nd*, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.
|
||
\q1
|
||
\v 9 \x - \xo 7.9: \xt If 2.23.\x*Ọlọ́run Olódodo,
|
||
\q2 Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn,
|
||
\q1 tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú
|
||
\q2 tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run,
|
||
\q2 ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́,
|
||
\q2 Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Bí kò bá yípadà,
|
||
\q2 Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú;
|
||
\q2 ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀;
|
||
\q2 ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ẹni tí ó lóyún ohun búburú,
|
||
\q2 tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde
|
||
\q2 jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀;
|
||
\q2 ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Èmi ó fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd* nítorí òdodo rẹ̀,
|
||
\q2 èmi ó kọrin ìyìn sí \nd Olúwa\nd* Ọ̀gá-ògo jùlọ.
|
||
\c 8
|
||
\cl Saamu 8
|
||
\d Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, Olúwa wa,
|
||
\q2 orúkọ rẹ̀ ti ní ìyìn tó ní gbogbo ayé!
|
||
\b
|
||
\q1 Ìwọ ti gbé ògo rẹ ga
|
||
\q2 ju àwọn ọ̀run lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 \x - \xo 8.2: \xt Mt 21.16.\x*Láti ẹnu ọmọ ọwọ́ àti ọmọ ọmú
|
||
\q2 ni o ti yan ìyìn nítorí àwọn ọ̀tá rẹ,
|
||
\q2 láti pa àwọn ọ̀tá àti àwọn olùgbẹ̀san lẹ́nu mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nígbà tí mo ro ọ̀run rẹ,
|
||
\q2 iṣẹ́ ìka rẹ,
|
||
\q1 òṣùpá àti ìràwọ̀,
|
||
\q2 tí ìwọ tí gbé kalẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 4 kí ni ènìyàn tí ìwọ ń rò nípa rẹ̀,
|
||
\q2 àní ọmọ ènìyàn tí ìwọ ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ ṣe é ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju Ọlọ́run lọ,
|
||
\q2 ìwọ sì dé e ní adé ògo àti ọlá.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìwọ mú un jẹ ọba lórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ;
|
||
\q2 ìwọ sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀:
|
||
\q1
|
||
\v 7 àwọn agbo àgùntàn àti àwọn màlúù,
|
||
\q2 àti ẹranko igbó,
|
||
\q1
|
||
\v 8 ẹyẹ ojú ọrun,
|
||
\q2 àti ẹja inú Òkun,
|
||
\q2 àti ohun tí ń wẹ nínú ipa Òkun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 \nd Olúwa\nd*, Olúwa wa,
|
||
\q2 orúkọ rẹ ti ní ìyìn tó ní gbogbo ayé!
|
||
\c 9
|
||
\cl Saamu 9
|
||
\d Fún adarí orin. Ní ti ohun orin. “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi ó yìn ọ́, \nd Olúwa\nd*, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi;
|
||
\q2 èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ;
|
||
\q2 èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà;
|
||
\q2 wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú;
|
||
\q2 ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run;
|
||
\q2 Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá,
|
||
\q2 ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu;
|
||
\q2 àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 \nd Olúwa\nd* jẹ ọba títí láé;
|
||
\q2 ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 8 \x - \xo 9.8: \xt Ap 17.31.\x*Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo;
|
||
\q2 yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.
|
||
\q1
|
||
\v 9 \nd Olúwa\nd* ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,
|
||
\q2 ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ,
|
||
\q2 nítorí, \nd Olúwa\nd*, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Kọ orin ìyìn sí \nd Olúwa\nd*, tí o ń jẹ ọba ní Sioni;
|
||
\q2 kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí;
|
||
\q2 òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 \nd Olúwa\nd*, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi!
|
||
\q2 Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,
|
||
\q1
|
||
\v 14 kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ
|
||
\q2 ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni
|
||
\q2 àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́;
|
||
\q2 ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 16 A mọ \nd Olúwa\nd* nípa òdodo rẹ̀;
|
||
\q2 àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú,
|
||
\q2 àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé,
|
||
\q2 ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Dìde, \nd Olúwa\nd*, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí;
|
||
\q2 jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. \qs Sela.\qs*
|
||
\c 10
|
||
\cl Saamu 10
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èéha ti ṣe, \nd Olúwa\nd*, tí ìwọ fi dúró ní òkè réré?
|
||
\q2 Èéha ti ṣe, tí ìwọ fi ara rẹ pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nínú àrékérekè ni ènìyàn búburú tí mu aláìlera,
|
||
\q2 ẹni ti ó mú nínú ìdẹ̀kùn àrékérekè rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí ènìyàn búburú ń ṣògo ìfẹ́ inú ọkàn rẹ̀;
|
||
\q2 Ó bùkún olójúkòkòrò, ó sì ń kẹ́gàn \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ènìyàn búburú kò lè rí nínú ìgbéraga rẹ̀;
|
||
\q2 kò sí ààyè fún Ọlọ́run nínú gbogbo èrò rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ọ̀nà rẹ̀ ń gún régé nígbà gbogbo;
|
||
\q2 òun ń gbéraga, òfin rẹ̀ sì jìnnà sí i;
|
||
\q2 òun kẹ́gàn àwọn ọ̀tá rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 O wí fún ara rẹ̀, “Kò sí ohun tí ó lè mì mí.
|
||
\q2 Inú mi yóò máa dùn nígbà gbogbo, èmi kò sì ní ní wàhálà.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 \x - \xo 10.7: \xt Ro 3.14.\x*Ẹnu rẹ̀ kún fún ègún àti irọ́ àti ìtànjẹ;
|
||
\q2 wàhálà àti ohun búburú wà lábẹ́ ahọ́n rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ó lúgọ ní bùba nítòsí ìletò.
|
||
\q2 Ò gọ níbi ìkọ̀kọ̀ láti pa aláìṣẹ̀.
|
||
\q1 Ojú rẹ̀ ń ṣọ́ àwọn tálákà ní ìkọ̀kọ̀.
|
||
\q2
|
||
\v 9 Ó ba ní ní bùba bí i kìnnìún nínú pàǹtí;
|
||
\q1 Ó ba ní bùba láti mú àwọn aláìní ìrànwọ́;
|
||
\q2 ó mú àwọn aláìlólùrànlọ́wọ́, ó sì wọ́ wọn lọ sínú àwọ̀n rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ó ba, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀;
|
||
\q2 kí tálákà ba à le bọ́ sí ọwọ́ agbára rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ó wí fún ara rẹ̀, “Ọlọ́run ti gbàgbé;
|
||
\q2 Ó pa ojú rẹ̀ mọ́, òun kì yóò rí i láéláé.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Dìde, \nd Olúwa\nd*! Gbé ọwọ́ rẹ sókè, Ọlọ́run.
|
||
\q2 Má ṣe gbàgbé àwọn olùpọ́njú.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Èéṣe tí ènìyàn búburú ṣe ń kẹ́gàn Ọlọ́run?
|
||
\q2 Èéṣe tí o fi wí nínú ọkàn ara rẹ̀,
|
||
\q2 “Kò ní pè mí láti ṣe ìṣirò”?
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni ó rí wàhálà àti ìrora;
|
||
\q2 Ìwọ rò láti fi sí ọwọ́ rẹ.
|
||
\q1 Tálákà fi ara rẹ̀ jì fún ọ;
|
||
\q2 Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìní baba.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ṣẹ́ apá àwọn ènìyàn búburú àti ènìyàn ibi;
|
||
\q2 pè é láti wá ṣírò fún ìwà ìkà rẹ̀
|
||
\q2 tí a kò le è rí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 \nd Olúwa\nd* ń jẹ ọba láé àti láéláé;
|
||
\q2 àwọn orílẹ̀-èdè yóò ṣègbé lórí ilé rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ìwọ́ gbọ́, \nd Olúwa\nd*, ìfẹ́ àwọn tí a ni lára;
|
||
\q2 Ìwọ gbà wọ́n níyànjú, ó sì gbọ́ igbe wọn,
|
||
\q1
|
||
\v 18 láti ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní baba àti àwọn ti a ni lára,
|
||
\q2 kí ọkùnrin, tí ó wà ní ayé,
|
||
\q2 kí ó má ṣe dẹ́rùbà ni mọ́.
|
||
\c 11
|
||
\cl Saamu 11
|
||
\d Fún adarí orin. Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q2 Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé,
|
||
\q2 “Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀;
|
||
\q2 wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn
|
||
\q1 láti tafà níbi òjìji
|
||
\q2 sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́
|
||
\q2 kí ni olódodo yóò ṣe?”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 \nd Olúwa\nd* ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run.
|
||
\q1 Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn;
|
||
\q2 ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.
|
||
\q1
|
||
\v 5 \nd Olúwa\nd* ń yẹ olódodo wò,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá
|
||
\q2 ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò
|
||
\q2 ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó;
|
||
\q2 àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nítorí, olódodo ní \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 o fẹ́ràn òdodo;
|
||
\q2 ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.
|
||
\c 12
|
||
\cl Saamu 12
|
||
\d Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ràn wá lọ́wọ́, \nd Olúwa\nd*, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́;
|
||
\q2 olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀;
|
||
\q2 ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kí \nd Olúwa\nd* kí ó gé ètè èké wọn
|
||
\q2 àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu
|
||
\q1
|
||
\v 4 tí ó wí pé,
|
||
\q2 “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa;
|
||
\q2 àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 “Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní,
|
||
\q2 Èmi yóò dìde nísinsin yìí,” ni \nd Olúwa\nd* wí.
|
||
\q2 “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn.”
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọ̀rọ̀ \nd Olúwa\nd* sì jẹ aláìlábùkù,
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀,
|
||
\q2 tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 \nd Olúwa\nd*, ìwọ yóò pa wá mọ́
|
||
\q2 kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri
|
||
\q2 nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.
|
||
\c 13
|
||
\cl Saamu 13
|
||
\d Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Yóò ti pẹ́ tó, \nd Olúwa\nd*? Ìwọ o ha gbàgbé mi títí láé?
|
||
\q2 Yóò tí pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa fi ojú rẹ pamọ́ fún mi?
|
||
\q1
|
||
\v 2 Yóò ti pẹ́ tó tí èmi ó máa bá èrò mi jà,
|
||
\q2 àti ní ojoojúmọ́ ni èmi ń ní ìbànújẹ́ ní ọkàn mi?
|
||
\q2 Yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ọ̀tá mi yóò máa borí mi?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Wò mí kí o sì dá mi lóhùn, \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run mi.
|
||
\q2 Fi ìmọ́lẹ̀ fún ojú mi, kí èmi ó má sún oorun ikú.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ọ̀tá mi wí pé, “Èmi ti ṣẹ́gun rẹ̀,”
|
||
\q2 àwọn ọ̀tá mi yóò yọ̀ tí mo bá ṣubú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ṣùgbọ́n mo gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà;
|
||
\q2 ọkàn mi ń yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmi ó máa kọrin sí \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí ó dára sí mi.
|
||
\c 14
|
||
\cl Saamu 14
|
||
\d Fún adarí orin. Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 14.1-3: \xt Ro 3.10-12.\x*\x - \xo 14.1-7: \xt Sm 53.1-6.\x*Aṣiwèrè wí nínú ọkàn rẹ̀ pé,
|
||
\q2 “Ko sí Ọlọ́run.”
|
||
\q1 Wọ́n díbàjẹ́, iṣẹ́ wọn sì burú;
|
||
\q2 kò sí ẹnìkan tí yóò ṣe rere.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd* sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run wá
|
||
\q2 lórí àwọn ọmọ ènìyàn
|
||
\q1 bóyá ó le rí ẹni tí òye yé,
|
||
\q2 ẹnikẹ́ni tó ń wá Ọlọ́run.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Gbogbo wọn sì ti yípadà, gbogbo wọn sì ti díbàjẹ́;
|
||
\q2 kò sì ṣí ẹni tí ó ń ṣe rere,
|
||
\q2 kò sí ẹnìkan.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ǹjẹ́ olùṣe búburú kò ha ní ìmọ̀?
|
||
\b
|
||
\q1 Àwọn tí ó ń pa ènìyàn mi jẹ bí ẹní jẹun;
|
||
\q2 wọn kò sì ké pe \nd Olúwa\nd*?
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọ́n wà níbẹ̀, tí a bò mọ́lẹ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù,
|
||
\q2 nítorí Ọlọ́run wà ní àwùjọ àwọn olódodo.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ẹ̀yin olùṣe búburú da èrò àwọn tálákà rú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n \nd Olúwa\nd* ni ààbò wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìgbàlà àwọn Israẹli yóò ti Sioni wá!
|
||
\q2 Nígbà tí \nd Olúwa\nd* bá mú ìkólọ àwọn ènìyàn rẹ̀ padà,
|
||
\q2 jẹ́ kí Jakọbu kí ó yọ̀, kí inú Israẹli kí ó dùn!
|
||
\c 15
|
||
\cl Saamu 15
|
||
\d Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, ta ni yóò máa ṣe àtìpó nínú àgọ́ rẹ?
|
||
\q2 Ta ni yóò máa gbé ní òkè mímọ́ rẹ?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹni tí ń rìn déédé
|
||
\q2 tí ó sì ń sọ òtítọ́,
|
||
\q2 láti inú ọkàn rẹ̀;
|
||
\q1
|
||
\v 3 tí kò fi ahọ́n rẹ̀ sọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn,
|
||
\q2 tí kò ṣe ibi sí aládùúgbò rẹ̀
|
||
\q2 tí kò sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí ẹnìkejì rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 4 ní ojú ẹni tí ènìyànkénìyàn di gígàn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó bọ̀wọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q1 ẹni tí ó búra sí ibi ara rẹ̀
|
||
\q2 àní tí kò sì yípadà,
|
||
\q1
|
||
\v 5 tí ó ń yá ni lówó láìsí èlé
|
||
\q2 tí kò sì gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lòdì sí aláìlẹ́ṣẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe èyí
|
||
\q2 ni a kì yóò mì láéláé.
|
||
\c 16
|
||
\cl Saamu 16
|
||
\d Miktamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Pa mí mọ́, Ọlọ́run,
|
||
\q2 nítorí nínú rẹ ni ààbò mi wà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Mo sọ fún \nd Olúwa\nd*, “Ìwọ ni Olúwa mi,
|
||
\q2 lẹ́yìn rẹ èmi kò ní ìre kan.”
|
||
\q1
|
||
\v 3 Sí àwọn ènìyàn tí ó wà ní ayé,
|
||
\q2 àwọn ni ológo nínú èyí tí ayọ̀ mí wà.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìṣòro àwọn wọ̀n-ọn-nì yóò pọ̀ sí i, àní àwọn tí ń tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn.
|
||
\q2 Ẹbọ ohun mímu ẹ̀jẹ̀ wọn ni èmi kì yóò ta sílẹ̀,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá orúkọ wọn lẹ́nu mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 \nd Olúwa\nd*, ni ìpín ìní mi tí mo yàn àti ago mi,
|
||
\q2 ó ti pa ohun tí í ṣe tèmi mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Okùn ààlà ilẹ̀ ti bọ́ sí ọ̀dọ̀ mi ní ibi dídára;
|
||
\q2 nítòótọ́ mo ti ní ogún rere.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Èmi yóò yin \nd Olúwa\nd*, ẹni tí ó gbà mí ní ìyànjú;
|
||
\q2 ní òru, ọkàn mí ń bá mi sọ̀rọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 8 \x - \xo 16.8-11: \xt Ap 2.25-28,31.\x*Mo ti gbé \nd Olúwa\nd* síwájú mi ní ìgbà gbogbo.
|
||
\q2 Nítorí tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún mi, a kì yóò mì mí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítorí èyí, ọkàn mi yọ̀, ahọ́n mi pẹ̀lú ń fò fáyọ̀;
|
||
\q2 ara mi pẹ̀lú yóò sinmi ní ààbò,
|
||
\q1
|
||
\v 10 \x - \xo 16.10: \xt Ap 13.35.\x*nítorí ìwọ kò ní fi ọ̀kan sílẹ̀ nínú isà òkú,
|
||
\q2 tàbí kí ìwọ jẹ́ kí ẹni mímọ́ rẹ kí ó rí ìdíbàjẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìwọ ti fi ipa ọ̀nà ìyè hàn mí;
|
||
\q2 Ìwọ yóò kún mi pẹ̀lú ayọ̀ ní iwájú rẹ,
|
||
\q2 pẹ̀lú ìdùnnú ayérayé ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
|
||
\c 17
|
||
\cl Saamu 17
|
||
\d Àdúrà ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Gbọ́, \nd Olúwa\nd*, ẹ̀bẹ̀ òtítọ́ mi;
|
||
\q2 fi etí sí igbe mi.
|
||
\q1 Tẹ́tí sí àdúrà mi
|
||
\q2 tí kò ti ètè ẹ̀tàn jáde.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Kí ìdáláre mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ;
|
||
\q2 kí ojú rẹ kí ó rí ohun tí ó tọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ìwọ ti dán àyà mi wò,
|
||
\q2 ìwọ sì bẹ̀ mí wò ní òru, o sì ti wádìí mi,
|
||
\q1 ìwọ kì yóò rí ohunkóhun èmi ti pinnu pé,
|
||
\q2 ẹnu mi kì yóò ṣẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Bí ó ṣe ti iṣẹ́ ènìyàn nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ,
|
||
\q2 èmi ti pa ara mi mọ́
|
||
\q2 kúrò ní ọ̀nà àwọn ìkà.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìrìn mí ti jẹ mọ́ ọ̀nà rẹ;
|
||
\q2 ẹsẹ̀ mi kì yóò yọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmi ké pè ọ́, Ọlọ́run, nítorí tí ìwọ yóò dá mi lóhùn
|
||
\q2 dẹ etí rẹ sí mi kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Fi ìṣeun ìyanu ìfẹ́ ńlá rẹ hàn
|
||
\q2 ìwọ tí ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gba àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ là
|
||
\q2 lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú rẹ;
|
||
\q2 fi mí pamọ́ sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ,
|
||
\q1
|
||
\v 9 lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú tí ń fóròó mi,
|
||
\q2 kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá apani tí ó yí mi ká.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Wọ́n pa ọkàn aláìláàánú wọn mọ́,
|
||
\q2 wọ́n sì fi ẹnu wọn sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Wọ́n sì mú mi mọ́lẹ̀, wọ́n sì yí mi ká,
|
||
\q2 pẹ̀lú ojú ìṣọ́ra láti ṣọ́ mi sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Wọn dàbí i kìnnìún tí ebi ń pa fún ìjẹ,
|
||
\q2 àní bí kìnnìún ńlá tí ó ń ba níbi ìkọ̀kọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Dìde, \nd Olúwa\nd*, dojúkọ wọ́n, rẹ̀ wọ́n sílẹ̀;
|
||
\q2 gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ẹni búburú nípa idà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 14 \nd Olúwa\nd*, nípa ọwọ́ rẹ, gbà mí kúrò lọ́wọ́ irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀,
|
||
\q2 kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn ayé yìí, tí èrè wọn wà nínú ayé yìí.
|
||
\q1 Ìwọ ń pa ebi àwọn tí ìwọ fẹ́ràn lẹ́nu mọ́;
|
||
\q2 àwọn ọmọ wọn sì ní ọ̀pọ̀lọpọ̀,
|
||
\q2 wọ́n sì kó ọrọ̀ jọ fún àwọn ọmọ wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi yóò máa wo ojú rẹ ní òdodo;
|
||
\q2 nígbà tí èmi bá jí, èmi yóò ní ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí èmi bá rí àwòrán rẹ.
|
||
\c 18
|
||
\cl Saamu 18
|
||
\d Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ \nd Olúwa\nd* tí ó kọ sí \nd Olúwa\nd*, ọ̀rọ̀ orin tí ó kọ sí \nd Olúwa\nd* fún ìdáǹdè kúrò lọ́wọ́ Saulu ọ̀tá rẹ̀. Ó wí pé.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 18.1-50: \xt 2Sa 22.2-51.\x*Mo fẹ́ ọ, \nd Olúwa\nd*, agbára mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd* ni àpáta àti odi mi, àti olùgbàlà mi;
|
||
\q2 Ọlọ́run mi ni àpáta mi, ẹni tí mo fi ṣe ibi ìsádi mi.
|
||
\q2 Òun ni àpáta ààbò àti ìwo ìgbàlà mi àti ibi ìsádi mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Mo ké pe \nd Olúwa\nd*, ẹni tí ìyìn yẹ fún,
|
||
\q2 a ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìrora ikú yí mi kà,
|
||
\q2 àti ìṣàn omi àwọn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Okùn isà òkú yí mi ká,
|
||
\q2 ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nínú ìpọ́njú mo ké pe \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 mo sọkún sí \nd Olúwa\nd* mi fún ìrànlọ́wọ́.
|
||
\q1 Láti inú tẹmpili rẹ̀, ó gbọ́ igbe mi;
|
||
\q2 ẹkún mi wá sí iwájú rẹ̀, sí inú etí rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ayé wárìrì, ó sì mì tìtì,
|
||
\q2 ìpìlẹ̀ àwọn òkè gíga sì ṣídìí;
|
||
\q2 wọ́n wárìrì nítorí tí ó ń bínú.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá;
|
||
\q2 iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá,
|
||
\q2 ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ó pín àwọn ọ̀run, Ó sì jáde wá;
|
||
\q2 àwọsánmọ̀ dúdú sì wà ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ó gun orí kérúbù, ó sì fò;
|
||
\q2 ó ń rábàbà lórí ìyẹ́ apá afẹ́fẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ó fi òkùnkùn ṣe ibojì rẹ̀, ó fi ṣe ìbòrí yí ara rẹ̀ ká
|
||
\q2 kurukuru òjò dúdú ní ojú ọ̀run.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nípa ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀, àwọsánmọ̀ ṣíṣú dudu rẹ kọjá lọ
|
||
\q2 pẹ̀lú yìnyín àti ẹ̀yín iná
|
||
\q1
|
||
\v 13 \nd Olúwa\nd* sán àrá láti ọ̀run wá;
|
||
\q2 Ọ̀gá-ògo sì fọ ohun rẹ̀; yìnyín àti ẹ̀yin iná.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ó ta àwọn ọfà rẹ̀, ó sì tú àwọn ọ̀tá náà ká,
|
||
\q2 ọfà mọ̀nàmọ́ná ńlá sì dà wọ́n rú.
|
||
\q1
|
||
\v 15 A sì fi ìsàlẹ̀ àwọn òkun hàn,
|
||
\q2 a sì rí àwọn ìpìlẹ̀ ayé
|
||
\q1 nípa ìbáwí rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nípa fífún èémí ihò imú rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ó sọ̀kalẹ̀ láti ibi gíga, ó sì dì mímú;
|
||
\q2 Ó fà mí jáde láti inú omi jíjìn.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára,
|
||
\q2 láti ọwọ́ àwọn ọ̀tá, ti ó lágbára jù fún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Wọ́n dojúkọ mí ní ọjọ́ ìpọ́njú mi;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n \nd Olúwa\nd* ni alátìlẹ́yìn mi.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ó mú mi jáde wá sínú ibi ńlá;
|
||
\q2 Ó gbà mí nítorí tí ó ní inú dídùn sí mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 \nd Olúwa\nd* ti hùwà sí mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi, ó ti fi èrè fún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Nítorí mo ti pa ọ̀nà \nd Olúwa\nd* mọ́;
|
||
\q2 èmi kò ṣe búburú nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Gbogbo òfin rẹ̀ ni ó wà níwájú mi;
|
||
\q2 èmi kò sì yípadà kúrò nínú ìlànà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Mo ti jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú rẹ̀;
|
||
\q2 mo sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 24 \nd Olúwa\nd* san ẹ̀san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi níwájú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Fún olóòtítọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní olóòtítọ́,
|
||
\q2 sí aláìlẹ́bi, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní aláìlẹ́bi,
|
||
\q1
|
||
\v 26 sí ọlọ́kàn mímọ́, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní ọlọ́kàn mímọ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n sí ọlọ́kàn-wíwọ́, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní òǹrorò.
|
||
\q1
|
||
\v 27 O pa onírẹ̀lẹ̀ mọ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó rẹ àwọn ti ń gbéraga sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ìwọ, \nd Olúwa\nd*, jẹ́ kí fìtílà mi
|
||
\q2 kí ó máa tàn; Ọlọ́run mi, yí òkùnkùn mi padà sí ìmọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ rẹ̀, èmi sáré tọ ogun lọ;
|
||
\q2 pẹ̀lú Ọlọ́run mi mo lè fo odi kan.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Bí ó ṣe ti Ọlọ́run mi, ọ̀nà rẹ̀ pé,
|
||
\q2 a ti rídìí ọ̀rọ̀ \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 òun ni àpáta ààbò fún gbogbo àwọn tí ó fi ṣe ààbò.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Nítorí ta ni ṣe Ọlọ́run bí kò ṣe \nd Olúwa\nd*?
|
||
\q2 Ta ní àpáta bí kò ṣe \nd Olúwa\nd* wa?
|
||
\q1
|
||
\v 32 Ọlọ́run ni ẹni tí ó fi agbára dì mí ní àmùrè
|
||
\q2 ó sì mú ọ̀nà mi pé.
|
||
\q1
|
||
\v 33 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi gẹ́gẹ́ bi ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín;
|
||
\q2 ó jẹ́ ki n lè dúró lórí ibi gíga.
|
||
\q1
|
||
\v 34 Ó kọ́ ọwọ́ mi ni ogun jíjà;
|
||
\q2 apá mi lè tẹ ọrùn idẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 35 Ìwọ fi asà ìṣẹ́gun rẹ̀ fún mi,
|
||
\q2 ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ gbé mí dúró;
|
||
\q2 àti ìwà pẹ̀lẹ́ rẹ̀ sọ mí di ńlá.
|
||
\q1
|
||
\v 36 Ìwọ sọ ìrìn ẹsẹ̀ mi di ńlá ní ìsàlẹ̀ mi,
|
||
\q2 kí kókó-ẹsẹ̀ mi má ṣe yẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 37 Èmi lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì bá wọn
|
||
\q2 èmi kò sì padà lẹ́yìn wọn títí a fi run wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 38 Èmi sá wọn ní ọgbẹ́ tí wọn ko fi le è dìde;
|
||
\q2 wọ́n ṣubú ní abẹ́ ẹsẹ̀ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 39 Nítorí ìwọ fi agbára dì mí ní àmùrè fún ogun náà;
|
||
\q2 ìwọ ti mú àwọn tí ó dìde si mí tẹríba ní abẹ́ ẹsẹ̀ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 40 Ìwọ yí ẹ̀yìn àwọn ọ̀tá mí padà sí mi
|
||
\q2 èmi sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
|
||
\q1
|
||
\v 41 Wọ́n kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbà wọ́n,
|
||
\q2 àní sí \nd Olúwa\nd*, ṣùgbọ́n kò dá wọn lóhùn.
|
||
\q1
|
||
\v 42 Mo lù wọ́n gẹ́gẹ́ bí eruku níwájú afẹ́fẹ́;
|
||
\q2 mo dà wọ́n síta gẹ́gẹ́ bí ẹrọ̀fọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 43 Ìwọ ti gbà mí lọ́wọ́ ìkọlù àwọn ènìyàn;
|
||
\q2 Ìwọ ti fi mí ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè.
|
||
\q1 Àwọn ènìyàn ti èmi kò mọ, yóò sì máa sìn mí,
|
||
\q2
|
||
\v 44 ni wéré ti wọ́n gbọ́ ohùn mi, wọ́n pa àṣẹ mi mọ́;
|
||
\q2 àwọn ọmọ àjèjì yóò tẹríba fún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 45 Àyà yóò pá àlejò;
|
||
\q2 wọn yóò sì fi ìbẹ̀rù jáde láti ibi kọ́lọ́fín wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 46 \nd Olúwa\nd* wà láààyè! Olùbùkún ni àpáta mi!
|
||
\q2 Gbígbéga ní Ọlọ́run Olùgbàlà mi.
|
||
\q1
|
||
\v 47 Òun ni Ọlọ́run tí ó ń gbẹ̀san mi,
|
||
\q2 tí ó sì ń ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní abẹ́ mi,
|
||
\q2
|
||
\v 48 tí ó pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mí.
|
||
\q1 Ìwọ gbé mi ga ju àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí mi lọ;
|
||
\q2 lọ́wọ́ àwọn ènìyàn alágbára ni ìwọ ti gbà mí.
|
||
\q1
|
||
\v 49 \x - \xo 18.49: \xt Ro 15.9.\x*Títí láéláé, èmi yóò máa yìn ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 èmi yóò sì máa kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 50 Ó fún ọba rẹ̀ ni ìṣẹ́gun ńlá;
|
||
\q2 ó fi ìkáàánú àìṣẹ̀tàn fún ẹni àmì òróró rẹ̀,
|
||
\q2 fún Dafidi àti ìran rẹ̀ títí láé.
|
||
\c 19
|
||
\cl Saamu 19
|
||
\d Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Àwọn ọ̀run ń sọ nípa ti ògo Ọlọ́run;
|
||
\q2 àwọsánmọ̀ ń sọ nípa ti iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Wọ́n ń fọhùn ní ọjọ́ dé ọjọ́;
|
||
\q2 wọ́n ń fi ìmọ̀ hàn ní alẹ́ dé alẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kò sí ohùn tàbí èdè
|
||
\q2 níbi tí a kò gbé gbọ́ ìró wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 19.4: \xt Ro 10.18.\x*Ohùn wọn jáde lọ sí gbogbo orílẹ̀ ayé,
|
||
\q2 ọ̀rọ̀ wọn títí dé òpin ilẹ̀ ayé.
|
||
\q1 Ó ti kọ́ àgọ́ fún oòrùn nínú àwọn ọ̀run.
|
||
\q2
|
||
\v 5 Tí ó dàbí ọkọ ìyàwó tí ó ń jáde ti yàrá rẹ̀ wá,
|
||
\q2 òun yọ bí alágbára ọkùnrin tí ó ń sáré ìje.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìjáde lọ rẹ̀ ni láti òpin ọ̀run wá
|
||
\q2 àti àyíká rẹ̀ sì dé ìpínlẹ̀ rẹ̀;
|
||
\q2 kò sì sí ohun tí ó pamọ́ kúrò nínú oore rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Pípé ni òfin \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ó ń yí ọkàn padà.
|
||
\q1 Ẹ̀rí \nd Olúwa\nd* dánilójú,
|
||
\q2 ó sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ìlànà \nd Olúwa\nd* tọ̀nà,
|
||
\q2 ó ń fi ayọ̀ fún ọkàn.
|
||
\q1 Àṣẹ \nd Olúwa\nd* ni mímọ́,
|
||
\q2 ó ń fi ìmọ́lẹ̀ fún ojú.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* mọ́,
|
||
\q2 ó ń faradà títí láéláé.
|
||
\q1 Ìdájọ́ \nd Olúwa\nd* dájú
|
||
\q2 òdodo ni gbogbo wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Wọn ṣọ̀wọ́n ju wúrà lọ,
|
||
\q2 ju wúrà tí o dára jùlọ,
|
||
\q1 wọ́n dùn ju oyin lọ,
|
||
\q2 àti ju afárá oyin lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Nípa wọn ni a ti ṣí ìránṣẹ́ rẹ̀ létí;
|
||
\q2 nípa pípa wọ́n mọ́, èrè púpọ̀ ń bẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ta ni ó lè mọ àṣìṣe rẹ̀?
|
||
\q2 Dáríjì mí nínú àṣìṣe mi tí ó pamọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Wẹ ìránṣẹ́ rẹ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀ọ́n-mọ̀-dá;
|
||
\q2 má ṣe jẹ kí wọn kí ó jẹ ọba lórí mi.
|
||
\q1 Nígbà náà ní èmi yóò dúró ṣinṣin,
|
||
\q2 èmi yóò sì ṣe aláìlẹ́bi kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi àti àṣàrò ọkàn mi
|
||
\q2 kí ó jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ,
|
||
\q2 Ìwọ \nd Olúwa\nd* àpáta mi, àti Olùdáǹdè mi.
|
||
\c 20
|
||
\cl Saamu 20
|
||
\d Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Kí \nd Olúwa\nd* kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú;
|
||
\q2 kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́
|
||
\q2 kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ
|
||
\q2 kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. \qs Sela.\qs*
|
||
\q1
|
||
\v 4 Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ
|
||
\q2 kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun
|
||
\q2 àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa.
|
||
\b
|
||
\q1 Kí \nd Olúwa\nd* kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* pa ẹni àmì òróró rẹ̀ mọ́.
|
||
\q1 Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá
|
||
\q2 pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 9 \nd Olúwa\nd*, fi ìṣẹ́gun fún ọba!
|
||
\q2 Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!
|
||
\c 21
|
||
\cl Saamu 21
|
||
\d Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Háà! \nd Olúwa\nd*, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ,
|
||
\q2 àti ní ìgbàlà rẹ, yóò ti yọ̀ pẹ́ tó!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu rẹ̀. \qs Sela.\qs*
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà
|
||
\q2 ìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un,
|
||
\q2 àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un;
|
||
\q2 ìwọ sì jẹ́ kí iyì ọláńlá rẹ̀ wà lára rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un:
|
||
\q2 ìwọ sì mú inú rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 nípasẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá-ògo tí kì í kùnà
|
||
\q2 kì yóò sípò padà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí;
|
||
\q2 ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò wá àwọn tí o kórìíra rẹ rí.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nígbà tí ìwọ bá yọ
|
||
\q2 ìwọ yóò mú wọn dàbí iná ìléru.
|
||
\q1 \nd Olúwa\nd* yóò gbé wọn mì nínú ìbínú rẹ̀,
|
||
\q2 àti pé iná rẹ̀ yóò jó wọn run.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀,
|
||
\q2 àti irú-ọmọ wọn kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ
|
||
\q2 wọ́n sì ń pète ìwà ìkà, wọn kì yóò ṣe àṣeyọrí.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà
|
||
\q2 nígbà tí o bá pinnu láti ta wọ́n ní ọfà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Gbígbéga ni ọ́ \nd Olúwa\nd*, nínú agbára rẹ;
|
||
\q2 a ó kọrin, a ó yín agbára a rẹ̀.
|
||
\c 22
|
||
\cl Saamu 22
|
||
\d Fún adarí orin. Tí ohùn orin “àgbọ̀nrín òwúrọ̀.” Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 22.1: \xt Mt 27.46; Mk 15.34.\x*Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀?
|
||
\q2 Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là,
|
||
\q2 àní sí igbe ìkérora mi?
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn:
|
||
\q2 àti ní òru èmi kò dákẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni Ìwọ;
|
||
\q2 ẹni tí ó tẹ ìyìn Israẹli dó.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ;
|
||
\q2 wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà;
|
||
\q2 ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójútì wọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn;
|
||
\q2 mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn, ẹlẹ́yà àwọn ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà;
|
||
\q2 wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí wọn pé.
|
||
\q1
|
||
\v 8 “Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 jẹ́ kí \nd Olúwa\nd* gbà á là.
|
||
\q1 Jẹ́ kí ó gbà á là,
|
||
\q2 nítorí pé, ó ní ayọ̀ nínú rẹ̀.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú;
|
||
\q2 ìwọ ni ó mú mi wà láìléwu, nígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá,
|
||
\q2 nígbà tí ìyá mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Má ṣe jìnnà sí mi,
|
||
\q2 nítorí pé ìyọnu súnmọ́ tòsí
|
||
\q2 kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká;
|
||
\q2 àwọn màlúù alágbára Baṣani rọ̀gbà yí mi ká.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri,
|
||
\q2 tí ń ké ramúramù.
|
||
\q1
|
||
\v 14 A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi,
|
||
\q2 gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé rẹ̀.
|
||
\q1 Ọkàn mi sì dàbí i ìda;
|
||
\q2 tí ó yọ́ láàrín inú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì,
|
||
\q2 ahọ́n mí sì tilẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi;
|
||
\q2 ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Àwọn ajá yí mi ká;
|
||
\q2 ìjọ àwọn ènìyàn ibi ti ká mi mọ́,
|
||
\q2 wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́sẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi;
|
||
\q2 àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn
|
||
\q2 àní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ṣùgbọ́n ìwọ, \nd Olúwa\nd*, má ṣe jìnnà sí mi.
|
||
\q2 Háà! Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wá fún àtìlẹ́yìn mi!
|
||
\q1
|
||
\v 20 Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà,
|
||
\q2 àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún;
|
||
\q2 kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi;
|
||
\q2 nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*, ẹ yìn ín!
|
||
\q2 Gbogbo ẹ̀yin ìran Jakọbu, ẹ fi ògo fún un!
|
||
\q2 Ẹ dìde fún un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú-ọmọ Israẹli!
|
||
\q1
|
||
\v 24 Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra
|
||
\q2 ìpọ́njú àwọn tí a ni lára;
|
||
\q1 kò sì fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún mi
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá;
|
||
\q2 ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù rẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 26 tálákà yóò jẹ yóò sì yó;
|
||
\q2 àwọn tí n wá \nd Olúwa\nd* yóò yin
|
||
\q2 jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ̀ wà láààyè títí ayérayé!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí
|
||
\q2 wọn yóò sì yípadà sí \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q1 àti gbogbo ìdílé orílẹ̀-èdè
|
||
\q2 ni wọn yóò jọ́sìn níwájú rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 28 nítorí ìjọba ni ti \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q2 Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn;
|
||
\q2 gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájú rẹ̀
|
||
\q2 àti ẹni tí kò lè pa ọkàn ara rẹ̀ mọ́ ni ààyè.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín;
|
||
\q2 a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ nípa \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀
|
||
\q2 sí àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí,
|
||
\q2 wí pé, òun ni ó ṣe èyí.
|
||
\c 23
|
||
\cl Saamu 23
|
||
\d Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd* ni olùṣọ́ èmi àgùntàn rẹ̀, èmi kì yóò ṣe aláìní.
|
||
\q2
|
||
\v 2 \x - \xo 23.2: \xt If 7.17.\x*Ó mú mi dùbúlẹ̀ sí ibi pápá oko tútù,
|
||
\q1 Ó mú mi lọ sí ibi omi dídákẹ́ rọ́rọ́,
|
||
\q2
|
||
\v 3 Ó mú ọkàn mi padà bọ̀ sípò.
|
||
\q1 Ó mú mi lọ sí ọ̀nà òdodo
|
||
\q2 nítorí orúkọ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Bí mo tilẹ̀ ń rìn
|
||
\q2 láàrín àfonífojì òjìji ikú,
|
||
\q1 èmi kì yóò bẹ̀rù ibi kan,
|
||
\q2 nítorí ìwọ wà pẹ̀lú mi;
|
||
\q1 ọ̀gọ rẹ àti ọ̀pá à rẹ,
|
||
\q2 wọ́n ń tù mí nínú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ tẹ́ tábìlì oúnjẹ sílẹ̀ níwájú mi
|
||
\q2 ní ojú àwọn ọ̀tá à mi.
|
||
\q1 Ìwọ ta òróró sí mi ní orí;
|
||
\q2 ago mí sì kún àkúnwọ́sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nítòótọ́, ìre àti àánú ni yóò máa tọ̀ mí lẹ́yìn
|
||
\q2 ní ọjọ́ ayé è mi gbogbo,
|
||
\q1 èmi yóò sì máa gbé inú ilé \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 títí láéláé.
|
||
\c 24
|
||
\cl Saamu 24
|
||
\d Ti Dafidi. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 24.1: \xt 1Kọ 10.26.\x*Ti \nd Olúwa\nd* ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀,
|
||
\q2 ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
|
||
\q1
|
||
\v 2 nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun
|
||
\q2 ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ta ni yóò gun orí òkè \nd Olúwa\nd* lọ?
|
||
\q2 Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 24.4: \xt Mt 5.8.\x*Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun,
|
||
\q2 ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán
|
||
\q2 tí kò sì búra èké.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀,
|
||
\q2 tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà;
|
||
\q2 kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé!
|
||
\q2 Kí ọba ògo le è wọlé.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ta ni ọba ògo náà?
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* tí ó lágbára tí ó sì le,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* gan an, tí ó lágbára ní ogun.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà;
|
||
\q2 kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé,
|
||
\q2 kí Ọba ògo le è wọlé wá.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ta ni Ọba ògo náà?
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun
|
||
\q2 Òun ni Ọba ògo náà. \qs Sela.\qs*
|
||
\c 25
|
||
\cl Saamu 25
|
||
\d Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ;
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹni tí ó dúró tì ọ́
|
||
\q2 ojú kì yóò tì í,
|
||
\q1 àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí
|
||
\q2 ni kí ojú kí ó tì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 kọ mi ní ipa tìrẹ;
|
||
\q1
|
||
\v 5 ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi,
|
||
\q2 nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi;
|
||
\q2 ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Rántí, \nd Olúwa\nd* àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá,
|
||
\q2 torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi
|
||
\q2 tàbí ìrékọjá mi;
|
||
\q1 gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi
|
||
\q2 nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára,
|
||
\q2 ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Gbogbo ipa ọ̀nà \nd Olúwa\nd* ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin,
|
||
\q2 fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Nítorí orúkọ rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*?
|
||
\q2 Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà,
|
||
\q2 àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
|
||
\q1
|
||
\v 14 \nd Olúwa\nd* fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀;
|
||
\q2 ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi;
|
||
\q2 nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi;
|
||
\q2 kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi,
|
||
\q2 kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi,
|
||
\q2 tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀;
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú,
|
||
\q2 nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́;
|
||
\q2 nítorí pé mo dúró tì ọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run,
|
||
\q2 nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!
|
||
\c 26
|
||
\cl Saamu 26
|
||
\d Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ṣe ìdájọ́ mi, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí tí mo ti ń rìn nínú ìwà òtítọ́ ọ̀ mi,
|
||
\q1 mo sì ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ǹjẹ́ ẹsẹ̀ mi kì yóò yẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Wádìí mi wò, Ìwọ \nd Olúwa\nd*, kí o sì dán mi wò,
|
||
\q2 dán àyà àti ọkàn mi wò;
|
||
\q1
|
||
\v 3 nítorí ìfẹ́ ẹ̀ rẹ tí ó dúró ṣinṣin ń bẹ níwájú mi,
|
||
\q2 èmí sì ti rìn nínú òtítọ́ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Èmi kò jókòó pẹ̀lú aláìṣòótọ́,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá àwọn àgàbàgebè wọlé.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Èmi ti kórìíra àwùjọ àwọn ènìyàn búburú
|
||
\q2 èmi kì yóò sì bá àwọn ènìyàn ìkà jókòó.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmí ó wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì yí pẹpẹ rẹ ká \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Èmi yóò kọrin sókè àní orin ọpẹ́,
|
||
\q2 èmi yóò sì máa sọ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Háà \nd Olúwa\nd*, èmí ń fẹ́ ilé rẹ níbi tí ìwọ ń gbé,
|
||
\q2 àní níbi tí ògo rẹ̀ wà.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Má ṣe gbá mi dànù pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,
|
||
\q2 tàbí ẹ̀mí mi pẹ̀lú àwọn ọkùnrin tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ,
|
||
\q1
|
||
\v 10 àwọn tí ọwọ́ wọn kún fún ìwà ibi,
|
||
\q2 tí ọwọ́ ọ̀tún wọn kún fún àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ṣùgbọ́n èmi ó máa rìn nínú ìwà títọ́;
|
||
\q2 rà mí padà, kí o sì ṣàánú fún mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ẹsẹ̀ mi dúró lórí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú;
|
||
\q2 nínú ìjọ ńlá èmi yóò fi ìbùkún fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 27
|
||
\cl Saamu 27
|
||
\d Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd* ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi;
|
||
\q2 ta ni èmi yóò bẹ̀rù?
|
||
\q1 \nd Olúwa\nd* ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi,
|
||
\q2 ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi
|
||
\q2 láti jẹ ẹran-ara mi,
|
||
\q1 àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi,
|
||
\q2 wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi,
|
||
\q2 ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù;
|
||
\q1 bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi,
|
||
\q2 nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 òhun ni èmi yóò máa wá kiri:
|
||
\q1 kí èmi kí ó le wà ní ilé \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ní ọjọ́ ayé mi gbogbo,
|
||
\q1 kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú
|
||
\q2 òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀;
|
||
\q1 níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́;
|
||
\q2 yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè
|
||
\q2 ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká;
|
||
\q1 èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀;
|
||
\q2 èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn,
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ọkàn mi wí pé, “Wá ojú u rẹ̀!”
|
||
\q2 Ojú rẹ, \nd Olúwa\nd*, ni ti èmí ń wá.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi,
|
||
\q2 má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì;
|
||
\q2 ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi,
|
||
\q1 Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí,
|
||
\q2 háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* yóò tẹ́wọ́ gbà mí.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú
|
||
\q2 nítorí àwọn ọ̀tá mi.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́,
|
||
\q2 nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi,
|
||
\q2 wọ́n sì mí ìmí ìkà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Èmi ní ìgbàgbọ́ pé,
|
||
\q2 èmi yóò rí ìre \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ní ilẹ̀ alààyè.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Dúró de \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le
|
||
\q2 àní dúró de \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 28
|
||
\cl Saamu 28
|
||
\d Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìwọ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 mo ké pe àpáta mi.
|
||
\q2 Má ṣe kọ etí dídi sí mi.
|
||
\q1 Tí ìwọ bá dákẹ́ sí mi,
|
||
\q2 èmí yóò dàbí àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú,
|
||
\q2 bí mo ṣe ń ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́,
|
||
\q1 bí mo ṣe gbé àwọn ọwọ́ mi sókè
|
||
\q2 sí Ibi Mímọ́ rẹ Jùlọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Má ṣe fà mí lọ pẹ̀lú ènìyàn búburú àti,
|
||
\q2 pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀,
|
||
\q1 tí ń sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò wọn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n tí ìwà ìkà ń bẹ nínú wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 4 San ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn
|
||
\q2 àti fún iṣẹ́ ibi wọn;
|
||
\q1 gba ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn;
|
||
\q2 kí o sì san ẹ̀san wọn bí ó ti tọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ \nd Olúwa\nd* sí,
|
||
\q2 tàbí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀
|
||
\q1 òun ó rún wọn wọlẹ̀
|
||
\q2 kì yóò sì gbé wọn ró mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Alábùkún fún ni \nd Olúwa\nd*!
|
||
\q2 Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 7 \nd Olúwa\nd* ni agbára mi àti asà mi;
|
||
\q2 nínú rẹ̀ ni mo gbẹ́kẹ̀lé; àní, ó sì ràn mí lọ́wọ́.
|
||
\q1 Ọkàn mi sì gbé sókè fún ayọ̀
|
||
\q2 àní pẹ̀lú orin mi mo fi ọpẹ́ fún un.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 \nd Olúwa\nd* ni agbára àwọn ènìyàn rẹ̀
|
||
\q2 òun ni odi ìgbàlà àwọn ẹni àmì òróró rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìwọ gba àwọn ènìyàn rẹ là, kí o sì bùkún àwọn ajogún rẹ;
|
||
\q2 di olùṣọ́-àgùntàn wọn, kí o sì gbé wọn lékè títí ayérayé.
|
||
\c 29
|
||
\cl Saamu 29
|
||
\d Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ fi fún \nd Olúwa\nd*, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run,
|
||
\q2 ẹ fi fún \nd Olúwa\nd*, ògo àti alágbára.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Fi fún \nd Olúwa\nd*, àní ògo orúkọ rẹ̀;
|
||
\q2 sin \nd Olúwa\nd* nínú ẹwà ìwà mímọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ohùn \nd Olúwa\nd* n ré àwọn omi kọjá;
|
||
\q2 Ọlọ́run ògo sán àrá,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* san ara.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ohùn \nd Olúwa\nd* ní agbára;
|
||
\q2 ohùn \nd Olúwa\nd* kún fún ọláńlá.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ohùn \nd Olúwa\nd* fa igi kedari;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù,
|
||
\q2 àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ohùn \nd Olúwa\nd* ń ya
|
||
\q2 bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ohùn \nd Olúwa\nd* ń mi aginjù.
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* mi aginjù Kadeṣi.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ohùn \nd Olúwa\nd* ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí,
|
||
\q2 ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò.
|
||
\q1 Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 \nd Olúwa\nd* jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Kí \nd Olúwa\nd* fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀;
|
||
\q2 bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
|
||
\c 30
|
||
\cl Saamu 30
|
||
\d Saamu. Orin. Fún ìyàsímímọ́ Tẹmpili. Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi yóò kókìkí i rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí ìwọ ni ó gbé mi lékè
|
||
\q2 tí ìwọ kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ mí.
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run mi, èmi ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́,
|
||
\q2 ìwọ sì ti wò mí sàn.
|
||
\q1
|
||
\v 3 \nd Olúwa\nd*, ìwọ ti yọ ọkàn mi jáde kúrò nínú isà òkú,
|
||
\q2 mú mi padà bọ̀ sípò alààyè kí èmi má ba à lọ sínú ihò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Kọ orin ìyìn sí \nd Olúwa\nd*, ẹ̀yin olódodo;
|
||
\q2 kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ̀ mímọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí pé ìbínú rẹ̀ wà fún ìgbà díẹ̀,
|
||
\q2 ojúrere rẹ̀ wà títí ayérayé;
|
||
\q1 ẹkún lè pẹ́ títí di alẹ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ayọ̀ yóò wá ní òwúrọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ní ìgbà ayé mi, mo wí pé,
|
||
\q2 “a kì yóò ṣí mi ní ipò padà.”
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nípa ojúrere rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ìwọ ti gbé mi kalẹ̀ bí òkè tí ó ní agbára;
|
||
\q1 ìwọ pa ojú rẹ mọ́,
|
||
\q2 àyà sì fò mí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Sí ọ \nd Olúwa\nd*, ni mo ké pè é;
|
||
\q2 àti sí Olúwa ni mo sọkún fún àánú:
|
||
\q1
|
||
\v 9 “Èrè kí ni ó wà nínú ikú ìparun mi,
|
||
\q2 nínú lílọ sí ihò mi?
|
||
\q1 Eruku yóò a yìn ọ́ bí?
|
||
\q2 Ǹjẹ́ yóò sọ nípa òdodo rẹ?
|
||
\q1
|
||
\v 10 Gbọ́, \nd Olúwa\nd*, kí o sì ṣàánú fún mi;
|
||
\q2 ìwọ \nd Olúwa\nd*, jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìwọ ti yí ìkáàánú mi di ijó fún mi;
|
||
\q2 ìwọ sì ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ mi, o sì fi aṣọ ayọ̀ wọ̀ mí,
|
||
\q1
|
||
\v 12 nítorí ìdí èyí ni kí ọkàn mi máa yìn ọ́, kí o má sì ṣe dákẹ́.
|
||
\q2 Ìwọ \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ títí láé.
|
||
\c 31
|
||
\cl Saamu 31
|
||
\d Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Nínú rẹ̀, \nd Olúwa\nd* ni mo ti rí ààbò;
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí;
|
||
\q2 gbà mí nínú òdodo rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Tẹ́ etí rẹ sí mi,
|
||
\q2 gbà mí kíákíá;
|
||
\q1 jẹ́ àpáta ààbò mi,
|
||
\q2 jẹ́ odi alágbára láti gbà mí.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ìwọ pàápàá ni àpáta àti ààbò mi,
|
||
\q2 nítorí orúkọ rẹ, máa ṣe olùtọ́ mi, kí o sì ṣe amọ̀nà mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Yọ mí jáde kúrò nínú àwọ̀n tí wọ́n dẹ pamọ́ fún mi,
|
||
\q2 nítorí ìwọ ni ìsádi mi.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ní ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé;
|
||
\q2 ìwọ ni o ti rà mí padà, \nd Olúwa\nd*, Ọlọ́run òtítọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmi ti kórìíra àwọn ẹni tí ń fiyèsí òrìṣà tí kò níye lórí;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Èmi yóò yọ̀, inú mi yóò dùn nínú ìfẹ́ ńlá rẹ,
|
||
\q2 nítorí ìwọ ti rí ìbìnújẹ́ mi
|
||
\q2 ìwọ ti mọ̀ ọkàn mi nínú ìpọ́njú.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Pẹ̀lú, ìwọ kò sì fà mi lé àwọn ọ̀tá lọ́wọ́
|
||
\q2 ìwọ ti fi ẹsẹ̀ mi lé ibi ààyè ńlá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ṣàánú fún mi, ìwọ \nd Olúwa\nd*, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú;
|
||
\q2 ojú mi fi ìbìnújẹ́ sùn,
|
||
\q2 ọkàn àti ara mi pẹ̀lú.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Èmi fi ìbànújẹ́ lo ọjọ́ mi
|
||
\q2 àti àwọn ọdún mi pẹ̀lú ìmí ẹ̀dùn;
|
||
\q1 agbára mi ti kùnà nítorí òsì mi,
|
||
\q2 egungun mi sì ti rún dànù.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Èmi di ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ọ̀tá mi gbogbo,
|
||
\q2 pẹ̀lúpẹ̀lú láàrín àwọn aládùúgbò mi,
|
||
\q1 mo sì di ẹ̀rù fún àwọn ojúlùmọ̀ mi;
|
||
\q2 àwọn tí ó rí mi ní òde ń yẹra fún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Èmi ti di ẹni ìgbàgbé kúrò ní ọkàn gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ti kú;
|
||
\q2 èmi sì dàbí ohun èlò tí ó ti fọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 13 \x - \xo 31.13: \xt Jr 6.25; 20.3,10; 46.5; 49.29.\x*Nítorí mo gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpayà tí ó yí mi ká;
|
||
\q2 tí wọn gbìmọ̀ pọ̀ sí mi,
|
||
\q1 wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi
|
||
\q2 láti gba ẹ̀mí mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ṣùgbọ́n èmí gbẹ́kẹ̀lé ọ, ìwọ \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 mo sọ wí pé, “Ìwọ ní Ọlọ́run mi.”
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ìgbà mi ń bẹ ní ọwọ́ rẹ;
|
||
\q2 gbà mí kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá mi
|
||
\q2 àti àwọn onínúnibíni.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tan ìmọ́lẹ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ lára;
|
||
\q2 gbà mí nínú ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Má ṣe jẹ́ kí ojú ki ó tì mí, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 nítorí pé mo ké pè ọ́;
|
||
\q1 jẹ́ kí ojú kí ó ti ènìyàn búburú;
|
||
\q2 jẹ́ kí wọ́n lọ pẹ̀lú ìdààmú sí isà òkú.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Jẹ́ kí àwọn ètè irọ́ kí ó dákẹ́ jẹ́ẹ́,
|
||
\q2 pẹ̀lú ìgbéraga àti ìkẹ́gàn,
|
||
\q2 wọ́n sọ̀rọ̀ àfojúdi sí olódodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Báwo ni títóbi oore rẹ̀ ti pọ̀ tó,
|
||
\q2 èyí tí ìwọ ti ní ní ìpamọ́ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ,
|
||
\q1 èyí tí ìwọ rọ̀jò rẹ̀ níwájú àwọn ènìyàn
|
||
\q2 tí wọ́n fi ọ́ ṣe ibi ìsádi wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ní abẹ́ ìbòòji iwájú rẹ ni ìwọ pa wọ́n mọ́ sí
|
||
\q2 kúrò nínú ìdìmọ̀lù àwọn ènìyàn;
|
||
\q1 ní ibùgbé rẹ, o mú wọn kúrò nínú ewu
|
||
\q2 kúrò nínú ìjà ahọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Olùbùkún ni \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí pé ó ti fi àgbà ìyanu ìfẹ́ tí ó ní sí mi hàn,
|
||
\q2 nígbà tí mo wà ní ìlú tí wọ́n rọ̀gbà yíká.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Èmí ti sọ nínú ìdágìrì mi,
|
||
\q2 “A gé mi kúrò ní ojú rẹ!”
|
||
\q1 Síbẹ̀ ìwọ ti gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú
|
||
\q2 nígbà tí mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ẹ fẹ́ \nd Olúwa\nd*, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́!
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* pa olódodo mọ́,
|
||
\q2 ó sì san án padà fún agbéraga ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Jẹ́ alágbára, yóò sì mú yín ní àyà le
|
||
\q2 gbogbo ẹ̀yin tí ó dúró de \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 32
|
||
\cl Saamu 32
|
||
\d Ti Dafidi. Maskili.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 32.1-2: \xt Ro 4.7-8.\x*Ìbùkún ni fún àwọn
|
||
\q2 tí a dárí ìrékọjá wọn jì,
|
||
\q2 tí a sì bo ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà
|
||
\q2 ẹni tí \nd Olúwa\nd* kò ka ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ sí i lọ́rùn
|
||
\q2 àti nínú ẹ̀mí ẹni tí kò sí ẹ̀tàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nígbà tí mo dákẹ́,
|
||
\q2 egungun mi di gbígbó dànù
|
||
\q2 nípa ìkérora mi ní gbogbo ọjọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí pé ni ọ̀sán àti ní òru
|
||
\q2 ọwọ́ rẹ̀ wúwo sí mi lára;
|
||
\q1 agbára mi gbẹ tán
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ooru ẹ̀ẹ̀rùn. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Èmi jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ
|
||
\q2 àti pé èmi kò sì fi àìṣòdodo mi pamọ́.
|
||
\q1 Èmi wí pé, “Èmi yóò jẹ́wọ́
|
||
\q2 ẹ̀ṣẹ̀ mi fún \nd Olúwa\nd*,”
|
||
\q1 ìwọ sì dárí
|
||
\q2 ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nítorí náà jẹ́ kí gbogbo àwọn olódodo máa gbà àdúrà sí ọ
|
||
\q2 ní ìgbà tí a lè rí ọ;
|
||
\q1 nítòótọ́ nígbà tí ìṣàn omi ńlá bá ru sókè,
|
||
\q2 wọn kì yóò lè dé ọ̀dọ̀ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìwọ ni ibi ìpamọ́ mi;
|
||
\q2 ìwọ yóò pa mí mọ́ kúrò nínú ìyọnu;
|
||
\q2 ìwọ yóò fi orin ìgbàlà yí mi ka. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Èmi yóò kọ́ ọ, èmi yóò sì fi ẹsẹ̀ rẹ lé ọ̀nà tí ìwọ yóò rìn
|
||
\q2 èmi yóò máa gbà ọ́ ní ìyànjú, èmi yóò sì máa fi ojú mi tọ́ ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Má ṣe dàbí ẹṣin tàbí ìbáaka,
|
||
\q2 tí kò ní òye
|
||
\q1 ẹnu ẹni tí a gbọdọ̀ fi ìjánu bọ̀,
|
||
\q2 kí wọn má ba à súnmọ́ ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ọ̀pọ̀ ìkáàánú ní yóò wà fún ènìyàn búburú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìfẹ́ \nd Olúwa\nd* tí ó dúró ṣinṣin
|
||
\q2 ni yóò yí àwọn tí ó ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú \nd Olúwa\nd* ká.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ẹ yọ̀ nínú \nd Olúwa\nd*, kí ẹ sì ní inú dídùn, ẹ̀yìn olódodo;
|
||
\q2 ẹ sì máa kọrin, gbogbo ẹ̀yìn tí àyà yín dúró ṣinṣin.
|
||
\c 33
|
||
\cl Saamu 33
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ yọ̀ nínú \nd Olúwa\nd*, ẹ̀yin olódodo;
|
||
\q2 ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ yin \nd Olúwa\nd* pẹ̀lú dùùrù;
|
||
\q2 ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹ kọ orin tuntun sí i;
|
||
\q2 ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí pé ọ̀rọ̀ \nd Olúwa\nd* dúró ṣinṣin,
|
||
\q2 gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́;
|
||
\q2 ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ \nd Olúwa\nd* ni a ṣe dá àwọn ọ̀run,
|
||
\q2 àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò;
|
||
\q2 ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀;
|
||
\q2 ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 \nd Olúwa\nd* ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán;
|
||
\q2 ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìgbìmọ̀ \nd Olúwa\nd* dúró títí ayérayé,
|
||
\q2 àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí \nd Olúwa\nd* jẹ́ tirẹ̀,
|
||
\q2 àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 13 \nd Olúwa\nd* wò láti ọ̀run wá;
|
||
\q2 Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́
|
||
\q2 Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
|
||
\q1
|
||
\v 15 ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà,
|
||
\q2 ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun;
|
||
\q2 kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun;
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Wò ó, ojú \nd Olúwa\nd* wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
|
||
\q2 àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú
|
||
\q2 àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ọkàn wa dúró de \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀,
|
||
\q2 nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Kí àánú rẹ, \nd Olúwa\nd*, kí ó wà lára wa,
|
||
\q2 àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.
|
||
\c 34
|
||
\cl Saamu 34
|
||
\d Tí Dafidi. Nígbà tí ó díbọ́n bí ẹni tí ń ṣe wèrè níwájú Abimeleki, ẹni tí ó lé e lọ, ó sì jáde lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi yóò máa fi ìbùkún fún \nd Olúwa\nd* nígbà gbogbo;
|
||
\q2 ìyìn rẹ̀ yóò máa wà ní ẹnu mi títí láé.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 jẹ́ kí àwọn onírẹ̀lẹ̀ gbọ́ kí inú wọn kí ó sì máa dùn.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Gbé \nd Olúwa\nd* ga pẹ̀lú mi;
|
||
\q2 kí ẹ sì jẹ́ kí a jọ gbé orúkọ rẹ̀ lékè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Èmi wá \nd Olúwa\nd*, ó sì dá mi lóhùn;
|
||
\q2 Ó sì gbà mí kúrò nínú ìbẹ̀rù mi gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn;
|
||
\q2 ojú kò sì tì wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, \nd Olúwa\nd* sì gbóhùn rẹ̀;
|
||
\q2 ó sì gbà á là kúrò nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Angẹli \nd Olúwa\nd* yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká
|
||
\q2 ó sì gbà wọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé \nd Olúwa\nd* dára;
|
||
\q2 ẹni ayọ̀ ni ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ààbò nínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ẹ bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́,
|
||
\q2 nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn tí ó wá \nd Olúwa\nd* kì yóò ṣe aláìní ohun tí ó dára.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi;
|
||
\q2 èmi yóò kọ́ ọ yín ní ẹ̀rù \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 12 \x - \xo 34.12-16: \xt 1Pt 3.10-12.\x*Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀;
|
||
\q2 kí ó lè gbádùn ọjọ́ rere?
|
||
\q1
|
||
\v 13 Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi
|
||
\q2 àti ètè rẹ̀ kúrò ní ẹ̀tàn sísọ.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere;
|
||
\q2 wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ojú \nd Olúwa\nd* ń bẹ lára àwọn olódodo;
|
||
\q2 etí i rẹ̀ sì ṣí sí ẹkún wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ojú \nd Olúwa\nd* korò sí àwọn tí ń ṣe búburú;
|
||
\q2 láti ké ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* a máa gbọ́, a sì yọ wọ́n jáde láti inú gbogbo wàhálà wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 18 \nd Olúwa\nd* súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn;
|
||
\q2 ó sì gba irú àwọn tí í ṣe oníròra ọkàn là.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n \nd Olúwa\nd* gbà wọ́n kúrò nínú gbogbo rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́;
|
||
\q2 kò sí ọ̀kan tí ó dá nínú wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ibi ni ó mú ikú ìkà wá,
|
||
\q2 àti àwọn tí ó kórìíra olódodo ni yóò jẹ̀bi.
|
||
\q1
|
||
\v 22 \nd Olúwa\nd* ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà;
|
||
\q2 kò sí ọ̀kan nínú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé tí yóò jẹ̀bi.
|
||
\c 35
|
||
\cl Saamu 35
|
||
\d Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, gbógun ti àwọn tí ń gbóguntì mí;
|
||
\q2 kí o sì kọ ojú ìjà sí àwọn tí ó ń bá mi í jà!
|
||
\q1
|
||
\v 2 Di asà àti àpáta mú,
|
||
\q2 kí o sì dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi!
|
||
\q1
|
||
\v 3 Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ
|
||
\q2 kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi.
|
||
\q1 Sọ fún ọkàn mi pé,
|
||
\q2 “Èmi ni ìgbàlà rẹ.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Kí wọn kí ó dààmú,
|
||
\q2 kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú;
|
||
\q1 kí a sì mú wọn padà,
|
||
\q2 kí a sì dààmú àwọn tí ń gbèrò ìpalára mi.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Jẹ́ kí wọn dàbí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́,
|
||
\q2 kí angẹli \nd Olúwa\nd* kí ó máa lé wọn kiri.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ́,
|
||
\q2 kí angẹli \nd Olúwa\nd* kí ó máa lépa wọn!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nítorí pé, ní àìnídìí ni wọ́n dẹ àwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,
|
||
\q2 ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtò sílẹ̀ fún ọkàn mi.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Kí ìparun kí ó wá sí orí rẹ̀ ní òjijì.
|
||
\q2 Àwọ̀n rẹ̀ tí ó dẹ, kí ó mú òun tìkára rẹ̀;
|
||
\q2 kí wọn ṣubú sínú kòtò sí ìparun ara rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nígbà náà ni ọkàn mi yóò yọ̀ nínú \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 àní, yóò sì máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Gbogbo egungun mi yóò wí pé,
|
||
\q2 “Ta ni ó dàbí ì ìwọ \nd Olúwa\nd*?
|
||
\q1 O gba tálákà lọ́wọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ,
|
||
\q2 tálákà àti aláìní lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;
|
||
\q2 wọ́n ń bi mi ní ohun tí èmi kò mọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Wọ́n fi búburú san ìre fún mi;
|
||
\q2 láti sọ ọkàn mi di òfo.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni, nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;
|
||
\q2 mo fi àwẹ̀ pọ́n ara mi lójú.
|
||
\q1 Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríba ní oókan àyà mi;
|
||
\q2
|
||
\v 14 èmí ń lọ kiri bí ẹni ń ṣọ̀fọ̀
|
||
\q2 bí i ẹni wí pé fún ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́n mi ni.
|
||
\q1 Èmí tẹríba nínú ìbànújẹ́
|
||
\q2 bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ìyà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ mi wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì kó ara wọn jọ;
|
||
\q2 wọ́n kó ara wọn jọ sí mi; àní àwọn tí èmi kò mọ̀.
|
||
\q2 Wọ́n fà mí ya wọ́n kò sì dákẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Bí àwọn àgàbàgebè tí ń ṣe ẹlẹ́yà ní àpèjẹ
|
||
\q2 wọ́n pa eyín wọn keke sí mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Yóò ti pẹ́ tó \nd Olúwa\nd*, tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ?
|
||
\q2 Yọ mí kúrò nínú ìparun wọn,
|
||
\q2 àní ẹ̀mí ì mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Nígbà náà ni èmi yóò ṣọpẹ́ fún Ọ nínú àjọ ńlá;
|
||
\q2 èmi yóò máa yìn Ọ́ ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 19 \x - \xo 35.19: \xt Sm 69.4; Jh 15.25.\x*Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi
|
||
\q2 kí ó yọ̀ lórí ì mi;
|
||
\q1 bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe àwọn tí ó kórìíra mi
|
||
\q2 ní àìnídìí máa ṣẹ́jú sí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n wọ́n lóyún ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn
|
||
\q2 sí àwọn ènìyàn dídákẹ́ ilẹ̀ náà.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi; wọ́n wí pé, “Háà! Háà!
|
||
\q2 Ojú wa sì ti rí i.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ìwọ́ ti rí i \nd Olúwa\nd*; má ṣe dákẹ́!
|
||
\q2 Olúwa má ṣe jìnnà sí mi!
|
||
\q1
|
||
\v 23 Dìde! ru ara rẹ̀ sókè fún ààbò mi,
|
||
\q2 àti sí ọ̀ràn mi, Ọlọ́run mi àti Olúwa mi!
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ṣe ìdájọ́ mi, \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ,
|
||
\q2 kí o má sì ṣe jẹ́ kí wọn kí ó yọ̀ lórí mi!
|
||
\q1
|
||
\v 25 Má ṣe jẹ́ kí wọn wí nínú ara wọn pé, “Háà! A ti rí ohun tí ọkàn wa ń fẹ́!”
|
||
\q2 Má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó wí pé, “A ti gbé e mì.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Kí ojú kí ó tì wọ́n,
|
||
\q2 kí wọn kí ó sì dààmú pọ̀,
|
||
\q1 àní àwọn tí ń yọ̀ sí ìyọnu mi
|
||
\q2 kí a fi ìtìjú àti àbùkù wọ̀ wọ́n ní aṣọ tí ń gbéraga sí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mi
|
||
\q2 fò fún ayọ̀ àti ìdùnnú;
|
||
\q1 kí wọn máa sọ ọ́ títí lọ, “Pé gbígbéga ni \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 sí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ̀.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ,
|
||
\q2 àti ìyìn rẹ ní gbogbo ọjọ́.
|
||
\c 36
|
||
\cl Saamu 36
|
||
\d Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 36.1: \xt Ro 3.18.\x*Ìré-òfin-kọjá ènìyàn búburú
|
||
\q2 jẹ́ kí n mọ̀ nínú ọkàn mi pé,
|
||
\q1 ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí
|
||
\q2 níwájú wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nítorí pé wọ́n pọ́n ara wọn ní ojú ara wọn
|
||
\q2 títí tí a kò fi le rí ẹ̀ṣẹ̀ wọn láti kórìíra.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọ̀rọ̀ ẹnu wọn ni ẹ̀ṣẹ̀ òhun ẹ̀tàn;
|
||
\q2 wọ́n ti fi ọgbọ́n àti ṣíṣe rere sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Wọ́n gbìmọ̀ ìwà ìkà nígbà tí wọ́n wà lórí ibùsùn wọn:
|
||
\q2 wọ́n gba ọ̀nà tí kò dára
|
||
\q2 wọn kò sì kọ ọ̀nà ibi sílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ, ìwọ \nd Olúwa\nd*, ó ga dé ọ̀run,
|
||
\q2 òtítọ́ ọ̀ rẹ ga dé àwọsánmọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Òdodo rẹ dàbí àwọn òkè Ọlọ́run,
|
||
\q2 àwọn ìdájọ́ rẹ dàbí ibú ńlá;
|
||
\q2 ìwọ gba ẹranko àti ènìyàn là, \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Báwo ni ìṣeun ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ ti tó! Ọlọ́run!
|
||
\q2 Kí gbogbo ọmọ ènìyàn le sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Àsè ilé rẹ yóò tẹ́ wọn lọ́rùn gidigidi;
|
||
\q2 ìwọ yóò sì mú wọn mu nínú odò inú dídùn rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítorí pé pẹ̀lú rẹ ni orísun ìyè wà:
|
||
\q2 nínú ìmọ́lẹ̀ rẹ ni àwa yóò rí ìmọ́lẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Mú ìṣeun ìfẹ́ ẹ̀ rẹ sí àwọn tí ó mọ̀ ọ́n
|
||
\q2 àti ìgbàlà rẹ sí àwọn tí ó ní ìdúró ṣinṣin ọkàn!
|
||
\q1
|
||
\v 11 Má ṣe jẹ́ kí ẹsẹ̀ agbéraga kí ó wá sí orí mi,
|
||
\q2 kí o má sì jẹ́ kí ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú sí mi ní ipò.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Níbẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ gbé ṣubú sí:
|
||
\q2 a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, wọn kì yóò le è dìde!
|
||
\c 37
|
||
\cl Saamu 37
|
||
\d Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú,
|
||
\q2 kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
|
||
\q1
|
||
\v 2 nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko,
|
||
\q2 wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*, kí o sì máa ṣe rere;
|
||
\q2 torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ṣe inú dídùn sí \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Fi ọ̀nà rẹ lé \nd Olúwa\nd* lọ́wọ́;
|
||
\q2 gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀,
|
||
\q2 àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 kí o sì fi sùúrù dúró dè é;
|
||
\q1 má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn,
|
||
\q2 nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀,
|
||
\q2 má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de \nd Olúwa\nd* àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀;
|
||
\q2 nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà,
|
||
\q2 wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́,
|
||
\q2 wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
|
||
\q1
|
||
\v 13 ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú,
|
||
\q2 nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ènìyàn búburú fa idà yọ,
|
||
\q2 wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn,
|
||
\q1 láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀,
|
||
\q2 láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ,
|
||
\q2 àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ohun díẹ̀ tí olódodo ní,
|
||
\q2 sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
|
||
\q1
|
||
\v 17 nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n \nd Olúwa\nd* gbé olódodo sókè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 \nd Olúwa\nd* mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin,
|
||
\q2 àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi,
|
||
\q2 àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé.
|
||
\q2 Àwọn ọ̀tá \nd Olúwa\nd* yóò dàbí ẹwà oko tútù;
|
||
\q2 wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
|
||
\q1
|
||
\v 22 nítorí àwọn tí \nd Olúwa\nd* bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà,
|
||
\q2 àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd* wá,
|
||
\q2 o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
|
||
\q1
|
||
\v 24 bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá,
|
||
\q2 nítorí tí \nd Olúwa\nd* di ọwọ́ rẹ̀ mú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà;
|
||
\q2 síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀,
|
||
\q2 tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni;
|
||
\q2 a sì máa bùsi i fún ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere;
|
||
\q2 nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Nítorí pé \nd Olúwa\nd* fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́,
|
||
\q2 kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1 Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà,
|
||
\q2 yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,
|
||
\q2 ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn;
|
||
\q2 àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 32 Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo,
|
||
\q2 Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
|
||
\q1
|
||
\v 33 \nd Olúwa\nd* kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi,
|
||
\q2 nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 34 Dúró de \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́.
|
||
\q1 Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà;
|
||
\q2 nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 35 Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà,
|
||
\q2 ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
|
||
\q1
|
||
\v 36 ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́;
|
||
\q2 bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 37 Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin;
|
||
\q2 nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
|
||
\q1
|
||
\v 38 Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀;
|
||
\q2 ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 39 Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
|
||
\q1
|
||
\v 40 \nd Olúwa\nd* yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n;
|
||
\q2 yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là,
|
||
\q2 nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.
|
||
\c 38
|
||
\cl Saamu 38
|
||
\d Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin,
|
||
\q2 ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ;
|
||
\q2 kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀;
|
||
\q2 wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́
|
||
\q2 nítorí òmùgọ̀ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi
|
||
\q2 èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni
|
||
\q2 kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ;
|
||
\q2 mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 \nd Olúwa\nd*, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ;
|
||
\q2 ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀;
|
||
\q2 bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi,
|
||
\q2 àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi;
|
||
\q2 àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun,
|
||
\q2 wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀;
|
||
\q2 àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀,
|
||
\q2 àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ṣùgbọ́n sí ọ \nd Olúwa\nd*, ìwọ ni mo dúró dè;
|
||
\q2 ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí;
|
||
\q2 nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú,
|
||
\q2 ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi;
|
||
\q2 àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀,
|
||
\q2 ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi
|
||
\q2 àwọn ni ọ̀tá mi
|
||
\q2 nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ \nd Olúwa\nd*!
|
||
\q2 Ọlọ́run mi, má ṣe jìnnà sí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, Olùgbàlà mi.
|
||
\c 39
|
||
\cl Saamu 39
|
||
\d Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Saamu Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Mo wí pé, “Èmi yóò ṣọ́ ọ̀nà mi
|
||
\q2 kí èmi kí ó má fi ahọ́n mi ṣẹ̀;
|
||
\q1 èmi yóò fi ìjánu kó ara mi ní ẹnu
|
||
\q2 níwọ̀n ìgbà tí ènìyàn búburú bá ń bẹ ní iwájú mi.”
|
||
\q1
|
||
\v 2 Mo fi ìdákẹ́ ya odi;
|
||
\q2 mo tilẹ̀ pa ẹnu mi mọ́ kúrò nínú ọ̀rọ̀ rere;
|
||
\q1 ìbànújẹ́ mi sì pọ̀ sí i.
|
||
\q2
|
||
\v 3 Àyà mi gbóná ní inú mi.
|
||
\q1 Nígbà tí mo ń ṣàṣàrò, iná ràn;
|
||
\q2 nígbà náà ni mo fi ahọ́n mi sọ̀rọ̀:
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 “\nd Olúwa\nd*, jẹ́ kí èmi kí ó mọ òpin mi,
|
||
\q2 àti ìwọ̀n ọjọ́ mi, bí ó ti rí
|
||
\q2 kí èmi kí o le mọ ìgbà tí mó ní níhìn-ín.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ ti ṣe ayé mi
|
||
\q2 bí ìbú àtẹ́lẹwọ́,
|
||
\q1 ọjọ́ orí mi sì dàbí asán
|
||
\q2 ní iwájú rẹ.
|
||
\q1 Dájúdájú olúkúlùkù ènìyàn nínú
|
||
\q2 ìjókòó rere rẹ̀ jásí asán pátápátá. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 “Nítòótọ́ ni olúkúlùkù ń rìn kiri bí òjìji.
|
||
\q2 Nítòótọ́ ni wọ́n ń yọ ara wọn lẹ́nu lórí asán;
|
||
\q1 wọ́n ń kó ọrọ̀ jọ,
|
||
\q2 wọn kò sì mọ ẹni tí yóò ko lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 “Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q1 kín ni mo ń dúró dè?
|
||
\q2 Ìrètí mí ń bẹ ní ọ̀dọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Gbà mí lọ́wọ́ ìrékọjá mi gbogbo.
|
||
\q2 Kí o má sì sọ mí di ẹni ẹ̀gàn
|
||
\q1 àwọn ènìyàn búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Mo dákẹ́ jẹ́ẹ́;
|
||
\q2 èmi kò sì ya ẹnu mi,
|
||
\q1 nítorí wí pé ìwọ ni ó ṣe é.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Mú pàṣán rẹ kúrò ní ara mi;
|
||
\q2 èmí ṣègbé tán nípa lílù ọwọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìwọ fi ìbáwí kìlọ̀
|
||
\q2 fún ènìyàn nítorí ẹ̀ṣẹ̀,
|
||
\q1 ìwọ a mú ẹwà rẹ parun
|
||
\q2 bí kòkòrò aṣọ;
|
||
\q1 nítòótọ́ asán ni ènìyàn gbogbo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 “Gbọ́ àdúrà mi, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 kí o sì fetí sí igbe mi;
|
||
\q2 kí o má ṣe di etí rẹ sí ẹkún mi.
|
||
\q1 Nítorí àlejò ni èmi lọ́dọ̀ rẹ,
|
||
\q2 àti àtìpó, bí gbogbo àwọn baba mi ti rí.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Dá mi sí, kí èmi lè ní agbára,
|
||
\q2 kí èmi tó lọ kúrò níhìn-ín yìí,
|
||
\q2 àti kí èmi ó tó ṣe aláìsí.”
|
||
\c 40
|
||
\cl Saamu 40
|
||
\d Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Mo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ dúró de \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 ó sì dẹtí sí mi, ó sì gbọ́ ẹkún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ó fà mí yọ gòkè
|
||
\q2 láti inú ihò ìparun,
|
||
\q1 láti inú ẹrẹ̀ pọ̀tọ̀pọ́tọ̀,
|
||
\q2 ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé orí àpáta,
|
||
\q1 ó sì jẹ́ kí ìgbésẹ̀ mi wà láìfòyà.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ó fi orin tuntun sí mi lẹ́nu,
|
||
\q2 àní orin ìyìn sí Ọlọ́run wa.
|
||
\q1 Ọ̀pọ̀ yóò rí i wọn yóò sì bẹ̀rù,
|
||
\q2 wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ayọ̀ ni fún àwọn wọ̀n-ọn-nì
|
||
\q2 tí ó fi \nd Olúwa\nd* ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé wọn
|
||
\q1 tí wọn kò sì yípadà sí agbéraga,
|
||
\q2 tàbí àwọn tí ó yapa
|
||
\q1 lọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́run mìíràn.
|
||
\q1
|
||
\v 5 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run mi,
|
||
\q2 ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ti ṣe.
|
||
\q1 Àwọn ohun tí ìwọ ti ṣètò sílẹ̀ fún wa;
|
||
\q2 ni ẹnikẹ́ni kò le kà wọ́n fún ọ lẹ́sẹẹsẹ,
|
||
\q1 tí èmi yóò sì sọ̀rọ̀ wọn,
|
||
\q2 wọ́n ju ohun tí
|
||
\q2 ènìyàn le è kà lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 \x - \xo 40.6-8: \xt Hb 10.5-9.\x*Ẹbọ àti ẹran ẹbọ ni ìwọ kò fẹ́,
|
||
\q2 ìwọ ti ṣí mi ní etí.
|
||
\q1 Ọrẹ ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀
|
||
\q2 ni ìwọ kò béèrè.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nígbà náà ni mo wí pé,
|
||
\q2 “Èmi nìyí;
|
||
\q1 nínú ìwé kíká ni
|
||
\q2 a kọ ọ nípa tèmi wí pé.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Mo ní inú dídùn
|
||
\q2 láti ṣe ìfẹ́ ẹ̀ rẹ,
|
||
\q1 ìwọ Ọlọ́run mi,
|
||
\q2 òfin rẹ̀ ń bẹ ní àyà mi.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Èmi ti sọ ìròyìn ayọ̀ ti ìgbàlà
|
||
\q2 láàrín àwùjọ ńlá;
|
||
\q1 wò ó,
|
||
\q2 èmi kò pa ètè mi mọ́,
|
||
\q1 gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti mọ̀,
|
||
\q2 ìwọ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Èmi kò fi ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà sin ní àyà mi;
|
||
\q2 èmí ti sọ̀rọ̀ nípa òtítọ́ àti ìgbàlà rẹ.
|
||
\q1 Èmi kò sì pa ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ mọ́
|
||
\q2 kúrò láàrín àwọn ìjọ ńlá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìwọ má ṣe, fa àánú rẹ tí ó rọ́nú sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ mi \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 jẹ́ kí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ
|
||
\q2 kí ó máa pa mi mọ́ títí ayérayé.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nítorí pé àìníye ibi
|
||
\q2 ni ó yí mi káàkiri,
|
||
\q1 ẹ̀ṣẹ̀ mi sì dì mọ́ mi,
|
||
\q2 títí tí èmi kò fi ríran mọ́;
|
||
\q1 wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ,
|
||
\q2 àti wí pé àyà mí ti kùnà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 \x - \xo 40.13-17: \xt Sm 70.1-5.\x*Jẹ́ kí ó wù ọ́,
|
||
\q2 ìwọ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q1 láti gbà mí là;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q1 yára láti ràn mí lọ́wọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Gbogbo àwọn wọ̀n-ọn-nì ni kí ojú kí ó tì
|
||
\q2 kí wọn kí ó sì dààmú;
|
||
\q1 àwọn tí ń wá ọkàn mi láti parun
|
||
\q2 jẹ́ kí a lé wọn padà sẹ́yìn kí a sì dójútì wọ́n,
|
||
\q2 àwọn tí ń wá ìpalára mi.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Jẹ́ kí àwọn tí ó wí fún mi pé, “Háà! Háà!”
|
||
\q2 ó di ẹni à fi ọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nítorí ìtìjú wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ
|
||
\q2 kí ó máa yọ̀
|
||
\q1 kí inú wọn sì máa dùn sí ọ;
|
||
\q2 kí gbogbo àwọn tí ó sì fẹ́ ìgbàlà rẹ
|
||
\q1 kí o máa wí nígbà gbogbo pé,
|
||
\q2 “Gbígbéga ni \nd Olúwa\nd*!”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Bí ó ṣe ti èmi ni,
|
||
\q2 tálákà àti aláìní ni èmi,
|
||
\q1 ṣùgbọ́n Olúwa ń ṣe ìrántí mi.
|
||
\q2 Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi
|
||
\q1 àti ìgbàlà mi;
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí ó pẹ́,
|
||
\q2 ìwọ Ọlọ́run mi.
|
||
\c 41
|
||
\cl Saamu 41
|
||
\d Fún adarí orin. Saamu Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní:
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd* yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́:
|
||
\q2 yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀
|
||
\q1 kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 \nd Olúwa\nd* yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀
|
||
\q2 yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ní ti èmi, mo wí pé “\nd Olúwa\nd*, ṣàánú fún mi;
|
||
\q2 wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé,
|
||
\q2 “Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí,
|
||
\q2 wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀;
|
||
\q1 nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi;
|
||
\q2 èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,
|
||
\q1
|
||
\v 8 wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin
|
||
\q2 àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí,
|
||
\q1 kì yóò dìde mọ́.”
|
||
\q1
|
||
\v 9 \x - \xo 41.9: \xt Jh 13.18.\x*Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé,
|
||
\q2 ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi,
|
||
\q1 tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ṣùgbọ́n ìwọ \nd Olúwa\nd*, ṣàánú fún mi;
|
||
\q2 gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi,
|
||
\q2 nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Bí ó ṣe tèmi ni
|
||
\q2 ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi
|
||
\q1 ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.
|
||
\b
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Olùbùkún ni \nd Olúwa\nd*, Ọlọ́run Israẹli,
|
||
\q2 láé àti láéláé.
|
||
\qc Àmín àti Àmín.
|
||
\c 42
|
||
\ms ÌWÉ KEJÌ
|
||
\mr Saamu 42–72
|
||
\cl Saamu 42
|
||
\d Fún adarí orin. Maskili ti àwọn ọmọ Kora.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè.
|
||
\q2 Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?
|
||
\q1
|
||
\v 3 Oúnjẹ mi ni omijé mi
|
||
\q2 ní ọ̀sán àti ní òru,
|
||
\q2 nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́ pé,
|
||
\q2 “Ọlọ́run rẹ dà?”
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí,
|
||
\q2 èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi:
|
||
\q1 èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ,
|
||
\q2 èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́run
|
||
\q1 pẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn,
|
||
\q2 pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?
|
||
\q2 Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?
|
||
\q1 Ìwọ ṣe ìrètí ní ti Ọlọ́run,
|
||
\q2 nítorí èmi yóò sá à máa yìn ín,
|
||
\q2 Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọlọ́run mi, ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi:
|
||
\q2 nítorí náà, èmi ó rántí rẹ
|
||
\q1 láti ilẹ̀ Jordani wá,
|
||
\q2 láti Hermoni láti òkè Mibsari.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ibú omi ń pe ibú omi
|
||
\q2 nípa híhó omi ṣíṣàn rẹ̀
|
||
\q1 gbogbo rírú omi àti bíbì omi rẹ̀
|
||
\q2 bò mí mọ́lẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ní ọ̀sán ní \nd Olúwa\nd* ran ìfẹ́ rẹ̀,
|
||
\q2 àti ni àṣálẹ́ ni orin rẹ̀ wà pẹ̀lú mi
|
||
\q1 àdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Èmi wí fún Ọlọ́run àpáta mi,
|
||
\q2 “Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi?
|
||
\q1 Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́,
|
||
\q2 nítorí ìnilára ọ̀tá?”
|
||
\q1
|
||
\v 10 Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tí
|
||
\q2 àwọn ọ̀tá mi ń gàn mí,
|
||
\q1 bí wọn ti ń béèrè ní gbogbo ọjọ́.
|
||
\q2 “Níbo ni Ọlọ́run rẹ wà?”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?
|
||
\q2 Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?
|
||
\q1 Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run,
|
||
\q2 nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun ni
|
||
\q2 Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
|
||
\c 43
|
||
\cl Saamu 43
|
||
\q1
|
||
\v 1 Dá mi láre, Ọlọ́run mi,
|
||
\q2 kí o sì gba ọ̀rọ̀ mi rò lọ́dọ̀ àwọn aláìláàánú orílẹ̀-èdè:
|
||
\q1 yọ mí kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́tàn àti àwọn ènìyàn búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìwọ ni Ọlọ́run ibi agbára mi.
|
||
\q2 Èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mi sílẹ̀?
|
||
\q1 Èéṣe tí èmi yóò máa rìn nínú ìbìnújẹ́,
|
||
\q2 nítorí ìnilára lọ́dọ̀ àwọn ọ̀tá?
|
||
\q1
|
||
\v 3 Rán ìmọ́lẹ̀ àti òtítọ́ rẹ jáde,
|
||
\q2 jẹ́ kí wọn ó máa dáàbò bò mí;
|
||
\q1 jẹ́ kí wọn mú mi wá sí òkè mímọ́ rẹ,
|
||
\q2 sí ibi tí ìwọ ń gbé.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nígbà náà ni èmi ó lọ sí ibi pẹpẹ Ọlọ́run,
|
||
\q2 sí Ọlọ́run ayọ̀ mi àti ìdùnnú mi,
|
||
\q1 èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú dùùrù,
|
||
\q2 ìwọ Ọlọ́run, Ọlọ́run mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mí?
|
||
\q2 Èéṣe tí ó fi ń ru sókè nínú mi?
|
||
\q1 Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run,
|
||
\q2 nítorí èmi yóò máa yìn ín, Òun ni
|
||
\q2 Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
|
||
\c 44
|
||
\cl Saamu 44
|
||
\d Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Maskili.
|
||
\q1
|
||
\v 1 À ti fi etí wa gbọ́, Ọlọ́run;
|
||
\q2 àwọn baba wa tí sọ fún wa
|
||
\q1 ohun tí ìwọ ṣe ní ọjọ́ wọn,
|
||
\q2 ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìwọ fi ọwọ́ rẹ lé orílẹ̀-èdè jáde,
|
||
\q2 Ìwọ sì gbin àwọn baba wa;
|
||
\q1 ìwọ run àwọn ènìyàn náà
|
||
\q2 Ìwọ sì mú àwọn baba wa gbilẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kì í ṣe nípa idà wọn ni wọ́n gba ilẹ̀ náà,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe apá wọn ní ó gbà wọ́n bí kò ṣe;
|
||
\q1 ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti, apá rẹ;
|
||
\q2 àti ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ̀, nítorí ìwọ fẹ́ wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìwọ ni ọba àti Ọlọ́run mi,
|
||
\q2 ẹni tí ó pàṣẹ ìṣẹ́gun fún Jakọbu.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nípasẹ̀ rẹ ni àwa ó bi àwọn ọ̀tá wa ṣubú;
|
||
\q2 nípasẹ̀ orúkọ rẹ ni àwa ó tẹ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wa mọ́lẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 6 èmi kì yóò gbẹ́kẹ̀lé ọrun mi,
|
||
\q2 idà mi kì yóò mú ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wá,
|
||
\q1
|
||
\v 7 ṣùgbọ́n ìwọ fún wa ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wa,
|
||
\q2 ìwọ sì ti dójúti àwọn tí ó kórìíra wa.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Nínú Ọlọ́run àwa ń ṣògo ní gbogbo ọjọ́,
|
||
\q2 àwa ó sì yin orúkọ rẹ títí láé. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ ti kọ̀ wá, ìwọ sì ti dójútì wá,
|
||
\q2 Ìwọ kò sì bá àwọn ọmọ-ogun wa jáde mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìwọ ti bá wa jà,
|
||
\q2 ìwọ sì ti ṣẹ́gun wa níwájú àwọn ọ̀tá wa,
|
||
\q1 àwọn ọ̀tá wa ti gba ilẹ̀ wa,
|
||
\q2 wọ́n sì fi ipá gba oko wa.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìwọ fi wá fún jíjẹ bí ẹran àgùntàn,
|
||
\q2 Ìwọ sì ti tú wa ká sí àárín àwọn kèfèrí.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ìwọ ta àwọn ènìyàn rẹ fún owó kékeré,
|
||
\q2 Ìwọ kò sì jẹ èrè kankan lórí iye tí ìwọ tà wọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìwọ sọ wá di ẹni ẹ̀sín ní ọ̀dọ̀ àwọn aládùúgbò wa,
|
||
\q2 ẹlẹ́yà àti ẹni àbùkù sí àwọn tí ó yí wa ká.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ìwọ ti sọ wá di ẹni ìfisọ̀rọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè;
|
||
\q2 àwọn ènìyàn ń mi orí wọn sí wa.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ìdójútì mi ń bẹ pẹ̀lú mi ní gbogbo ọjọ́,
|
||
\q2 ìtìjú sì bojú mi mọ́lẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 16 nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn
|
||
\q2 ní ojú àwọn ọ̀tá àti olùgbẹ̀san.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ń ṣẹlẹ̀ sí wa,
|
||
\q2 síbẹ̀ àwa kò gbàgbé rẹ
|
||
\q1 bẹ́ẹ̀ ni a kò ṣèké sí májẹ̀mú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ọkàn wa kò padà sẹ́yìn;
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wa kò yẹ̀ kúrò ní ọ̀nà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ṣùgbọ́n wọ́n kọlù wá,
|
||
\q2 ìwọ sì sọ wá di ẹran ọdẹ fún àwọn ẹranko búburú,
|
||
\q1 tí wọn sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Bí àwa bá ti gbàgbé orúkọ Ọlọ́run wa
|
||
\q2 tàbí tí a na ọwọ́ wa sí ọlọ́run àjèjì.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kì yóò rí ìdí rẹ̀,
|
||
\q2 níwọ̀n ìgbà tí ó mọ ohun ìkọ̀kọ̀ inú ọkàn?
|
||
\q1
|
||
\v 22 \x - \xo 44.22: \xt Ro 8.36.\x*Síbẹ̀, nítorí rẹ̀ àwa da àyà kọ ikú, ní ojoojúmọ́
|
||
\q2 a ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Jí, \nd Olúwa\nd*! Èéṣe tí ìwọ ń sùn?
|
||
\q2 Dìde fúnra rẹ̀! Má ṣe kọ̀ wá sílẹ̀ láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Èéṣe tí ìwọ ń pa ojú rẹ mọ́
|
||
\q2 tí ìwọ sì gbàgbé ìpọ́njú àti ìnira wa?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Nítorí a tẹrí ọkàn wa ba sínú eruku;
|
||
\q2 ara wa sì dì mọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Dìde kí o sì ràn wá lọ́wọ́;
|
||
\q2 rà wá padà nítorí ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.
|
||
\c 45
|
||
\cl Saamu 45
|
||
\d Fún adarí orin. Tí ohun orin “Lílì.” Ti orin àwọn ọmọ Kora. Maskili. Orin ìgbéyàwó.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọkàn mi mọ ọ̀rọ̀ rere
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń sọ ohun tí mo ti ṣe fún ọba
|
||
\q2 ahọ́n mi ni kálámù ayára kọ̀wé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìwọ yanjú ju àwọn ọmọ ènìyàn lọ:
|
||
\q2 a da oore-ọ̀fẹ́ sí ọ ní ètè:
|
||
\q2 nítorí náà ni Ọlọ́run ṣe bùkún fún ọ láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Gba idà rẹ mọ́ ìhà rẹ, ìwọ alágbára jùlọ
|
||
\q2 wọ ara rẹ ní ògo àti ọláńlá.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nínú ọláńlá rẹ, máa gẹṣin lọ ní àlàáfíà lórí òtítọ́,
|
||
\q2 ìwà tútù àti òtítọ́;
|
||
\q2 jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ohun ẹ̀rù.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Jẹ́ kí ọfà mímú rẹ̀ dá ọkàn àwọn ọ̀tá ọba lu
|
||
\q2 jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè ṣubú sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 \x - \xo 45.6-7: \xt Hb 1.8-9.\x*Ọlọ́run láé, àti láéláé ni ìtẹ́ rẹ,
|
||
\q2 ọ̀pá aládé ìjọba rẹ, ọ̀pá aládé òtítọ́ ni.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìwọ fẹ́ olódodo, ìwọ sì kórìíra ìwà búburú
|
||
\q2 nígbà náà Ọlọ́run, Ọlọ́run rẹ ti yàn ọ́ ṣe olórí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ,
|
||
\q2 nípa fífi àmì òróró ayọ̀ kùn ọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Gbogbo aṣọ rẹ̀ ni ó ń rùn pẹ̀lú òjìá àti aloe àti kasia;
|
||
\q2 láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣe
|
||
\q2 orin olókùn tẹ́ẹ́rẹ́ mú inú rẹ̀ dùn.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Àwọn ọmọbìnrin àwọn ọba
|
||
\q2 wà nínú àwọn àyànfẹ́ rẹ̀,
|
||
\q1 ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni ayaba náà gbé dúró
|
||
\q2 nínú wúrà Ofiri.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Gbọ́ ìwọ ọmọbìnrin, ronú kí o sì dẹtí rẹ sí mi
|
||
\q2 gbàgbé àwọn ènìyàn rẹ àti ilé baba rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Bẹ́ẹ̀ ni ọba yóò fẹ́ ẹwà rẹ gidigidi
|
||
\q2 nítorí òun ni olúwa rẹ
|
||
\q1 kí ìwọ sì máa tẹríba fún un.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ọmọbìnrin ọba Tire yóò wá pẹ̀lú ẹ̀bùn
|
||
\q2 àwọn ọkùnrin ọlọ́rọ̀ yóò máa wá ojúrere rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Gbogbo ògo ni ti ọmọbìnrin ọba ní àárín ilé rẹ̀,
|
||
\q2 iṣẹ́ wúrà ọnà abẹ́rẹ́ ní aṣọ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Nínú aṣọ olówó iyebíye ni a mú un tọ́ ọba wá,
|
||
\q2 àwọn wúńdíá ẹgbẹ́ rẹ̀ tẹ̀lé e, wọ́n sí mú un tọ̀ ọ́ wá.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Wọ́n sì mú un wá pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn
|
||
\q2 wọ́n sì wọ ààfin ọba.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ọmọ rẹ̀ ni yóò gba ipò baba rẹ̀
|
||
\q2 ìwọ yóò sì fi wọ́n joyè lórí ilẹ̀ gbogbo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Èmí yóò máa rántí orúkọ rẹ̀ ní ìran gbogbo,
|
||
\q2 nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò yìn ọ́ láé àti láéláé.
|
||
\c 46
|
||
\cl Saamu 46
|
||
\d Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Gẹ́gẹ́ bí ti alamoti. Orin.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọlọ́run ni ààbò àti agbára wa
|
||
\q2 ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ ní ìgbà ìpọ́njú.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nítorí náà àwa kì yóò bẹ̀rù, bí a tilẹ̀ ṣí ayé ní ìdí,
|
||
\q2 tí òkè sì ṣubú sínú Òkun.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Tí omi rẹ̀ tilẹ̀ ń hó tí ó sì ń mì
|
||
\q2 tí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ń mì pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Odò ńlá kan wà tí ṣíṣàn rẹ̀ mú inú ìlú Ọlọ́run dùn,
|
||
\q2 ibi mímọ́, níbi ti Ọ̀gá-ògo ń gbé.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀, kò ní yẹ̀:
|
||
\q2 Ọlọ́run yóò ràn án lọ́wọ́ ní kùtùkùtù òwúrọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Àwọn orílẹ̀-èdè ń bínú, àwọn ilẹ̀ ọba ṣubú,
|
||
\q2 ó gbé ohun rẹ̀ sókè, ayé yọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa,
|
||
\q2 Ọlọ́run Jakọbu ni ààbò wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹ wá wo iṣẹ́ \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 irú ahoro tí ó ṣe ní ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 9 O mú ọ̀tẹ̀ tán de òpin ilẹ̀ ayé
|
||
\q2 ó ṣẹ́ ọrun, ó sì gé ọ̀kọ̀ sí méjì
|
||
\q1 ó fi kẹ̀kẹ́ ogun jóná.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ẹ dúró jẹ́ẹ́, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ní Ọlọ́run.
|
||
\q1 A ó gbé mi ga nínú àwọn orílẹ̀-èdè,
|
||
\q2 a ó gbé mi ga ní ayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa;
|
||
\q2 Ọlọ́run Jakọbu sì ni ààbò wa.
|
||
\c 47
|
||
\cl Saamu 47
|
||
\d Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn
|
||
\q2 ẹ hó sí Ọlọ́run pẹ̀lú orin ayọ̀ tó rinlẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Báwo ni \nd Olúwa\nd* Ọ̀gá-ògo ti ní ẹ̀rù tó
|
||
\q2 ọba ńlá lórí gbogbo ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ṣe ìkápá àwọn orílẹ̀-èdè lábẹ́ wa
|
||
\q2 àwọn ènìyàn lábẹ́ ẹsẹ̀ wa
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ó mú ilẹ̀ ìní wa fún wa,
|
||
\q2 ọlá Jakọbu, ẹni tí ó fẹ́ wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ọlọ́run tó gòkè lọ tí òun tayọ̀,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ti òun ti ariwo ìpè.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ẹ kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn.
|
||
\q2 Ẹ kọrin ìyìn sí ọba wa, ẹ kọrin ìyìn!
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nítorí Ọlọ́run ni ọba gbogbo ayé,
|
||
\q2 ẹ kọrin ìyìn pẹ̀lú Saamu!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ọlọ́run jẹ ọba lórí gbogbo kèfèrí;
|
||
\q2 Ọlọ́run jókòó lórí ìtẹ́ ìwà mímọ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Àwọn aládé ayé kó ara wọn jọ
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run Abrahamu
|
||
\q1 nítorí asà ayé ti Ọlọ́run ni,
|
||
\q2 òun ni ó ga jùlọ.
|
||
\c 48
|
||
\cl Saamu 48
|
||
\d Orin. Saamu ti àwọn ọmọ Kora.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹni ńlá ní \nd Olúwa\nd*, tí ó sì yẹ láti máa yìn
|
||
\q2 ní ìlú Ọlọ́run wa, lórí òkè mímọ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 \x - \xo 48.2: \xt Mt 5.35.\x*Ó dára nínú ipò ìtẹ́ rẹ̀,
|
||
\q2 ayọ̀ gbogbo ayé,
|
||
\q1 òkè Sioni, ní ìhà àríwá
|
||
\q2 ní ìlú ọba ńlá.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọlọ́run wà nínú ààbò ààfin rẹ̀;
|
||
\q2 ó fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ odi alágbára.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nígbà tí àwọn ọba kógun jọ pọ̀,
|
||
\q2 wọ́n jùmọ̀ ń kọjá lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọn rí i, bẹ́ẹ̀ ni ẹnu sì yà wọ́n,
|
||
\q2 a yọ wọ́n lẹ́nu, wọ́n yára lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ẹ̀rù sì bà wọ́n níbẹ̀,
|
||
\q2 ìrora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó wà nínú ìrọbí.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìwọ bà wọ́n jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọkọ̀ orí omi Tarṣiṣi,
|
||
\q2 wọ́n fọ́nká láti ọwọ́ ìjì ìlà-oòrùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Gẹ́gẹ́ bí a ṣe gbọ́,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni àwa rí,
|
||
\q1 ní inú \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun
|
||
\q2 ní ìlú Ọlọ́run wa,
|
||
\q2 Ọlọ́run jẹ́ kí ó wà ní abẹ́ ààbò títí láéláé. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Láàrín tẹmpili rẹ, Ọlọ́run,
|
||
\q2 àwa ti ń sọ ti ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Gẹ́gẹ́ bí orúkọ rẹ Ọlọ́run,
|
||
\q2 ìyìn rẹ̀ dé òpin ayé,
|
||
\q2 ọwọ́ ọ̀tún rẹ kún fún òdodo.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Jẹ́ kí òkè Sioni kí ó yọ̀
|
||
\q2 kí inú àwọn ọmọbìnrin Juda kí ó dùn
|
||
\q2 nítorí ìdájọ́ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Rìn Sioni kiri lọ yíká rẹ̀,
|
||
\q2 ka ilé ìṣọ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Kíyèsi odi rẹ̀,
|
||
\q2 kíyèsi àwọn ààfin rẹ̀
|
||
\q1 kí ẹ̀yin lè máa wí fún ìran tí ń bọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Nítorí Ọlọ́run yìí Ọlọ́run wà ní títí ayé,
|
||
\q2 Òun ni yóò ṣe amọ̀nà wa títí dè òpin ayé.
|
||
\c 49
|
||
\cl Saamu 49
|
||
\d Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ gbọ́ èyí, gbogbo ènìyàn!
|
||
\q2 Ẹ fi etí sí i, gbogbo ẹ̀yin aráyé.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Àti ẹni tí ó ga àti ẹni tí ó kéré
|
||
\q2 tálákà àti ọlọ́lá pẹ̀lú!
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,
|
||
\q2 èrò láti ọkàn mi yóò mú òye wá
|
||
\q1
|
||
\v 4 èmi yóò dẹ etí mi sílẹ̀ sí òwe,
|
||
\q2 èmi yóò ṣí ọ̀rọ̀ ìkọ̀kọ̀ mi sílẹ̀ lójú okùn dùùrù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Èéṣe ti èmi yóò bẹ̀rù nígbà tí ọjọ́ ibi dé?
|
||
\q2 Nígbà tí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ajinnilẹ́sẹ̀ mi yí mi ká,
|
||
\q1
|
||
\v 6 àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn,
|
||
\q2 tí wọn sì ń ṣe ìlérí ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Kò sí ọkùnrin tí ó lè ra ẹ̀mí ẹnìkejì rẹ̀
|
||
\q2 padà tàbí san owó ìràpadà fún
|
||
\q1 Ọlọ́run.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Nítorí ìràpadà fún ẹni jẹ́ iyebíye
|
||
\q2 kò sì sí iye owó tó tó fún sísan rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 9 ní ti kí ó máa wà títí ayé
|
||
\q2 láìrí isà òkú.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rí ọkùnrin ọlọ́gbọ́n tí ó kú,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n pẹ̀lú ṣègbé
|
||
\q1 wọ́n sì fi ọrọ̀ wọn sílẹ̀ fún ẹlòmíràn.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ibojì wọn ni yóò jẹ́ ilé wọn láéláé,
|
||
\q2 ibùgbé wọn láti ìrandíran,
|
||
\q1 wọn sọ orúkọ ilẹ̀ wọn ní orúkọ ara wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí o wà nínú ọlá kò dúró pẹ́
|
||
\q2 ó sì dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Èyí ni òtítọ́ àwọn ènìyàn tí ó
|
||
\q2 gbàgbọ́ nínú ara wọn,
|
||
\q1 àti àwọn tí ń tẹ̀lé wọn,
|
||
\q2 tí ó gba ọ̀rọ̀ wọn. \qs Sela.\qs*
|
||
\q1
|
||
\v 14 Gẹ́gẹ́ bí àgùntàn ni a tẹ́ wọn sínú isà òkú
|
||
\q2 ikú yóò jẹun lórí wọn;
|
||
\q1 ẹni tí ó dúró ṣinṣin ni yóò,
|
||
\q2 jẹ ọba lórí wọn ní òwúrọ̀.
|
||
\q1 Ẹwà wọn yóò díbàjẹ́,
|
||
\q2 isà òkú ni ibùgbé ẹwà wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ra ọkàn mi padà
|
||
\q2 kúrò nínú isà òkú,
|
||
\q1 yóò gbé mi lọ sọ́dọ̀ òun fún rara rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Má ṣe bẹ̀rù nígbà tí ẹnìkan bá di ọlọ́rọ̀.
|
||
\q2 Nígbà tí ìyìn ilé rẹ̀ ń pọ̀ sí i.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Nítorí kì yóò mú ohun kan lọ nígbà tí ó bá kú,
|
||
\q2 ògo rẹ̀ kò ní bá a sọ̀kalẹ̀ sí ipò òkú.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Nígbà tí ó wà láyé, ó súre fún ọkàn ara rẹ̀.
|
||
\q2 Àwọn ènìyàn yìn ọ́ nígbà tí ìwọ ṣe rere.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Òun yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ìran àwọn baba rẹ̀
|
||
\q2 àwọn tí ki yóò ri ìmọ́lẹ̀ ayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ọkùnrin tí ó ní ọlá tí kò ní òye dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.
|
||
\c 50
|
||
\cl Saamu 50
|
||
\d Saamu ti Asafu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, Ọlọ́run alágbára,
|
||
\q2 sọ̀rọ̀ kí o sì pe ayé jọ
|
||
\q2 láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Láti Sioni wá, pípé ni ẹwà,
|
||
\q2 Ọlọ́run tí ń tan ìmọ́lẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọlọ́run ń bọ̀,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dákẹ́,
|
||
\q1 iná yóò máa jó níwájú rẹ̀,
|
||
\q2 àti ní àyíká rẹ̀ ni ẹ̀fúùfù líle yóò ti máa jà ká.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Yóò sì pe àwọn ọ̀run láti òkè wá jọ àti ayé,
|
||
\q2 kí o le máa ṣe ìdárò àwọn ènìyàn rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 “Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún mi
|
||
\q2 àwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi.”
|
||
\q1
|
||
\v 6 Àwọn ọ̀run yóò sì sọ̀rọ̀ òdodo rẹ̀,
|
||
\q2 nítorí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni onídàájọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Israẹli, èmi yóò jẹ́rìí sí ọ:
|
||
\q2 èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Èmi kí yóò bá ọ wí
|
||
\q2 nítorí àwọn ìrúbọ rẹ,
|
||
\q1 tàbí ọrẹ ẹbọ sísun rẹ, èyí tí ó wà níwájú mi
|
||
\q2 ní ìgbà gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Èmí kò fẹ́ kí ó mú akọ màlúù láti inú ilé tí o kọ́ fún un,
|
||
\q2 tàbí kí o mú òbúkọ láti
|
||
\q1 inú agbo ẹran rẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 10 nítorí gbogbo ẹran igbó ni tèmi
|
||
\q2 àti ẹran ọ̀sìn lórí ẹgbẹ̀rún (1,000) òkè.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Èmi mọ gbogbo ẹyẹ ní orí àwọn òkè ńlá
|
||
\q2 àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà ní orí ilẹ̀ ni tèmi.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Bí ebi tilẹ̀ ń pa mí, èmi kì yóò sọ fún ọ,
|
||
\q2 nítorí ayé ni tèmi àti ohun gbogbo
|
||
\q1 tí ó wa ní inú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ǹjẹ́ èmi yóò ha jẹ ẹran akọ màlúù tàbí
|
||
\q2 mú ẹ̀jẹ̀ òbúkọ?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 “Rú ẹbọ ọpẹ́ sí Ọlọ́run,
|
||
\q2 kí o sì san ẹ̀jẹ́ rẹ fún Ọ̀gá-ògo.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Kí o sì pè mí ní ọjọ́ ìpọ́njú,
|
||
\q2 èmi yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì bu ọlá fún mi.”
|
||
\p
|
||
\v 16 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún àwọn, ènìyàn búburú:
|
||
\q1 “Kí ní ẹ̀tọ́ tí o ní tí ìwọ fi ń tún àwọn ìlànà mi sọ,
|
||
\q2 tàbí tí ìwọ sì ń sọ májẹ̀mú mi ní ẹnu rẹ?
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ìwọ kórìíra àṣẹ mi,
|
||
\q2 ìwọ sì ṣá ọ̀rọ̀ mí tì sí apá kan.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Nígbà tí ìwọ rí olè, ìwọ dára pọ̀ mọ́ ọn,
|
||
\q2 ìwọ sì da ara rẹ dé àwọn alágbèrè.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ìwọ lo ẹnu rẹ fún aburú,
|
||
\q2 ìwọ sì ń fi ahọ́n rẹ pète ẹ̀tàn.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ní ìgbà gbogbo ìwọ ń sọ̀rọ̀ sí arákùnrin rẹ,
|
||
\q2 ìwọ sì ń ba orúkọ ọmọ ìyá rẹ jẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ ti ṣe, mo sì dákẹ́;
|
||
\q2 ìwọ rò pé mo jẹ́ irú kan náà bí ìrẹ,
|
||
\q1 ṣùgbọ́n èmi yóò bá ọ wí,
|
||
\q2 èmi yóò sì fi ẹ̀sùn kàn ọ́ ní ojú ara rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 “Ǹjẹ́ ìwọ ro èyí wò, ẹ̀yin tí ó gbàgbé Ọlọ́run.
|
||
\q2 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ èmi yóò fa yin ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, láìsí ẹni tí yóò gbà yin sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ẹni tí ó ba ní ẹbọ ọrẹ-ọpẹ́ bu ọlá fún mi; kí ó sì tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe,
|
||
\q2 kí èmi kí ó le fi ìgbàlà Ọlọ́run hàn án.”
|
||
\c 51
|
||
\cl Saamu 51
|
||
\d Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nígbà ti wòlíì Natani tọ wá, lẹ́yìn tí Dafidi dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè rẹ̀ pẹ̀lú Batṣeba.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run,
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ̀,
|
||
\q1 gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ àánú rẹ̀
|
||
\q2 kí o sì pa gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Wẹ gbogbo àìṣedéédéé mi nù kúrò
|
||
\q2 kí o sì wẹ̀ mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí mo mọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi,
|
||
\q2 nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi wà níwájú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 51.4: \xt Ro 3.4.\x*Sí ọ, ìwọ nìkan ṣoṣo, ni mo dẹ́ṣẹ̀ sí
|
||
\q2 ni mo sì ṣe búburú níwájú rẹ̀,
|
||
\q1 kí a lè dá ọ láre nígbà tí ìwọ bá ń sọ̀rọ̀,
|
||
\q2 kí o sì le wà láìlẹ́bi, nígbà tí ìwọ bá ń ṣe ìdájọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítòótọ́, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni a ti bí mi,
|
||
\q2 nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mí sì lóyún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nítòótọ́ ìwọ fẹ́ òtítọ́ ní inú;
|
||
\q2 ìwọ kọ́ mi ní ọgbọ́n ní ìhà ìkọ̀kọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Wẹ̀ mí pẹ̀lú ewé hísópù, èmi yóò sì mọ́;
|
||
\q2 fọ̀ mí, èmi yóò sì funfun ju yìnyín lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Jẹ́ kí n gbọ́ ayọ̀ àti inú dídùn;
|
||
\q2 jẹ́ kí gbogbo egungun tí ìwọ ti run kí ó máa yọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Pa ojú rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi
|
||
\q2 kí o sì pa gbogbo àwọn àìṣedéédéé mi rẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run,
|
||
\q2 kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Má ṣe jù mi nù kúrò níwájú rẹ,
|
||
\q2 kí o má ṣe gba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Mú ayọ̀ ìgbàlà rẹ tọ̀ mí wá,
|
||
\q2 kí o sì fún mi ní ẹ̀mí ìfẹ́, tí yóò mú mi dúró.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nígbà náà ni èmi yóò máa kọ́ àwọn olùrékọjá ní ọ̀nà rẹ,
|
||
\q2 àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò sì yí padà sí ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Gbà mí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀, Ọlọ́run,
|
||
\q2 ìwọ Ọlọ́run ìgbàlà mi,
|
||
\q1 ahọ́n mi yóò sì máa kọrin òdodo rẹ kíkan.
|
||
\q1
|
||
\v 15 \nd Olúwa\nd*, ṣí mi ní ètè mi gbogbo,
|
||
\q2 àti ẹnu mi yóò sì máa kéde ìyìn rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nítorí ìwọ kò ní inú dídùn sí ẹbọ, tí èmi kò bá mú wá;
|
||
\q2 Ìwọ kò ní inú dídùn sí ọrẹ ẹbọ sísun.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ẹbọ Ọlọ́run ni ìròbìnújẹ́ ọkàn ìròbìnújẹ́ àti ìrora àyà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ṣe rere ní dídùn inú rẹ sí Sioni,
|
||
\q2 ṣe rere; tún odi Jerusalẹmu mọ.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Nígbà náà ni inú rẹ yóò dùn sí ẹbọ òdodo,
|
||
\q2 pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ọrẹ ẹbọ sísun,
|
||
\q2 nígbà náà ni wọn yóò fi akọ màlúù rú ẹbọ lórí pẹpẹ rẹ.
|
||
\c 52
|
||
\cl Saamu 52
|
||
\d Fún adarí orin. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí Doegi ará Edomu tọ Saulu lọ láti sọ fún pé, “Dafidi wà ní ilé Ahimeleki.”
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe féfé nínú ìwà ìkà, ìwọ alágbára ọkùnrin?
|
||
\q2 Èéṣe tí ìwọ fi ń gbéraga nígbà gbogbo,
|
||
\q2 ìwọ ẹni ẹ̀gàn níwájú Ọlọ́run?
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ahọ́n rẹ̀ ń gbìmọ̀ ìparun;
|
||
\q2 ó dàbí abẹ mímú,
|
||
\q2 ìwọ ẹni tí ń hùwà ẹ̀tàn.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ìwọ fẹ́ràn ibi ju ìre lọ,
|
||
\q2 àti èké ju kí ó sọ òtítọ́ lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìwọ fẹ́ràn ọ̀rọ̀ ìpanilára gbogbo,
|
||
\q2 ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ọlọ́run yóò sì lù ọ́ bolẹ̀ láéláé,
|
||
\q2 yóò sì dì ọ́ mú,
|
||
\q1 yóò sì já ọ kúrò ni ibùjókòó rẹ,
|
||
\q2 yóò sì fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè. \qs Sela.\qs*
|
||
\q1
|
||
\v 6 Àwọn olódodo yóò rí, wọn yóò sì bẹ̀rù
|
||
\q2 wọn yóò sì rẹ́rìn-ín rẹ̀, wí pé,
|
||
\q1
|
||
\v 7 “Èyí ni ọkùnrin náà ti kò fi Ọlọ́run ṣe agbára rẹ̀,
|
||
\q2 bí kò ṣe ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ rẹ̀ ni ó gbẹ́kẹ̀lé,
|
||
\q2 ó sì mu ara rẹ̀ le nínú ìwà búburú rẹ̀.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ṣùgbọ́n èmi dàbí igi Olifi
|
||
\q2 tí ó gbilẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run;
|
||
\q1 èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọ́run tí kì í kùnà
|
||
\q2 láé àti láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Èmi yóò yìn ọ títí fún ohun tí ó ti ṣe;
|
||
\q2 èmi ní ìrètí nínú orúkọ rẹ,
|
||
\q1 nítorí orúkọ rẹ dára.
|
||
\q2 Èmi yóò yìn ọ́ níwájú àwọn ènìyàn mímọ́.
|
||
\c 53
|
||
\cl Saamu 53
|
||
\d Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí mahalati. Maskili ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 53.1-3: \xt Ro 3.10-12.\x*\x - \xo 53.1-6: \xt Sm 14.1-7.\x*Aṣiwèrè wí ní ọkàn rẹ̀ pé,
|
||
\q2 “Ọlọ́run kò sí.”
|
||
\q1 Wọ́n bàjẹ́, gbogbo ọ̀nà wọn sì burú;
|
||
\q2 kò sì ṣí ẹnìkan tí ń ṣe rere.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ọlọ́run bojú wo ilẹ̀ láti ọ̀run
|
||
\q2 sórí àwọn ọmọ ènìyàn,
|
||
\q1 láti wò bóyá ẹnìkan wà, tí ó ní òye,
|
||
\q2 tí ó sì ń wá Ọlọ́run.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Gbogbo ènìyàn tí ó ti yí padà,
|
||
\q2 wọ́n ti parapọ̀ di ìbàjẹ́;
|
||
\q1 kò sí ẹnìkan tí ó ń ṣe rere, kò sí ẹnìkan.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ṣé àwọn oníṣẹ́ búburú kò ní ìmọ̀?
|
||
\b
|
||
\q2 Àwọn ẹni tí ń jẹ ènìyàn mi, bí ẹni jẹun
|
||
\q2 tí wọn kò sì pe Ọlọ́run?
|
||
\q1
|
||
\v 5 Níbẹ̀ ni ìwọ gbé wà ní ìbẹ̀rù ńlá
|
||
\q2 níbi tí ẹ̀rù kò gbé sí,
|
||
\q1 nítorí Ọlọ́run tí fọ́n egungun àwọn tí ó dó tì ọ́ ká;
|
||
\q2 ìwọ tí dójútì wọ́n, nítorí Ọlọ́run ti kẹ́gàn wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìgbàlà Israẹli ìbá jáde wá láti Sioni!
|
||
\q2 Nígbà tí Ọlọ́run bá mú ohun ìní àwọn ènìyàn rẹ̀ padà,
|
||
\q2 jẹ́ kí Jakọbu yọ̀ kí inú Israẹli sì máa dùn!
|
||
\c 54
|
||
\cl Saamu 54
|
||
\d Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí àwọn ará Sifi lọ sọ fún Saulu pé, “Dafidi sá pamọ́ sọ́dọ̀ wa?”
|
||
\q1
|
||
\v 1 Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ rẹ:
|
||
\q2 dá mi láre nípa agbára rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run;
|
||
\q2 fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Àwọn agbéraga àlejò dìde sí mí.
|
||
\q2 Àwọn aninilára sì ń wá mi láti pa,
|
||
\q1 àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Kíyèsi i Ọlọ́run ni olùrànlọ́wọ́ mi;
|
||
\q2 Olúwa ní ẹni tí ó mú mi dúró,
|
||
\q2 pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi;
|
||
\q2 pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ,
|
||
\q2 èmi yóò yin orúkọ rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí tí ó dára.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo
|
||
\q2 ojú mi ti wo ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá mi.
|
||
\c 55
|
||
\cl Saamu 55
|
||
\d Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Fi etí sí àdúrà mi, Ọlọ́run,
|
||
\q2 má ṣe fi ojú pa ẹ̀bẹ̀ mi rẹ́:
|
||
\q2
|
||
\v 2 gbọ́ mi kí o sì dá mi lóhùn.
|
||
\q1 Èrò mi ń dà mí láàmú, èmi sì ń pariwo.
|
||
\q2
|
||
\v 3 Sí ohùn àwọn ọ̀tá ni,
|
||
\q2 nítorí igbe àwọn ènìyàn búburú;
|
||
\q1 nítorí wọ́n mú ìjìyà wá sórí mi,
|
||
\q2 wọ́n sì kẹ́gàn mi nínú ìbínú wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ọkàn mi wà nínú ìrora pẹ̀lú;
|
||
\q2 ẹ̀rù ikú kọjú ìjà sí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìbẹ̀rù àti ìwárìrì wa sí ara mi;
|
||
\q2 ìbẹ̀rù ti bò mí mọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmi sọ pé, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà!
|
||
\q2 Èmi ìbá fò lọ kí n sì sinmi.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Èmi ìbá sálọ, jìnnà réré,
|
||
\q2 kí ń sì dúró sí aginjù;
|
||
\q1
|
||
\v 8 èmi ìbá yára lọ́ si ibùgbé mi ní ibi ààbò,
|
||
\q2 jìnnà kúrò nínú ìjì àti ẹ̀fúùfù líle.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Da àwọn ẹni búburú láàmú, \nd Olúwa\nd*, da ahọ́n wọn rú,
|
||
\q2 nítorí èmi rí ìwà agbára àti ìjà ní ìlú náà.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ọ̀sán àti òru ni wọ́n fi ń rìn gbogbo odi kiri;
|
||
\q2 ìwà ìkà àti èébú wà láàrín rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìwà búburú ń bẹ ní àárín rẹ̀;
|
||
\q2 ẹ̀tàn àti èké kò kúrò ní ìgboro rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Tí ọ̀tá bá tàbùkù mi,
|
||
\q2 èmi yóò fi ara mọ́ ọn;
|
||
\q1 tí ọ̀tá bá gbé ara rẹ̀ ga sí mi,
|
||
\q2 èmi ìbá sá pamọ́ fún un.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ṣùgbọ́n tí ó bá ṣe ìwọ, ọkùnrin bí ẹgbẹ́ mi,
|
||
\q2 ẹlẹgbẹ́ mi, àti ọ̀rẹ́ tí ó súnmọ́ mi,
|
||
\q1
|
||
\v 14 pẹ̀lú ẹni tí èmi ti jẹ ìgbádùn adùn ìdàpọ̀,
|
||
\q2 bí a ṣe ń rìn pẹ̀lú àwùjọ ní ilé Ọlọ́run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Kí ikú kí ó dé bá wọn,
|
||
\q2 kí wọn ó lọ láààyè sí isà òkú,
|
||
\q1 jẹ́ kí wọn ó sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú ìpayà,
|
||
\q2 nítorí tí ìwà búburú ń bẹ ní ibùjókòó wọn, àti nínú wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ṣùgbọ́n èmi pe Ọlọ́run;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* yóò sì gbà mí.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ní alẹ́, ní òwúrọ̀ àti ní ọ̀sán
|
||
\q2 èmi sọkún jáde nínú ìpọ́njú,
|
||
\q2 o sì gbọ́ ohùn mi.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ó rà mí padà láìléwu
|
||
\q2 kúrò nínú ogun tí ó dìde sí mi,
|
||
\q2 nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó dìde sí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ọlọ́run yóò gbọ́, yóò sì pọ́n wọn lójú àní,
|
||
\q2 ẹni tí ó ti jókòó láti ìgbàanì \qs Sela,\qs*
|
||
\q1 nítorí tí wọn kò ní àyípadà,
|
||
\q2 tí wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọ́run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ọ̀rẹ́ mi yìí ti dalẹ̀ èmi ọ̀rẹ́ rẹ̀;
|
||
\q2 ó ti ba májẹ̀mú rẹ̀ jẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ kúnná ju òrí-àmọ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ogun wà ni àyà rẹ̀;
|
||
\q1 ọ̀rọ̀ rẹ̀ fẹ́lẹ́ ju òróró lọ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n idà fífàyọ ní wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 \x - \xo 55.22: \xt 1Pt 5.7.\x*Gbé ẹrù rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 yóò sì mú ọ dúró;
|
||
\q1 òun kò ní jẹ́ kí olódodo ṣubú.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni yóò mu àwọn ọ̀tá mi
|
||
\q2 wá sí ihò ìparun;
|
||
\q1 àwọn ẹni tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ àti ẹni ẹ̀tàn,
|
||
\q2 kì yóò gbé ààbọ̀ ọjọ́ wọn.
|
||
\b
|
||
\q1 Ṣùgbọ́n fún èmi, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ.
|
||
\c 56
|
||
\cl Saamu 56
|
||
\d Fún adarí orin. Ti ohùn “Àdàbà lórí Óákù òkè réré.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí àwọn ará Filistini ka mọ́ ní Gati.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run,
|
||
\q2 nítorí àwọn ènìyàn ń fi ìgbónára lépa mi;
|
||
\q2 ní gbogbo ọjọ́ ni wọn ń kọjú ìjà sí mi, wọn ń ni mi lára.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Àwọn ọ̀tá mi ń lé mi ní gbogbo ọjọ́,
|
||
\q2 àwọn ènìyàn ń kọjú ìjà sí mi nínú ìgbéraga wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nígbà tí ẹ̀rù bà ń bà mí,
|
||
\q2 èmi o gbẹ́kẹ̀lé ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nínú Ọlọ́run èmi yóò máa yìn ọ̀rọ̀ rẹ,
|
||
\q2 nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi; ẹ̀rù kì yóò bà mí
|
||
\q1 kí ni ẹran-ara lè ṣe sí mi?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọn ń yí ọ̀rọ̀ mí ní gbogbo ọjọ́,
|
||
\q2 wọn ń gbèrò nígbà gbogbo láti ṣe mí níbi.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Wọn kó ara wọn jọ, wọ́n ba.
|
||
\q2 Wọ́n ń ṣọ́ ìgbésẹ̀ mi
|
||
\q1 wọn ń làkàkà láti gba ẹ̀mí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 7 San ẹ̀san iṣẹ́ búburú wọ́n fún wọn;
|
||
\q2 ní ìbínú rẹ, Ọlọ́run, wọ́ àwọn ènìyàn náà bọ́ sílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Kọ ẹkún mi sílẹ̀;
|
||
\q2 kó omijé mi sí ìgò rẹ,
|
||
\q1 wọ́n kò ha sí nínú ìkọ̀sílẹ̀ rẹ bí?
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nígbà náà ni àwọn ọ̀tá mi yóò pẹ̀yìndà
|
||
\q2 nígbà tí mo bá pè fún ìrànlọ́wọ́
|
||
\q2 nípa èyí ni mo mọ̀ pé Ọlọ́run ń bẹ fún mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nínú Ọlọ́run, ẹni tí mo yìn ọ̀rọ̀ rẹ̀
|
||
\q2 nínú \nd Olúwa\nd*, ẹni tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 11 nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi:
|
||
\q2 ẹ̀rù kì yóò bà mí.
|
||
\q1 Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Mo jẹ́ ẹ̀jẹ́ lábẹ́ rẹ Ọlọ́run:
|
||
\q2 èmi o mú ìyìn mi wá fún ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nítorí ìwọ tí gbà mí lọ́wọ́ ikú
|
||
\q2 àti ẹsẹ̀ mi lọ́wọ́ ìṣubú,
|
||
\q1 kí èmí lè máa rìn níwájú Ọlọ́run
|
||
\q2 ní ìmọ́lẹ̀ àwọn alààyè.
|
||
\c 57
|
||
\cl Saamu 57
|
||
\d Fún adarí orin. Ní ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí ó sá níwájú Saulu lọ sínú ihò òkúta.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, ṣàánú fún mi,
|
||
\q2 nítorí nínú rẹ ni ààbò ọkàn mí wà.
|
||
\q1 Èmi o fi ààbò mí sí ibi ìyẹ́ apá rẹ
|
||
\q2 títí tí ewu yóò fi kọjá lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Mo kígbe sókè sí Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ,
|
||
\q2 sí Ọlọ́run tó ń pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ fún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Òun yóò ránṣẹ́ láti ọ̀run wá,
|
||
\q2 yóò sì gbà mí, bí ẹni tí ń fẹ́ gbé mi mì
|
||
\q1 tilẹ̀ ń kẹ́gàn mi.
|
||
\q2 Ọlọ́run yóò rán àánú rẹ̀ àti òdodo rẹ̀ jáde.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Mo wà ní àárín àwọn kìnnìún;
|
||
\q2 mo dùbúlẹ̀ ni abẹ́ àwọn ẹ̀dá búburú,
|
||
\q1 àwọn ènìyàn tí eyín wọn dàbí ọ̀kọ̀ àti ọfà
|
||
\q2 ẹni tí ahọ́n rẹ̀ jẹ́ idà mímú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Kí a yìn ọ́ Ọlọ́run, ju ọ̀run lọ,
|
||
\q2 kí ògo rẹ kò ju ti gbogbo ayé lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Wọ́n ti ta àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ mi:
|
||
\q2 a tẹ orí ọkàn mi ba nínú ìtìjú,
|
||
\q1 wọ́n gbẹ́ kòtò sí ọ̀nà mi:
|
||
\q1 ṣùgbọ́n wọ́n ti jì síbẹ̀ fún ara wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 \x - \xo 57.7-11: \xt Sm 108.1-5.\x*Ọkàn mi ti múra Ọlọ́run;
|
||
\q2 ọkàn mi ti múra, èmi ó kọrin, èmi ó si máa kọrin ìyìn.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Jí, ìwọ ọkàn mi!
|
||
\q2 Jí, ohun orin èlò àti dùùrù!
|
||
\q2 Èmi tìkára mi, yóò sì jí ní kùtùkùtù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Èmi ó máa yìn ọ́, \nd Olúwa\nd*, láàrín àwọn orílẹ̀-èdè;
|
||
\q2 èmi ó máa kọrin sí ọ láàrín àwọn ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nítorí títóbi ní ìfẹ́ rẹ, tí ó dé ọ̀run;
|
||
\q2 òtítọ́ rẹ tàn dé àwọsánmọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Gbígbéga ni ọ́, Ọlọ́run, ju àwọn ọ̀run lọ;
|
||
\q2 kí ògo rẹ kí ó ju gbogbo ayé lọ.
|
||
\c 58
|
||
\cl Saamu 58
|
||
\d Fún adarí orin. Tí ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ̀yin ha ń sọ òdodo nítòótọ́
|
||
\q2 ẹ̀yin ìjọ ènìyàn?
|
||
\q1 Ǹjẹ́ ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ tí ó ṣe títọ́
|
||
\q2 ẹ̀yìn ọmọ ènìyàn?
|
||
\q1
|
||
\v 2 Bẹ́ẹ̀ kọ́, nínú ọkàn yín ẹ̀yìn ń gbèrò àìṣòdodo,
|
||
\q2 ọwọ́ yín sì tú ìwà ipá jáde ni ayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ní inú ìyá wọn wá ni ènìyàn búburú tí ṣìnà,
|
||
\q2 lójúkan náà tí a ti bí wọn, wọn a máa ṣèké.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Oró wọn dàbí oró ejò,
|
||
\q2 wọn dàbí adití ejò paramọ́lẹ̀ tí ó di ara rẹ̀ ni etí,
|
||
\q1
|
||
\v 5 tí kò ní gbọ́ ìpè àwọn atunilójú,
|
||
\q2 bí ó ti wù kí ó máa fi ọgbọ́n ṣe ìtujú tó.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ká eyín ẹnu wọn, Ọlọ́run;
|
||
\q2 ní ẹnu wọn,
|
||
\q1 ká ọ̀gàn àwọn ọmọ kìnnìún, \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Jẹ́ kí wọn parẹ́ bí omi tó ń sàn lọ;
|
||
\q2 nígbà tí ó bá fa ọfà rẹ̀, kí ọ̀kọ̀ wọn kí ó ṣẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Jẹ́ kí wọn rí bí ìgbín tí rẹ̀ dànù tí ó sì ṣègbé
|
||
\q2 bí ọmọ tí oṣù rẹ̀ kò pé, kí wọn má ṣe rí oòrùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Kí ìkòkò yín kí ó tó mọ ìgbóná ẹ̀gún;
|
||
\q2 bóyá ní tútù tàbí ní gbígbẹ, yóò fi ìjì gbá wọn lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Olódodo yóò yọ̀ nígbà a bá ń gbẹ̀san wọn,
|
||
\q2 nígbà tí wọn bá wẹ ẹsẹ̀ wọn nínú ẹ̀jẹ̀ ènìyàn búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Àwọn ènìyàn yóò wí pé,
|
||
\q2 “Lóòtítọ́ èrè àwọn ń bẹ fún olódodo;
|
||
\q2 lóòtítọ́ òun ni Ọlọ́run tí ń ṣe ìdájọ́ ní ayé.”
|
||
\c 59
|
||
\cl Saamu 59
|
||
\d Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run;
|
||
\q2 dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú
|
||
\q2 kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí!
|
||
\q2 Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi
|
||
\q1 kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí.
|
||
\q2 Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
|
||
\q1
|
||
\v 5 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run Alágbára,
|
||
\q2 Ọlọ́run Israẹli,
|
||
\q1 dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí;
|
||
\q2 má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Wọ́n padà ní àṣálẹ́,
|
||
\q2 wọ́n ń gbó bí àwọn ajá,
|
||
\q2 wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu:
|
||
\q2 wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn,
|
||
\q2 wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ṣùgbọ́n ìwọ, \nd Olúwa\nd*, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín,
|
||
\q2 Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ;
|
||
\q2 nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
|
||
\q2
|
||
\v 10 Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi.
|
||
\b
|
||
\q1 Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi.
|
||
\q2 Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa,
|
||
\q2 kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé.
|
||
\q1 Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri,
|
||
\q2 kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn,
|
||
\q2 ní ọ̀rọ̀ ètè wọn,
|
||
\q2 kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn.
|
||
\q1 Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
|
||
\q2
|
||
\v 13 pa wọ́n run nínú ìbínú,
|
||
\q2 run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́.
|
||
\q1 Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé
|
||
\q2 pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́,
|
||
\q2 wọn ń gbó bí àwọn ajá
|
||
\q2 wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ
|
||
\q2 wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ,
|
||
\q2 n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀;
|
||
\q1 nítorí ìwọ ni ààbò mi,
|
||
\q2 ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ;
|
||
\q2 ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.
|
||
\c 60
|
||
\cl Saamu 60
|
||
\d Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì ti Májẹ̀mú.” Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀,
|
||
\q2 Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká,
|
||
\q1 ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ;
|
||
\q2 mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ;
|
||
\q2 ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún
|
||
\q2 kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 \x - \xo 60.5-12: \xt Sm 108.6-13.\x*Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́,
|
||
\q2 kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀:
|
||
\q2 “Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde
|
||
\q2 èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase;
|
||
\q2 Efraimu ni àṣíborí mi,
|
||
\q2 Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi,
|
||
\q2 lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí;
|
||
\q2 lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì?
|
||
\q2 Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?
|
||
\q1
|
||
\v 10 Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀
|
||
\q2 tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
|
||
\q1
|
||
\v 11 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá,
|
||
\q2 nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun,
|
||
\q2 yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
|
||
\c 61
|
||
\cl Saamu 61
|
||
\d Fún adarí orin. Ohun èlò orin olókùn. Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Gbọ́ ẹkún mi, Ọlọ́run;
|
||
\q2 tẹ́tí sí àdúrà mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Láti òpin ayé wá ni èmi yóò pè ọ́,
|
||
\q2 mo pè nígbà àyà mi ń ṣàárẹ̀;
|
||
\q2 mú mi lọ sí ibi àpáta tí ó ga jù mí lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí ìwọ ti jẹ́ ibi ààbò mi,
|
||
\q2 ilé ìṣọ́ agbára àwọn ọ̀tá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Mo ń lépa láti máa gbé nínú àgọ́ rẹ títí láé
|
||
\q2 kí n sì rí ààbò níbi ìyẹ́ apá rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí ìwọ ti gbọ́ àwọn ẹ̀jẹ́ mi, Ọlọ́run;
|
||
\q2 Ìwọ ti fún mi ní ogún àwọn tí ó bẹ̀rù orúkọ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Jẹ́ kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn,
|
||
\q2 ọdún rẹ̀ fún ìrandíran.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Kí ó máa jẹ ọba níwájú Ọlọ́run títí láé;
|
||
\q2 pèsè àánú àti òtítọ́ rẹ tí yóò máa ṣe ìtọ́jú rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Nígbà náà ni èmi ó máa kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ títí láé
|
||
\q2 kí n san ẹ̀jẹ́ mi ní ojoojúmọ́.
|
||
\c 62
|
||
\cl Saamu 62
|
||
\d Fún adarí orin. Fun Jedutuni. Saamu Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Nínú Ọlọ́run nìkan ni ọkàn mi ti rí ìsinmi;
|
||
\q2 ìgbàlà mi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Òun nìkan ní àpáta mi àti ìgbàlà mi;
|
||
\q2 Òun ni ààbò mi, a kì yóò sí mi ní ipò padà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹ̀yin ó ti máa kọ́lú ènìyàn kan pẹ́ tó?
|
||
\q2 Gbogbo yín ni ó fẹ́ pa á,
|
||
\q2 bí ògiri tí ó fẹ́ yẹ̀, àti bí ọgbà tí ń wó lọ?
|
||
\q1
|
||
\v 4 Kìkì èrò wọn ni láti bì ṣubú
|
||
\q2 kúrò nínú ọlá rẹ̀;
|
||
\q2 inú wọn dùn sí irọ́.
|
||
\q1 Wọ́n ń fi ẹnu wọn súre,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n wọ́n ń gégùn ún nínú ọkàn wọn. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nínú Ọlọ́run nìkan ni ìsinmi wà, ìwọ Ọlọ́run mi.
|
||
\q2 Ìrètí mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Òun nìkan ní àpáta àti ìgbàlà mi;
|
||
\q2 Òun ni ààbò mi, a kì yóò ṣí mi ní ipò.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìgbàlà mi àti ògo mi dúró nínú Ọlọ́run;
|
||
\q2 Òun ní àpáta ńlá mi, àti ààbò mi.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Gbẹ́kẹ̀lé ní gbogbo ìgbà, ẹ̀yin ènìyàn;
|
||
\q2 tú ọkàn rẹ jáde sí i,
|
||
\q1 nítorí Ọlọ́run ni ààbò wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítòótọ́, asán ni àwọn ọmọ ènìyàn,
|
||
\q2 èké sì ni àwọn olóyè,
|
||
\q1 wọ́n gòkè nínú ìwọ̀n,
|
||
\q2 lápapọ̀ wọ́n jẹ́ èémí.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Má ṣe gbẹ́kẹ̀lé ìnilára,
|
||
\q2 tàbí gbéraga nínú olè jíjà,
|
||
\q1 nítòótọ́ bí ọrọ̀ rẹ̀ ń pọ̀ sí i,
|
||
\q2 má ṣe gbẹ́kẹ̀ rẹ lé wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kejì,
|
||
\q2 ni mo gbọ́ èyí pé,
|
||
\q1 “Ti Ọlọ́run ni agbára,
|
||
\q2
|
||
\v 12 \x - \xo 62.12: \xt Jr 17.10; If 2.23; 22.12.\x*pẹ̀lúpẹ̀lú, \nd Olúwa\nd*, tìrẹ ni àánú;
|
||
\q2 nítorí tí ìwọ san án fún olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.”
|
||
\c 63
|
||
\cl Saamu 63
|
||
\d Saamu ti Dafidi. Nígbà tí ó wà nínú aginjù Juda.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run mi,
|
||
\q2 nígbà gbogbo ni mo ń ṣàfẹ́rí rẹ,
|
||
\q1 òǹgbẹ rẹ ń gbẹ ọkàn mi,
|
||
\q2 ara mi fà sí ọ,
|
||
\q1 ní ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tí ń ṣàárẹ̀
|
||
\q2 níbi tí kò sí omi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Èmi ti rí ọ ní ibi mímọ́,
|
||
\q2 mo rí agbára àti ògo rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ayé lọ,
|
||
\q2 ètè mi yóò fògo fún ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Èmi ó yìn ọ́ níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè,
|
||
\q2 èmi ó gbé ọwọ́ sókè, èmi ó sì pe orúkọ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 A ó tẹ́ ọkàn mi lọ́rùn bí ọlọ́ràá oúnjẹ;
|
||
\q2 pẹ̀lú ètè ìyìn, ẹnu mi yóò yìn ọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nígbà tí mo rántí rẹ lórí ibùsùn mi;
|
||
\q2 èmi ń ronú rẹ títí ìṣọ́ òru.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nítorí ìwọ ni ìrànlọ́wọ́ mi,
|
||
\q2 mo kọrin níbi òjìji ìyẹ́ apá rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ọkàn mí fà sí ọ:
|
||
\q2 ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbé mi ró.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Àwọn tí ó ń wá ọkàn mí ni a ó parun;
|
||
\q2 wọn ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Wọn ó ti ọwọ́ idà ṣubú
|
||
\q2 wọn ó sì di jíjẹ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ṣùgbọ́n ọba yóò yọ̀ nínú Ọlọ́run
|
||
\q2 ẹni tí ó fi orúkọ Ọlọ́run búra yóò ṣògo
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ẹnu àwọn òpùrọ́ la ó pamọ́.
|
||
\c 64
|
||
\cl Saamu 64
|
||
\d Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Gbóhùn mi, Ọlọ́run, bí mo ti ń sọ àròyé mi
|
||
\q2 pa ọkàn mi mọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹ̀rù àwọn ọ̀tá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ ìmọ̀ ìkọ̀kọ̀ àwọn ènìyàn búburú
|
||
\q2 kúrò nínú ọ̀pọ̀ igbe lọ́wọ́ ìrúkèrúdò oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Wọ́n pọ́n ahọ́n wọn bí idà,
|
||
\q2 wọ́n sì fa ọrun wọn le láti tafà wọn, àní ọ̀rọ̀ kíkorò.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Wọ́n tafà ní ìkọ̀kọ̀ sí àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀:
|
||
\q2 wọ́n tafà si lójijì, wọn kò sì bẹ̀rù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọ́n, gba ara wọn níyànjú nínú èrò búburú,
|
||
\q2 wọ́n sọ̀rọ̀ lórí dídẹkùn sílẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀
|
||
\q2 wọ́n wí pé, “Ta ni yóò rí wa?”
|
||
\q1
|
||
\v 6 Wọ́n gbìmọ̀ àìṣòdodo, wọ́n wí pé,
|
||
\q2 “A wa ti parí èrò tí a gbà tán!”
|
||
\q2 Lóòótọ́ àyà àti ọkàn ènìyàn kún fún àrékérekè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ta wọ́n ní ọfà;
|
||
\q2 wọn ó sì gbọgbẹ́ lójijì.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ahọ́n wọn yóò sì dojú ìjà kọ wọ́n, yóò sì run wọ́n,
|
||
\q2 gbogbo ẹni tí ó bá rí wọn yóò sì mi orí fún wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Gbogbo ènìyàn yóò máa bẹ̀rù
|
||
\q2 wọn ó kéde iṣẹ́ Ọlọ́run
|
||
\q2 wọn ó dúró lé ohun tí ó ṣe.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Jẹ́ kí olódodo kí ó yọ̀ nínú \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 yóò sì rí ààbò nínú rẹ̀.
|
||
\q2 Gbogbo ẹni ìdúró ṣinṣin ní ọkàn yóò máa yìn ín.
|
||
\c 65
|
||
\cl Saamu 65
|
||
\d Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Orin.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìyìn ń dúró dè ọ́, Ọlọ́run, ní Sioni;
|
||
\q2 sí ọ ni a ó mú ẹ̀jẹ́ wa ṣẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìwọ tí ó ń gbọ́ àdúrà,
|
||
\q2 gbogbo ènìyàn yóò sì wá sọ́dọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọ̀ràn àìṣedéédéé borí mi bí ó ṣe ti ìrékọjá wa ni!
|
||
\q2 Ìwọ ni yóò wẹ̀ wọ́n nù kúrò.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìbùkún ni fún àwọn tí o yàn
|
||
\q2 tí o mú wa láti máa gbé àgọ́ rẹ!
|
||
\q1 A tẹ́ wá lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere inú ilé rẹ,
|
||
\q2 ti tẹmpili mímọ́ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ dá wa lóhùn pẹ̀lú ohun ìyanu ti òdodo,
|
||
\q2 Ọlọ́run olùgbàlà wa,
|
||
\q1 ẹni tí ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé gbogbo òpin ayé
|
||
\q2 àti àwọn tí ó jìnnà nínú òkun,
|
||
\q1
|
||
\v 6 ìwọ tí ó dá òkè nípa agbára rẹ,
|
||
\q2 tí odi ara rẹ ní àmùrè agbára,
|
||
\q1
|
||
\v 7 ẹni tí ó mú rírú omi òkun dákẹ́,
|
||
\q2 ríru ariwo omi wọn,
|
||
\q2 àti ìdágìrì àwọn ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Àwọn tí ó ń gbé òkèrè bẹ̀rù,
|
||
\q2 nítorí àmì rẹ wọ̀n-ọn-nì;
|
||
\q2 ìwọ mú ìjáde òwúrọ̀ àti ti àṣálẹ́ yọ̀,
|
||
\q2 ìwọ pè fún orin ayọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìwọ bẹ ayé wò, o sì bomirin;
|
||
\q2 ìwọ mú un ọ̀rọ̀ púpọ̀.
|
||
\q1 Odò Ọlọ́run kún fún omi
|
||
\q2 láti pèsè ọkà fún àwọn ènìyàn,
|
||
\q1 nítorí ibẹ̀ ni ìwọ ti yàn án.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìwọ fi bomirin sí aporo rẹ̀
|
||
\q2 ìwọ tẹ́ ògúlùtu rẹ̀;
|
||
\q1 ìwọ fi òjò mú ilẹ̀ rẹ̀ rọ̀,
|
||
\q2 o sì bùkún ọ̀gbìn rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìwọ fi oore rẹ dé ọdún ní adé,
|
||
\q2 ọ̀rá ń kán ní ipa ọ̀nà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Pápá tútù ní aginjù ń kan
|
||
\q2 àwọn òkè kéékèèké fi ayọ̀ di ara wọn ní àmùrè.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Agbo ẹran ni a fi wọ pápá tútù náà ní aṣọ;
|
||
\q2 àfonífojì ni a fi ọkà bò mọ́lẹ̀,
|
||
\q2 wọ́n hó fún ayọ̀, wọ́n ń kọrin pẹ̀lú.
|
||
\c 66
|
||
\cl Saamu 66
|
||
\d Fún adarí orin. Orin. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
|
||
\q2
|
||
\v 2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀;
|
||
\q2 ẹ kọrin ìyìnsí i.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ!
|
||
\q2 Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ
|
||
\q2 ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ;
|
||
\q2 wọn ń kọrin ìyìn sí ọ,
|
||
\q2 wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe,
|
||
\q2 iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ,
|
||
\q2 wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá,
|
||
\q2 níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀,
|
||
\q2 ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè
|
||
\q2 kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn,
|
||
\q2 jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa,
|
||
\q2 kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò;
|
||
\q2 ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n
|
||
\q2 o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí
|
||
\q2 àwa la iná àti omi kọjá
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun,
|
||
\q2 kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
|
||
\q1
|
||
\v 14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ
|
||
\q2 nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ,
|
||
\q2 àti ẹbọ ọ̀rá àgbò;
|
||
\q2 èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run;
|
||
\q2 ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i,
|
||
\q2 ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi,
|
||
\q2 Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
|
||
\q1
|
||
\v 19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́
|
||
\q2 ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run
|
||
\q2 ẹni tí kò kọ àdúrà mi
|
||
\q2 tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
|
||
\c 67
|
||
\cl Saamu 67
|
||
\d Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu. Orin.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Kí Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa kí ó sì bùkún fún wa,
|
||
\q2 kí ó sì jẹ́ kí ojú rẹ̀ tàn yí wa ká,
|
||
\q1
|
||
\v 2 kí ọ̀nà rẹ le di mí mọ̀ ní ayé,
|
||
\q2 ìgbàlà rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kí àwọn ènìyàn kí ó yìn ọ́, Ọlọ́run;
|
||
\q2 kí gbogbo ènìyàn kí ó yìn ọ́!
|
||
\q1
|
||
\v 4 Kí orílẹ̀-èdè kí ó yọ̀, kí ó sì kọrin fún ayọ̀,
|
||
\q2 nítorí ìwọ fi òdodo darí àwọn ènìyàn,
|
||
\q2 ìwọ sì jẹ ọba àwọn orílẹ̀-èdè ní ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Kí àwọn ènìyàn kí ó yìn ọ́, Ọlọ́run;
|
||
\q2 kí gbogbo ènìyàn kí ó yìn ọ́. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nígbà náà ní ilẹ̀ yóò mú ìkórè rẹ̀ wá, Ọlọ́run,
|
||
\q2 Ọlọ́run wa, yóò bùkún fún wa.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ọlọ́run yóò bùkún fún wa,
|
||
\q2 àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò sì máa bẹ̀rù rẹ̀.
|
||
\c 68
|
||
\cl Saamu 68
|
||
\d Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká;
|
||
\q2 kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ,
|
||
\q2 kí ó fẹ́ wọn lọ;
|
||
\q1 bí ìda ti í yọ́ níwájú iná,
|
||
\q2 kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn
|
||
\q2 kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run;
|
||
\q2 kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ẹ kọrin sí Ọlọ́run,
|
||
\q2 ẹ kọrin ìyìn sí i,
|
||
\q1 ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù.
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé
|
||
\q2 rẹ̀ mímọ́
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọlọ́run gbé aláìlera
|
||
\q2 kalẹ̀ nínú ìdílé,
|
||
\q1 ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run,
|
||
\q2 tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, \qs Sela.\qs*
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ilẹ̀ mì títí,
|
||
\q2 àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde,
|
||
\q1 níwájú Ọlọ́run,
|
||
\q2 ẹni Sinai,
|
||
\q1 níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run;
|
||
\q2 ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀
|
||
\q2 nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀,
|
||
\q2 púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 12 “Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ;
|
||
\q2 obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran,
|
||
\q2 nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà,
|
||
\q2 àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
|
||
\q1
|
||
\v 14 Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà,
|
||
\q2 ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run;
|
||
\q2 òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara,
|
||
\q2 ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba
|
||
\q2 níbi tí \nd Olúwa\nd* fúnra rẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run
|
||
\q2 ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún;
|
||
\q2 Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga
|
||
\q2 ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ;
|
||
\q2 ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn:
|
||
\q1 nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú,
|
||
\q2 kí \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Olùbùkún ni \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 Ọlọ́run Olùgbàlà wa,
|
||
\q1 ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. \qs Sela.\qs*
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà
|
||
\q2 àti sí \nd Olúwa\nd* Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀,
|
||
\q2 àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
|
||
\q1
|
||
\v 22 Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani;
|
||
\q2 èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
|
||
\q1
|
||
\v 23 kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ,
|
||
\q2 àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run,
|
||
\q2 ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Àwọn akọrin wà ní iwájú, àwọn olórin wà lẹ́yìn;
|
||
\q2 àwọn ọmọbìnrin tí ń lu ṣaworo sì wà pẹ̀lú wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd* ní ẹgbẹgbẹ́;
|
||
\q2 àní fún \nd Olúwa\nd* ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn,
|
||
\q2 níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda,
|
||
\q2 níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run;
|
||
\q2 fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu
|
||
\q2 àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Bá àwọn ẹranko búburú wí,
|
||
\q2 tí ń gbé láàrín eèsún
|
||
\q1 ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù
|
||
\q2 pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù
|
||
\q1 títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà:
|
||
\q2 tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti;
|
||
\q2 Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 32 Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé,
|
||
\q2 kọrin ìyìn sí \nd Olúwa\nd*, \qs Sela.\qs*
|
||
\q1
|
||
\v 33 Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè,
|
||
\q2 tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
|
||
\q1
|
||
\v 34 Kéde agbára Ọlọ́run,
|
||
\q2 ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli,
|
||
\q2 tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
|
||
\q1
|
||
\v 35 Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ;
|
||
\q2 Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1 Olùbùkún ní Ọlọ́run!
|
||
\c 69
|
||
\cl Saamu 69
|
||
\d Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Gbà mí, Ọlọ́run,
|
||
\q2 nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Mo ń rì nínú irà jíjìn,
|
||
\q2 níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé.
|
||
\q1 Mo ti wá sínú omi jíjìn;
|
||
\q2 ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́;
|
||
\q2 ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú,
|
||
\q1 nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 69.4: \xt Sm 35.19; Jh 15.25.\x*Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí
|
||
\q2 wọ́n ju irun orí mi lọ,
|
||
\q1 púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí,
|
||
\q2 àwọn tí ń wá láti pa mí run.
|
||
\q1 A fi ipá mú mi
|
||
\q2 láti san ohun tí èmi kò jí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run;
|
||
\q2 ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi,
|
||
\q2 Olúwa, \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun;
|
||
\q1 má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi,
|
||
\q2 Ọlọ́run Israẹli.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn,
|
||
\q2 ìtìjú sì bo ojú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi;
|
||
\q2 àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
|
||
\q1
|
||
\v 9 \x - \xo 69.9: \xt Jh 2.17; Ro 15.3.\x*nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run,
|
||
\q2 àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nígbà tí mo sọkún
|
||
\q2 tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà
|
||
\q1 èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
|
||
\q1
|
||
\v 11 nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà,
|
||
\q2 àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi,
|
||
\q2 mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni
|
||
\q2 ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q1 ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà
|
||
\q2 Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ,
|
||
\q1 dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀,
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí n rì;
|
||
\q1 gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi,
|
||
\q2 kúrò nínú ibú omi.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì
|
||
\q1 kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Dá mí lóhùn, \nd Olúwa\nd*, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ;
|
||
\q2 nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ:
|
||
\q2 yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là;
|
||
\q2 rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá;
|
||
\q2 gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́,
|
||
\q2 wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́;
|
||
\q2 mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí,
|
||
\q2 mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi,
|
||
\q2 àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn
|
||
\q2 ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ
|
||
\q2 fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran,
|
||
\q2 kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
|
||
\q1
|
||
\v 24 \x - \xo 69.24: \xt If 16.1.\x*Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn;
|
||
\q2 kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 25 \x - \xo 69.25: \xt Ap 1.20.\x*Kí ibùjókòó wọn di ahoro;
|
||
\q2 kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù,
|
||
\q2 àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn;
|
||
\q2 Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 28 \x - \xo 69.28: \xt If 3.5; 13.8; 17.8; 20.12,15; 21.27.\x*Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè
|
||
\q2 kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí,
|
||
\q2 Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga
|
||
\q2 èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Eléyìí tẹ́ \nd Olúwa\nd* lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ
|
||
\q2 ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 32 Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀:
|
||
\q2 ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
|
||
\q1
|
||
\v 33 \nd Olúwa\nd*, gbọ́ ti aláìní,
|
||
\q2 kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 34 Kí ọ̀run àti ayé yìn ín,
|
||
\q2 òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 35 nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là
|
||
\q2 yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́.
|
||
\q1 Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
|
||
\q2
|
||
\v 36 àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀,
|
||
\q2 àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.
|
||
\c 70
|
||
\cl Saamu 70
|
||
\d Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ẹ̀bẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 70.1-5: \xt Sm 40.13-17.\x*Yára, Ọlọ́run, láti gbà mí là,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, wá kánkán láti ràn mí lọ́wọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Kí àwọn tí ń wá ọkàn mi
|
||
\q2 kí a dójútì wọ́n, kí wọn sì dààmú;
|
||
\q1 kí àwọn tó ń wá ìparun mi
|
||
\q2 yí ẹ̀yìn padà nínú ìtìjú.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kí a pa wọ́n ní ẹ̀yìn dà fún èrè
|
||
\q2 ìtìjú àwọn tí ń wí pé, “Háà! Háà!”
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ṣùgbọ́n kí àwọn tí ó ń wá ọ ó máa yọ̀
|
||
\q2 kí inú wọn kí ó sì máa dùn nípa rẹ,
|
||
\q1 kí àwọn tí ó ń fẹ́ ìgbàlà rẹ máa wí pé,
|
||
\q2 “Jẹ́ kí a gbé Ọlọ́run ga!”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ṣùgbọ́n mo jẹ́ òtòṣì àti aláìní;
|
||
\q2 wa kánkán sí ọ̀dọ̀ mi, Ọlọ́run.
|
||
\q1 Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àti olùdáǹdè mi;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, má ṣe dúró pẹ́.
|
||
\c 71
|
||
\cl Saamu 71
|
||
\q1
|
||
\v 1 Nínú rẹ, \nd Olúwa\nd*, ni mo ní ààbò;
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Gbà mí kí o sì tú mi sílẹ̀ nínú òdodo rẹ;
|
||
\q2 dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbà mí.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Jẹ́ àpáta ààbò mi,
|
||
\q2 níbi tí èmi lè máa lọ,
|
||
\q1 pa àṣẹ láti gbà mí,
|
||
\q2 nítorí ìwọ ni àpáta àti odi agbára mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Gbà mí, Ọlọ́run mi, lọ́wọ́ àwọn olùṣe búburú,
|
||
\q2 ní ọwọ́ aláìṣòdodo àti ìkà ọkùnrin.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí ìwọ jẹ́ ìrètí mi, \nd Olúwa\nd* Olódùmarè,
|
||
\q2 ìwọ ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi láti ìgbà èwe.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi;
|
||
\q2 Ìwọ mú mi jáde láti inú ìyá mi wá
|
||
\q1 èmi ó máa yìn ọ́ títí láé.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Mo di àmì fún ọ̀pọ̀ ènìyàn,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ìyìn rẹ̀ kún ẹnu mi,
|
||
\q2 ó ń sọ ti ọlá rẹ ní ọjọ́ gbogbo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Má ṣe ta mí nù ní ọjọ́ ogbó mi,
|
||
\q2 má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀-òdì sí mi,
|
||
\q2 àwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀;
|
||
\q2 lépa rẹ̀ kí ẹ sì mu,
|
||
\q2 nítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”
|
||
\q1
|
||
\v 12 Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run;
|
||
\q2 wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti ràn mí lọ́wọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Jẹ́ kí wọn kí ó dààmú,
|
||
\q2 kí a sì run àwọn tí ń ṣe ọ̀tá ọkàn mi
|
||
\q1 kí a sì fi ẹ̀gàn àti àbùkù
|
||
\q2 bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ṣùgbọ́n ní tèmi, ìgbà gbogbo ní ìrètí mi;
|
||
\q2 èmi ó yìn ọ́ síwájú àti síwájú sí i.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ẹnu mi yóò sọ nípa ti òdodo rẹ,
|
||
\q1 ti ìgbàlà rẹ, ni gbogbo ọjọ́,
|
||
\q1 lóòtítọ́, èmi kò mọ iye rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Èmi ó wá láti wá kéde agbára,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* Olódùmarè;
|
||
\q2 èmi ó kéde òdodo rẹ̀ nìkan.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Láti ìgbà èwe, Ọlọ́run ni ìwọ ti kọ́ mi
|
||
\q2 títí di òní ni mo ń sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Pẹ̀lúpẹ̀lú, nígbà tí èmi di arúgbó tán tí mo sì hewú,
|
||
\q2 má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọ́run mi,
|
||
\q1 títí èmi ó fi ipá rẹ han ìran tí ń bọ̀,
|
||
\q2 àti agbára rẹ fún gbogbo àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ọlọ́run, òdodo rẹ dé ọ̀run,
|
||
\q2 ìwọ tí o ti ṣe ohun ńlá.
|
||
\q2 Ta ni ó dàbí rẹ, Ọlọ́run?
|
||
\q1
|
||
\v 20 Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ ti mú mi rí ìdààmú, tí ó pọ̀ tí ó sì korò,
|
||
\q2 ìwọ yóò tún sọ ayé mi jí
|
||
\q1 ìwọ yóò sì tún mú mi sọ sókè
|
||
\q2 láti ọ̀gbun ilẹ̀ wá.
|
||
\q1 Ìwọ yóò sọ ọlá mi di púpọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ìwọ yóò fi kún ọwọ́ mi
|
||
\q2 ìwọ yóò tù mí nínú ní ha gbogbo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 Èmi yóò fi dùùrù mi yìn
|
||
\q2 fún òtítọ́ rẹ, Ọlọ́run mi;
|
||
\q1 èmi ó kọrin ìyìn sí ọ pẹ̀lú dùùrù
|
||
\q2 ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ètè mi yóò kígbe fún ìyìn
|
||
\q2 nígbà tí mo bá kọrin ìyìn sí ọ:
|
||
\q2 èmi, ẹni tí o rà padà.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ahọ́n mi yóò sọ ti òdodo rẹ ní gbogbo ọjọ́,
|
||
\q2 fún àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára,
|
||
\q2 a sì dójúti àwọn tí ń wá ìdààmú mi.
|
||
\c 72
|
||
\cl Saamu 72
|
||
\d Ti Solomoni.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Fi ìdájọ́ fún àwọn ọba, Ọlọ́run,
|
||
\q2 ọmọ-aládé ni ìwọ fi òdodo rẹ fún.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú òdodo,
|
||
\q2 yóò sì máa fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn tálákà rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Àwọn òkè ńlá yóò máa mú àlàáfíà fún àwọn ènìyàn
|
||
\q2 àti òkè kéékèèké nípa òdodo.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Yóò dáàbò bo àwọn tí a pọ́n lójú láàrín àwọn ènìyàn
|
||
\q2 yóò gba àwọn ọmọ aláìní;
|
||
\q2 yóò sì fa àwọn aninilára ya.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Àwọn òtòṣì àti aláìní
|
||
\q2 yóò máa fi ọ̀wọ̀ ńlá fún ọ nígbà gbogbo,
|
||
\q1 níwọ̀n ìgbà tí oòrùn àti òṣùpá bá ń ràn,
|
||
\q2 yóò ti pẹ́ tó, láti ìrandíran.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Yóò dàbí òjò tí ó ń rọ̀ sórí pápá ìrẹ́mọ́lẹ̀,
|
||
\q2 bí ọwọ́ òjò tó ń rin ilẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Àwọn olódodo yóò gbilẹ̀ ni ọjọ́ rẹ̀
|
||
\q2 ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà yóò sì wà;
|
||
\q2 títí tí òṣùpá kò fi ní sí mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Yóò máa jẹ ọba láti òkun dé òkun
|
||
\q2 àti láti odò Eufurate títí dé òpin ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Àwọn tí ó wà ní aginjù yóò tẹríba fún un
|
||
\q2 àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóò máa lá erùpẹ̀ ilẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Àwọn ọba Tarṣiṣi àti ti erékùṣù
|
||
\q2 wọn yóò mú ọrẹ wá fún un;
|
||
\q1 àwọn ọba Ṣeba àti Seba
|
||
\q2 wọn ó mú ẹ̀bùn wá fún un.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Gbogbo ọba yóò tẹríba fún un
|
||
\q2 àti gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sìn ín.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nítorí yóò gba àwọn aláìní
|
||
\q2 nígbà tí ó bá ń ké,
|
||
\q1 tálákà àti ẹni tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Yóò káàánú àwọn aláìlera àti aláìní
|
||
\q2 yóò pa aláìní mọ́ kúrò nínú ikú.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Yóò ra ọkàn wọn padà lọ́wọ́ ẹ̀tàn àti ipá
|
||
\q2 nítorí ẹ̀jẹ̀ wọn ṣọ̀wọ́n níwájú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Yóò sì pẹ́ ní ayé!
|
||
\q2 A ó sì fún un ní wúrà Ṣeba.
|
||
\q1 Àwọn ènìyàn yóò sì máa gbàdúrà fún un nígbà gbogbo
|
||
\q2 kí a sì bùkún fún un lójoojúmọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Kí ìkúnwọ́ ọkà wà lórí ilẹ̀;
|
||
\q2 ní orí òkè ni kí ó máa dàgbà
|
||
\q1 kí èso rẹ̀ kí o gbilẹ̀ bí ti Lebanoni
|
||
\q2 yóò máa gbá yìn bí i koríko ilẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Kí orúkọ rẹ̀ kí ó wà títí láé;
|
||
\q2 orúkọ rẹ̀ yóò máa gbilẹ̀ níwọ̀n bí oòrùn yóò ti pẹ́ tó.
|
||
\b
|
||
\q1 Wọn ó sì máa bùkún fún ara wọn nípasẹ̀ rẹ.
|
||
\q2 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ní yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
|
||
\b
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Olùbùkún ni \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli,
|
||
\q2 ẹnìkan ṣoṣo tí ó ń ṣe ohun ìyanu.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Olùbùkún ni orúkọ rẹ̀ tí ó lógo títí láé;
|
||
\q2 kí gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.
|
||
\qc Àmín àti Àmín.
|
||
\b
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Èyí ni ìparí àdúrà Dafidi ọmọ Jese.
|
||
\c 73
|
||
\ms ÌWÉ KẸTA
|
||
\mr Saamu 73–89
|
||
\cl Saamu 73
|
||
\d Saamu ti Asafu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli,
|
||
\q2 fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán;
|
||
\q2 ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé
|
||
\q2 nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Wọn kò ṣe wàhálà;
|
||
\q2 ara wọn mókun wọn sì lágbára.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn;
|
||
\q2 a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn;
|
||
\q2 ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá;
|
||
\q2 ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára,
|
||
\q2 wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run
|
||
\q2 ahọ́n wọn gba ipò ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn
|
||
\q2 wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀?
|
||
\q2 Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí,
|
||
\q2 ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́;
|
||
\q2 nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu;
|
||
\q2 a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,”
|
||
\q2 èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí,
|
||
\q2 Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
|
||
\q1
|
||
\v 17 títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run;
|
||
\q2 nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́
|
||
\q2 ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí
|
||
\q2 bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan!
|
||
\q1 Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
|
||
\q1
|
||
\v 20 Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Nígbà tí inú mi bàjẹ́
|
||
\q2 àti ọkàn mi ṣì korò,
|
||
\q1
|
||
\v 22 mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye;
|
||
\q2 mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo;
|
||
\q2 ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi
|
||
\q2 ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ?
|
||
\q2 Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà
|
||
\q2 ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi
|
||
\q2 àti ìpín mi títí láé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé
|
||
\q2 ìwọ ti pa gbogbo wọn run;
|
||
\q1 tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run.
|
||
\q2 Èmi ti fi \nd Olúwa\nd* Olódùmarè ṣe ààbò mi;
|
||
\q2 kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.
|
||
\c 74
|
||
\cl Saamu 74
|
||
\d Maskili ti Asafu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọlọ́run, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ wá sílẹ̀ títí láé?
|
||
\q2 Èéṣe tí ìbínú rẹ̀ fi dìde sí àwọn àgùntàn pápá rẹ?
|
||
\q1
|
||
\v 2 Rántí àwọn ènìyàn tí ìwọ ti rà nígbà àtijọ́,
|
||
\q2 ẹ̀yà ilẹ̀ ìní rẹ, tí ìwọ ti rà padà.
|
||
\q2 Òkè Sioni, níbi tí ìwọ ń gbé.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Yí ẹsẹ̀ rẹ padà sí ìparun ayérayé wọn,
|
||
\q2 gbogbo ìparun yìí tí ọ̀tá ti mú wá sí ibi mímọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àwọn ọ̀tá rẹ ń bú ramúramù
|
||
\q2 láàrín ènìyàn rẹ,
|
||
\q1 wọ́n ń gbé àsíá wọn sókè fún àmì.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọ́n ń rí bí ọkùnrin tí ó gbé àáké rẹ̀ sókè
|
||
\q2 láti gé igi igbó dídí.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, iṣẹ́ ọnà fínfín,
|
||
\q2 ni wọ́n fi àáké wó lulẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kan náà.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Wọ́n sun ibi mímọ́ rẹ lulẹ̀
|
||
\q2 wọ́n ba ibùgbé orúkọ rẹ jẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Wọ́n wí ní ọkàn wọn. “Àwa ó run wọ́n pátápátá!”
|
||
\q2 Wọ́n sun gbogbo ibi ìjọ́sìn Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 A kò fún wa ní àmì iṣẹ́ ìyanu kankan;
|
||
\q2 kò sí wòlíì kankan
|
||
\q2 ẹnìkankan wa kò mọ ìgbà tí eléyìí yóò dà.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Àwọn ọ̀tá yóò ti kùn sí ọ pẹ́ tó, Ọlọ́run?
|
||
\q2 Àwọn ọ̀tá yóò ha ba orúkọ rẹ jẹ́ títí láé?
|
||
\q1
|
||
\v 11 Èéṣe tí ìwọ fi dá ọwọ́ rẹ dúró, ọwọ́ ọ̀tún rẹ?
|
||
\q2 Mú un kúrò nínú ìṣẹ́po aṣọ rẹ kí o sì run wọ́n!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run ni ọba mi láti ìgbà pípẹ́;
|
||
\q2 Ó mú ìgbàlà wá sórí ilẹ̀ ayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìwọ ni ó la òkun sílẹ̀ nípa agbára rẹ;
|
||
\q2 ìwọ fọ́ orí ẹ̀mí búburú nínú omi.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ìwọ fọ́ orí Lefitani túútúú, o sì fi ṣe oúnjẹ fun àwọn ẹ̀dá tí ń gbé inú ijù
|
||
\q2 tìrẹ ni ọ̀sán, tìrẹ sì ni alẹ́ pẹ̀lú;
|
||
\q2 ìwọ fi ìdí oòrùn àti òṣùpá lélẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ìwọ ya orísun omi àti ìṣàn omi;
|
||
\q2 Ìwọ mú kí odò tó ń sàn gbẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Tìrẹ ni ọ̀sán, tìrẹ ni òru pẹ̀lú;
|
||
\q2 ìwọ yà oòrùn àti òṣùpá.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ìwọ pààlà etí ayé;
|
||
\q2 Ìwọ dá ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn àti ìgbà òtútù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Rántí bí àwọn ọ̀tá ń kẹ́gàn rẹ, \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 bí àwọn aṣiwèrè ènìyàn ti ń ba orúkọ rẹ jẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Má ṣe fi ẹ̀mí àdàbà rẹ fún ẹranko igbó búburú;
|
||
\q2 má ṣe gbàgbé ẹ̀mí àwọn ènìyàn rẹ tí a ń pọ́n lójú títí láé.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Bojú wo májẹ̀mú rẹ,
|
||
\q2 nítorí ibi òkùnkùn ayé kún fún ibùgbé ìkà.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Má ṣe jẹ́ kí àwọn aninilára padà sẹ́yìn nínú ìtìjú
|
||
\q2 jẹ́ kí àwọn aláìní àti tálákà yin orúkọ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Dìde, Ọlọ́run, gba ẹjọ́ ara rẹ rò;
|
||
\q2 rántí bí àwọn aṣiwèrè ti ń kẹ́gàn rẹ ní gbogbo ọjọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Má ṣe gbàgbé ohùn àwọn ọ̀tá rẹ,
|
||
\q2 bíbú àwọn ọ̀tá rẹ, tí ó ń pọ̀ sí i nígbà gbogbo.
|
||
\c 75
|
||
\cl Saamu 75
|
||
\d Fún adarí orin. Tí ohùn, “Má ṣe parun.” Saamu ti Asafu. Orin.
|
||
\q1
|
||
\v 1 A fi ìyìn fún ọ, Ọlọ́run,
|
||
\q2 a yìn ọ́, nítorí orúkọ rẹ súnmọ́ tòsí;
|
||
\q2 àwọn ènìyàn ń sọ ti ìyanu rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìwọ wí pé, “Mo yan àkókò ìyàsọ́tọ̀;
|
||
\q2 Èmi ni ẹni tí ń ṣe ìdájọ́ òdodo.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nígbà tí ayé àti àwọn ènìyàn ibẹ̀ wárìrì,
|
||
\q2 Èmi ni mo di òpó rẹ̀ mú ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Èmí wí fún àwọn agbéraga pé,
|
||
\q2 ẹ má ṣe gbéraga mọ́;
|
||
\q1 àti sí ènìyàn búburú;
|
||
\q2 ẹ má ṣe gbé ìwo yín sókè.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹ má ṣe gbe ìwo yín sókè sí ọ̀run;
|
||
\q2 ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọrùn líle.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nítorí ìgbéga kò ti ìlà-oòrùn wá
|
||
\q2 tàbí ní ìwọ̀-oòrùn,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe láti gúúsù wá.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni olùdájọ́;
|
||
\q2 Ó ń rẹ ẹnìkan sílẹ̀, ó sì ń gbé ẹlòmíràn ga.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ní ọwọ́ \nd Olúwa\nd* ni ago kan wà,
|
||
\q2 ọtí wáìnì náà sì pọ́n, ó kún fún àdàlú,
|
||
\q1 ó fún ọtí àdàlú tí a pò mọ́ òórùn dídùn tí ó tú jáde,
|
||
\q2 àwọn ènìyàn búburú ayé gbogbo mú u pátápátá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ṣùgbọ́n èmi, ó máa ròyìn rẹ títí láé;
|
||
\q2 èmi ó kọrin ìyìn sí Ọlọ́run Jakọbu.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Èmi ó gé ìwo gbogbo ènìyàn búburú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìwo àwọn olódodo ni a ó gbéga.
|
||
\c 76
|
||
\cl Saamu 76
|
||
\d Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Asafu. Orin.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ní Juda ni a mọ Ọlọ́run;
|
||
\q2 orúkọ rẹ̀ sì lágbára ní Israẹli
|
||
\q1
|
||
\v 2 Àgọ́ rẹ̀ wà ní Salẹmu,
|
||
\q2 ibùgbé rẹ̀ ni Sioni.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Níbẹ̀ ni ó ṣẹ́ ọfà,
|
||
\q2 asà àti àwọn idà, ohun ìjà ogun. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìwọ ni ògo àti ọlá,
|
||
\q2 ju òkè ńlá ìkógun wọ̀nyí lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 A kó àwọn alágídí ọkàn ní ìkógun
|
||
\q2 wọ́n sun oorun ìgbẹ̀yìn wọn;
|
||
\q1 kò sí ọ̀kan nínú àwọn akọni
|
||
\q2 tó lè gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ní ìfibú rẹ, Ọlọ́run Jakọbu,
|
||
\q2 àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun sì dùbúlẹ̀ síbẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìwọ nìkan ni ó yẹ kí a bẹ̀rù.
|
||
\q2 Ta ló lé dúró níwájú rẹ, nígbà tí ìwọ bá ń bínú?
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ìwọ ń ṣe ìdájọ́ láti ọ̀run,
|
||
\q2 ilé ayé bẹ̀rù, ó sì dúró jẹ́ẹ́,
|
||
\q1
|
||
\v 9 nígbà tí, ìwọ Ọlọ́run,
|
||
\q2 bá dìde láti ṣe ìdájọ́,
|
||
\q1 láti gba àwọn ẹni ìnilára ilẹ̀ náà. \qs Sela.\qs*
|
||
\q1
|
||
\v 10 Lóòótọ́, ìbínú rẹ sí àwọn ènìyàn ń mú ìyìn wá fún ọ,
|
||
\q2 ẹni tí ó yọ nínú ìbínú rẹ ní a dá nígbà tí ìwọ bá fi ìbínú ìyókù di ara rẹ ni àmùrè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Jẹ́ ẹ̀jẹ́ sí \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run rẹ kí o sì mú un ṣẹ;
|
||
\q2 kí gbogbo àwọn tí ó yí i ká
|
||
\q2 mú ẹ̀bùn wá fún ẹni tí ó tọ́ láti bẹ̀rù.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ó ké ẹ̀mí àwọn aládé kúrò;
|
||
\q2 àwọn ọba ayé sì ń bẹ̀rù rẹ̀.
|
||
\c 77
|
||
\cl Saamu 77
|
||
\d Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Ti Asafu. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́;
|
||
\q2 mo kígbe sí Ọlọ́run láti gbọ́ tèmi.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú,
|
||
\q2 mo wá \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q1 ní òru ni mo na ọwọ́ mi jáde ní àìkáárẹ̀
|
||
\q2 ọkàn mí sì kọ̀ láti tù ú nínú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run,
|
||
\q2 mo sì kẹ́dùn;
|
||
\q1 mo ṣe àròyé, ẹ̀mí mi sì rẹ̀wẹ̀sì. \qs Sela.\qs*
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun,
|
||
\q2 mo dààmú tó bẹ́ẹ̀ tí ń kò le sọ̀rọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì;
|
||
\q2 ọdún pípẹ́ sẹ́yìn;
|
||
\q1
|
||
\v 6 mo rántí orin mi ní òru.
|
||
\q2 Èmi ń bá àyà mi sọ̀rọ̀,
|
||
\q2 ọkàn mi sì ń ṣe àwárí jọjọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 “Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé?
|
||
\q2 Ki yóò ha ṣe ojúrere rẹ̀ mọ́?
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé?
|
||
\q2 Ìlérí rẹ̀ ha kùnà títí ayé?
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú?
|
||
\q2 Ní ìbínú rẹ̀, ó ha sé ojúrere rẹ̀ mọ́?” \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi,
|
||
\q2 pé ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Èmi ó rántí iṣẹ́ \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo,
|
||
\q2 pẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́.
|
||
\q2 Ọlọ́run wo ni ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu;
|
||
\q2 ìwọ fi agbára rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà,
|
||
\q2 àwọn ọmọ Jakọbu àti Josẹfu. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run,
|
||
\q2 nígbà tí àwọn omi rí ọ,
|
||
\q1 ẹ̀rù bà wọ́n,
|
||
\q2 nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀,
|
||
\q2 àwọsánmọ̀ fi àrá dáhùn;
|
||
\q2 ọfà rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì,
|
||
\q2 ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé;
|
||
\q2 ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun,
|
||
\q2 ọ̀nà la omi alágbára kọjá ipa rẹ̀ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá,
|
||
\q2 nítòótọ́ a kò rí ojú ẹsẹ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran
|
||
\q2 nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
|
||
\c 78
|
||
\cl Saamu 78
|
||
\d Maskili ti Asafu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ mi;
|
||
\q2 tẹ́tí rẹ sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
|
||
\q1
|
||
\v 2 \x - \xo 78.2: \xt Mt 13.35.\x*Èmi ó la ẹnu mi ní òwe,
|
||
\q2 èmi o sọ ohun ìkọ̀kọ̀, ohun ti ọjọ́ pípẹ́;
|
||
\q1
|
||
\v 3 ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀,
|
||
\q2 ohun tí àwọn baba wa ti sọ fún wa.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àwa kì yóò pa wọ́n mọ́
|
||
\q2 kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ,
|
||
\q1 ní fífi ìyìn \nd Olúwa\nd*, àti ipa rẹ̀
|
||
\q2 àti iṣẹ́ ìyanu tó ti ṣe hàn
|
||
\q1 fún ìran tí ń bọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jakọbu
|
||
\q2 o sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Israẹli,
|
||
\q1 èyí tí ó pàṣẹ fún àwọn baba ńlá wa
|
||
\q2 láti kọ́ àwọn ọmọ wọn,
|
||
\q1
|
||
\v 6 nítorí náà, àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́n
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí
|
||
\q2 tí yóò dìde tí wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nígbà náà ni wọ́n ò fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́run
|
||
\q2 wọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́run
|
||
\q2 ṣùgbọ́n wọn ó pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Kí wọn kí ó má ṣe dàbí àwọn baba ńlá wọn,
|
||
\q2 ìran alágídí àti ọlọ́tẹ̀,
|
||
\q2 ìran tí ọkàn wọn kò ṣọ òtítọ́ si olóore,
|
||
\q2 àti ẹ̀mí ẹni tí kò bá Ọlọ́run dúró ṣinṣin.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Àwọn ọkùnrin Efraimu, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun,
|
||
\q2 wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun
|
||
\q1
|
||
\v 10 Wọn kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́
|
||
\q2 wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe,
|
||
\q2 àwọn ìyanu tí ó ti fihàn wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ó ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Ejibiti, ní agbègbè Ṣoani.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ó pín òkun ní yà, ó sì mú wọn kọjá
|
||
\q2 Ó mù kí omi náà dúró bi odi gíga.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ní ọ̀sán, ó fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọn
|
||
\q2 àti ní gbogbo òru pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ iná.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ó sán àpáta ní aginjù
|
||
\q2 ó sì fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọ́pọ̀
|
||
\q2 bí ẹni pé láti inú ibú wá.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta
|
||
\q2 omi ṣíṣàn sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí odò.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Wọ́n sì tún tẹ̀síwájú láti dẹ́ṣẹ̀ sí i
|
||
\q2 ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo ní aginjù.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Wọ́n mọ̀ ọ́n mọ̀ dán Ọlọ́run wò
|
||
\q2 nípa bíbéèrè fún oúnjẹ tí wọn bẹ̀bẹ̀ fún.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Wọ́n sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run, wí pé
|
||
\q2 “Ọlọ́run ha lè tẹ́ tábìlì ní aginjù?
|
||
\q1
|
||
\v 20 Nígbà tí ó lu àpáta, omi tú jáde,
|
||
\q2 odò sì sàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀
|
||
\q1 ṣùgbọ́n òun ha lè fún wa lóúnjẹ
|
||
\q2 ó ha le pèsè ẹran fún àwọn ènìyàn rẹ̀?”
|
||
\q1
|
||
\v 21 Nígbà tí \nd Olúwa\nd* gbọ́ wọn, ó bínú gidigidi;
|
||
\q1 iná rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ sí Jakọbu,
|
||
\q1 ìbínú rẹ̀ sì rú sí Israẹli,
|
||
\q1
|
||
\v 22 nítorí wọn kò gba Ọlọ́run gbọ́,
|
||
\q2 wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé ìgbàlà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Síbẹ̀ ó pàṣẹ fún ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
|
||
\q2 ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀;
|
||
\q1
|
||
\v 24 \x - \xo 78.24: \xt Jh 6.31.\x*Ó rọ manna fún àwọn ènìyàn láti jẹ,
|
||
\q2 ó fún wọn ní ọkà láti ọ̀run.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Àwọn ènìyàn jẹ oúnjẹ àwọn angẹli;
|
||
\q2 Ó fún wọn ní oúnjẹ ní àjẹyó,
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ó mú afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀run wá
|
||
\q2 ó mú afẹ́fẹ́ gúúsù wá nípa agbára rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ó rọ òjò ẹran sílẹ̀ sórí wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀,
|
||
\q2 àti ẹyẹ abìyẹ́ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn,
|
||
\q2 yíká àgọ́ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Wọ́n jẹ, wọ́n sì yó jọjọ
|
||
\q2 nítorí ó ti fún wọn ní ohun tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún,
|
||
\q2 nígbà tí oúnjẹ wọn sì wà ní ẹnu wọn,
|
||
\q1
|
||
\v 31 ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọn
|
||
\q2 ó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn,
|
||
\q2 ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli bolẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 32 Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ síwájú;
|
||
\q2 nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 33 O fi òpin sí ayé wọn nínú asán
|
||
\q2 àti ọdún wọn nínú ìpayà.
|
||
\q1
|
||
\v 34 Nígbàkígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n,
|
||
\q2 wọn yóò wá a kiri;
|
||
\q2 wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.
|
||
\q1
|
||
\v 35 Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn;
|
||
\q2 wí pé Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 36 Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́n
|
||
\q2 wọ́n fi ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;
|
||
\q1
|
||
\v 37 \x - \xo 78.37: \xt Ap 8.21.\x*ọkàn wọn kò sòtítọ́ sí i,
|
||
\q2 wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 38 Síbẹ̀ ó ṣàánú;
|
||
\q2 ó dárí àìṣedéédéé wọn jì
|
||
\q1 òun kò sì pa wọ́n run
|
||
\q2 nígbà púpọ̀ ló ń yí ìbínú rẹ̀ padà
|
||
\q1 kò sì ru ìbínú rẹ̀ sókè
|
||
\q1
|
||
\v 39 Ó rántí pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n,
|
||
\q2 afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò lè padà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 40 Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ sí i ní aginjù
|
||
\q2 wọn mú un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!
|
||
\q1
|
||
\v 41 Síwájú àti síwájú wọ́n dán Ọlọ́run wò;
|
||
\q2 wọ́n mú ẹni mímọ́ Israẹli bínú.
|
||
\q1
|
||
\v 42 Wọ́n kò rántí agbára rẹ̀:
|
||
\q2 ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,
|
||
\q1
|
||
\v 43 ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ hàn ní Ejibiti,
|
||
\q2 àti iṣẹ́ àmì rẹ̀ ni ẹkùn Ṣoani
|
||
\q1
|
||
\v 44 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀;
|
||
\q2 wọn kò lè mu láti odò wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 45 Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin láti pa wọ́n run,
|
||
\q2 àti ọ̀pọ̀lọ́ tí ó bá wọn jẹun.
|
||
\q1
|
||
\v 46 Ó fi ọkà wọn fún láńtata,
|
||
\q2 àwọn ìre oko wọn fún eṣú.
|
||
\q1
|
||
\v 47 Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́
|
||
\q2 ó bá èso sikamore wọn jẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 48 Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyín,
|
||
\q2 agbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná.
|
||
\q1
|
||
\v 49 Ó mú kíkorò ìbínú rẹ̀ wá sí wọn lára,
|
||
\q2 ìrunú àti ìkáàánú, àti ìpọ́njú,
|
||
\q2 nípa rírán angẹli apanirun sí wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 50 Ó pèsè ipa fún ìbínú rẹ̀,
|
||
\q2 òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-ààrùn.
|
||
\q1
|
||
\v 51 Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin Ejibiti,
|
||
\q2 olórí agbára wọn nínú àgọ́ Hamu.
|
||
\q1
|
||
\v 52 Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran;
|
||
\q2 ó ṣọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú aginjù.
|
||
\q1
|
||
\v 53 Ó dáàbò bò wọ́n dáradára, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́n
|
||
\q2 ṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 54 Bákan náà ni ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀
|
||
\q2 òkè tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ti gbà
|
||
\q1
|
||
\v 55 Ó lé kèfèrí jáde níwájú wọn
|
||
\q2 ó sì fi títa okùn pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní;
|
||
\q2 ó mú àwọn ẹ̀yà Israẹli jókòó ní ilẹ̀ wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 56 Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wò
|
||
\q2 wọn sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo;
|
||
\q2 wọn kò pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 57 Ṣùgbọ́n wọ́n yípadà,
|
||
\q2 wọn jẹ́ aláìṣòdodo gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn
|
||
\q1 wọ́n sì pẹ̀yìndà sí apákan bí ọrun ẹ̀tàn.
|
||
\q1
|
||
\v 58 Wọ́n bí i nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn;
|
||
\q2 wọn rú owú rẹ̀ sókè nípa òrìṣà wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 59 Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn,
|
||
\q2 inú bí i gidigidi;
|
||
\q1 ó kọ Israẹli pátápátá.
|
||
\q1
|
||
\v 60 Ó kọ àgọ́ Ṣilo sílẹ̀,
|
||
\q2 àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 61 Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn,
|
||
\q2 dídán ògo rẹ̀ lọ sí ọwọ́ àwọn ọ̀tá.
|
||
\q1
|
||
\v 62 Ó fi àwọn ènìyàn rẹ̀ lé idà lọ́wọ́,
|
||
\q2 ó sì bínú sí àwọn ohun ìní rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 63 Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn,
|
||
\q2 àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
|
||
\q1
|
||
\v 64 àfi àlùfáà wọn fún idà,
|
||
\q2 àwọn opó wọn kò sì le è sọkún.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 65 Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun,
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jí kúrò nínú ìraníyè ọtí.
|
||
\q1
|
||
\v 66 Ó kọlu àwọn ọ̀tá rẹ̀ padà;
|
||
\q2 ó fi wọn sínú ìtìjú ayérayé.
|
||
\q1
|
||
\v 67 Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Josẹfu,
|
||
\q2 kò sì yan ẹ̀yà Efraimu,
|
||
\q1
|
||
\v 68 ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Juda,
|
||
\q2 òkè Sioni, èyí tí ó fẹ́ràn.
|
||
\q1
|
||
\v 69 Ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀, ibi gíga,
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.
|
||
\q1
|
||
\v 70 Ó yan Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀
|
||
\q2 ó mú láti inú àwọn agbo ẹran;
|
||
\q1
|
||
\v 71 Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntàn
|
||
\q2 láti jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn rẹ̀ Jakọbu
|
||
\q2 àti Israẹli ogún un rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 72 Dafidi sì ṣọ́ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn;
|
||
\q2 pẹ̀lú ọwọ́ òye ni ó fi darí wọn.
|
||
\c 79
|
||
\cl Saamu 79
|
||
\d Saamu ti Asafu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ;
|
||
\q2 wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́,
|
||
\q2 wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ
|
||
\q2 fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ,
|
||
\q2 ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi
|
||
\q2 yí Jerusalẹmu ká,
|
||
\q2 kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká,
|
||
\q2 àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nígbà wo, \nd Olúwa\nd*? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé?
|
||
\q2 Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
|
||
\q1
|
||
\v 6 Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè
|
||
\q2 tí kò ní ìmọ̀ rẹ,
|
||
\q1 lórí àwọn ìjọba
|
||
\q2 tí kò pe orúkọ rẹ;
|
||
\q1
|
||
\v 7 nítorí wọ́n ti run Jakọbu
|
||
\q2 wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn
|
||
\q2 jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa,
|
||
\q2 nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa,
|
||
\q2 fún ògo orúkọ rẹ;
|
||
\q1 gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì
|
||
\q2 nítorí orúkọ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé,
|
||
\q2 “Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?”
|
||
\b
|
||
\q1 Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè
|
||
\q2 kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ,
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ
|
||
\q2 ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.
|
||
\q1
|
||
\v 12 San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje
|
||
\q2 nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ,
|
||
\q2 àti àgùntàn pápá rẹ,
|
||
\q1 yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé;
|
||
\q2 láti ìran dé ìran
|
||
\q1 ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.
|
||
\c 80
|
||
\cl Saamu 80
|
||
\d Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì Ti Májẹ̀mú.” Ti Safu. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Gbọ́ tiwa, ìwọ olùṣọ́-àgùntàn Israẹli;
|
||
\q2 ìwọ tí ó darí Josẹfu bí ọ̀wọ́ ẹran.
|
||
\q1 Ìwọ tí o jókòó lórí ìtẹ́ láàrín Kérúbù,
|
||
\q2 tàn jáde
|
||
\v 2 níwájú Efraimu, Benjamini àti Manase.
|
||
\q1 Ru agbára rẹ̀ sókè;
|
||
\q2 wá fún ìgbàlà wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Mú wa padà bọ̀ sípò, ìwọ Ọlọ́run;
|
||
\q2 jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tan ìmọ́lẹ̀ sí wa,
|
||
\q1 kí a bá à lè gbà wá là.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run alágbára,
|
||
\q2 ìbínú rẹ̀ yóò ti pẹ́ tó
|
||
\q2 sí àdúrà àwọn ènìyàn rẹ?
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ ti fi oúnjẹ bọ́ wọn
|
||
\q2 ìwọ ti mú wọn wa ẹkún mu ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìwọ sọ wá di ẹlẹ́yà fún àwọn aládùúgbò wa,
|
||
\q2 àwọn ọ̀tá wa sì ń yọ̀ wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Tún wa yípadà, ìwọ, Ọlọ́run alágbára;
|
||
\q2 jẹ́ kí ojú rẹ tàn sí wa,
|
||
\q2 kí a ba à lè gbà wá là.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ìwọ mú àjàrà jáde láti Ejibiti;
|
||
\q2 ìwọ lé àwọn kèfèrí jáde, o sì gbìn ín.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìwọ ṣí ààyè sílẹ̀ fún un,
|
||
\q2 ìwọ sì mu ta gbòǹgbò jinlẹ̀
|
||
\q1 ó sì kún ilẹ̀ náà.
|
||
\q1
|
||
\v 10 A bò àwọn òkè mọ́lẹ̀ òkè pẹ̀lú òjìji rẹ̀,
|
||
\q2 ẹ̀ka rẹ̀ dàbí kedari Ọlọ́run.
|
||
\q1
|
||
\v 11 O yọ ẹ̀ka rẹ̀ sínú Òkun,
|
||
\q2 ọwọ́ rẹ̀ sí odò ńlá nì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Èéṣe tí ìwọ fi wó odi rẹ̀
|
||
\q2 tí àwọn ènìyàn tí ó ń kọjá fi ń ṣa èso rẹ̀?
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìmàdò láti inú igbó ń bá a jẹ́
|
||
\q2 àti ẹranko igbó ń jẹ ẹ́ run.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Yípadà sí wa, àwa ń bẹ̀ ọ́, Ọlọ́run alágbára!
|
||
\q2 Bojú wolẹ̀ láti ọ̀run kí o sì wò ó!
|
||
\q1 Kí o sì bẹ àjàrà yìí wò,
|
||
\q1
|
||
\v 15 gbòǹgbò èyí tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ ti gbìn,
|
||
\q2 àti ẹ̀ka tí ìwọ ti mú lágbára fún ara rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 A gé àjàrà rẹ lulẹ̀, a ti fi iná sun ún;
|
||
\q2 ní ìfibú, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń ṣègbé.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà lára ọkùnrin tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ,
|
||
\q2 ọmọ ènìyàn tí ìwọ tí gbé kalẹ̀ fún ara rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Nígbà náà àwa kí yóò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ;
|
||
\q2 mú wa yè, àwa o sì máa pe orúkọ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Tún wa yípadà, \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run alágbára;
|
||
\q2 kí ojú rẹ̀ kí ó tan ìmọ́lẹ̀ sí wa,
|
||
\q2 kí á ba à lè gbà wá là.
|
||
\c 81
|
||
\cl Saamu 81
|
||
\d Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti Asafu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa
|
||
\q2 ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jakọbu!
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wá,
|
||
\q2 tẹ dùùrù dídùn pẹ̀lú ohun èlò orin mímọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹ fún ìpè ní oṣù tuntun
|
||
\q2 àní nígbà tí a yàn;
|
||
\q1 ní ọjọ́ àjọ wa tí ó ní ìrònú.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Èyí ni àṣẹ fún Israẹli,
|
||
\q2 àti òfin Ọlọ́run Jakọbu.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Josẹfu
|
||
\q2 nígbà tí ó la ilẹ̀ Ejibiti já.
|
||
\b
|
||
\q2 Níbi tí a ti gbọ́ èdè tí kò yé wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúrò ní èjìká yín,
|
||
\q2 a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là,
|
||
\q2 mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá,
|
||
\q2 mo dán an yín wò ní odò Meriba. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 “Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín,
|
||
\q2 bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Israẹli.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrín yín;
|
||
\q2 ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Èmi ni \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run rẹ,
|
||
\q2 ẹni tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti.
|
||
\q2 Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 “Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi;
|
||
\q2 Israẹli kò ní tẹríba fún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn
|
||
\q2 láti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 “Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi
|
||
\q2 bí Israẹli yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,
|
||
\q1
|
||
\v 14 ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn
|
||
\q2 kí n sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!
|
||
\q1
|
||
\v 15 Àwọn tí ó kórìíra \nd Olúwa\nd* yóò tẹríba níwájú rẹ̀.
|
||
\q2 Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín
|
||
\q2 èmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”
|
||
\c 82
|
||
\cl Saamu 82
|
||
\d Saamu ti Asafu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọlọ́run ń ṣàkóso nínú ìpéjọpọ̀ ńlá,
|
||
\q2 ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn “ọlọ́run òrìṣà”.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 “Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa gbèjà àwọn aláìṣòdodo
|
||
\q2 kí ó sì ṣe ojú ìṣáájú sí àwọn ènìyàn búburú?
|
||
\q1
|
||
\v 3 Gbèjà àwọn aláìlágbára àti aláìní baba;
|
||
\q2 ṣe ìtọ́jú ẹ̀tọ́ àwọn aláìní àti ẹni ìnilára.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Gba àwọn aláìlágbára àti aláìní;
|
||
\q2 gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 “Wọn kò mọ̀ ohun kankan,
|
||
\q2 wọn kò lóye ohun kankan.
|
||
\q1 Wọn ń rìn kiri nínú òkùnkùn;
|
||
\q2 à si mí gbogbo ìpìlẹ̀ ayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 \x - \xo 82.6: \xt Jh 10.34.\x*“Mo wí pé, ‘Ẹyin ní “Ọlọ́run òrìṣà”;
|
||
\q2 ẹ̀yin ní gbogbo ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ.’
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ó kú bí ènìyàn lásán;
|
||
\q2 ẹ̀yin ó ṣubú bí ọ̀kan nínú ọmọ-aládé.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Dìde, Ọlọ́run, ṣe ìdájọ́ ayé,
|
||
\q2 nítorí gbogbo orílẹ̀-èdè ni ìní rẹ.
|
||
\c 83
|
||
\cl Saamu 83
|
||
\d Orin. Saamu ti Asafu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọlọ́run, má ṣe dákẹ́;
|
||
\q2 má ṣe dákẹ́, Ọlọ́run má ṣe dúró jẹ́ẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Wo bí àwọn ọ̀tá rẹ ti ń rọ́kẹ̀kẹ̀ lọ,
|
||
\q2 bi àwọn ọ̀tá rẹ ti ń gbé ohùn wọn sókè.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Pẹ̀lú àrékérekè ni wọn dìtẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ;
|
||
\q2 wọn sí dìtẹ̀ mọ́ àwọn tí o fẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Wọn wí pé, “wá, ẹ jẹ́ kí á pa wọ́n run bí orílẹ̀-èdè,
|
||
\q2 kí orúkọ Israẹli ma bá a sí ní ìrántí mọ́.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọ́n gbìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú ọkàn kan;
|
||
\q2 wọ́n ṣe àdéhùn láti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ
|
||
\q1
|
||
\v 6 Àgọ́ Edomu àti ti àwọn ará Iṣmaeli,
|
||
\q2 ti Moabu àti ti Hagari
|
||
\q1
|
||
\v 7 Gebali, Ammoni àti Amaleki,
|
||
\q2 Filistia, pẹ̀lú àwọn ènìyàn Tire.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Asiria pẹ̀lú ti darapọ̀ mọ́ wọn
|
||
\q2 láti ran àwọn ọmọ Lọti lọ́wọ́. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ṣe sí wọn bí ìwọ ti ṣe sí Midiani
|
||
\q2 bí o ti ṣe sí Sisera àti Jabini ní odò Kiṣoni,
|
||
\q1
|
||
\v 10 ẹni tí ó ṣègbé ní Endori
|
||
\q2 tí wọn sì dàbí ààtàn ní orí ilẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ṣe àwọn ọlọ́lá wọn bí Orebu àti Seebu,
|
||
\q2 àwọn ọmọ-aládé wọn bí Seba àti Salmunna,
|
||
\q1
|
||
\v 12 tí ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a gbà ní ìní
|
||
\q2 àní pápá oko tútù Ọlọ́run.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìwọ Ọlọ́run, ṣe wọ́n bí ààjà,
|
||
\q2 bí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Bí iná ti í jó igbó,
|
||
\q2 àti bí ọ̀wọ́-iná ti ń mú òkè ńlá gbiná,
|
||
\q1
|
||
\v 15 bẹ́ẹ̀ ni kí o fi ẹ̀fúùfù líle rẹ lépa wọn
|
||
\q2 dẹ́rùbà wọn lójú pẹ̀lú ìjì rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Fi ìtìjú kún ojú wọn,
|
||
\q2 kí àwọn ènìyàn bá à lè ṣe àfẹ́rí orúkọ rẹ àti kí o fi ìjì líle rẹ dẹ́rùbà, ìwọ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Jẹ́ kí ojú kí ó tì wọ́n, kí wọ́n sì dààmú láéláé
|
||
\q2 kí wọ́n ṣègbé sínú ẹ̀gàn
|
||
\q1
|
||
\v 18 jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ìwọ, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 pé ìwọ nìkan ní Ọ̀gá-ògo jùlọ lórí gbogbo ayé.
|
||
\c 84
|
||
\cl Saamu 84
|
||
\d Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ibùgbé rẹ̀ ti lẹ́wà tó,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun!
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ọkàn mi ń ṣàfẹ́rí nítòótọ́
|
||
\q2 ó tilẹ̀ pòǹgbẹ fún àgbàlá \nd Olúwa\nd*
|
||
\q1 àyà mi àti ara mi ń kọrin ayọ̀
|
||
\q2 sí Ọlọ́run alààyè.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítòótọ́ ológoṣẹ́ ri ilé,
|
||
\q2 ẹyẹ alápáǹdẹ̀dẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ fún ara rẹ̀,
|
||
\q2 níbi tí yóò máa pa ọmọ rẹ̀ mọ́ sí:
|
||
\q1 ibùgbé ní tòsí pẹpẹ rẹ̀,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun, ọba mí àti Ọlọ́run mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìbùkún ní fún àwọn tí ó ń gbé inú ilé rẹ;
|
||
\q2 wọn ó máa yìn ọ́ títí láé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìbùkún ni fún àwọn tí agbára wọn wà nínú rẹ
|
||
\q2 àwọn tí wọ́n gbé ọkàn lé bíbẹ ibi mímọ́ wò.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Àwọn tí ń la àfonífojì omijé lọ
|
||
\q2 wọn sọ ọ́ di kànga
|
||
\q2 àkọ́rọ̀ òjò sì fi ìbùkún bò ó.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Wọ́n ń lọ láti ipa dé ipá
|
||
\q2 títí tí ọ̀kọ̀ọ̀kan fi farahàn níwájú Ọlọ́run ní Sioni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Gbọ́ àdúrà mi, \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run Alágbára;
|
||
\q2 tẹ́tí sí mi, Ọlọ́run Jakọbu.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Wo asà wa, Ọlọ́run;
|
||
\q2 fi ojú àánú wò àwọn ẹni àmì òróró rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Dídára ní ọjọ́ kan ní ààfin rẹ
|
||
\q2 ju ẹgbẹ̀rún (1,000) ọjọ́ lọ;
|
||
\q1 èmi o kúkú máa ṣe aṣọ́nà nínú ilé Ọlọ́run mi
|
||
\q2 jù láti gbé ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Nítorí \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run jẹ́ òòrùn àti asà;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* fún ni ní ojúrere àti ọlá;
|
||
\q1 kò sí ohun rere kan tí yóò fàsẹ́yìn
|
||
\q2 fún àwọn tí ó rìn ní àìlábùkù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 \nd Olúwa\nd* àwọn ọmọ-ogun,
|
||
\q2 ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
|
||
\c 85
|
||
\cl Saamu 85
|
||
\d Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì
|
||
\q2 ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. \qs Sela.\qs*
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan
|
||
\q2 ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa,
|
||
\q2 kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé?
|
||
\q2 Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́,
|
||
\q2 pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?
|
||
\q1
|
||
\v 7 Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Èmi ó gbọ́ ohun tí \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run yóò wí;
|
||
\q2 ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀,
|
||
\q1 ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
|
||
\q2 pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀;
|
||
\q2 òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá
|
||
\q2 òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.
|
||
\q1
|
||
\v 12 \nd Olúwa\nd* yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́,
|
||
\q2 ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Òdodo síwájú rẹ lọ
|
||
\q2 o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.
|
||
\c 86
|
||
\cl Saamu 86
|
||
\d Àdúrà ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Gbọ́, \nd Olúwa\nd*, kí o sì dá mi lóhùn,
|
||
\q2 nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ:
|
||
\q2 ìwọ ni Ọlọ́run mi,
|
||
\q1 gbà ìránṣẹ́ rẹ là
|
||
\q2 tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ṣàánú fún mi, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ,
|
||
\q2 nítorí ìwọ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Gbọ́ àdúrà mi, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́,
|
||
\q2 nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá
|
||
\q2 yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa;
|
||
\q2 wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu;
|
||
\q2 ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ;
|
||
\q1 fún mi ní ọkàn tí kì í yapa,
|
||
\q2 kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi;
|
||
\q2 èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi;
|
||
\q2 ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run;
|
||
\q2 àti ìjọ àwọn alágbára ń wá
|
||
\q1 ọkàn mi kiri,
|
||
\q2 wọn kò sì fi ọ́ pè.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ṣùgbọ́n ìwọ, \nd Olúwa\nd*, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere,
|
||
\q2 Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi;
|
||
\q2 fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára
|
||
\q2 kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Fi àmì hàn mí fún rere,
|
||
\q2 kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri,
|
||
\q1 kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ni ó ti tù mí nínú.
|
||
\c 87
|
||
\cl Saamu 87
|
||
\d Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd* fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni
|
||
\q2 ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀,
|
||
\q2 ìlú Ọlọ́run,
|
||
\q1
|
||
\v 4 “Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli
|
||
\q2 láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi:
|
||
\q1 Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi,
|
||
\q2 yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’ ”
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ,
|
||
\q2 “Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀,
|
||
\q2 àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀.”
|
||
\q1
|
||
\v 6 \nd Olúwa\nd* yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀:
|
||
\q2 “Eléyìí ni a bí ní Sioni.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu
|
||
\q2 ohun èlò orin yóò wí pé,
|
||
\q2 “Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ.”
|
||
\c 88
|
||
\cl Saamu 88
|
||
\d Orin. Saamu ti àwọn ọmọ Kora. Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti mahalati leannoti. Maskili ti Hemani ará Esra.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, Ọlọ́run tí ó gbà mí là,
|
||
\q2 ní ọ̀sán àti ní òru, mo kígbe sókè sí Ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Jẹ́ kí àdúrà mi kí ó wá sí iwájú rẹ;
|
||
\q2 dẹ etí rẹ sí igbe mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí ọkàn mi kún fún ìpọ́njú
|
||
\q2 ọkàn mi sì súnmọ́ isà òkú.
|
||
\q1
|
||
\v 4 A kà mí mọ́ àwọn tí wọ́n lọ sí ọ̀gbun ilẹ̀
|
||
\q2 èmi dàbí ọkùnrin tí kò ni agbára.
|
||
\q1
|
||
\v 5 A yà mí sọ́tọ̀ pẹ̀lú àwọn òkú
|
||
\q2 bí ẹni tí a pa tí ó dùbúlẹ̀ ní ipò ikú,
|
||
\q1 ẹni tí ìwọ kò rántí mọ́,
|
||
\q2 ẹni tí a gé kúrò lára àwọn tí ìwọ ń tọ́jú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìwọ tí ó fi mí sí kòtò jíjìn,
|
||
\q2 ní ibi ọ̀gbun tó ṣókùnkùn.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ìbínú rẹ ṣubú lé mi gidigidi;
|
||
\q2 ìwọ ti fi àwọn ìjì rẹ borí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ìwọ tí gba ọ̀rẹ́ mi tí ó súnmọ́ mi kúrò lọ́wọ́ mi
|
||
\q2 ìwọ sì sọ mi di ìríra sí wọn.
|
||
\q1 A há mi mọ́, èmi kò sì le è jáde;
|
||
\q1
|
||
\v 9 ojú mi káàánú nítorí ìpọ́njú.
|
||
\b
|
||
\q2 Mo kígbe pè ọ́, \nd Olúwa\nd*, ní gbogbo ọjọ́;
|
||
\q1 mo na ọwọ́ mi jáde sí ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìwọ ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ hàn fún òkú bi?
|
||
\q2 Àwọn òkú yóò ha dìde láti yìn ọ́ bí?
|
||
\q1
|
||
\v 11 A ó ha fi ìṣeun ìfẹ́ rẹ hàn ní ibojì bí,
|
||
\q2 tàbí òtítọ́ rẹ ní ipò ìparun?
|
||
\q1
|
||
\v 12 A ha lè mọ iṣẹ́ ìyanu rẹ ní òkùnkùn bí
|
||
\q2 àti òdodo rẹ ní ilẹ̀ ìgbàgbé?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ṣùgbọ́n mo kígbe sí ọ fún ìrànlọ́wọ́, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 ní òwúrọ̀ ni àdúrà mí wá sọ́dọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 14 \nd Olúwa\nd*, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí
|
||
\q2 tí ìwọ fi ojú rẹ pamọ́ fún mi?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Láti ìgbà èwe mi, ìṣẹ́ ń ṣẹ́ mi,
|
||
\q2 èmi múra àti kú;
|
||
\q1 nígbà tí ẹ̀rù rẹ bá ń bà mí,
|
||
\q2 èmi di gbére-gbère.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ìbínú rẹ ti kọjá lára mi;
|
||
\q2 ìbẹ̀rù rẹ ti gé mi kúrò.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ní gbogbo ọjọ́ ni wọn yí mi ká bí ìkún omi;
|
||
\q2 wọ́n mù mí pátápátá.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ìwọ ti mú ọ̀rẹ́ àti olùfẹ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi;
|
||
\q2 òkùnkùn sì jẹ́ ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi.
|
||
\c 89
|
||
\cl Saamu 89
|
||
\d Maskili ti Etani ará Esra.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ \nd Olúwa\nd* títí láé;
|
||
\q2 pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé,
|
||
\q2 pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 \x - \xo 89.3-4: \xt Sm 132.11; Ap 2.30.\x*Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi
|
||
\q2 mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 ‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé
|
||
\q2 èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’ ”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé \nd Olúwa\nd*?
|
||
\q2 Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé \nd Olúwa\nd*?
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi;
|
||
\q2 ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
|
||
\q1
|
||
\v 8 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ
|
||
\q2 ìwọ jẹ́ alágbára, \nd Olúwa\nd*, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìwọ ń darí ríru omi Òkun;
|
||
\q2 nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ
|
||
\q2 bí ẹni tí a pa;
|
||
\q1 ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ
|
||
\q2 tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ:
|
||
\q2 ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀:
|
||
\q1 ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn;
|
||
\q2 Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìwọ ní apá agbára;
|
||
\q2 agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ:
|
||
\q2 ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́,
|
||
\q2 wọn ń yin òdodo rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn;
|
||
\q2 nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Nítorí ti \nd Olúwa\nd* ni asà wa,
|
||
\q2 ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé,
|
||
\q2 “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára,
|
||
\q2 èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
|
||
\q1
|
||
\v 20 \x - \xo 89.20: \xt Ap 13.22.\x*Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi;
|
||
\q2 pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀
|
||
\q2 apá mí yóò sì fi agbára fún un.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀,
|
||
\q2 àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ
|
||
\q2 èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ
|
||
\q2 àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun,
|
||
\q2 àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
|
||
\q1
|
||
\v 27 \x - \xo 89.27: \xt If 1.5.\x*Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi,
|
||
\q2 ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un,
|
||
\q2 àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé,
|
||
\q2 àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀
|
||
\q2 tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́
|
||
\q2 tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
|
||
\q1
|
||
\v 32 nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò;
|
||
\q2 àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
|
||
\q1
|
||
\v 33 ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 34 Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
|
||
\q1
|
||
\v 35 Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra;
|
||
\q1 èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 36 Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé,
|
||
\q2 àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 37 \x - \xo 89.37: \xt If 1.5; 3.14.\x*A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá,
|
||
\q2 àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 38 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra;
|
||
\q2 ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 39 Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo;
|
||
\q2 ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
|
||
\q1
|
||
\v 40 Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀
|
||
\q2 ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
|
||
\q1
|
||
\v 41 Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ;
|
||
\q2 ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 42 Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè;
|
||
\q2 ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 43 Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà,
|
||
\q2 ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
|
||
\q1
|
||
\v 44 Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà,
|
||
\q2 ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 45 Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú;
|
||
\q2 ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 46 Yóò ti pẹ́ tó, \nd Olúwa\nd*?
|
||
\q2 Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé?
|
||
\q2 Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
|
||
\q1
|
||
\v 47 Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó
|
||
\q2 nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
|
||
\q1
|
||
\v 48 Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀?
|
||
\q2 Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú?
|
||
\q1
|
||
\v 49 \nd Olúwa\nd*, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà,
|
||
\q2 tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
|
||
\q1
|
||
\v 50 Rántí, \nd Olúwa\nd*, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ;
|
||
\q2 bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
|
||
\q1
|
||
\v 51 ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
|
||
\b
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 52 Olùbùkún ní \nd Olúwa\nd* títí láé.
|
||
\qc Àmín àti Àmín.
|
||
\c 90
|
||
\ms ÌWÉ KẸRIN
|
||
\mr Saamu 90–106
|
||
\cl Saamu 90
|
||
\d Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Kí a tó bí àwọn òkè ńlá
|
||
\q2 àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé,
|
||
\q1 láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀,
|
||
\q2 wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 90.4: \xt 2Pt 3.8.\x*Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún (1,000) ọdún bá kọjá lójú rẹ,
|
||
\q2 bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú;
|
||
\q2 wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun
|
||
\q2 ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 A pa wá run nípa ìbínú rẹ
|
||
\q2 nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ,
|
||
\q2 àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ;
|
||
\q2 àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá,
|
||
\q2 bi ó sì ṣe pé nípa agbára
|
||
\q1 tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún,
|
||
\q2 agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni,
|
||
\q1 nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò,
|
||
\q2 àwa a sì fò lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ?
|
||
\q2 Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára,
|
||
\q2 kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Yípadà, \nd Olúwa\nd*! Yóò ti pẹ́ tó?
|
||
\q2 Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ,
|
||
\q2 kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀
|
||
\q2 kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú,
|
||
\q2 fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀,
|
||
\q2 ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa;
|
||
\q2 fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.
|
||
\c 91
|
||
\cl Saamu 91
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹni tí ó gbé ibi ìkọ̀kọ̀ Ọ̀gá-ògo
|
||
\q2 ni yóò sinmi ní ibi òjìji Olódùmarè.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Èmi yóò sọ nípa ti \nd Olúwa\nd* pé,
|
||
\q2 “Òun ni ààbò àti odi mi,
|
||
\q2 Ọlọ́run mi, ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé”.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítòótọ́ òun yóò gbà mí nínú
|
||
\q2 ìdẹ̀kùn àwọn pẹyẹpẹyẹ
|
||
\q2 àti nínú àjàkálẹ̀-ààrùn búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Òun yóò fi ìyẹ́ rẹ̀ bò mí,
|
||
\q2 àti ni abẹ́ ìyẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti rí ààbò;
|
||
\q2 òtítọ́ rẹ̀ ni yóò ṣe ààbò àti odi mi.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ kì yóò bẹ̀rù nítorí ẹ̀rù òru,
|
||
\q2 tàbí fún ọfà tí ń fò ní ọ̀sán,
|
||
\q1
|
||
\v 6 tàbí fún àjàkálẹ̀-ààrùn tí ń rìn kiri ní òkùnkùn,
|
||
\q2 tàbí fún ìparun tí ń rìn kiri ní ọ̀sán gangan.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ẹgbẹ̀rún (1,000) yóò ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ,
|
||
\q2 ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n kì yóò súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ìwọ yóò máa wò ó pẹ̀lú ojú rẹ
|
||
\q2 àti wo ìjìyà àwọn ẹni búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítorí ìwọ fi \nd Olúwa\nd* ṣe ààbò rẹ,
|
||
\q2 ìwọ fi Ọ̀gá-ògo ṣe ibùgbé rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Búburú kan ki yóò ṣubú lù ọ́,
|
||
\q2 Bẹ́ẹ̀ ni ààrùnkárùn kì yóò súnmọ́ ilé rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 \x - \xo 91.11-12: \xt Mt 4.6; Lk 4.10-11.\x*Nítorí yóò fi àṣẹ fún àwọn angẹli nípa tìrẹ
|
||
\q2 láti pa ọ́ mọ́ ní gbogbo ọ̀nà rẹ;
|
||
\q1
|
||
\v 12 wọn yóò gbé ọ sókè ní ọwọ́ wọn,
|
||
\q2 nítorí kí ìwọ má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gún òkúta.
|
||
\q1
|
||
\v 13 \x - \xo 91.13: \xt Lk 10.19.\x*Ìwọ yóò rìn lórí kìnnìún àti paramọ́lẹ̀;
|
||
\q2 ìwọ yóò tẹ kìnnìún ńlá àti ejò ńlá ni ìwọ yóò fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 “Nítorí ti ìfẹ́ rẹ sí mi, èmi yóò gbà ọ́;
|
||
\q2 èmi yóò pa ọ́ mọ́, nítorí ìwọ jẹ́wọ́ orúkọ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Òun yóò pè mí, èmi yóò sì dá a lóhùn;
|
||
\q2 èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìpọ́njú,
|
||
\q2 èmi yóò gbà á, èmi yóò sì bu ọlá fún un.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Pẹ̀lú ẹ̀mí gígùn ni èmi yóò fi tẹ́ ẹ lọ́rùn,
|
||
\q2 èmi yóò sì fi ìgbàlà mi hàn án.”
|
||
\c 92
|
||
\cl Saamu 92
|
||
\d Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
|
||
\q1
|
||
\v 2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀
|
||
\q2 àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
|
||
\q1
|
||
\v 3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá
|
||
\q2 àti lára ohun èlò orin haapu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn
|
||
\q2 nípa iṣẹ́ rẹ \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q1 èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, \nd Olúwa\nd*?
|
||
\q2 Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
|
||
\q1
|
||
\v 6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n,
|
||
\q2 aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
|
||
\q1
|
||
\v 7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko
|
||
\q2 àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú,
|
||
\q2 wọn yóò run láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ṣùgbọ́n ìwọ \nd Olúwa\nd* ni a ó gbéga títí láé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ,
|
||
\q1 \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé;
|
||
\q1 gbogbo àwọn olùṣe búburú
|
||
\q2 ni a ó fọ́nká.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó;
|
||
\q2 òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi;
|
||
\q2 ìparun sí àwọn ènìyàn búburú
|
||
\q2 tí ó dìde sí mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ,
|
||
\q2 wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
|
||
\q1
|
||
\v 13 tí a gbìn sí ilé \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó,
|
||
\q2 wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
|
||
\q1
|
||
\v 15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú
|
||
\q2 kankan nínú rẹ̀.”
|
||
\c 93
|
||
\cl Saamu 93
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd* ń jẹ ọba, ọláńlá ni ó wọ̀ ní aṣọ;
|
||
\q2 ọláńlá ni \nd Olúwa\nd* wọ̀ ní aṣọ
|
||
\q2 àti ìhámọ́ra rẹ̀ pẹ̀lú agbára.
|
||
\q1 Ó fi ìdí ayé múlẹ̀;
|
||
\q2 kò sì le è yí.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìjọba rẹ̀ wà láti ọjọ́ pípẹ́;
|
||
\q2 ìwọ wà títí ayérayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 A ti gbé òkun sókè, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 òkun ti gbé ohùn wọn sókè;
|
||
\q2 òkun ti gbé rírú omi wọn sókè.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ó ni ògo ju àrá omi ńlá lọ,
|
||
\q2 ó ni ògo ju òkun rírú lọ
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ga ní ògo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹ̀rí rẹ̀ dúró ṣinṣin;
|
||
\q2 ìwà mímọ́ ni ó fi ṣe ilé rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́
|
||
\q2 fún ọjọ́ àìlópin, \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 94
|
||
\cl Saamu 94
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san,
|
||
\q2 Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Gbé ara rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé;
|
||
\q2 san ẹ̀san fún agbéraga
|
||
\q2 ohun tí ó yẹ wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Báwo ní yóò ti pẹ́ tó,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*
|
||
\q1 tí àwọn ẹni búburú
|
||
\q2 yóò kọ orin ayọ̀?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga jáde;
|
||
\q2 gbogbo àwọn olùṣe búburú
|
||
\q1 kún fún ìṣògo.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn rẹ túútúú, \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní rẹ̀ lójú.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò,
|
||
\q2 wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Wọ́n sọ pé, “\nd Olúwa\nd* kò rí i;
|
||
\q2 Ọlọ́run Jakọbu kò sì kíyèsi i.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Kíyèsi i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyàn;
|
||
\q2 ẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bí?
|
||
\q2 Ẹni tí ó dá ojú?
|
||
\q1 Ó ha lè ṣe aláìríran bí?
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ẹni tí ń bá orílẹ̀-èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni ṣọ́nà bí?
|
||
\q2 Ẹni tí ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
|
||
\q1
|
||
\v 11 \x - \xo 94.11: \xt 1Kọ 3.20.\x*\nd Olúwa\nd* mọ èrò inú ènìyàn;
|
||
\q2 ó mọ̀ pé asán ni wọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí
|
||
\q2 ìwọ bá wí, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q1 ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin rẹ,
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi,
|
||
\q2 títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Nítorí \nd Olúwa\nd* kò ní kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀,
|
||
\q1 Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní rẹ̀ sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo,
|
||
\q2 àti gbogbo àwọn ọlọ́kàn
|
||
\q2 dídúró ṣinṣin yóò tẹ̀lé e lẹ́yìn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ta ni yóò dìde fún mi
|
||
\q2 sí àwọn olùṣe búburú?
|
||
\q2 Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
|
||
\q1
|
||
\v 17 Bí kò ṣe pé \nd Olúwa\nd* fún mi ní ìrànlọ́wọ́,
|
||
\q2 èmi fẹ́rẹ̀ máa gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Nígbà tí mo sọ pé, “Ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, ìfẹ́ rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi,
|
||
\q2 ìtùnú rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú rẹ
|
||
\q2 ẹni tí ń fi òfin dì mọ́ ìwà ìkà?
|
||
\q1
|
||
\v 21 Wọ́n kó ara wọn jọ sí olódodo
|
||
\q2 wọ́n sì ń dá àwọn aláìṣẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ṣùgbọ́n, \nd Olúwa\nd* ti di odi alágbára mi,
|
||
\q2 àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹni
|
||
\q2 tí mo ti ń gba ààbò.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọn
|
||
\q2 yóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.
|
||
\c 95
|
||
\cl Saamu 95
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a kọ orin ayọ̀ sí \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ẹ jẹ́ kí a kígbe sókè sí àpáta ìgbàlà wa.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́
|
||
\q2 kí a sì pòkìkí rẹ̀ pẹ̀lú ohun èlò
|
||
\q2 orin àti ìyìn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run títóbi ni,
|
||
\q2 ọba tí ó tóbi ju gbogbo òrìṣà lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ní ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà,
|
||
\q2 ṣóńṣó orí òkè tirẹ̀ ní ṣe.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Tirẹ̀ ni Òkun, nítorí òun ni ó dá a
|
||
\q2 àti ọwọ́ rẹ̀ ni ó fi dá ìyàngbẹ ilẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a foríbalẹ̀ kí a sìn ín,
|
||
\q2 ẹ jẹ́ kí a kúnlẹ̀ níwájú
|
||
\q1 \nd Olúwa\nd* ẹni tí ó dá wa,
|
||
\q1
|
||
\v 7 \x - \xo 95.7-11: \xt Hb 3.7-11; 4.3-11.\x*nítorí òun ni Ọlọ́run wa,
|
||
\q2 àwa sì ni ènìyàn pápá rẹ̀,
|
||
\q1 àti ọ̀wọ́ ẹran ni abẹ́ ìpamọ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q2 Lónìí tí ìwọ bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 8 “Ẹ má ṣe sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ní Meriba,
|
||
\q2 àti bí ẹ ti ṣe ní ọjọ́ náà ní Massa ní aginjù,
|
||
\q1
|
||
\v 9 nígbà tí àwọn baba yín dán mi wò
|
||
\q2 tí wọn wádìí mi,
|
||
\q1 tí wọn sì rí iṣẹ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Fún ogójì ọdún ni èmi fi bínú sí ìran náà;
|
||
\q2 mo wí pé, ‘Wọ́n jẹ́ ènìyàn tí ọkàn wọn ṣáko lọ
|
||
\q2 wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
|
||
\q1
|
||
\v 11 Nítorí náà ni mo kéde ìbúra nínú ìbínú mi,
|
||
\q2 ‘Wọn kì yóò wọ ibi ìsinmi mi.’ ”
|
||
\c 96
|
||
\cl Saamu 96
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 96.1-13: \xt 1Ki 16.23-33.\x*Ẹ kọrin tuntun sí \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ẹ kọrin sí \nd Olúwa\nd* gbogbo ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ kọrin sí \nd Olúwa\nd*, yin orúkọ rẹ̀
|
||
\q2 ẹ sọ ti ìgbàlà rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹ sọ ti ògo rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè
|
||
\q2 àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrín gbogbo ènìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí títóbi ní \nd Olúwa\nd* ẹni tí ìyìn tọ́ sí;
|
||
\q2 òun ní o yẹ kí a bẹ̀rù ju gbogbo òrìṣà lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí asán ni gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè
|
||
\q2 ṣùgbọ́n \nd Olúwa\nd* dá àwọn ọ̀run.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọlá àti ọláńlá wà ní iwájú rẹ̀
|
||
\q2 agbára àti ògo wà ní ibi mímọ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ẹ fi fún \nd Olúwa\nd*, ẹ̀yin ìbátan ènìyàn,
|
||
\q2 ẹ fi agbára àti ògo fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹ fi ògo tí ó tọ́ sí \nd Olúwa\nd* fún un;
|
||
\q2 ẹ mú ọrẹ wá, kí ẹ sì wá sí àgbàlá rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ẹ máa sin \nd Olúwa\nd* nínú ẹwà ìwà mímọ́ rẹ̀;
|
||
\q2 ẹ wárìrì níwájú rẹ̀ gbogbo ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, “\nd Olúwa\nd* jẹ ọba.”
|
||
\q2 A fi ìdí ayé múlẹ̀, tí kò sì lè yí;
|
||
\q2 ẹni tí yóò fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ ènìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, kí ayé sì pariwo
|
||
\q2 jẹ́ kí pápá òkun kí ó hó pẹ̀lú ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Jẹ́ kí oko kún fún ayọ̀, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀;
|
||
\q1 nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóò máa yọ̀.
|
||
\q2
|
||
\v 13 Wọn yóò kọrin níwájú \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí tí ó ń bọ̀ wá, ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé.
|
||
\q1 Yóò fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé
|
||
\q2 àti ti àwọn ènìyàn ni yóò fi òtítọ́ rẹ̀ ṣe.
|
||
\c 97
|
||
\cl Saamu 97
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd* jẹ ọba, jẹ́ kí ayé kí ó yọ̀
|
||
\q2 jẹ́ kí inú ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù kí ó dùn.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ojú ọ̀run àti òkùnkùn yíká
|
||
\q2 òdodo àti ìdájọ́ ni ó ṣe ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìtẹ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Iná ń jó níwájú rẹ̀. Ó sì ń jó àwọn ọ̀tá rẹ̀ yíkákiri.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn ó sì kárí ayé
|
||
\q2 ayé rí i ó sì wárìrì.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Òkè gíga yọ́ gẹ́gẹ́ bí ìda níwájú \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 níwájú Olúwa gbogbo ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Àwọn ọ̀run ròyìn òdodo rẹ̀, gbogbo ènìyàn sì rí ògo rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 \x - \xo 97.7: \xt Hb 1.6.\x*Gbogbo àwọn tí ń sin ère fínfín ni ojú yóò tì,
|
||
\q2 àwọn tí ń fi ère gbéraga,
|
||
\q2 ẹ máa sìn ín, gbogbo ẹ̀yin ọlọ́run!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Sioni gbọ́, inú rẹ̀ sì dùn
|
||
\q2 inú àwọn ilé Juda sì dùn,
|
||
\q2 nítorí ìdájọ́ rẹ, \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítorí pé ìwọ, \nd Olúwa\nd*, ni ó ga ju gbogbo ayé lọ
|
||
\q2 ìwọ ni ó ga ju gbogbo òrìṣà lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Jẹ kí gbogbo àwọn tí ó fẹ́
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, kórìíra ibi, ó pa ọkàn àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ mọ́
|
||
\q2 ó gbà wọ́n ní ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìmọ́lẹ̀ tàn sórí àwọn olódodo
|
||
\q2 àti ayọ̀ nínú àlàyé ọkàn.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ẹ yọ̀ nínú \nd Olúwa\nd*, ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olódodo,
|
||
\q2 kí ẹ sì yin orúkọ rẹ̀ mímọ́.
|
||
\c 98
|
||
\cl Saamu 98
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ kọrin tuntun sí \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí tí ó ṣe ohun ìyanu;
|
||
\q1 ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti apá mímọ́ rẹ̀
|
||
\q2 o ṣe iṣẹ́ ìgbàlà fún un
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd* ti sọ ìgbàlà rẹ̀ di mí mọ̀
|
||
\q2 o fi òdodo rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ó rántí ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ fún àwọn ará ilé Israẹli;
|
||
\q2 gbogbo òpin ayé ni ó ti rí
|
||
\q2 iṣẹ́ ìgbàlà Ọlọ́run wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí \nd Olúwa\nd*, gbogbo ayé,
|
||
\q2 ẹ bú sáyọ̀, ẹ kọrin ìyìn,
|
||
\q1
|
||
\v 5 ẹ fi dùùrù kọrin sí \nd Olúwa\nd*, pẹ̀lú dùùrù àti ìró ohùn orin mímọ́,
|
||
\q1
|
||
\v 6 pẹ̀lú ìpè àti fèrè
|
||
\q2 ẹ hó fún ayọ̀ níwájú \nd Olúwa\nd* ọba.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Jẹ́ kí òkun kí ó hó pẹ̀lú gbogbo
|
||
\q2 ohun tí ó wà nínú rẹ̀,
|
||
\q1 Gbogbo ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹ jẹ́ kí odo kí ó ṣápẹ́,
|
||
\q2 ẹ jẹ́ kí òkè kí ó kọrin pẹ̀lú ayọ̀;
|
||
\q1
|
||
\v 9 ẹ jẹ́ kí wọn kọrin níwájú \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí tí yóò wá ṣèdájọ́ ayé
|
||
\q1 bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè nínú òdodo
|
||
\q2 àti àwọn ènìyàn ní àìṣègbè pẹ̀lú.
|
||
\c 99
|
||
\cl Saamu 99
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd* jẹ ọba;
|
||
\q2 jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì
|
||
\q1 Ó jókòó lórí ìtẹ́ kérúbù
|
||
\q2 jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì.
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd* tóbi ní Sioni;
|
||
\q2 Ó sì ga jù gbogbo orílẹ̀-èdè lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kí wọ́n sì yin orúkọ rẹ̀ tí ó tóbi
|
||
\q2 tí ó ni ẹ̀rù, Mímọ́ ni Òun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ọba náà ní agbára, ó sì fẹ́ òdodo,
|
||
\q2 ìwọ fi ìdí àìṣègbè múlẹ̀;
|
||
\q2 ìwọ ṣe ohun tí ó tọ́ àti ohun tí ó yẹ nínú Jakọbu.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Gbígbéga ni \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa
|
||
\q2 ẹ foríbalẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀; ó jẹ́ mímọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Mose àti Aaroni wà nínú àwọn àlùfáà rẹ̀
|
||
\q2 Samuẹli wà nínú àwọn tí ó ń ké pe orúkọ rẹ̀
|
||
\q2 wọ́n ké pe \nd Olúwa\nd*, ó sì dá wọn lóhùn.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ó sọ̀rọ̀ sí wọn nínú ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀,
|
||
\q2 wọ́n pa ẹ̀rí rẹ̀ mọ́ àti ìlànà tí ó fún wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa, ó dá wọn lóhùn;
|
||
\q2 ó jẹ́ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì àwọn ọmọ Israẹli
|
||
\q2 ìwọ tí ó ń fi ìyà àìṣedéédéé wọn jẹ wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Gbígbéga ni \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa
|
||
\q2 kí a sìn ín ní òkè mímọ́ rẹ̀
|
||
\q2 nítorí \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa jẹ́ mímọ́.
|
||
\c 100
|
||
\cl Saamu 100
|
||
\d Saamu. Fún ọpẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí \nd Olúwa\nd*, gbogbo ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ fi ayọ̀ sin \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ẹ wá síwájú rẹ̀ pẹ̀lú orin dídùn
|
||
\q1
|
||
\v 3 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run ni ó dá wa,
|
||
\q2 kí ẹ̀yin kí ó mọ̀ pé
|
||
\q1 tirẹ̀ ni àwa, àwa ní ènìyàn rẹ̀
|
||
\q2 àti àgùntàn pápá rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ẹ lọ sí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́
|
||
\q2 àti sí àgbàlá rẹ̀ pẹ̀lú ìyìn;
|
||
\q2 ẹ fi ọpẹ́ àti ìyìn fún orúkọ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí tí \nd Olúwa\nd* pọ̀ ní oore
|
||
\q2 ìfẹ́ rẹ̀ sì wà títí láé;
|
||
\q2 àti òtítọ́ rẹ̀ láti ìran de ìran.
|
||
\c 101
|
||
\cl Saamu 101
|
||
\d Ti Dafidi. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo;
|
||
\q2 sí ọ \nd Olúwa\nd*, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀,
|
||
\q2 ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi?
|
||
\b
|
||
\q1 Èmi yóò máa rìn ní ilé mi
|
||
\q2 pẹ̀lú àyà pípé.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi:
|
||
\q2 iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra.
|
||
\b
|
||
\q2 Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi;
|
||
\q2 èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀,
|
||
\q2 òun ní èmi yóò gé kúrò
|
||
\q1 ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà,
|
||
\q2 òun ní èmi kì yóò faradà fún.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀,
|
||
\q2 kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé;
|
||
\q1 ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé
|
||
\q2 òun ni yóò máa sìn mí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi,
|
||
\q2 kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ
|
||
\q2 gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà;
|
||
\q1 èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú
|
||
\q2 kúrò ní ìlú \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 102
|
||
\cl Saamu 102
|
||
\d Àdúrà olùpọ́njú tí àárẹ̀ mú, tí ó sí ọkàn rẹ̀ payá níwájú \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Gbọ́ àdúrà mi, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 jẹ́ kí igbe ẹ̀bẹ̀ mi kí ó wá sí ọ̀dọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi
|
||
\q2 ní ọjọ́ tí èmi wà nínú ìpọ́njú.
|
||
\q1 Dẹ etí rẹ sí mi;
|
||
\q2 nígbà tí mo bá pè, dá mi lóhùn kíákíá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí tí ọjọ́ mi run bí èéfín;
|
||
\q2 egungun mi sì jóná bí ààrò.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àyà mi lù, ó sì rọ bí i koríko;
|
||
\q2 mo gbàgbé láti jẹ oúnjẹ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí ohùn ìkérora mi,
|
||
\q2 egungun mi lẹ̀ mọ́ ẹran-ara mi.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmi dàbí ẹyẹ igún ní ijù:
|
||
\q2 èmi dàbí òwìwí ibi ahoro.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Èmi dìde; èmi dàbí ẹyẹ lórí ilé.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ní ọjọ́ gbogbo, àwọn ọ̀tá ológoṣẹ́ mi ń gàn mí;
|
||
\q2 àwọn tí ń ṣe ìkanra sí mi ń fi orúkọ mi bú.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi sì da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omijé.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nítorí ìbínú ríru rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ọjọ́ mi dàbí òjìji àṣálẹ́
|
||
\q2 èmi sì rọ bí koríko.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ṣùgbọ́n ìwọ, \nd Olúwa\nd*, ni yóò dúró láéláé;
|
||
\q2 ìrántí rẹ láti ìran dé ìran.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìwọ ó dìde ìwọ ó sì ṣàánú fún Sioni,
|
||
\q2 nítorí ìgbà àti ṣe ojúrere sí i;
|
||
\q2 àkókò náà ti dé.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Nítorí tí àwọn òkúta jẹ́ inú dídùn sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ;
|
||
\q2 wọ́n sì káàánú erùpẹ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Àwọn kèfèrí yóò bẹ̀rù orúkọ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 gbogbo ọba ayé yóò máa bẹ̀rù ògo rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Torí tí \nd Olúwa\nd* yóò gbé Sioni ró, yóò farahàn nínú ògo rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Yóò dáhùn àdúrà àwọn aláìní;
|
||
\q2 kì yóò sì gan ẹ̀bẹ̀ wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 18 Jẹ́ kí a kọ èyí fún ìran tí ń bọ̀,
|
||
\q2 àwọn ènìyàn tí a kò tí ì dá yóò yin \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q1
|
||
\v 19 “\nd Olúwa\nd* wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀ wá
|
||
\q2 láti ọ̀run wá ni ó bojú wo ayé,
|
||
\q1
|
||
\v 20 láti gbọ́ ìrora ará túbú,
|
||
\q2 láti tú àwọn tí a yàn sí ikú sílẹ̀.”
|
||
\q1
|
||
\v 21 Kí a lè sọ orúkọ \nd Olúwa\nd* ní Sioni
|
||
\q2 àti ìyìn rẹ̀ ní Jerusalẹmu.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ní ìgbà tí a kó àwọn ènìyàn àti
|
||
\q2 ìjọba pọ̀ láti máa sìn \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ní ipa ọ̀nà mi, ó rẹ agbára mi sílẹ̀,
|
||
\q2 ó gé ọjọ́ mi kúrú.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Èmi sì wí pé:
|
||
\q2 “Ọlọ́run mi, má ṣe mú mi kúrò ní agbede-méjì ọjọ́ mi; ọdún rẹ̀ ń lọ láti ìran dé ìran.
|
||
\q1
|
||
\v 25 \x - \xo 102.25-27: \xt Hb 1.10-12.\x*Ní ìbẹ̀rẹ̀ ní ìwọ fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀,
|
||
\q2 ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Wọn yóò ṣègbé, wọn yóò parun, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà;
|
||
\q2 gbogbo wọn ni yóò gbó bí aṣọ.
|
||
\q1 Bí ẹ̀wù ni ìwọ yóò pààrọ̀ wọn
|
||
\q2 wọn yóò sì di àpatì.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Ṣùgbọ́n ìwọ wà digbí síbẹ̀,
|
||
\q2 ọdún rẹ kò sì ní òpin.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Àwọn ọmọ ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò dúró ní iwájú rẹ pẹ́;
|
||
\q2 a ó sì fi ẹsẹ̀ irú-ọmọ wọn sọlẹ̀ ní iwájú rẹ.”
|
||
\c 103
|
||
\cl Saamu 103
|
||
\d Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Yin \nd Olúwa\nd*, ìwọ ọkàn mi; àti gbogbo ohun tí ó wà nínú mi, yín orúkọ rẹ̀ mímọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Yin \nd Olúwa\nd*, ìwọ ọkàn mi, kí o má ṣe gbàgbé gbogbo oore rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 3 ẹni tí ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jì ọ́
|
||
\q2 tí ó sì wo gbogbo ààrùn rẹ̀ sàn,
|
||
\q1
|
||
\v 4 ẹni tí ó ra ẹ̀mí rẹ padà kúrò nínú kòtò ikú
|
||
\q2 ẹni tí ó fi ìṣeun ìfẹ́ àti ìyọ́nú dé ọ ní adé,
|
||
\q1
|
||
\v 5 ẹni tí ó fi ohun dídára tẹ́ ọ lọ́rùn
|
||
\q2 kí ìgbà èwe rẹ̀ lè di ọ̀tún bí ti ẹyẹ idì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 \nd Olúwa\nd* ń ṣe òdodo àti ìdájọ́ fún
|
||
\q2 gbogbo àwọn tí a ni lára.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ó fi ọ̀nà rẹ̀ hàn fún Mose, iṣẹ́ rẹ̀ fun àwọn ọmọ Israẹli;
|
||
\q1
|
||
\v 8 \x - \xo 103.8: \xt Jk 5.11.\x*\nd Olúwa\nd* ni aláàánú àti olóore,
|
||
\q2 ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Òun kì í bá ni wí ní ìgbà gbogbo
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kì í pa ìbínú rẹ mọ́ láéláé,
|
||
\q1
|
||
\v 10 Òun kì í ṣe sí wa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ wa
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kì í san án fún wa gẹ́gẹ́
|
||
\q1 bí àìṣedéédéé wa.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Nítorí bí ọ̀run ṣe ga sílẹ̀,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ rẹ̀ tóbi sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Bí ìlà-oòrùn ti jìnnà sí ìwọ̀-oòrùn
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe mú ìrékọjá wá jìnnà sí wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Bí baba ti ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ rẹ̀,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni \nd Olúwa\nd* ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 14 nítorí tí ó mọ dídá wa,
|
||
\q2 ó rántí pé erùpẹ̀ ni wá.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Bí ó ṣe ti ènìyàn ni, ọjọ́ rẹ̀ dàbí koríko,
|
||
\q2 ó gbilẹ̀ bí ìtànná ewéko igbó,
|
||
\q1
|
||
\v 16 afẹ́fẹ́ fẹ́ kọjá lọ lórí rẹ̀,
|
||
\q2 kò sì rántí ibùjókòó rẹ̀ mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 17 \x - \xo 103.17: \xt Lk 1.50.\x*Ṣùgbọ́n láti ayérayé ni ìfẹ́
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ti wà pẹ̀lú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
|
||
\q2 àti òdodo rẹ̀ wà láti ọmọdọ́mọ,
|
||
\q1
|
||
\v 18 sí àwọn tí ó pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́
|
||
\q2 àti àwọn tí ó rántí òfin rẹ̀ láti ṣe wọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 \nd Olúwa\nd* ti pèsè ìtẹ́ rẹ̀ nínú ọ̀run,
|
||
\q2 ìjọba rẹ̀ ní ó sì borí ohun gbogbo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 20 Yin \nd Olúwa\nd*, ẹ̀yin angẹli rẹ̀,
|
||
\q2 tí ó ní ipá,
|
||
\q2 tí ó pa òfin ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́, tì ó sì ń se ìfẹ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Yin \nd Olúwa\nd*, ẹ̀yin ogun ọ̀run rẹ̀ gbogbo,
|
||
\q2 ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Yin \nd Olúwa\nd*, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ní
|
||
\q2 ibi gbogbo ìjọba rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1 Yin \nd Olúwa\nd*, ìwọ ọkàn mi.
|
||
\c 104
|
||
\cl Saamu 104
|
||
\q1
|
||
\v 1 Yin \nd Olúwa\nd*, ìwọ ọkàn mi.
|
||
\b
|
||
\q1 \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run mi, ìwọ tóbi jọjọ;
|
||
\q2 ọlá àti ọláńlá ni ìwọ wọ̀ ní aṣọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìwọ fi ìmọ́lẹ̀ bo ara rẹ gẹ́gẹ́ bí aṣọ;
|
||
\q2 ó tẹ ọ̀run bí títẹ́ ẹní,
|
||
\q1
|
||
\v 3 ìwọ tí ó fi omi ṣe ìtì igi àjà ìyẹ̀wù rẹ.
|
||
\q2 Ìwọ tí o ṣe àwọsánmọ̀ ní kẹ̀kẹ́ ogun rẹ
|
||
\q2 ìwọ tí ó ń rìn lórí apá ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 104.4: \xt Hb 1.7.\x*Ó fi ẹ̀fúùfù ṣe àwọn ìránṣẹ́ rẹ,
|
||
\q2 ọ̀wọ́-iná ni àwọn olùránṣẹ́ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 O fi ayé gúnlẹ̀ lórí àwọn ìpìlẹ̀;
|
||
\q2 tí a kò le è mì láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ìwọ fi ibú omi bò ó mọ́lẹ̀ bí aṣọ;
|
||
\q2 àwọn omi sì dúró lórí àwọn òkè ńlá.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ṣùgbọ́n nípa ìbáwí rẹ ni àwọn omi lọ,
|
||
\q2 nípa ohùn àrá rẹ ni wọ́n sálọ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 wọ́n sàn kọjá lórí àwọn òkè,
|
||
\q2 wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀,
|
||
\q2 sí ibi tí ìwọ ti yàn fún wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìwọ gbé òpin tí wọn kò lè kọjá rẹ̀ kálẹ̀;
|
||
\q2 láéláé ni wọ́n kò ní lè bo ayé mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìwọ mú kí ìsun da omi sí àwọn àfonífojì;
|
||
\q2 tí ó ń sàn láàrín àwọn òkè.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Wọ́n fún gbogbo àwọn ẹranko igbó ní omi
|
||
\q2 àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ń pa òǹgbẹ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Àwọn ẹyẹ ojú òfúrufú tẹ́ ìtẹ́ wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi
|
||
\q2 wọ́n ń kọrin láàrín àwọn ẹ̀ka.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ó bu omi rin àwọn òkè láti ìyẹ̀wù rẹ̀ wá;
|
||
\q2 a tẹ́ ayé lọ́rùn nípa èso iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ó mú kí koríko hù jáde fún àwọn ẹranko láti jẹ
|
||
\q2 àti àwọn ewébẹ̀ fún ènìyàn láti lò,
|
||
\q2 kí ó lè mú oúnjẹ jáde láti ilẹ̀ wá.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ọtí wáìnì tí ó ń mú ọkàn ènìyàn yọ̀,
|
||
\q2 òróró láti mú ojú rẹ̀ tan,
|
||
\q2 àti àkàrà láti ra ọkàn rẹ̀ padà.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Àwọn igi \nd Olúwa\nd* ni a bu omi rin dáradára,
|
||
\q2 kedari ti Lebanoni tí ó gbìn.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Níbẹ̀ ní àwọn ẹyẹ ṣe ìtẹ́ wọn
|
||
\q2 bí ó ṣe tí àkọ̀ ni, orí igi gíga ni ilé rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó;
|
||
\q2 àti àwọn àlàpà jẹ́ ààbò fún àwọn ehoro.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Òṣùpá jẹ́ àmì fún àkókò
|
||
\q2 oòrùn sì mọ ìgbà tí yóò wọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru,
|
||
\q2 nínú èyí tí gbogbo ẹranko igbó ń rìn kiri.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọn
|
||
\q2 wọ́n sì ń wá oúnjẹ wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Oòrùn ràn, wọ́n sì kó ara wọn jọ,
|
||
\q2 wọn padà lọ dùbúlẹ̀ sí ihò wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,
|
||
\q2 àti sí làálàá rẹ̀ títí di àṣálẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Iṣẹ́ rẹ ti pọ̀ tó, \nd Olúwa\nd*!
|
||
\q2 Nínú ọgbọ́n ni ìwọ ṣe gbogbo wọn:
|
||
\q2 ayé kún fún àwọn ìṣẹ̀dá á rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Bẹ́ẹ̀ ni Òkun yìí tí ó tóbi, tí ó sì ni ìbú,
|
||
\q2 tí ó kún fún àwọn ẹ̀dá alààyè ní ìsàlẹ̀ láìníye
|
||
\q2 ohun alààyè tí tóbi àti kékeré.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Níbẹ̀ ni ọkọ̀ ń lọ síwá sẹ́yìn,
|
||
\q2 àti Lefitani, tí ìwọ dá láti ṣe àríyá nínú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 27 Àwọn wọ̀nyí ń wò ọ́
|
||
\q2 láti fún wọn ní oúnjẹ wọn lákòókò rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Nígbà tí ìwọ bá fi fún wọn,
|
||
\q2 wọn yóò kó jọ;
|
||
\q1 nígbà tí ìwọ bá la ọwọ́ rẹ̀,
|
||
\q2 a tẹ́ wọn lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Nígbà tí ìwọ bá pa ojú rẹ mọ́
|
||
\q2 ara kò rọ̀ wọ́n
|
||
\q1 nígbà tí ìwọ bá mú ẹ̀mí wọn lọ,
|
||
\q2 wọn ó kú, wọn ó sì padà sí erùpẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí rẹ,
|
||
\q2 ni a dá wọn,
|
||
\q2 ìwọ sì tún ojú ayé ṣe.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 31 Jẹ́ kí ògo \nd Olúwa\nd* wà pẹ́ títí láé;
|
||
\q2 kí inú \nd Olúwa\nd* kí ó dùn ní ti iṣẹ́ rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 32 ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì,
|
||
\q2 ẹni tí ó fọwọ́ tọ́ àwọn òkè, tí wọ́n yọ èéfín.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 33 Ní gbogbo ayé mi ní n ó kọrin sí \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 èmi ó kọrin ìyìn sí \nd Olúwa\nd*
|
||
\q1 níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè.
|
||
\q1
|
||
\v 34 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ́ ọ lọ́rùn
|
||
\q2 bí mo ti ń yọ̀ nínú \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 35 Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́ṣẹ̀ kúrò láyé
|
||
\q2 kí ènìyàn búburú má sì sí mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1 Yin \nd Olúwa\nd*, ìwọ ọkàn mi.
|
||
\b
|
||
\q1 Yin \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 105
|
||
\cl Saamu 105
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 105.1-15: \xt 1Ki 16.8-22.\x*Ẹ fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd*, ké pe orúkọ rẹ̀,
|
||
\q2 jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i;
|
||
\q2 sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀,
|
||
\q2 jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá \nd Olúwa\nd* kí ó yọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Wá \nd Olúwa\nd* àti ipá rẹ̀;
|
||
\q2 wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe,
|
||
\q2 ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
|
||
\q1
|
||
\v 6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀,
|
||
\q2 ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Òun ni \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa:
|
||
\q2 ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 \x - \xo 105.8-9: \xt Lk 1.72-73.\x*Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé,
|
||
\q2 ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
|
||
\q1
|
||
\v 9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu,
|
||
\q2 ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ,
|
||
\q2 sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
|
||
\q1
|
||
\v 11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nígbà tí wọn kéré níye,
|
||
\q2 wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè,
|
||
\q2 láti ìjọba kan sí èkejì.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú;
|
||
\q2 ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
|
||
\q1
|
||
\v 15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà
|
||
\q2 ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn
|
||
\q2 Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀
|
||
\q2 a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
|
||
\q1
|
||
\v 19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ
|
||
\q2 títí ọ̀rọ̀ \nd Olúwa\nd* fi dá a láre.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀
|
||
\q2 àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀,
|
||
\q2 aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
|
||
\q1
|
||
\v 22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa
|
||
\q2 ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé
|
||
\q2 kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Israẹli wá sí Ejibiti;
|
||
\q2 Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
|
||
\q1
|
||
\v 24 \nd Olúwa\nd*, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i
|
||
\q2 ó sì mú wọn lágbára jù
|
||
\q2 àwọn ọ̀tá wọn lọ
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn
|
||
\q2 láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀,
|
||
\q2 àti Aaroni tí ó ti yàn.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn
|
||
\q2 ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú
|
||
\q2 wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀,
|
||
\q2 ó pa ẹja wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá,
|
||
\q2 èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde,
|
||
\q2 ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
|
||
\q1
|
||
\v 32 Ó sọ òjò di yìnyín,
|
||
\q2 àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
|
||
\q1
|
||
\v 33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn
|
||
\q2 ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé,
|
||
\q2 àti kòkòrò ní àìníye,
|
||
\q1
|
||
\v 35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn,
|
||
\q2 wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
|
||
\q1
|
||
\v 36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn,
|
||
\q2 ààyò gbogbo ipá wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 37 Ó mú Israẹli jáde
|
||
\q2 ti òun ti fàdákà àti wúrà,
|
||
\q2 nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
|
||
\q1
|
||
\v 38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ,
|
||
\q2 nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí,
|
||
\q2 àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá,
|
||
\q2 ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
|
||
\q1
|
||
\v 41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde;
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀
|
||
\q2 àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde
|
||
\q2 pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà,
|
||
\q2 wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
|
||
\q1
|
||
\v 45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́
|
||
\q2 kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 106
|
||
\cl Saamu 106
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 106.1: \xt 1Ki 16.34.\x*Yin \nd Olúwa\nd*! Ẹ fi ìyìn fún
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, nítorí tí ó ṣeun.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd* nítorí tí ó ṣeun,
|
||
\q2 nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́?
|
||
\q2 Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Rántí mi, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn,
|
||
\q2 wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
|
||
\q1
|
||
\v 5 kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn,
|
||
\q2 kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn,
|
||
\q2 ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe,
|
||
\q2 àwa ti ṣe ohun tí kò dá a,
|
||
\q2 a sì ti hùwà búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti,
|
||
\q2 iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn,
|
||
\q1 wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ,
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ
|
||
\q2 láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ;
|
||
\q2 o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
|
||
\q1
|
||
\v 10 O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn,
|
||
\q2 láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn;
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́
|
||
\q2 wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe
|
||
\q2 wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́,
|
||
\q2 nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose
|
||
\q2 pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì
|
||
\q2 ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀;
|
||
\q2 iná jo àwọn ènìyàn búburú.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù
|
||
\q2 wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Wọ́n pa ògo wọn dà
|
||
\q2 sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n
|
||
\q2 ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
|
||
\q1
|
||
\v 22 iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu
|
||
\q2 àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run
|
||
\q2 bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn,
|
||
\q1 tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà
|
||
\q2 tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 24 Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà
|
||
\q2 wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn
|
||
\q2 wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè
|
||
\q2 kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
|
||
\q1
|
||
\v 27 láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè
|
||
\q2 láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori,
|
||
\q2 wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
|
||
\q1
|
||
\v 29 wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe
|
||
\q2 àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i,
|
||
\q2 àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
|
||
\q1
|
||
\v 31 A sì ka èyí sí òdodo fún un àti
|
||
\q2 fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
|
||
\q1
|
||
\v 32 Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú,
|
||
\q2 ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 33 Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run.
|
||
\q2 Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 34 Wọn kò pa àwọn ènìyàn run
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí \nd Olúwa\nd* ti sọ fún wọn,
|
||
\q1
|
||
\v 35 Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè,
|
||
\q2 wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 36 Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn
|
||
\q2 tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 37 Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ
|
||
\q2 àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
|
||
\q1
|
||
\v 38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,
|
||
\q2 ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ.
|
||
\q1 Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani,
|
||
\q2 ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 39 Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́,
|
||
\q2 wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 40 Nígbà náà ni \nd Olúwa\nd* bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀
|
||
\q2 ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 41 Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́,
|
||
\q2 àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 42 Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú
|
||
\q2 wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 43 Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n,
|
||
\q2 síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i
|
||
\q2 wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 44 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro
|
||
\q2 nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
|
||
\q1
|
||
\v 45 ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn
|
||
\q2 Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 46 Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn
|
||
\q2 ó mú wọn rí àánú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 47 \x - \xo 106.47-48: \xt 1Ki 16.35-36.\x*Gbà wá, \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa,
|
||
\q2 kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí,
|
||
\q1 láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ
|
||
\q2 láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
|
||
\b
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 48 Olùbùkún ni \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran.
|
||
\b
|
||
\q1 Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!”
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*!
|
||
\c 107
|
||
\ms ÌWÉ KARÙN-ÚN
|
||
\mr Saamu 107–150
|
||
\cl Saamu 107
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd*, nítorí tí ó ṣeun;
|
||
\q2 nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà \nd Olúwa\nd* kí ó wí báyìí,
|
||
\q2 àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
|
||
\q1
|
||
\v 3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì,
|
||
\q2 láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn,
|
||
\q2 láti àríwá àti Òkun wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí,
|
||
\q2 wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí
|
||
\q2 wọn ó máa gbé.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n,
|
||
\q2 ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè
|
||
\q2 sí \nd Olúwa\nd* nínú ìdààmú wọn,
|
||
\q1 ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú
|
||
\q2 tí wọn lè máa gbé.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin \nd Olúwa\nd* nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́
|
||
\q2 ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
|
||
\q1
|
||
\v 9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run
|
||
\q2 ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú,
|
||
\q2 a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
|
||
\q1
|
||
\v 11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀
|
||
\q2 Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀;
|
||
\q2 wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí
|
||
\q2 yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* nínú ìdààmú wọn,
|
||
\q2 ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú
|
||
\q2 òkùnkùn àti òjìji ikú,
|
||
\q2 ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd*! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì
|
||
\q2 ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn
|
||
\q2 wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ
|
||
\q2 wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí \nd Olúwa\nd* nínú ìṣòro wọn,
|
||
\q2 ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá
|
||
\q2 ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd* nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́
|
||
\q2 kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi,
|
||
\q2 wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Wọ́n rí iṣẹ́ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́
|
||
\q2 tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì
|
||
\q2 tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú:
|
||
\q2 nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn:
|
||
\q2 ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè
|
||
\q2 sí \nd Olúwa\nd* nínú ìdààmú wọn,
|
||
\q2 ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀,
|
||
\q2 ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀
|
||
\q2 àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn
|
||
\q2 kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 33 Ó sọ odò di aginjù,
|
||
\q2 àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀
|
||
\q2 nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 35 O sọ aginjù di adágún omi àti
|
||
\q2 ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
|
||
\q1
|
||
\v 36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà,
|
||
\q2 wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
|
||
\q1
|
||
\v 37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà
|
||
\q2 tí yóò máa so èso tí ó dára;
|
||
\q1
|
||
\v 38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye
|
||
\q2 kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú,
|
||
\q2 ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
|
||
\q1
|
||
\v 40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé
|
||
\q2 ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
|
||
\q1
|
||
\v 41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira
|
||
\q2 ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
|
||
\q1
|
||
\v 42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn
|
||
\q2 ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí
|
||
\q2 kí ó wo títóbi ìfẹ́ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 108
|
||
\cl Saamu 108
|
||
\d Orin. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 108.1-5: \xt Sm 57.7-11.\x*Ọlọ́run, ọkàn mi dúró ṣinṣin
|
||
\q2 èmi ó máa kọrin, èmi ó máa fi ọkàn mi kọrin.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Jí ohun èlò orin àti haapu!
|
||
\q2 Èmi ó jí ní kùtùkùtù,
|
||
\q1
|
||
\v 3 èmi ó yìn ọ́, \nd Olúwa\nd*, nínú àwọn orílẹ̀-èdè,
|
||
\q2 èmi ó kọrin rẹ nínú àwọn ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí tí o tóbi ní àánú rẹ
|
||
\q2 ju àwọn ọ̀run lọ
|
||
\q2 àti òdodo rẹ dé àwọsánmọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Gbé ara rẹ ga, Ọlọ́run, lórí àwọn ọ̀run,
|
||
\q2 àti ògo rẹ lórí gbogbo ayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 \x - \xo 108.6-13: \xt Sm 60.5-12.\x*Kí a sì lè gba àwọn olùfẹ́ rẹ là;
|
||
\q2 fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ìgbàlà,
|
||
\q2 kí o sì dá mi lóhùn
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀ pé,
|
||
\q2 “Èmi yóò yọ̀, èmi yóò pín Ṣekemu,
|
||
\q2 èmi yóò sì wọn àfonífojì Sukkoti kúrò.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Gileadi ni tèmi, Manase ni tèmi,
|
||
\q2 Efraimu ni ìbòrí mi,
|
||
\q2 Juda ni olófin mi,
|
||
\q1
|
||
\v 9 Moabu sì ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi,
|
||
\q2 lórí Edomu ni èmi ó bọ́ bàtà mi sí,
|
||
\q2 lórí òkè Filistia ni èmi yóò hó ìhó ayọ̀.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi?
|
||
\q2 Ta ni yóò sìn mí wá sí Edomu?
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ìwọ Ọlọ́run ha kọ́, ìwọ tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀.
|
||
\q2 Ọlọ́run ìwọ kì yóò bá àwọn jagunjagun wa jáde mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ nínú ìpọ́njú,
|
||
\q2 nítorí ìrànlọ́wọ́ ènìyàn asán ni.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nípasẹ̀ Ọlọ́run ni àwa ó ṣe akin
|
||
\q2 nítorí òun ó tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
|
||
\c 109
|
||
\cl Saamu 109
|
||
\d Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún,
|
||
\q2 má ṣe dákẹ́,
|
||
\q1
|
||
\v 2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn
|
||
\q2 ti ya ẹnu wọn sí mi
|
||
\q2 wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri;
|
||
\q2 wọ́n bá mi jà láìnídìí
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi
|
||
\q2 àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ
|
||
\q2 jẹ́ kí àwọn olùfisùn
|
||
\q2 dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́
|
||
\q2 kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 8 \x - \xo 109.8: \xt Ap 1.20.\x*Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú;
|
||
\q2 kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba
|
||
\q2 kí aya rẹ̀ sì di opó.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri
|
||
\q2 kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní
|
||
\q2 jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un
|
||
\q2 tàbí kí wọn káàánú lórí
|
||
\q2 àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò
|
||
\q2 kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí
|
||
\q2 ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q2 Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú,
|
||
\q2 kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀:
|
||
\q2 bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara,
|
||
\q2 àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ \nd Olúwa\nd* wá;
|
||
\q2 àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi \nd Olúwa\nd* Olódùmarè,
|
||
\q2 ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ.
|
||
\q2 Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí,
|
||
\q2 àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́,
|
||
\q2 mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà
|
||
\q2 ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
|
||
\q1
|
||
\v 25 \x - \xo 109.25: \xt Mt 27.39; Mk 15.29.\x*Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi;
|
||
\q2 nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ràn mí lọ́wọ́, \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run mi;
|
||
\q2 gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí
|
||
\q2 wí pé ìwọ, \nd Olúwa\nd*, ni ó ṣe é.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre,
|
||
\q2 nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú
|
||
\q2 kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin \nd Olúwa\nd* gidigidi
|
||
\q2 ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní
|
||
\q2 láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.
|
||
\c 110
|
||
\cl Saamu 110
|
||
\d Ti Dafidi. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 110.1: \xt Mt 22.44; 26.64; Mk 12.36; 14.62; 16.19; Lk 20.42-43; 22.69; Ap 2.34; 1Kọ 15.25; Ef 1.20; Kl 3.1; Hb 1.3,13; 10.12-13; 12.2.\x*\nd Olúwa\nd* sọ fún Olúwa mi pé,
|
||
\b
|
||
\q1 “Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi,
|
||
\q2 títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ
|
||
\q2 di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd* yóò na ọ̀pá agbára rẹ̀
|
||
\q2 láti Sioni wá, ìwọ jẹ ọba láàrín àwọn ọ̀tá rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Àwọn ènìyàn rẹ jẹ́ ọ̀rẹ́ àtinúwá
|
||
\q2 ní ọjọ́ ìjáde ogun rẹ, nínú ẹwà mímọ́,
|
||
\q2 láti inú òwúrọ̀ wá ìwọ ni ìrì ẹwà rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 110.4: \xt Hb 5.6,10; 6.20; 7.11,15,21.\x*\nd Olúwa\nd* ti búra,
|
||
\q2 kò sì í yí ọkàn padà pé,
|
||
\q1 “Ìwọ ni àlùfáà,
|
||
\q2 ní ipasẹ̀ Melkisedeki.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 \nd Olúwa\nd*, ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni
|
||
\q2 yóò lu àwọn ọba bolẹ̀ ni ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Yóò ṣe ìdájọ́ láàrín kèfèrí,
|
||
\q2 yóò kún ibùgbé wọn pẹ̀lú òkú ara;
|
||
\q2 yóò fọ́n àwọn olórí ká sí orí ilẹ̀ ayé tí ó gbòòrò.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Yóò mu nínú odò ṣíṣàn ní ọ̀nà:
|
||
\q2 nítorí náà ni yóò ṣe gbé orí sókè.
|
||
\c 111
|
||
\cl Saamu 111
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ máa yin \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1 Èmi yóò máa yin \nd Olúwa\nd* pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi,
|
||
\q2 ní àwùjọ àwọn olóòtítọ́, àti ní ìjọ ènìyàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Iṣẹ́ \nd Olúwa\nd* tóbi, àwọn tí ó ní inú dídùn, ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Iṣẹ́ rẹ̀ ni ọláńlá àti ògo:
|
||
\q2 àti òdodo rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ó ti ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, láti máa rántí:
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ni olóore-ọ̀fẹ́ àti pé ó kún fún àánú.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ó ti fi oúnjẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀:
|
||
\q2 òun ń rántí májẹ̀mú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ó ti fihan àwọn ènìyàn rẹ̀ agbára iṣẹ́ rẹ̀
|
||
\q2 láti fún wọn ní ilẹ̀ ìlérí ní ìní.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ jẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́;
|
||
\q2 gbogbo òfin rẹ̀ sì dájú.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Wọ́n dúró láé àti láé,
|
||
\q2 ní òtítọ́ àti òdodo ni a ṣe wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ó rán ìràpadà sí àwọn ènìyàn rẹ̀:
|
||
\q2 ó pàṣẹ májẹ̀mú rẹ̀ títí láé,
|
||
\q2 mímọ́ àti ọ̀wọ̀ ni orúkọ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ìbẹ̀rù \nd Olúwa\nd* ni ìpilẹ̀ṣẹ̀ ọgbọ́n:
|
||
\q2 òye dáradára ni yóò máa ṣe òfin rẹ̀,
|
||
\q2 ìyìn rẹ̀ dúró láé.
|
||
\c 112
|
||
\cl Saamu 112
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run,
|
||
\q2 tí ó ní inú dídùn ńlá sí àwọn òfin rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Irú-ọmọ rẹ̀ yóò jẹ́ alágbára ní ayé:
|
||
\q2 ìran àwọn olóòtítọ́ ni a ó bùkún fún.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọlá àti ọrọ̀ yóò wà nínú ilé rẹ̀;
|
||
\q2 òdodo rẹ̀ sì dúró láé.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Fún olóòótọ́ ni ìmọ́lẹ̀ yóò tàn fún ní òkùnkùn:
|
||
\q2 olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú àti òdodo.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ènìyàn rere fi ojúrere hàn,
|
||
\q2 a sì wínni;
|
||
\q2 ìmòye ni yóò máa fi la ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Dájúdájú a kì yóò le yí ní ipò padà láéláé:
|
||
\q2 olódodo ni a ó máa ṣe ìrántí rẹ láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Òun kì yóò béèrè ìyìn búburú:
|
||
\q2 ọkàn rẹ̀ ti dúró, ó ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ó ti mú ọkàn rẹ̀ gbilẹ̀, ẹ̀rù kí yóò bà á,
|
||
\q2 títí yóò fi rí ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 \x - \xo 112.9: \xt 2Kọ 9.9.\x*Ó ti pín ká, ó ti fi fún àwọn olùpọ́njú,
|
||
\q2 nítorí òdodo rẹ̀ dúró láé;
|
||
\q2 ìwo rẹ̀ ní a ó gbé sókè pẹ̀lú ọlá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ènìyàn búburú yóò ri, inú wọn yóò sì bàjẹ́,
|
||
\q2 yóò sì pa eyín keke, yó sì yọ dànù:
|
||
\q2 èròǹgbà ọkàn ènìyàn búburú ni yóò ṣègbé.
|
||
\c 113
|
||
\cl Saamu 113
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ máa yin \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1 Yìn ín ẹ̀yin ìránṣẹ́ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q1 ẹ yin orúkọ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Fi ìbùkún fún orúkọ \nd Olúwa\nd* láti
|
||
\q2 ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀
|
||
\q2 orúkọ \nd Olúwa\nd* ni kí a máa yìn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 \nd Olúwa\nd* ga lórí gbogbo orílẹ̀-èdè,
|
||
\q2 àti ògo rẹ̀ lórí àwọn ọ̀run.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ta ló dàbí \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa,
|
||
\q2 tí ó gbé ní ibi gíga.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Tí ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ láti wò
|
||
\q2 òun tí ó ń bẹ lọ́run, àti nínú ayé!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ó gbé òtòṣì dìde láti inú erùpẹ̀,
|
||
\q2 àti pé ó gbé aláìní sókè láti inú ààtàn wá.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Kí ó le mú un jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé
|
||
\q2 àní pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé àwọn ènìyàn rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ó mú àgàn obìnrin gbé inú ilé,
|
||
\q2 àti láti jẹ́ aláyọ̀ ìyá fún àwọn ọmọ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ yin \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 114
|
||
\cl Saamu 114
|
||
\q1
|
||
\v 1 Nígbà tí Israẹli jáde ní Ejibiti,
|
||
\q2 ilé Jakọbu láti inú ènìyàn àjèjì èdè
|
||
\q1
|
||
\v 2 Juda wà ní ibi mímọ́,
|
||
\q2 Israẹli wà ní ìjọba.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 \x - \xo 114.3: \xt El 14.21; Jo 3.16.\x*Òkun sì rí i, ó sì wárìrì:
|
||
\q2 Jordani sì padà sẹ́yìn.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àwọn òkè ńlá ń fò bí àgbò àti
|
||
\q2 òkè kéékèèké bí ọ̀dọ́-àgùntàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Kí ni ó ṣe ọ́, ìwọ Òkun, tí ìwọ fi wárìrì?
|
||
\q2 Ìwọ Jordani, tí ìwọ fi padà sẹ́yìn?
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ẹ̀yin òkè ńlá kí ló dé ti ẹ fi ń fò bí àgbò,
|
||
\q2 àti ẹ̀yin òkè kéékèèké bí ọ̀dọ́-àgùntàn?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Wárìrì, ìwọ ilẹ̀, níwájú \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 ní iwájú Ọlọ́run Jakọbu
|
||
\q1
|
||
\v 8 tí ó sọ àpáta di adágún omi,
|
||
\q2 àti òkúta-ìbọn di orísun omi.
|
||
\c 115
|
||
\cl Saamu 115
|
||
\q1
|
||
\v 1 Kì í ṣe fún wa, \nd Olúwa\nd* kì í ṣe fún wa,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n fún orúkọ rẹ ni a fi ògo fún,
|
||
\q2 fún àánú àti òtítọ́ rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Torí kí ni àwọn kèfèrí yóò ṣe sọ pé,
|
||
\q2 níbo ni Ọlọ́run wa wà.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run:
|
||
\q2 tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú.
|
||
\q1
|
||
\v 4 \x - \xo 115.4-8: \xt Sm 135.15-18.\x*Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà,
|
||
\q2 iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀,
|
||
\q2 wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀:
|
||
\q2 wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbóòórùn.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó,
|
||
\q2 wọ́n ní ẹsẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn;
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn;
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìwọ Israẹli gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ẹ̀ yin ilé Aaroni, gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*, gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 òun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 \nd Olúwa\nd* tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Israẹli;
|
||
\q2 yóò bùkún ilé Aaroni.
|
||
\q1
|
||
\v 13 \x - \xo 115.13: \xt If 11.18; 19.5.\x*Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 àti kékeré àti ńlá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 14 \nd Olúwa\nd* yóò mú ọ pọ̀ sí i síwájú àti síwájú,
|
||
\q2 ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ẹ fi ìbùkún fún \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ọ̀run àní ọ̀run ni ti \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ayé ló fi fún ọmọ ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Òkú kò lè yìn \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 tàbí ẹni tí ó ti lọ sí ìsàlẹ̀ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ṣùgbọ́n àwa ó fi ìbùkún fún \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ yin \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 116
|
||
\cl Saamu 116
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi fẹ́ràn \nd Olúwa\nd*, nítorí ó gbọ́ ohùn mi;
|
||
\q2 ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi,
|
||
\q2 èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Okùn ikú yí mi ká,
|
||
\q2 ìrora isà òkú wá sórí mi;
|
||
\q2 ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 “\nd Olúwa\nd*, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 \nd Olúwa\nd* ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo;
|
||
\q2 Ọlọ́run wa kún fún àánú.
|
||
\q1
|
||
\v 6 \nd Olúwa\nd* pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́
|
||
\q2 nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ,
|
||
\q2 nítorí \nd Olúwa\nd* ṣe dáradára sí ọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Nítorí ìwọ, \nd Olúwa\nd*, ti gba ọkàn mi
|
||
\q2 kúrò lọ́wọ́ ikú,
|
||
\q1 ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé,
|
||
\q2 àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
|
||
\q1
|
||
\v 9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ní ilẹ̀ alààyè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 \x - \xo 116.10: \xt 2Kọ 4.13.\x*Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé,
|
||
\q2 “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé,
|
||
\q2 “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Kí ni èmi yóò san fún \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè
|
||
\q2 èmi yóò sì máa ké pe orúkọ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Iyebíye ní ojú \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 16 \nd Olúwa\nd*, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́;
|
||
\q2 èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ;
|
||
\q2 ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ
|
||
\q2 èmi yóò sì ké pe orúkọ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 19 nínú àgbàlá ilé \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ yin \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 117
|
||
\cl Saamu 117
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 117.1: \xt Ro 15.11.\x*Ẹ yin \nd Olúwa\nd*, gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè;
|
||
\q2 ẹ pòkìkí rẹ̀, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nítorí ìfẹ́ ńlá rẹ̀ tí ó ní sí wa,
|
||
\q2 àti òtítọ́ \nd Olúwa\nd* dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ yin \nd Olúwa\nd*!
|
||
\c 118
|
||
\cl Saamu 118
|
||
\q1
|
||
\v 1 \x - \xo 118.1: \xt 1Ki 16.34; 2Ki 5.13; 7.3; Es 3.11; Sm 100.5; 106.1; 107.1; 136.1; Jr 33.11.\x*Ẹ fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd*, nítorí tí ó dára;
|
||
\q2 àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé:
|
||
\q2 “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé:
|
||
\q2 “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd* wí pé:
|
||
\q2 “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 \x - \xo 118.6: \xt Hb 13.6.\x*\nd Olúwa\nd* ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù.
|
||
\q2 Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
|
||
\q1
|
||
\v 7 \nd Olúwa\nd* ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi.
|
||
\q2 Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ní orúkọ \nd Olúwa\nd* èmi gé wọn kúrò.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ní orúkọ \nd Olúwa\nd* èmi gé wọn dànù.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún;
|
||
\q2 ní orúkọ \nd Olúwa\nd* èmi ké wọn dànù.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n \nd Olúwa\nd* ràn mí lọ́wọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 14 \nd Olúwa\nd* ni agbára àti orin mi;
|
||
\q2 ó sì di ìgbàlà mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo:
|
||
\q2 “Ọwọ́ ọ̀tún \nd Olúwa\nd* ń ṣe ohun agbára!
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ọwọ́ ọ̀tún \nd Olúwa\nd* ní a gbéga;
|
||
\q2 ọwọ́ ọ̀tún \nd Olúwa\nd* ń ṣe ohun agbára!”
|
||
\q1
|
||
\v 17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè,
|
||
\q2 èmi yóò pòkìkí ohun tí \nd Olúwa\nd* ṣe.
|
||
\q1
|
||
\v 18 \nd Olúwa\nd* bá mi wí gidigidi,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi:
|
||
\q2 èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Èyí ni ìlẹ̀kùn \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn;
|
||
\q2 ìwọ sì di ìgbàlà mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 22 \x - \xo 118.22-23: \xt Mt 21.42; Mk 12.10-11; Lk 20.17; Ap 4.11; 1Pt 2.7.\x*Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀,
|
||
\q2 ni ó di pàtàkì igun ilé;
|
||
\q1
|
||
\v 23 \nd Olúwa\nd* ti ṣe èyí,
|
||
\q2 ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Èyí ni ọjọ́ tí \nd Olúwa\nd* dá:
|
||
\q2 ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 \x - \xo 118.25-26: \xt Mt 21.9; 23.39; Mk 11.9-10; Lk 13.35; 19.38; Jh 12.13.\x*\nd Olúwa\nd*, gbà wá;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, fún wa ní àlàáfíà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q2 Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé \nd Olúwa\nd* wá.
|
||
\q1
|
||
\v 27 \nd Olúwa\nd* ni Ọlọ́run,
|
||
\q2 ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára
|
||
\q2 pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́
|
||
\q1 ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀
|
||
\q2 ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ;
|
||
\q2 ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 29 Ẹ fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd*, nítorí tí ó ṣeun;
|
||
\q2 nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\c 119
|
||
\cl Saamu 119
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀,
|
||
\q2 ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́
|
||
\q2 tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára;
|
||
\q2 wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀
|
||
\q2 kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin
|
||
\q2 láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
|
||
\q1
|
||
\v 6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí
|
||
\q2 nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin
|
||
\q2 bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀,
|
||
\q2 má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́?
|
||
\q1 Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi
|
||
\q2 kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ìyìn ni fún \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò
|
||
\q2 gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ,
|
||
\q2 bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ
|
||
\q2 èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ;
|
||
\q2 èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè;
|
||
\q2 èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí
|
||
\q2 ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé,
|
||
\q2 má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà
|
||
\q2 nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún
|
||
\q2 tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi,
|
||
\q2 nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀,
|
||
\q2 wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi;
|
||
\q2 àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀;
|
||
\q2 ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn;
|
||
\q2 kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ:
|
||
\q2 nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́;
|
||
\q2 fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn
|
||
\q2 fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́
|
||
\q2 èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 31 Èmi yára di òfin rẹ mú. \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
|
||
\q1
|
||
\v 32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ,
|
||
\q2 nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 33 Kọ́ mi, \nd Olúwa\nd*, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ;
|
||
\q2 nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
|
||
\q1
|
||
\v 34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
|
||
\q2 èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
|
||
\q1
|
||
\v 35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí,
|
||
\q2 nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
|
||
\q1
|
||
\v 36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ
|
||
\q2 kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán:
|
||
\q2 pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ,
|
||
\q2 nítorí òfin rẹ dára.
|
||
\q1
|
||
\v 39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù
|
||
\q2 nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
|
||
\q1
|
||
\v 40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ!
|
||
\q2 Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 42 Nígbà náà ni èmi yóò dá
|
||
\q2 ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn,
|
||
\q2 nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi
|
||
\q2 nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo
|
||
\q2 láé àti láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira,
|
||
\q2 nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
|
||
\q1
|
||
\v 46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba
|
||
\q2 ojú kì yóò sì tì mí,
|
||
\q1
|
||
\v 47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ
|
||
\q2 nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn,
|
||
\q2 èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ,
|
||
\q2 nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
|
||
\q1
|
||
\v 50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí:
|
||
\q2 ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú,
|
||
\q2 tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi
|
||
\q2 níbikíbi tí èmi ń gbé.
|
||
\q1
|
||
\v 55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
|
||
\q1
|
||
\v 56 nítorí tí mo
|
||
\q2 gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 57 Ìwọ ni ìpín mi, \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi:
|
||
\q2 fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi
|
||
\q2 èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra
|
||
\q2 láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn,
|
||
\q2 èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ
|
||
\q2 nítorí òfin òdodo rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ,
|
||
\q2 sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 kọ́ mi ní òfin rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere,
|
||
\q2 nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni;
|
||
\q2 kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí,
|
||
\q2 èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
|
||
\q1
|
||
\v 70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú
|
||
\q2 nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ
|
||
\q2 ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí;
|
||
\q2 fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi,
|
||
\q2 nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 75 Èmi mọ, \nd Olúwa\nd*, nítorí òfin rẹ òdodo ni,
|
||
\q2 àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
|
||
\q1
|
||
\v 76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi,
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè,
|
||
\q2 nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga
|
||
\q2 nítorí wọn pa mí lára láìnídìí
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi,
|
||
\q2 àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ,
|
||
\q2 kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ;
|
||
\q2 èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
|
||
\q1
|
||
\v 83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín,
|
||
\q2 èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó?
|
||
\q2 Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn
|
||
\q2 tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
|
||
\q1
|
||
\v 85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi,
|
||
\q2 tí ó lòdì sí òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé;
|
||
\q2 ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
|
||
\q1
|
||
\v 87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ,
|
||
\q2 èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 89 Ọ̀rọ̀ rẹ, \nd Olúwa\nd*, títí láé ni;
|
||
\q2 ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
|
||
\q1
|
||
\v 90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran;
|
||
\q2 ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 91 Òfin rẹ dúró di òní
|
||
\q2 nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi,
|
||
\q2 èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé,
|
||
\q2 nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ
|
||
\q2 èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó!
|
||
\q2 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀
|
||
\q1 ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
|
||
\q1
|
||
\v 98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ,
|
||
\q2 nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
|
||
\q1
|
||
\v 99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ,
|
||
\q2 nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ,
|
||
\q2 nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi
|
||
\q2 nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ,
|
||
\q2 nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó,
|
||
\q2 ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
|
||
\q1
|
||
\v 104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ;
|
||
\q2 nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi
|
||
\q2 àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
|
||
\q1
|
||
\v 106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn
|
||
\q2 wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 107 A pọ́n mi lójú gidigidi;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
|
||
\q1
|
||
\v 108 \nd Olúwa\nd*, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi,
|
||
\q2 kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo,
|
||
\q2 èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé;
|
||
\q2 àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
|
||
\q1
|
||
\v 112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́
|
||
\q2 láé dé òpin.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi;
|
||
\q2 èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú,
|
||
\q2 kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
|
||
\q1
|
||
\v 116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ,
|
||
\q2 kí èmi kí ó lè yè
|
||
\q2 Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
|
||
\q1
|
||
\v 117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu;
|
||
\q2 nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ,
|
||
\q2 nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
|
||
\q1
|
||
\v 119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́;
|
||
\q2 nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀:
|
||
\q2 èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́:
|
||
\q2 má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
|
||
\q1
|
||
\v 122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú:
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
|
||
\q1
|
||
\v 123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ,
|
||
\q2 fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ
|
||
\q2 kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye
|
||
\q2 kí èmi lè ní òye òfin rẹ
|
||
\q1
|
||
\v 126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 nítorí òfin rẹ ti fọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ
|
||
\q2 ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
|
||
\q1
|
||
\v 128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀,
|
||
\q2 èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni:
|
||
\q2 nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá;
|
||
\q2 ó fi òye fún àwọn òpè.
|
||
\q1
|
||
\v 131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ,
|
||
\q2 nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi,
|
||
\q2 bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn
|
||
\q2 tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ,
|
||
\q2 má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn,
|
||
\q2 kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára
|
||
\q2 kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 136 Omijé sàn jáde ní ojú mi,
|
||
\q2 nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 137 Olódodo ni ìwọ \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo:
|
||
\q2 wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
|
||
\q1
|
||
\v 139 Ìtara mi ti pa mí run,
|
||
\q2 nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
|
||
\q1
|
||
\v 140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá
|
||
\q2 ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn
|
||
\q2 èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 142 Òdodo rẹ wà títí láé
|
||
\q2 òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
|
||
\q1
|
||
\v 144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé;
|
||
\q2 fún mi ní òye kí èmi lè yè.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi:
|
||
\q2 dá mi lóhùn \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí
|
||
\q2 èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́;
|
||
\q2 èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru,
|
||
\q2 nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ:
|
||
\q2 pa ayé mi mọ́, \nd Olúwa\nd*, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ
|
||
\q2 tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí,
|
||
\q2 nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà;
|
||
\q2 pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú
|
||
\q2 nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́
|
||
\q2 nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ;
|
||
\q2 pa ayé mi mọ́, \nd Olúwa\nd*, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ;
|
||
\q2 gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ
|
||
\q2 bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe
|
||
\q2 ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́
|
||
\q2 nítorí òfin òdodo rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ,
|
||
\q2 kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́,
|
||
\q2 nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ,
|
||
\q2 nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ;
|
||
\q2 gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde,
|
||
\q2 nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ,
|
||
\q2 nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
|
||
\q1
|
||
\v 173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́,
|
||
\q2 nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́,
|
||
\q2 kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
|
||
\q1
|
||
\v 176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù.
|
||
\q2 Wá ìránṣẹ́ rẹ,
|
||
\q2 nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
|
||
\c 120
|
||
\cl Saamu 120
|
||
\d Orin fún ìgòkè.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi ké pe \nd Olúwa\nd* nínú ìpọ́njú mi,
|
||
\q2 ó sì dá mi lóhùn.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Gbà mí, \nd Olúwa\nd*, kúrò lọ́wọ́ ètè èké
|
||
\q2 àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kí ni kí a fi fún ọ?
|
||
\q2 Àti kí ni kí a túnṣe fún ọ,
|
||
\q2 ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?
|
||
\q1
|
||
\v 4 Òun yóò bá ọ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun,
|
||
\q2 pẹ̀lú ẹ̀yín iná igi ìgbálẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Meṣeki,
|
||
\q2 nítorí èmi gbé nínú àgọ́ ìlú Kedari!
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé
|
||
\q2 láàrín àwọn tí ó kórìíra àlàáfíà.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ènìyàn àlàáfíà ni mí;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni dúró fun wọn.
|
||
\c 121
|
||
\cl Saamu 121
|
||
\d Orin fún ìgòkè.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi yóò gbé ojú mi sórí òkè wọ̀n-ọn-nì—
|
||
\q2 níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi yóò ti wá?
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìrànlọ́wọ́ mi tí ọwọ́ \nd Olúwa\nd* wá,
|
||
\q2 ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Òun kì yóò jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó yẹ̀;
|
||
\q2 ẹni tí ó pa ọ́ mọ́ kì í tòògbé.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Kíyèsi, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́,
|
||
\q2 kì í tòògbé bẹ́ẹ̀ ni kì í sùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 \nd Olúwa\nd* ni olùpamọ́ rẹ;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ní òjìji rẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Oòrùn kì yóò pa ọ́ ní ìgbà ọ̀sán
|
||
\q2 tàbí òṣùpá ní ìgbà òru.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 \nd Olúwa\nd* yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ibi gbogbo
|
||
\q2 yóò pa ọkàn rẹ mọ́
|
||
\q1
|
||
\v 8 \nd Olúwa\nd* yóò pa àlọ àti ààbọ̀ rẹ mọ́
|
||
\q2 láti ìgbà yìí lọ àti títí láéláé.
|
||
\c 122
|
||
\cl Saamu 122
|
||
\d Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Inú mi dùn nígbà tí wọ́n wí fún mi pé,
|
||
\q2 “Ẹ jẹ́ kí á lọ sílé \nd Olúwa\nd*.”
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹsẹ̀ wa yóò dúró ní ẹnu ibodè rẹ,
|
||
\q2 ìwọ Jerusalẹmu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Jerusalẹmu, ìwọ tí a kọ́ bí ìlú
|
||
\q2 tí o fi ara mọ́ra pọ̀ ṣọ̀kan.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Níbi tí àwọn ẹ̀yà máa ń gòkè lọ,
|
||
\q2 àwọn ẹ̀yà \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q1 ẹ̀rí fún Israẹli,
|
||
\q2 láti máa dúpẹ́ fún orúkọ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí ibẹ̀ ni a gbé ìtẹ́ ìdájọ́ kalẹ̀,
|
||
\q2 àwọn ìtẹ́ ilé Dafidi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Gbàdúrà fún àlàáfíà Jerusalẹmu;
|
||
\q2 àwọn tí ó fẹ́ ọ yóò ṣe rere.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Kí àlàáfíà kí ó wà nínú odi rẹ̀,
|
||
\q2 àti ìre nínú ààfin rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Nítorí àwọn ọkùnrin àti àwọn ẹgbẹ́ mi
|
||
\q2 èmi yóò wí nísinsin yìí pé,
|
||
\q2 kí àlàáfíà kí ó wà nínú rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Nítorí ilé \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa,
|
||
\q2 èmi yóò máa wá ìre rẹ̀.
|
||
\c 123
|
||
\cl Saamu 123
|
||
\d Orin fún ìgòkè.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìwọ ní mo gbé ojú mí sókè sí,
|
||
\q2 ìwọ tí ń gbé inú ọ̀run.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Kíyèsi, bí ojú àwọn
|
||
\q2 ìránṣẹ́kùnrin ti máa ń wo ọwọ́ àwọn baba wọn,
|
||
\q2 àti bí ojú ìránṣẹ́bìnrin ti máa ń wo ọwọ́ ìyá rẹ̀
|
||
\q1 bẹ́ẹ̀ ni ojú wa ń wo \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run wa,
|
||
\q2 títí yóò fi ṣàánú fún wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 \nd Olúwa\nd*, ṣàánú fún wa, ṣàánú fún wa;
|
||
\q2 nítorí tí a kún fún ẹ̀gàn púpọ̀púpọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ọkàn wa kún púpọ̀
|
||
\q2 fún ẹ̀gàn àwọn onírera,
|
||
\q2 àti fún ẹ̀gàn àwọn agbéraga.
|
||
\c 124
|
||
\cl Saamu 124
|
||
\d Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 “Ìbá má ṣe pé \nd Olúwa\nd* tí ó ti wà fún wa,”
|
||
\q2 kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
|
||
\q1
|
||
\v 2 ìbá má ṣe pé \nd Olúwa\nd* tó wà ní tiwa,
|
||
\q2 nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
|
||
\q1
|
||
\v 3 nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè
|
||
\q2 nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
|
||
\q1
|
||
\v 4 nígbà náà ni omi
|
||
\q2 wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
|
||
\q1
|
||
\v 5 nígbà náà ni agbéraga
|
||
\q1 omi ìbá borí ọkàn wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Olùbùkún ni \nd Olúwa\nd*, tí kò fi wá fún wọ́n
|
||
\q2 bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ;
|
||
\q2 okùn já àwa sì yọ.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 tí ó dá ọ̀run òun ayé.
|
||
\c 125
|
||
\cl Saamu 125
|
||
\d Orin fún ìgòkè.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé \nd Olúwa\nd* yóò dàbí òkè Sioni,
|
||
\q2 tí a kò lè ṣí ní ìdí, bí kò ṣe pé ó dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Bí òkè ńlá ti yí Jerusalẹmu ká,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni \nd Olúwa\nd* yí ènìyàn ká
|
||
\q2 láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí tí ọ̀pá àwọn ènìyàn búburú
|
||
\q2 kì yóò bà lé ìpín àwọn olódodo;
|
||
\q1 kí àwọn olódodo kí ó máa ba à
|
||
\q2 fi ọwọ́ wọn lé ẹ̀ṣẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 \nd Olúwa\nd* ṣe rere fún àwọn ẹni rere,
|
||
\q2 àti fún àwọn tí àyà wọn dúró ṣinṣin.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Bí ó ṣe ti irú àwọn tí wọn yà sí ipa ọ̀nà wíwọ́ wọn;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* yóò jẹ́ kí wọn lọ pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1 Ṣùgbọ́n àlàáfíà yóò wà lórí Israẹli.
|
||
\c 126
|
||
\cl Saamu 126
|
||
\d Orin fún ìgòkè.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Nígbà tí \nd Olúwa\nd* mú ìkólọ Sioni padà,
|
||
\q2 àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín,
|
||
\q2 àti ahọ́n wa kọ orin;
|
||
\q1 nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ṣe ohun ńlá fún wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 3 \nd Olúwa\nd* ṣe ohun ńlá fún wa;
|
||
\q2 nítorí náà àwa ń yọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 \nd Olúwa\nd* mú ìkólọ wa padà,
|
||
\q2 bí ìṣàn omi ní gúúsù.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn
|
||
\q2 yóò fi ayọ̀ ka.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ,
|
||
\q2 tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́,
|
||
\q1 lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá,
|
||
\q2 yóò sì ru ìtí rẹ̀.
|
||
\c 127
|
||
\cl Saamu 127
|
||
\d Orin fún ìgòkè. Ti Solomoni.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Bí kò ṣe pé \nd Olúwa\nd* bá kọ́ ilé náà
|
||
\q2 àwọn tí ń kọ́ ọ ń ṣiṣẹ́ lásán ni;
|
||
\q2 bí kò ṣe pé \nd Olúwa\nd* bá pa ìlú mọ́, olùṣọ́ jí lásán.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Asán ni fún ẹ̀yin ti ẹ dìde ní kùtùkùtù
|
||
\q2 láti pẹ́ dùbúlẹ̀, láti jẹ oúnjẹ làálàá;
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ó ń fi ìre fún olùfẹ́ rẹ̀ lójú ọ̀run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Kíyèsi i, àwọn ọmọ ni ìní \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 ọmọ inú sì ni èrè rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Bí ọfà ti rí ní ọwọ́ alágbára,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ èwe.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí apó rẹ̀ kún fún wọn;
|
||
\q2 ojú kì yóò tì wọ́n,
|
||
\q2 ṣùgbọ́n wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá ní ẹnu-ọ̀nà.
|
||
\c 128
|
||
\cl Saamu 128
|
||
\d Orin fún ìgòkè.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìbùkún ni fún gbogbo ẹni tí ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 tí ó sì ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nítorí tí ìwọ yóò jẹ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ
|
||
\q2 ìbùkún ni fún ọ; yóò sì dára fún ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Obìnrin rẹ yóò dàbí àjàrà rere
|
||
\q2 eléso púpọ̀ ní àárín ilé rẹ;
|
||
\q2 àwọn ọmọ rẹ yóò dàbí igi olifi tí ó yí tábìlì rẹ ká.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Kíyèsi i pé, bẹ́ẹ̀ ni a ó bùsi i fún ọkùnrin náà,
|
||
\q2 tí ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Kí \nd Olúwa\nd* kí ó bùsi i fún ọ láti Sioni wá,
|
||
\q2 kí ìwọ kí ó sì máa rí ìre
|
||
\q1 Jerusalẹmu ní ọjọ́ ayé rẹ gbogbo.
|
||
\q2
|
||
\v 6 Bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó sì máa rí àti ọmọdọ́mọ rẹ.
|
||
\q1 Láti àlàáfíà lára Israẹli.
|
||
\c 129
|
||
\cl Saamu 129
|
||
\d Orin fún ìgòkè.
|
||
\q1
|
||
\v 1 “Ìgbà púpọ̀ ni wọ́n ti pọ́n mi lójú
|
||
\q2 láti ìgbà èwe mi wá,”
|
||
\q2 jẹ́ kí Israẹli kí ó wí nísinsin yìí;
|
||
\q1
|
||
\v 2 “Ìgbà púpọ̀ ni wọ́n ti pọ́n mi lójú
|
||
\q2 láti ìgbà èwe mi wá;
|
||
\q2 síbẹ̀ wọn kò tí ì borí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Àwọn awalẹ̀ walẹ̀ sí ẹ̀yìn mi:
|
||
\q2 wọ́n sì la aporo wọn gígùn.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Olódodo ni \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 ó ti ké okùn àwọn ènìyàn búburú kúrò.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Kí gbogbo àwọn tí ó kórìíra Sioni kí ó dààmú,
|
||
\q2 kí wọn kí ó sì yí ẹ̀yìn padà.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Kí wọn kí ó dàbí koríko orí ilẹ̀
|
||
\q2 tí ó gbẹ dànù kí ó tó dàgbàsókè,
|
||
\q1
|
||
\v 7 èyí tí olóko pípa kó kún ọwọ́ rẹ̀:
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń di ìtí, kó kún apá rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ń kọjá lọ kò wí pé,
|
||
\q2 ìbùkún \nd Olúwa\nd* kí ó pẹ̀lú yín:
|
||
\q2 àwa ń súre fún yin ní orúkọ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 130
|
||
\cl Saamu 130
|
||
\d Orin fún ìgòkè.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Láti inú ibú wá ni
|
||
\q2 èmi ń ké pè é ọ́ \nd Olúwa\nd*
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd*, gbóhùn mi,
|
||
\q2 jẹ́ kí etí rẹ kí o tẹ́ sílẹ̀ sí ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 \x - \xo 130.3: \xt Sm 143.2; Ro 3.20; Ga 2.16.\x*\nd Olúwa\nd*, ìbá ṣe pé kí ìwọ máa sàmì ẹ̀ṣẹ̀,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, tá ni ìbá dúró.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí ìdáríjì wà lọ́dọ̀ rẹ,
|
||
\q2 kí a lè máa bẹ̀rù rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Èmi dúró de \nd Olúwa\nd*, ọkàn mi dúró,
|
||
\q2 àti nínú ọ̀rọ̀ rẹ ni èmi ń ṣe ìrètí.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ọkàn mi dúró de \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ,
|
||
\q2 àní ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Israẹli, ìwọ ní ìrètí ní ti \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 nítorí pé lọ́dọ̀ \nd Olúwa\nd* ni àánú wà,
|
||
\q2 àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìdáǹdè wà.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Òun ó sì dá Israẹli ní ìdè
|
||
\q2 kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ gbogbo.
|
||
\c 131
|
||
\cl Saamu 131
|
||
\d Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd* àyà mi kò gbéga,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ojú mi kò gbé sókè:
|
||
\q1 bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi ọwọ́ mi lé ọ̀ràn ńlá,
|
||
\q2 tàbí lé ohun tí ó ga jù mí lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Nítòótọ́ èmi mú ọkàn mi sinmi,
|
||
\q2 mo sì mú un dákẹ́ jẹ́ẹ́,
|
||
\q1 bí ọmọ tí a ti ọwọ́ ìyá rẹ̀ gbà ní ẹnu ọmú:
|
||
\q2 ọkàn mi rí gẹ́gẹ́ bí ọmọ tí a já ní ẹnu ọmú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Israẹli, ìwọ ní ìrètí ní ti \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 láti ìsinsin yìí lọ àti láéláé.
|
||
\c 132
|
||
\cl Saamu 132
|
||
\d Orin fún ìgòkè.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, rántí Dafidi
|
||
\q2 nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹni tí ó ti búra fún \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi,
|
||
\q2 tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
|
||
\q1
|
||
\v 5 títí èmi ó fi rí ibi fún \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata:
|
||
\q2 àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀:
|
||
\q2 àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 8 \nd Olúwa\nd*, dìde sí ibi ìsinmi rẹ:
|
||
\q2 ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ:
|
||
\q2 kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀,
|
||
\q2 má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 \x - \xo 132.11: \xt Sm 89.3-4; Ap 2.30.\x*\nd Olúwa\nd* ti búra nítòótọ́ fún Dafidi,
|
||
\q2 Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀,
|
||
\q2 nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́
|
||
\q2 àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn,
|
||
\q2 àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nítorí tí \nd Olúwa\nd* ti yan Sioni:
|
||
\q2 ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé:
|
||
\q2 níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé:
|
||
\q2 nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀:
|
||
\q2 èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀:
|
||
\q2 àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀,
|
||
\q2 èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀:
|
||
\q2 ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.
|
||
\c 133
|
||
\cl Saamu 133
|
||
\d Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Kíyèsi, ó ti dára ó sì ti dùn tó fún
|
||
\q2 àwọn ará láti máa jùmọ̀ gbé ní ìrẹ́pọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ó dàbí òróró ìkunra iyebíye ní orí,
|
||
\q2 tí ó sàn dé irùngbọ̀n, àní irùngbọ̀n Aaroni:
|
||
\q2 tí ó sì sàn sí etí aṣọ sórí rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Bí ìrì Hermoni
|
||
\q2 tí o sàn sórí òkè Sioni.
|
||
\q1 Nítorí níbẹ̀ ní \nd Olúwa\nd* gbé pàṣẹ ìbùkún,
|
||
\q2 àní ìyè láéláé.
|
||
\c 134
|
||
\cl Saamu 134
|
||
\d Orin ìgòkè.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ kíyèsi i, ẹ fi ìbùkún fún \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 gbogbo ẹ̀yin ìránṣẹ́ \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 tí ó dúró ní ilé \nd Olúwa\nd* ní òru.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ gbé ọwọ́ yín sókè sí ibi mímọ́,
|
||
\q2 kí ẹ sì fi ìbùkún fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 \nd Olúwa\nd* tí ó dá ọ̀run òun ayé,
|
||
\q2 kí ó bùsi i fún ọ láti Sioni wá.
|
||
\c 135
|
||
\cl Saamu 135
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ yin \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ yin orúkọ \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹ yin \nd Olúwa\nd*: nítorí tí \nd Olúwa\nd* ṣeun;
|
||
\q2 ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí tí \nd Olúwa\nd* ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀;
|
||
\q2 àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítorí tí èmi mọ̀ pé \nd Olúwa\nd* tóbi,
|
||
\q2 àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 6 \nd Olúwa\nd* ṣe ohunkóhun tí ó wù ú,
|
||
\q2 ní ọ̀run àti ní ayé,
|
||
\q2 ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá:
|
||
\q2 ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò:
|
||
\q2 ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti,
|
||
\q2 àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ẹni tí ó rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti,
|
||
\q2 sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀,
|
||
\q2 tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu,
|
||
\q2 ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:
|
||
\q1
|
||
\v 12 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
|
||
\q2 ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 \nd Olúwa\nd* orúkọ rẹ dúró láéláé;
|
||
\q2 ìrántí rẹ \nd Olúwa\nd*, láti ìrandíran.
|
||
\q1
|
||
\v 14 \x - \xo 135.14: \xt Hb 10.30.\x*Nítorí tí \nd Olúwa\nd* yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀,
|
||
\q2 yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà,
|
||
\q2 iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀;
|
||
\q2 wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀;
|
||
\q1 bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn:
|
||
\q2 gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù \nd Olúwa\nd*, fi ìbùkún fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Olùbùkún ni \nd Olúwa\nd*, láti Sioni wá,
|
||
\q2 tí ń gbé Jerusalẹmu.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 136
|
||
\cl Saamu 136
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ fi ọpẹ́ fún \nd Olúwa\nd* nítorí tí ó ṣeun;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run:
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Fún Òun nìkan tí ń ṣiṣẹ́ ìyanu ńlá;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 6 \x - \xo 136.6: \xt Gẹ 1.2.\x*Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 7 \x - \xo 136.7-9: \xt Gẹ 1.16.\x*Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Òòrùn láti jẹ ọba ọ̀sán;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Òṣùpá àti ìràwọ̀ láti jẹ ọba òru;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 \x - \xo 136.10: \xt Ek 12.29.\x*Fún ẹni tí ó kọlu Ejibiti lára àwọn àkọ́bí wọn;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 11 \x - \xo 136.11: \xt Ek 12.51.\x*Ó sì mú Israẹli jáde kúrò láàrín wọn;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 \x - \xo 136.13-15: \xt Ek 14.21-29.\x*Fún ẹni tí ó pín Òkun pupa ní ìyà;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ó sì mú Israẹli kọjá láàrín rẹ̀
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ṣùgbọ́n ó bi Farao àti ogun rẹ̀ ṣubú nínú Òkun pupa;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 16 Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn rẹ̀ la aginjù já
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 Fún ẹni tí ó kọlu àwọn ọba ńlá;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ó sì pa àwọn ọba olókìkí
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Sihoni, ọba àwọn ará Amori
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Àti Ogu, ọba Baṣani;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 22 Ìní fún Israẹli, ìránṣẹ́ rẹ̀,
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 25 Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbo
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 26 Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;
|
||
\qr nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
|
||
\c 137
|
||
\cl Saamu 137
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ní ẹ̀bá odò Babeli, níbẹ̀ ni àwa gbé jókòó
|
||
\q2 àwa sì sọkún nígbà tí àwa rántí Sioni.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Àwa fi dùùrù wa kọ́ sí orí igi wílò,
|
||
\q2 tí ó wà láàrín rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nítorí pé níbẹ̀ ni àwọn
|
||
\q2 tí ó kó wa ní ìgbèkùn béèrè orin lọ́wọ́ wa,
|
||
\q1 àti àwọn tí ó ni wá lára béèrè ìdárayá;
|
||
\q2 wọn wí pé, “Ẹ kọ orin Sioni kan fún wa!”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Àwa ó ti ṣe kọ orin
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* ní ilẹ̀ àjèjì
|
||
\q1
|
||
\v 5 Jerusalẹmu, bí èmi bá gbàgbé rẹ
|
||
\q2 jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó gbàgbé ìlò rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Bí èmi kò bá rántí rẹ,
|
||
\q2 jẹ́ kí ahọ́n mi kí ó lẹ̀ mọ́ èrìgì mi;
|
||
\q1 bí èmi kò bá fi Jerusalẹmu ṣáájú
|
||
\q2 olórí ayọ̀ mi gbogbo.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 \nd Olúwa\nd* rántí ọjọ́ Jerusalẹmu,
|
||
\q2 lára àwọn ọmọ Edomu,
|
||
\q1 àwọn ẹni tí ń wí pé,
|
||
\q2 “Wó o palẹ̀, wó o palẹ̀ dé ìpìlẹ̀ rẹ̀!”
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ìwọ, ọmọbìnrin Babeli, ẹni tí a ó parun;
|
||
\q2 ìbùkún ni fún ẹni tí ó san án fún ọ
|
||
\q2 bí ìwọ ti rò sí wa.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó mú ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ
|
||
\q2 tí ó sì fi wọ́n ṣán òkúta.
|
||
\c 138
|
||
\cl Saamu 138
|
||
\d Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi yóò yìn ọ́ tinútinú mi gbogbo;
|
||
\q2 níwájú àwọn òrìṣà ni èmi ó kọrin ìyìn sí ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Èmi ó máa gbàdúrà sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀
|
||
\q2 èmi ó sì máa yin orúkọ rẹ
|
||
\q1 nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ;
|
||
\q2 nítorí ìwọ gbé ọ̀rọ̀ rẹ ga ju orúkọ rẹ lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ní ọjọ́ tí mo ké pè é ọ́, ìwọ dá mi lóhùn,
|
||
\q2 ìwọ sì fi ipa mú mi lára le ní ọkàn mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 Gbogbo àwọn ọba ayé yóò yìn ọ́,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, ní ìgbà tí wọn bá gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Nítòótọ́, wọn ó máa kọrin ní ipa ọ̀nà \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 nítorí pé ńlá ni ògo \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Bí \nd Olúwa\nd* tilẹ̀ ga, síbẹ̀ ó júbà àwọn onírẹ̀lẹ̀;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n agbéraga ni ó mọ̀ ní òkèrè réré.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Bí èmi tilẹ̀ ń rìn nínú ìpọ́njú ìwọ ni yóò sọ mi di ààyè;
|
||
\q2 ìwọ ó na ọwọ́ rẹ sí àwọn ọ̀tá mi,
|
||
\q2 ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì gbà mí.
|
||
\q1
|
||
\v 8 \nd Olúwa\nd* yóò ṣe ohun tí ń ṣe tèmi láṣepé;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, àánú rẹ dúró láéláé;
|
||
\q2 má ṣe kọ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ sílẹ̀.
|
||
\c 139
|
||
\cl Saamu 139
|
||
\d Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, ìwọ tí wádìí mi,
|
||
\q2 ìwọ sì ti mọ̀ mí.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ìwọ mọ̀ ìjókòó mi àti ìdìde mi,
|
||
\q2 ìwọ mọ̀ èrò mi ní ọ̀nà jíjìn réré.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ìwọ yí ipa ọ̀nà mi ká àti ìdùbúlẹ̀ mi,
|
||
\q2 gbogbo ọ̀nà mi sì di mí mọ̀ fún ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí tí kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ahọ́n mi,
|
||
\q2 kíyèsi i, \nd Olúwa\nd*, ìwọ mọ̀ ọ́n pátápátá.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìwọ sé mi mọ́ lẹ́yìn àti níwájú,
|
||
\q2 ìwọ sì fi ọwọ́ rẹ lé mi.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Irú ìmọ̀ yìí jẹ ohun ìyanu fún mi jù;
|
||
\q2 ó ga, èmi kò le mọ̀ ọ́n.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Níbo ní èmi yóò gbé lọ kúrò ni ọwọ́ ẹ̀mí rẹ?
|
||
\q2 Tàbí níbo ni èmi yóò sáré kúrò níwájú rẹ?
|
||
\q1
|
||
\v 8 Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀;
|
||
\q2 bí èmí ba sì tẹ́ ẹní mi ní ipò òkú,
|
||
\q2 kíyèsi i, ìwọ wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀,
|
||
\q2 kí èmi sì lọ jókòó ní ìhà òpin Òkun,
|
||
\q1
|
||
\v 10 àní, níbẹ̀ náà ni ọwọ́ rẹ̀ yóò fà mí
|
||
\q2 ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì dì mímú.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Bí mo bá wí pé, “Ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀;
|
||
\q2 kí ìmọ́lẹ̀ kí ó di òru yí mi ká.”
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọ́dọ̀ rẹ;
|
||
\q2 ṣùgbọ́n òru tan ìmọ́lẹ̀ bí ọ̀sán;
|
||
\q2 àti òkùnkùn àti ọ̀sán, méjèèjì bákan náà ní fún ọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nítorí ìwọ ni ó dá ọkàn mi;
|
||
\q2 ìwọ ni ó bò mí mọ́lẹ̀ nínú ìyá mi.
|
||
\q1
|
||
\v 14 Èmi yóò yìn ọ, nítorí tẹ̀rù tẹ̀rù àti tìyanu tìyanu ní a dá mi;
|
||
\q2 ìyanu ní iṣẹ́ rẹ;
|
||
\q2 èyí nì ni ọkàn mi sì mọ̀ dájúdájú.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ,
|
||
\q2 nígbà tí a dá mi ní ìkọ̀kọ̀.
|
||
\q2 Tí a sì ń ṣiṣẹ́ ní àràbarà ní ìhà ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
|
||
\q1
|
||
\v 16 ojú rẹ ti rí ohun ara mi
|
||
\q2 nígbà tí a kò tí ì ṣe mí pé,
|
||
\q2 àti nínú ìwé rẹ ni a ti kọ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sí,
|
||
\q1 ní ọjọ́ tí a dá wọn,
|
||
\q2 nígbà tí wọn kò tilẹ̀ tí ì sí.
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ọlọ́run, èrò inú rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi,
|
||
\q2 iye wọn ti pọ̀ tó!
|
||
\q1
|
||
\v 18 Èmi ìbá kà wọ́n,
|
||
\q2 wọ́n ju iyanrìn lọ ní iye:
|
||
\q1 nígbà tí mo bá jí,
|
||
\q2 èmi yóò wà lọ́dọ̀ rẹ síbẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa àwọn ènìyàn búburú nítòótọ́;
|
||
\q2 nítorí náà kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin ọkùnrin ẹlẹ́jẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ,
|
||
\q2 àwọn ọ̀tá rẹ ń pe orúkọ rẹ ní asán!
|
||
\q1
|
||
\v 21 \nd Olúwa\nd*, ǹjẹ́ èmi kò kórìíra àwọn tó kórìíra rẹ?
|
||
\q2 Ǹjẹ́ inú mi kò a sì bàjẹ́ sí àwọn tí ó dìde sí ọ?
|
||
\q1
|
||
\v 22 Èmi kórìíra wọn ní àkótán;
|
||
\q2 èmi kà wọ́n sí ọ̀tá mi.
|
||
\q1
|
||
\v 23 Ọlọ́run, wádìí mi, kí o sì mọ ọkàn mí;
|
||
\q2 dán mi wò, kí o sì mọ ìrò inú mi.
|
||
\q1
|
||
\v 24 Kí ó sì wò ó bí ipa ọ̀nà búburú
|
||
\q2 kan bá wà nínú mi kí ó sì
|
||
\q2 fi ẹsẹ̀ mi lé ọ̀nà àìnípẹ̀kun.
|
||
\c 140
|
||
\cl Saamu 140
|
||
\d Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì,
|
||
\q2 yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
|
||
\q1
|
||
\v 2 ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn;
|
||
\q2 nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò,
|
||
\q2 oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 4 \nd Olúwa\nd*, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú;
|
||
\q2 yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì
|
||
\q2 ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn:
|
||
\q2 wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà;
|
||
\q2 wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmi wí fún \nd Olúwa\nd* pé ìwọ ni Ọlọ́run mi;
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd*, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 7 \nd Olúwa\nd* Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi,
|
||
\q2 ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
|
||
\q1
|
||
\v 8 \nd Olúwa\nd*, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un;
|
||
\q2 má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́;
|
||
\q2 kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni,
|
||
\q2 jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára,
|
||
\q2 Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná,
|
||
\q1 sínú ọ̀gbun omi jíjìn,
|
||
\q2 kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé;
|
||
\q2 ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Èmi mọ̀ pé, \nd Olúwa\nd* yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró,
|
||
\q2 yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò
|
||
\q2 máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ;
|
||
\q2 àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.
|
||
\c 141
|
||
\cl Saamu 141
|
||
\d Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd*, èmi ké pè ọ́; yára wá sí ọ̀dọ̀ mi.
|
||
\q2 Gbọ́ ohùn mi, nígbà tí mo bá ń ké pè ọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Jẹ́ kí àdúrà mi ó wá sí iwájú rẹ bí ẹbọ tùràrí
|
||
\q2 àti ìgbé ọwọ́ mi si òkè rí bí ẹbọ àṣálẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Fi ẹ̀ṣọ́ ṣọ́ ẹnu mi, \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 kí o sì máa pa ìlẹ̀kùn ètè mi mọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn mi fà sí ohun tí ń ṣe ibi,
|
||
\q2 láti máa bá àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ búburú
|
||
\q2 má sì ṣe jẹ́ kí èmi jẹ àdídùn wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Jẹ́ kí olódodo lù mí, ìṣeun ni ó jẹ́:
|
||
\q2 jẹ́ kí ó bá mi wí, ó jẹ́ òróró ní orí mi.
|
||
\q2 Tí kì yóò fọ́ mi ní orí.
|
||
\b
|
||
\q1 Síbẹ̀ àdúrà mi wá láìsí ìṣe àwọn olùṣe búburú.
|
||
\q2
|
||
\v 6 A ó ju àwọn alákòóso sílẹ̀ láti bẹ̀bẹ̀ òkúta,
|
||
\q2 àwọn ẹni búburú yóò kọ pé àwọn ọ̀rọ̀ mi dùn.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Wọn yóò wí pé, “Bí ẹni tí ó la aporo sórí ilẹ̀,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni egungun wa tànkálẹ̀ ní ẹnu isà òkú.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ṣùgbọ́n ojú mi ń bẹ lára rẹ, \nd Olúwa\nd* Olódùmarè;
|
||
\q2 nínú rẹ̀ ni èmi ti rí ààbò, má ṣe fà mi fún ikú.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Pa mí mọ́ kúrò nínú okùn tí wọn ti dẹ sílẹ̀ fún mi,
|
||
\q2 kúrò nínú ìkẹ́kùn àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Jẹ́ kí àwọn ẹni búburú ṣubú sínú àwọ̀n ara wọn,
|
||
\q2 nígbà tí èmi bá kọjá lọ láìléwu.
|
||
\c 142
|
||
\cl Saamu 142
|
||
\d Maskili ti Dafidi. Nígbà tí ó wà nínú ihò òkúta. Àdúrà.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi kígbe sókè sí \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 èmi gbé ohùn mi sókè sí \nd Olúwa\nd* fún àánú.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Èmi tú àròyé mí sílẹ̀ níwájú rẹ̀,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ní èmi fi iṣẹ́ mi hàn níwájú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Nígbà tí ẹ̀mí mi ṣàárẹ̀ nínú mi,
|
||
\q2 ìwọ ni ẹni tí ó mọ ọ̀nà mi.
|
||
\q1 Ní ipa ọ̀nà tí èmi ń rìn
|
||
\q2 ènìyàn ti dẹ okùn fún mi ní ìkọ̀kọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Wo ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó sì rì i
|
||
\q2 kò sí ẹni tí ó ṣe àníyàn mi
|
||
\q1 èmi kò ní ààbò;
|
||
\q2 kò sí ẹni tí ó náání ọkàn mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Èmi kígbe sí ọ, \nd Olúwa\nd*:
|
||
\q2 èmi wí pé, “Ìwọ ni ààbò mi,
|
||
\q2 ìpín mi ní ilẹ̀ alààyè.”
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Fi etí sí igbe mi,
|
||
\q2 nítorí tí èmi wà nínú àìnírètí
|
||
\q1 gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi,
|
||
\q2 nítorí wọ́n lágbára jù mí lọ.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Mú ọkàn mi jáde kúrò nínú túbú,
|
||
\q2 kí èmi lè máa yin orúkọ rẹ.
|
||
\q1 Nígbà náà ni àwọn olódodo yóò yí mi káàkiri
|
||
\q2 nítorí ìwọ yóò fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ba mi ṣe.
|
||
\c 143
|
||
\cl Saamu 143
|
||
\d Saamu ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 \nd Olúwa\nd* gbọ́ àdúrà mi,
|
||
\q2 fetísí igbe mi fún àánú;
|
||
\q2 nínú òtítọ́ àti òdodo rẹ, wá fún ìrànlọ́wọ́ mi.
|
||
\q1
|
||
\v 2 \x - \xo 143.2: \xt Sm 130.3; Ro 3.20; Ga 2.16.\x*Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìdájọ́,
|
||
\q2 nítorí kò sí ẹnìkan tí ó wà láààyè
|
||
\q2 tí ó ṣe òdodo níwájú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ọ̀tá ń lépa mi,
|
||
\q2 ó fún mi pamọ́ ilẹ̀;
|
||
\q1 ó mú mi gbé nínú òkùnkùn
|
||
\q2 bí àwọn tí ó ti kú ti pẹ́.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí náà ẹ̀mí mi ṣe rẹ̀wẹ̀sì nínú mi;
|
||
\q2 ọkàn mi nínú mi ṣì pòruurù.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Èmi rántí ọjọ́ tí ó ti pẹ́;
|
||
\q2 èmi ń ṣe àṣàrò lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ
|
||
\q2 mo sì ṣe àkíyèsí ohun tí ọwọ́ rẹ ti ṣe.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Èmi na ọwọ́ mi jáde sí ọ:
|
||
\q2 òǹgbẹ rẹ gbẹ ọkàn mi bí i ìyàngbẹ ilẹ̀. \qs Sela.\qs*
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Dá mi lóhùn kánkán, \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 ó rẹ ẹ̀mí mi tán.
|
||
\q1 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lára mi
|
||
\q2 kí èmi má ba à dàbí àwọn tí ó lọ sínú ihò.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Mú mi gbọ́ ìṣeun ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀:
|
||
\q2 nítorí ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé.
|
||
\q1 Fi ọ̀nà tí èmi i bá rìn hàn mí,
|
||
\q2 nítorí èmi gbé ọkàn mi sókè sí ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi, \nd Olúwa\nd*,
|
||
\q2 nítorí èmi fi ara mi pamọ́ sínú rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Kọ́ mi láti ṣe ìfẹ́ rẹ,
|
||
\q2 nítorí ìwọ ni Ọlọ́run mi
|
||
\q1 jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ dídára
|
||
\q2 darí mi sí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 11 Nítorí orúkọ rẹ, \nd Olúwa\nd*, sọ mi di ààyè;
|
||
\q2 nínú òdodo rẹ, mú ọkàn mi jáde nínú wàhálà.
|
||
\q1
|
||
\v 12 Nínú ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà, ké àwọn ọ̀tá mi kúrò,
|
||
\q2 run gbogbo àwọn tí ń ni ọkàn mi lára,
|
||
\q2 nítorí pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ.
|
||
\c 144
|
||
\cl Saamu 144
|
||
\d Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ìyìn sí \nd Olúwa\nd* àpáta mi,
|
||
\q2 ẹni tí ó kọ́ ọwọ́ mi fún ogun,
|
||
\q2 àti ìka mi fún ìjà.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Òun ni Ọlọ́run ìfẹ́ mi àti odi alágbára mi,
|
||
\q2 ibi gíga mi àti olùgbàlà mi, asà mi,
|
||
\q1 ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé,
|
||
\q2 ẹni tí ó tẹrí àwọn ènìyàn ba lábẹ́ mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 \nd Olúwa\nd*, kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣàníyàn fún un,
|
||
\q2 tàbí ọmọ ènìyàn tí ìwọ fi ń ronú nípa rẹ̀?
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ènìyàn rí bí èmi;
|
||
\q2 ọjọ́ rẹ̀ rí bí òjìji tí ń kọjá lọ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Tẹ ọ̀run rẹ ba, \nd Olúwa\nd*, kí o sì sọ̀kalẹ̀;
|
||
\q2 tọ́ àwọn òkè ńlá wọn yóò sí rú èéfín.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Rán mọ̀nàmọ́ná kí ó sì fọ́n àwọn ọ̀tá ká;
|
||
\q2 ta ọfà rẹ kí ó sì dà wọ́n rú.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Na ọwọ́ rẹ sílẹ̀ láti ibi gíga;
|
||
\q2 gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu
|
||
\q1 kúrò nínú omi ńlá:
|
||
\q2 kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì.
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ẹnu ẹni tí ó kún fún èké
|
||
\q2 ẹni tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jẹ́ ìrẹ́jẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 Èmi yóò kọ orin tuntun sí ọ
|
||
\q2 Ọlọ́run; lára ohun èlò orin
|
||
\q1 olókùn mẹ́wàá èmi yóò
|
||
\q2 kọ orin sí ọ.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Òun ni ó fi ìgbàlà fún àwọn ọba,
|
||
\q2 ẹni tí ó gba Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ idà ìpanilára.
|
||
\b
|
||
\q1 Lọ́wọ́ pípanirun.
|
||
\v 11 Gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu
|
||
\q2 kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì
|
||
\q1 tí ẹnu wọn kún fún èké,
|
||
\q2 tí ọwọ́ ọ̀tún wọn jẹ́ ọwọ́ ọ̀tún èké.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Kí àwọn ọmọkùnrin wa
|
||
\q2 kí ó dàbí igi gbígbìn tí ó dàgbà ni ìgbà èwe wọn,
|
||
\q1 àti ọmọbìnrin wa yóò dàbí òpó ilé
|
||
\q2 tí a ṣe ọ̀nà sí bí àfarawé ààfin.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Àká wa yóò kún
|
||
\q2 pẹ̀lú gbogbo onírúurú oúnjẹ
|
||
\q1 àgùntàn wa yóò pọ̀ si ní ẹgbẹ̀rún,
|
||
\q2 ní ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní oko wa:
|
||
\q1
|
||
\v 14 àwọn màlúù wa yóò ru ẹrù wúwo
|
||
\q2 kí ó má sí ìkọlù,
|
||
\q1 kí ó má sí ìkólọ sí ìgbèkùn,
|
||
\q2 kí ó má sí i igbe ìpọ́njú ní ìgboro wa.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà tí ó wà ní irú ipò bẹ́ẹ̀,
|
||
\q2 ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà,
|
||
\q2 tí ẹni tí Ọlọ́run \nd Olúwa\nd* ń ṣe.
|
||
\c 145
|
||
\cl Saamu 145
|
||
\d Saamu ìyìn. Ti Dafidi.
|
||
\q1
|
||
\v 1 Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi;
|
||
\q2 èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́
|
||
\q2 èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 3 Títóbi ni \nd Olúwa\nd*. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀:
|
||
\q2 kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn;
|
||
\q2 wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo,
|
||
\q2 èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 6 Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù
|
||
\q2 èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀
|
||
\q2 ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Olóore-ọ̀fẹ́ ni \nd Olúwa\nd* àti aláàánú
|
||
\q2 ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 9 \nd Olúwa\nd* dára sí ẹni gbogbo;
|
||
\q2 ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
|
||
\q1
|
||
\v 10 Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni
|
||
\q2 yóò máa yìn ọ́ \nd Olúwa\nd*;
|
||
\q2 àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 11 Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ
|
||
\q2 wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
|
||
\q1
|
||
\v 12 kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀
|
||
\q2 àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni,
|
||
\q2 àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
|
||
\q1
|
||
\v 14 \nd Olúwa\nd* mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró
|
||
\q2 ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
|
||
\q1
|
||
\v 15 Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́,
|
||
\q2 ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ
|
||
\q2 ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 17 \nd Olúwa\nd* jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀
|
||
\q2 àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
|
||
\q1
|
||
\v 18 \nd Olúwa\nd* wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é,
|
||
\q2 sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ;
|
||
\q2 ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 20 \nd Olúwa\nd* dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí
|
||
\q2 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni
|
||
\q2 búburú ní yóò parun.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 21 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q2 Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.
|
||
\c 146
|
||
\cl Saamu 146
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1 Fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*, ìwọ ọkàn mi.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Èmi yóò yin \nd Olúwa\nd* ní gbogbo ayé mi,
|
||
\q2 èmi yóò kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, níwọ̀n ìgbà tí mo bá wà láààyè.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹ má ṣe ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú àwọn ọmọ-aládé,
|
||
\q2 àní, ọmọ ènìyàn,
|
||
\q2 lọ́wọ́ ẹni tí kò sí ìrànlọ́wọ́.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ẹ̀mí rẹ jáde lọ, ó padà sí erùpẹ̀,
|
||
\q2 ní ọjọ́ náà gan, èrò wọn yóò di òfo.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ìbùkún ni fún ẹni tí
|
||
\q2 Ọlọ́run Jakọbu ń ṣe ìrànlọ́wọ́ rẹ̀
|
||
\q2 tí ìrètí rẹ̀ wà nínú \nd Olúwa\nd* Ọlọ́run rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ẹni tí ó dá ọ̀run àti ayé,
|
||
\q2 òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn,
|
||
\q2 ẹni tí ó pa òtítọ́ mọ́ títí ayé.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ẹni tí ń ṣe ìdájọ́ àwọn tí a ni lára,
|
||
\q2 tí ó fi oúnjẹ fún àwọn tí ebi ń pa,
|
||
\q1 \nd Olúwa\nd*, tú àwọn oǹdè sílẹ̀,
|
||
\q2
|
||
\v 8 \nd Olúwa\nd* mú àwọn afọ́jú ríran,
|
||
\q1 \nd Olúwa\nd*, gbé àwọn tí a rẹ̀ sílẹ̀ ga,
|
||
\q2 \nd Olúwa\nd* fẹ́ràn àwọn olódodo.
|
||
\q1
|
||
\v 9 \nd Olúwa\nd* ń dá ààbò bo àwọn àlejò
|
||
\q2 ó sì ń dá àwọn aláìní baba àti opó sí
|
||
\q2 ṣùgbọ́n ó ba ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú jẹ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 \nd Olúwa\nd* jẹ ọba títí láé;
|
||
\q2 Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni, àti fún gbogbo ìran.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 147
|
||
\cl Saamu 147
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1 Nítorí ohun rere ni láti máa kọrin ìyìn sí Ọlọ́run wa,
|
||
\q2 ó yẹ láti kọrin ìyìn sí i!
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 \nd Olúwa\nd* kọ́ Jerusalẹmu;
|
||
\q2 Ó kó àwọn Israẹli tí a lé sọnù jọ.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ sàn
|
||
\q2 ó sì di ọgbẹ́ wọ́n.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ó ka iye àwọn ìràwọ̀
|
||
\q2 ó sì pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní orúkọ.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Títóbi ni Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbára
|
||
\q2 òye rẹ̀ kò sì ní òpin.
|
||
\q1
|
||
\v 6 \nd Olúwa\nd* wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni ó rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Fi ọpẹ́ kọrin sí \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 8 Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀
|
||
\q2 ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé
|
||
\q2 ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè
|
||
\q1
|
||
\v 9 Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko
|
||
\q2 àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 10 Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin,
|
||
\q2 bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin
|
||
\q1
|
||
\v 11 \nd Olúwa\nd* ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
|
||
\q2 sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 12 Yin \nd Olúwa\nd*, ìwọ Jerusalẹmu;
|
||
\q2 yin Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ibodè rẹ̀ lágbára,
|
||
\q2 Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ rẹ̀ nínú rẹ
|
||
\q1
|
||
\v 14 Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè rẹ̀,
|
||
\q2 òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 15 Òun sì rán àṣẹ rẹ̀ sí ayé
|
||
\q2 ọ̀rọ̀ rẹ̀ sáré tete.
|
||
\q1
|
||
\v 16 Ó fi yìnyín fún ni bi irun àgùntàn
|
||
\q2 ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú
|
||
\q1
|
||
\v 17 Ó rọ òjò yìnyín rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́
|
||
\q2 ta ni ó lè dúró níwájú òtútù rẹ̀
|
||
\q1
|
||
\v 18 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀
|
||
\q2 ó mú kí afẹ́fẹ́ rẹ̀ fẹ́
|
||
\q2 ó sì mú odò rẹ̀ sàn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 19 Ó sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ di mí mọ̀ fún Jakọbu
|
||
\q2 àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀ fún Israẹli.
|
||
\q1
|
||
\v 20 Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀-èdè kan rí, bí ó ṣe ti ìdájọ́ rẹ̀
|
||
\q2 wọn ko mọ òfin rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 148
|
||
\cl Saamu 148
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd* láti ọ̀run wá,
|
||
\q2 ẹ fi ìyìn fún un níbi gíga.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ fi ìyìn fún un,
|
||
\q2 gbogbo ẹ̀yin angẹli rẹ̀,
|
||
\q1 ẹ fi ìyìn fún un,
|
||
\q2 gbogbo ẹ̀yin ọmọ-ogun rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹ fi ìyìn fún un,
|
||
\q2 oòrùn àti òṣùpá.
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún un,
|
||
\q2 gbogbo ẹ̀yin ìràwọ̀ ìmọ́lẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ẹ fi ìyìn fún un,
|
||
\q2 ẹ̀yin ọ̀run àti àwọn ọ̀run gíga
|
||
\q2 àti ẹ̀yin omi tí ń bẹ ní òkè ọ̀run.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹ jẹ́ kí wọn kí ó yin orúkọ \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 nítorí ó pàṣẹ a sì dá wọn
|
||
\q1
|
||
\v 6 Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láé àti láéláé
|
||
\q2 ó sì ti ṣe ìlànà kan tí kì yóò já.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 7 Ẹ yin \nd Olúwa\nd* láti ilẹ̀ ayé wá
|
||
\q2 ẹ̀yin ẹ̀dá inú òkun títóbi
|
||
\q2 àti ẹ̀yin ibú òkun,
|
||
\q1
|
||
\v 8 mọ̀nàmọ́ná àti òjò yìnyín
|
||
\q2 ìdí omi àti àwọn ìkùùkuu,
|
||
\q2 ìjì líle tí ń mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ,
|
||
\q1
|
||
\v 9 òkè ńlá àti gbogbo òkè kéékèèké,
|
||
\q2 igi eléso àti gbogbo igi kedari,
|
||
\q1
|
||
\v 10 àwọn ẹranko ńlá àti ẹran ọ̀sìn
|
||
\q2 gbogbo ohun afàyàfà àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́,
|
||
\q1
|
||
\v 11 àwọn ọba ayé àti ènìyàn ayé gbogbo
|
||
\q2 àwọn ọmọ-aládé àti gbogbo àwọn onídàájọ́ ayé,
|
||
\q1
|
||
\v 12 ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin
|
||
\q2 àwọn arúgbó àti àwọn ọmọdé.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 13 Ẹ jẹ́ kí wọn kí ó yin orúkọ \nd Olúwa\nd*
|
||
\q2 nítorí orúkọ rẹ̀ nìkan ni ó ní ọlá
|
||
\q2 ògo rẹ̀ kọjá ayé àti ọ̀run
|
||
\q1
|
||
\v 14 Ó sì gbé ìwo kan sókè fún àwọn ènìyàn rẹ̀,
|
||
\q2 ìyìn fún gbogbo ènìyàn mímọ́ rẹ̀ àní fún àwọn ọmọ Israẹli,
|
||
\q2 àwọn ènìyàn tí ó súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 149
|
||
\cl Saamu 149
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ kọrin tuntun sí \nd Olúwa\nd*.
|
||
\q2 Ẹ yìn ín ní àwùjọ àwọn ènìyàn mímọ́.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 2 Jẹ́ kí Israẹli kí ó ní inú dídùn sí ẹni tí ó dá a
|
||
\q2 jẹ́ kí àwọn ọmọ Sioni kí ó ní
|
||
\q2 ayọ̀ nínú ọba wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Jẹ́ kí wọn kí ó fi ijó yin orúkọ rẹ̀
|
||
\q2 jẹ́ kí wọn kí ó fi ohun èlò orin kọrin ìyìn sí i.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Nítorí \nd Olúwa\nd* ní inú dídùn sí àwọn ènìyàn rẹ̀
|
||
\q2 ó fi ìgbàlà dé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ládé.
|
||
\q1
|
||
\v 5 Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mímọ́ kí ó yọ̀ nínú ọlá rẹ̀
|
||
\q2 kí wọn kí ó máa kọrin fún ayọ̀ ní orí ibùsùn wọn.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Kí ìyìn Ọlọ́run kí ó wà ní ẹnu wọn
|
||
\q2 àti idà olójú méjì ní ọwọ́ wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 7 Láti gba ẹ̀san lára àwọn orílẹ̀-èdè,
|
||
\q2 àti ìjìyà lára àwọn ènìyàn,
|
||
\q1
|
||
\v 8 láti fi ẹ̀wọ̀n de àwọn ọba wọn
|
||
\q2 àti láti fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀
|
||
\q1 irin de àwọn ọlọ́lá wọn.
|
||
\q1
|
||
\v 9 Láti ṣe ìdájọ́ tí àkọsílẹ̀ rẹ̀ sí wọn
|
||
\q2 èyí ni ògo àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\c 150
|
||
\cl Saamu 150
|
||
\q1
|
||
\v 1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún Ọlọ́run ní ibi mímọ́ rẹ̀,
|
||
\q2 ẹ yìn ín nínú agbára ọ̀run rẹ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 2 Ẹ yìn ín fún iṣẹ́ agbára rẹ̀.
|
||
\q2 Ẹ yìn ín fún títóbi rẹ̀ tí ó tayọ̀.
|
||
\q1
|
||
\v 3 Ẹ fi ohùn ìpè yìn ín.
|
||
\q2 Ẹ fi ohun èlò orin yìn ín.
|
||
\q1
|
||
\v 4 Ẹ fi ohun èlò orin àti ijó yìn ín
|
||
\q2 fi ohun èlò orin olókùn àti ìpè yìn ín,
|
||
\q1
|
||
\v 5 Ẹ yìn ín pẹ̀lú aro olóhùn òkè,
|
||
\q2 ẹ yìn ín lára aro olóhùn gooro.
|
||
\b
|
||
\q1
|
||
\v 6 Jẹ́ kí gbogbo ohun tí ó ní ẹ̀mí yin \nd Olúwa\nd*.
|
||
\b
|
||
\q1 Ẹ fi ìyìn fún \nd Olúwa\nd*.
|